< Psalmów 11 >

1 Przedniejszemu śpiewakowi psalm Dawidowy. W Panu ja ufam. Jakoż tedy mówicie duszy mojej: Ulatuj jako ptak z góry swojej?
Fún adarí orin. Ti Dafidi. Ìgbẹ́kẹ̀lé mi wà nínú Olúwa. Báwo ní ẹ̀yin ó ṣe sọ fún ọkàn mi pé, “Fò gẹ́gẹ́ bi ẹyẹ lọ si orí òkè rẹ.
2 Bo oto niepobożni naciągają łuk, przykładają strzałę swą na cięciwę, aby strzelali w ciemności na uprzejmych sercem.
Wò ó nítorí náà, ènìyàn búburú fa ọfà rẹ̀; wọn ti fi ọfà wọn sí ojú okùn láti tafà níbi òjìji sí àyà ẹni ìdúró ṣinṣin.
3 Ale zamysły ich będą skażone; bo sprawiedliwy cóż uczynił?
Nígbà tí ìpìlẹ̀ bá bàjẹ́ kí ni olódodo yóò ṣe?”
4 Pan jest w kościele świętem swoim, stolica Pańska jest na niebie; oczy jego upatrują, powieki jego doświadczają synów ludzkich.
Olúwa ń bẹ nínú tẹmpili mímọ́ rẹ̀; Olúwa ń bẹ lórí ìtẹ́ rẹ̀ ní ọ̀run. Ó ń wo àwọn ọmọ ènìyàn; ojú rẹ̀ ń yẹ̀ wọ́n wò.
5 Pan doświadcza sprawiedliwego; ale niepobożnego i miłującego nieprawość ma w nienawiści dusza jego.
Olúwa ń yẹ olódodo wò, ṣùgbọ́n ènìyàn búburú àti àwọn tí o fẹ́ ìwà ipá ni ọkàn rẹ̀ kórìíra.
6 Wyleje jako deszcz na niepobożnych sidła, ogień i siarkę, a wicher będzie cząstką kielicha ich.
Sí orí àwọn ènìyàn búburú ni yóò rọ̀jò ẹ̀yín iná àti imí-ọjọ́ tí ń jó; àti ìjì gbígbóná ní yóò jẹ ìpín wọn.
7 Bo sprawiedliwy Pan, sprawiedliwość miłuje, na szczerego patrzą oczy jego.
Nítorí, olódodo ní Olúwa, o fẹ́ràn òdodo; ẹni ìdúró ṣinṣin yóò sì rí i.

< Psalmów 11 >