< Przysłów 8 >

1 Izali mądrość nie woła, i roztropność nie wydaje głosu swego?
Ǹjẹ́ ọgbọ́n kò ha ń kígbe síta? Òye kò ha ń gbé ohùn rẹ sókè?
2 Na wierzchu wysokich miejsc, przy drodze i na rozstaniu dróg stoi.
Ní ibi gíga ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà, ní ìkóríta, ní ó dúró;
3 U bram, kędy się chodzi do miasta, i w wejściu u drzwi woła, mówiąc:
ní ẹgbẹ́ ibodè tí ó wọ ìlú, ní ẹnu ibodè ni ó ń kígbe sókè:
4 Na was wołam, o mężowie! a głos mój obracam do synów ludzkich.
“Sí i yín ẹ̀yin ènìyàn, ní mo ń kígbe pè; mo gbé ohun mi sókè sí gbogbo ènìyàn.
5 Zrozumijcie prostacy ostrożność, a głupi zrozumijcie sercem.
Ẹ̀yin aláìmọ̀kan, ẹ kọ́gbọ́n; ẹ̀yin aṣiwèrè, ẹ gba òye.
6 Słuchajcie; bo o wielkich rzeczach będę mówił, a otworzenie warg moich opowie szczerość.
Ẹ gbọ́, nítorí tí èmi ó sọ̀rọ̀ ohun iyebíye; Èmí ṣí ètè mi láti sọ ohun tí ó tọ́,
7 Zaisteć prawdę mówią usta moje, a niezbożność obrzydliwością jest wargom moim.
ẹnu mi ń sọ ohun tí í ṣe òtítọ́, nítorí ètè mi kórìíra ibi.
8 Sprawiedliwe są wszystkie słowa ust moich; nie masz w nich nic nieprawego ani przewrotnego.
Gbogbo ọ̀rọ̀ ẹnu mi ni ó tọ́, kò sí èyí tí ó jẹ́ ẹ̀tàn tàbí àyídáyidà níbẹ̀.
9 Wszystkie są prawe rozumnemu, a uprzejme tym, którzy znajdują umiejętność.
Fún olóye gbogbo rẹ̀ ni ó tọ̀nà; wọ́n jẹ́ aláìlẹ́gàn fún gbogbo ẹni tí ó ní ìmọ̀.
10 Przyjmijcież ćwiczenie moje, a nie srebro, a umiejętność raczej, niż złoto wyborne.
Yan ẹ̀kọ́ mi dípò fàdákà, ìmọ̀ dípò o wúrà àṣàyàn,
11 Albowiem lepsza jest mądrość niż perły, także wszystkie pożądane rzeczy nie porównają z nią.
nítorí ọgbọ́n ṣe iyebíye jù iyùn lọ, kò sí ohun tí ọkàn rẹ̀ fẹ́ tí a sì le fiwé e.
12 Ja mądrość mieszkam z roztropnością, i umiejętność ostrożności wynajduję.
“Èmi, ọgbọ́n ń gbé pẹ̀lú òye; mo ní ìmọ̀ àti ọgbọ́n-inú.
13 Bojaźń Pańska jest, mieć w nienawiści złe. Ja nienawidzę pychy, wysokomyślności, i drogi złej, i ust przewrotnych.
Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìkórìíra ibi mo kórìíra ìgbéraga àti agídí, ìwà ibi àti ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn.
14 Przy mnie jest rada, i prawdziwa mądrość; jam jest roztropność, a moc jest moja.
Ìmọ̀ràn àti ọgbọ́n tí ó yè kooro jẹ́ tèmi mo ní òye àti agbára.
15 Przez mię królowie królują, i książęta stanowią sprawiedliwość.
Nípasẹ̀ mi ni ọba ń ṣàkóso tí àwọn aláṣẹ sì ń ṣe òfin tí ó dára.
16 Przez mię książęta panują, i wielmożnymi są wszyscy sędziowie ziemi.
Nípasẹ̀ mi àwọn ọmọ-aládé ń ṣàkóso, àti gbogbo ọlọ́lá tí ń ṣàkóso ilẹ̀ ayé.
17 Ja miłuję tych, którzy mię miłują; a którzy mię szukają rano, znajdują mię.
Mo fẹ́ràn àwọn tí ó fẹ́ràn mi, àwọn tí ó sì wá mi rí mi.
18 Bogactwo i sława przy mnie jest; majętność trwała i sprawiedliwość.
Lọ́dọ̀ mi ni ọrọ̀ àti ọlá wà, ọrọ̀ tí í tọ́jọ́ àti ìgbéga rere.
19 Lepszy jest owoc mój, niż złoto, i niż najkosztowniejsze złoto, a dochody moje lepsze, niż srebro wyborne.
Èso mi dára ju wúrà dáradára lọ; ohun tí mò ń mú wá ju àṣàyàn fàdákà lọ.
20 Prowadzę ścieszką sprawiedliwości, pośrodkiem ścieżek sądu,
Mò ń rìn ní ọ̀nà òdodo, ní ojú ọ̀nà òtítọ́,
21 Abym tym, którzy mię miłują, dała w dziedzictwo majętność wieczną, i skarby ich napełniła.
mò ń fi ọrọ̀ fún gbogbo àwọn tí ó fẹ́ràn mi mo sì ń mú kí ilé ìṣúra wọn kún.
22 Pan mię miał przy początku drogi swej, przed sprawami swemi, przed wszystkiemi czasy.
“Èmi ni Olúwa kọ́kọ́ dá nínú iṣẹ́ rẹ̀. Ṣáájú àwọn iṣẹ́ rẹ̀ àtijọ́;
23 Przed wieki jestem zrządzona, przed początkiem; pierwej niż była ziemia;
a ti yàn mí láti ayérayé, láti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀, kí ayé tó bẹ̀rẹ̀.
24 Gdy jeszcze nie było przepaści, spłodzonam jest, gdy jeszcze nie było źródeł opływających wodami.
Nígbà tí kò tí ì sí Òkun, ni a ti bí mi, nígbà tí kò tí ì sí ìsun tí ó ní omi nínú;
25 Pierwej niż góry założone były, niż były pagórki, spłodzonam jest.
kí a tó fi àwọn òkè sí ipò wọn, ṣáájú àwọn òkè ni a ti bí mi,
26 Jeszcze był nie uczynił ziemi, i równin, ani początku prochu okręgu ziemskiego.
kí ó tó dá ilẹ̀ ayé tàbí àwọn oko rẹ̀ tàbí èyíkéyìí nínú eruku ayé.
27 Gdy gotował niebiosa, tamem była; gdy rozmierzał okrągłość nad przepaściami;
Mo wà níbẹ̀ nígbà tí ó fi àwọn ọ̀run sí ipò wọn, nígbà tí ó fi òsùwọ̀n àyíká sórí ibú omi,
28 Gdy utwierdzał obłoki w górze, i umacniał źródła przepaści;
nígbà tí ó ṣẹ̀dá òfúrufú lókè tí ó sì fi orísun ibú omi sí ipò rẹ̀ láì le è yẹsẹ̀,
29 Gdy zakładał morzu granice jego, i wodom, aby nie przestępowały rozkazania jego; gdy rozmierzał grunty ziemi:
nígbà tí ó ṣe ààlà fún omi Òkun kí omi má ba à kọjá ààlà àṣẹ rẹ̀, àti nígbà tí ó pààlà ìpìlẹ̀ ayé.
30 Tedym była u niego jako wychowaniec, i byłam uciechą jego na każdy dzień, grając przed nim na każdy czas.
Nígbà náà èmi ni gbẹ́nàgbẹ́nà ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ mo kún fún inú dídùn lójoojúmọ́, mo ń yọ̀ nígbà gbogbo níwájú rẹ̀.
31 Gram na okręgu ziemi jego, a rozkoszy moje, mieszkać z synami ludzkimi.
Mo ń yọ̀ nínú gbogbo àgbáyé tí ó dá mo sì ní inú dídùn sí àwọn ọmọ ènìyàn.
32 Słuchajcież mię tedy teraz, synowie! albowiem błogosławieni, którzy strzegą dróg moich.
“Nítorí náà báyìí, ẹ̀yin ọmọ mi, ìbùkún ni fún àwọn tí ó pa ọ̀nà mi mọ́.
33 Słuchajcie ćwiczenia, nabądźcie rozumu, a nie cofajcie się.
Fetí sí ìtọ́sọ́nà mi kí o sì gbọ́n; má ṣe pa á tì sápá kan.
34 Błogosławiony człowiek, który mię słucha, czując u wrót moich na każdy dzień, a strzegąc podwoi drzwi moich.
Ìbùkún ni fún ẹni tí ó fetísílẹ̀ sí mi, tí ń ṣọ́nà ní ẹnu-ọ̀nà mi lójoojúmọ́, tí ń dúró ní ẹnu-ọ̀nà mi.
35 Bo kto mię znajduje, znajduje żywot, a otrzymuje łaskę od Pana.
Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá rí mi rí ìyè ó sì rí ojúrere gbà lọ́dọ̀ Olúwa.
36 Ale kto grzeszy przeciwko mnie, krzywdę czyni duszy swojej; wszyscy, którzy mię nienawidzą, miłują śmierć.
Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti rí ń pa ara rẹ̀ lára gbogbo ẹni tí ó kórìíra mi fẹ́ ikú.”

< Przysłów 8 >