< Psalmów 101 >
1 Psalm samego Dawida. O miłosierdziu i o sądzie śpiewać będę; tobie, o Panie! śpiewać będę.
Ti Dafidi. Saamu. Èmi yóò kọrin ìfẹ́ àti òdodo; sí ọ Olúwa, èmi yóò máa kọrin ìyìn.
2 Ostrożnym będę na drodze uprzejmej, kiedy przyjdziesz do mnie; będę chodził ustawicznie w szczerości serca mego, w domu moim.
Èmi yóò máa rin ìrìn mi pẹ̀lú ọgbọ́n láìlẹ́ṣẹ̀, ìgbà wo ni ìwọ yóò wá sí ọ̀dọ̀ mi? Èmi yóò máa rìn ní ilé mi pẹ̀lú àyà pípé.
3 Nie położę przed oczy moje złej rzeczy; każdą sprawę występników mam w nienawiści, a nie chwyci się mnie.
Èmi kì yóò gbé ohun búburú sí iwájú mi: iṣẹ́ àwọn tí ó yapa ni èmi kórìíra. Wọn kì yóò rọ̀ mọ́ mi.
4 Serce przewrotne odstąpi odemnie, a o złe nie będę dbał.
Agídí ọkàn yóò kúrò lọ́dọ̀ mi; èmi kì yóò mọ ènìyàn búburú.
5 Tego, który potajemnie obmawia bliźniego swego, wytnę; oczów wyniosłych, i serca nadętego nie będę mógł cierpieć.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń sọ̀rọ̀ ẹnìkejì rẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀, òun ní èmi yóò gé kúrò ẹni tí ó bá gbé ojú rẹ̀ ga tí ó sì ní ìgbéraga àyà, òun ní èmi kì yóò faradà fún.
6 Oczy moje obrócone będą na prawdomównych w ziemi, aby siadali zemną; kto chodzi drogą uprzejmą, ten mi służyć będzie.
Ojú mi yóò wà lára àwọn olóòtítọ́ lórí ilẹ̀, kí wọn kí ó lè máa bá mi gbé; ẹni tí ó bá n rin ọ̀nà pípé òun ni yóò máa sìn mí.
7 Nie będzie mieszkał w domu moim zdrajca, ten, który mówi kłamstwo, nie ostoi się przed oczyma memi.
Ẹni tí ó bá ń ṣe ẹ̀tàn, kì yóò gbé ilé mi, kò sí ẹni tí ń ṣèké tí yóò dúró ní iwájú mi.
8 Co poranek tracić będę wszystkich niezbożnych na ziemi, abym tak wykorzenił z miasta Pańskiego wszystkich, którzy czynią nieprawość.
Ní ojoojúmọ́ ní èmi yóò wá máa pa a lẹ́nu mọ gbogbo àwọn ènìyàn búburú ilẹ̀ náà; èmi yóò gé àwọn olùṣe búburú kúrò ní ìlú Olúwa.