< Psalmów 104 >

1 Błogosław, duszo moja! Panu. Panie, Boże mój! wielceś jest wielmożnym; chwałę i ozdobę przyoblokłeś.
Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi. Olúwa Ọlọ́run mi, ìwọ tóbi jọjọ; ọlá àti ọláńlá ni ìwọ wọ̀ ní aṣọ.
2 Przyodziałeś się światłością jako szatą; rozciągnąłeś niebiosa jako oponę.
Ìwọ fi ìmọ́lẹ̀ bo ara rẹ gẹ́gẹ́ bí aṣọ; ó tẹ ọ̀run bí títẹ́ ẹní,
3 Któryś zasklepił na wodach pałace swoje; który używasz obłoków miasto wozów; który chodzisz na skrzydłach wiatrowych;
ìwọ tí ó fi omi ṣe ìtì igi àjà ìyẹ̀wù rẹ. Ìwọ tí o ṣe àwọsánmọ̀ ní kẹ̀kẹ́ ogun rẹ ìwọ tí ó ń rìn lórí apá ìyẹ́ afẹ́fẹ́.
4 Który czynisz duchy posłami swymi; ty czynisz sługi swe ogniem pałającym.
Ó fi ẹ̀fúùfù ṣe àwọn ìránṣẹ́ rẹ, ọ̀wọ́-iná ni àwọn olùránṣẹ́ rẹ.
5 Ugruntowałeś ziemię na słupach jej, tak, że się nie poruszy na wieki wieczne.
O fi ayé gúnlẹ̀ lórí àwọn ìpìlẹ̀; tí a kò le è mì láéláé.
6 Przepaścią jako szatą przyodziałeś ją był, tak, że wody stały nad górami.
Ìwọ fi ibú omi bò ó mọ́lẹ̀ bí aṣọ; àwọn omi sì dúró lórí àwọn òkè ńlá.
7 Na zgromienie twojerozbiegły się, a na głos pogromu twego prędko zuciekały.
Ṣùgbọ́n nípa ìbáwí rẹ ni àwọn omi lọ, nípa ohùn àrá rẹ ni wọ́n sálọ.
8 Wstąpiły góry, zniżyły się doliny na miejsce, któreś im założył.
wọ́n sàn kọjá lórí àwọn òkè, wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ sí àwọn pẹ̀tẹ́lẹ̀, sí ibi tí ìwọ ti yàn fún wọn.
9 Zamierzyłeś im kres, aby go nie przestępowały, ani się wracały na okrycie ziemi.
Ìwọ gbé òpin tí wọn kò lè kọjá rẹ̀ kálẹ̀; láéláé ni wọ́n kò ní lè bo ayé mọ́lẹ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i.
10 Który wypuszczasz źródła po dolinach, aby płynęły między górami,
Ìwọ mú kí ìsun da omi sí àwọn àfonífojì; tí ó ń sàn láàrín àwọn òkè.
11 A napój dawały wszystkiemu zwierzowi polnemu; a z nich gaszą leśne osły pragnienie swoje.
Wọ́n fún gbogbo àwọn ẹranko igbó ní omi àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ń pa òǹgbẹ wọn.
12 Przy nich mieszka ptastwo niebieskie, a z pośród gałązek głos wydaje.
Àwọn ẹyẹ ojú òfúrufú tẹ́ ìtẹ́ wọn lẹ́gbẹ̀ẹ́ omi wọ́n ń kọrin láàrín àwọn ẹ̀ka.
13 Który pokrapiasz góry z pałaców swoich, aby się z owoców spraw twoich nasycała ziemia.
Ó bu omi rin àwọn òkè láti ìyẹ̀wù rẹ̀ wá; a tẹ́ ayé lọ́rùn nípa èso iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
14 Za twoją sprawą rośnie trawa dla bydła, a zioła na pożytek człowieczy; ty wywodzisz chleb z ziemi:
Ó mú kí koríko hù jáde fún àwọn ẹranko láti jẹ àti àwọn ewébẹ̀ fún ènìyàn láti lò, kí ó lè mú oúnjẹ jáde láti ilẹ̀ wá.
15 I wino, które uwesela serce człowiecze, od którego się lśni twarz jako od oleju; i chleb, który zatrzymuje żywot ludzki.
Ọtí wáìnì tí ó ń mú ọkàn ènìyàn yọ̀, òróró láti mú ojú rẹ̀ tan, àti àkàrà láti ra ọkàn rẹ̀ padà.
16 Nasycone bywają i drzewa Pańskie, i cedry Libanu, których nasadził;
Àwọn igi Olúwa ni a bu omi rin dáradára, kedari ti Lebanoni tí ó gbìn.
17 Na których ptaki gniazda swe mają, i bocian na jedlinach ma dom swój.
Níbẹ̀ ní àwọn ẹyẹ ṣe ìtẹ́ wọn bí ó ṣe tí àkọ̀ ni, orí igi gíga ni ilé rẹ̀.
18 Góry wysokie dzikim kozom, a skały są ucieczką królikom.
Àwọn òkè gíga ni ààbò fún àwọn ewúrẹ́ igbó; àti àwọn àlàpà jẹ́ ààbò fún àwọn ehoro.
19 Uczynił miesiąc dla pewnych czasów, a słońce zna zachód swój.
Òṣùpá jẹ́ àmì fún àkókò oòrùn sì mọ ìgbà tí yóò wọ̀.
20 Przywodzisz ciemność, i bywa noc, w którą wychodzą wszystkie zwierzęta leśne.
Ìwọ mú òkùnkùn wá, ó sì di òru, nínú èyí tí gbogbo ẹranko igbó ń rìn kiri.
21 Lwięta ryczą do łupu, i szukają od Boga pokarmu swego.
Kìnnìún ń bú ramúramù fún ohun ọdẹ wọn wọ́n sì ń wá oúnjẹ wọn láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.
22 Lecz gdy słońce wznijdzie, zaś się zgromadzają, i w jamach swoich kładą się.
Oòrùn ràn, wọ́n sì kó ara wọn jọ, wọn padà lọ dùbúlẹ̀ sí ihò wọn.
23 Tedy wychodzi człowiek do roboty swojej, i do pracy swojej aż do wieczora.
Ọkùnrin jáde lọ sí iṣẹ́ wọn, àti sí làálàá rẹ̀ títí di àṣálẹ́.
24 O jakoż wielkie są sprawy twoje, Panie! te wszystkie mądrześ uczynił, a napełniona jest ziemia bogactwem twojem.
Iṣẹ́ rẹ ti pọ̀ tó, Olúwa! Nínú ọgbọ́n ni ìwọ ṣe gbogbo wọn: ayé kún fún àwọn ìṣẹ̀dá á rẹ.
25 W morzu zaś wielkiem i bardzo szerokiem, tam są płazy, którym nie masz liczby, i zwierzęta małe i wielkie.
Bẹ́ẹ̀ ni Òkun yìí tí ó tóbi, tí ó sì ni ìbú, tí ó kún fún àwọn ẹ̀dá alààyè ní ìsàlẹ̀ láìníye ohun alààyè tí tóbi àti kékeré.
26 Po niem okręty przechodzą, i wieloryb, któregoś ty stworzył, aby w niem igrał.
Níbẹ̀ ni ọkọ̀ ń lọ síwá sẹ́yìn, àti Lefitani, tí ìwọ dá láti ṣe àríyá nínú rẹ̀.
27 Wszystko to na cię oczekuje, abyś im dał pokarm czasu swego.
Àwọn wọ̀nyí ń wò ọ́ láti fún wọn ní oúnjẹ wọn lákòókò rẹ̀.
28 Gdy im dajesz, zbierają; gdy otwierasz rękę twoję, nasycone bywają dobremi rzeczami.
Nígbà tí ìwọ bá fi fún wọn, wọn yóò kó jọ; nígbà tí ìwọ bá la ọwọ́ rẹ̀, a tẹ́ wọn lọ́rùn pẹ̀lú ohun rere.
29 Lecz gdy ukrywasz oblicze twoje, trwożą sobą; gdy odbierasz ducha ich, giną, i w proch się swój obracają.
Nígbà tí ìwọ bá pa ojú rẹ mọ́ ara kò rọ̀ wọ́n nígbà tí ìwọ bá mú ẹ̀mí wọn lọ, wọn ó kú, wọn ó sì padà sí erùpẹ̀.
30 Gdy wysyłasz ducha twego, stworzone bywają, i odnawiasz oblicze ziemi.
Nígbà tí ìwọ rán ẹ̀mí rẹ, ni a dá wọn, ìwọ sì tún ojú ayé ṣe.
31 Niechajże będzie chwała Pańska na wieki; niech się rozweseli Pan w sprawach swoich.
Jẹ́ kí ògo Olúwa wà pẹ́ títí láé; kí inú Olúwa kí ó dùn ní ti iṣẹ́ rẹ̀,
32 On gdy wejrzy na ziemię, zadrży; dotknie się gór, a zakurzą się.
ẹni tí ó wo ayé, tí ó sì wárìrì, ẹni tí ó fọwọ́ tọ́ àwọn òkè, tí wọ́n yọ èéfín.
33 Będę śpiewał Panu za żywota mego; będę śpiewał Bogu memu, póki mię staje.
Ní gbogbo ayé mi ní n ó kọrin sí Olúwa: èmi ó kọrin ìyìn sí Olúwa níwọ̀n ìgbà tí mo wà láààyè.
34 O nim będzie wdzięczna mowa moja, a ja się rozweselę w Panu.
Jẹ́ kí ẹ̀kọ́ mi kí ó tẹ́ ọ lọ́rùn bí mo ti ń yọ̀ nínú Olúwa.
35 Oby byli wytraceni grzesznicy z ziemi, a niezbożnych aby już nie było! Błogosław, duszo moja! Panu. Halleluja.
Ṣùgbọ́n kí ẹlẹ́ṣẹ̀ kúrò láyé kí ènìyàn búburú má sì sí mọ́. Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi. Yin Olúwa.

< Psalmów 104 >