< Przysłów 31 >

1 Te są słowa Lemuela króla, i zebranie mów, któremi go ćwiczyła matka jego.
Àwọn ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ ti Lemueli ọba, ọ̀rọ̀ ẹ̀kọ́ tí ìyá rẹ̀ kọ́ ọ,
2 Cóż rzekę, synu mój? cóż rzekę, synu żywota mego? i cóż rzekę, synu ślubów moich?
“Gbọ́ ìwọ ọmọ mi, gbọ́ ìwọ ọmọ inú mi! Gbọ́ ìwọ ọmọ ẹ̀jẹ́ mi.
3 Nie dawaj niewiastom siły twojej, ani dróg twoich tym, którzy do zginienia królów przywodzą.
Má ṣe lo agbára rẹ lórí obìnrin, okun rẹ lórí àwọn tí ó pa àwọn ọba run.
4 Nie królom, o Lemuelu! nie królom należy pić wino, a nie panom bawić się napojem mocnym;
“Kì í ṣe fún àwọn ọba, ìwọ Lemueli, kì í ṣe fún ọba láti mu ọtí wáìnì, kì í ṣe fún alákòóso láti máa wá ọtí líle,
5 By snać pijąc nie zapomniał na ustawy, a nie odmienił spraw wszystkich ludzi uciśnionych.
kí wọn má ba à mu ọtí yó kí wọn sì gbàgbé ohun tí òfin wí, kí wọn sì fi ẹ̀tọ́ àwọn tí ara ń ni dù wọ́n.
6 Dajcie napój mocny ginącemu, a wino tym, którzy są ducha sfrasowanego.
Fi ọtí líle fún àwọn tí ń ṣègbé wáìnì fún àwọn tí ó wà nínú ìrora.
7 Niech się napije, a zapomni ubóstwa swego, a na utrapienie swoje niech więcej nie wspomni.
Jẹ́ kí wọn mu ọtí kí wọn sì gbàgbé òsì wọn kí wọn má sì rántí òsì wọn mọ́.
8 Otwórz usta swe za niemym w sprawie wszystkich osądzonych na śmierć.
“Sọ̀rọ̀ lórúkọ àwọn tí kò le sọ̀rọ̀ fúnra wọn fún ẹ̀tọ́ àwọn ẹni tí ń parun.
9 Otwórz usta swe, sądź sprawiedliwie, a podejmij się sprawy ubogiego i nędznego.
Sọ̀rọ̀ kí o sì ṣe ìdájọ́ àìṣègbè jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà àti aláìní.”
10 Któż znajdzie niewiastę stateczną, gdyż nad perły daleko większa jest cena jej?
Ta ni ó le rí aya oníwà rere? Ó níye lórí ju iyùn lọ.
11 Serce męża jej ufa jej, a na korzyściach schodzić mu nie będzie.
Ọkọ rẹ̀ ní ìgbẹ́kẹ̀lé púpọ̀ nínú rẹ̀ kò sì ṣí ìwà rere tí kò pé lọ́wọ́ rẹ̀.
12 Dobrze mu czyni, a nie źle, po wszystkie dni żywota swego.
Ire ní ó ń ṣe fún un, kì í ṣe ibi ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.
13 Szuka wełny i lnu, a pracuje ochotnie rękami swemi.
Ó sa aṣọ irun àgùntàn olówùú àti ọ̀gbọ̀ Ó sì ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ìyárí.
14 Podobna jest okrętom kupieckim; z daleka przywodzi żywność swoję.
Ó dàbí ọkọ̀ ojú omi tí àwọn oníṣòwò; ó ń gbé oúnjẹ rẹ̀ wá láti ọ̀nà jíjìn.
15 I wstaje bardzo rano, a daje pokarm czeladzi swej, a obrok słuszny dziewkom swym.
Ó dìde nígbà tí òkùnkùn sì kùn; ó ṣe oúnjẹ fún ìdílé rẹ̀ àti ìpín oúnjẹ fún àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀.
16 Obmyśla rolę, i ujmuje ją; z zarobku rąk swoich szczepi winnice.
Ó kíyèsi oko kan, ó sì rà á; nínú ohun tí ó ń wọlé fún un ó gbin ọgbà àjàrà rẹ̀.
17 Przepasuje mocą biodra swe, a posila ramiona swoje.
Ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rẹ̀ tagbára tagbára apá rẹ̀ le koko fún iṣẹ́.
18 Doświadcza, że jest dobra skrzętność jej, a nie gaśnie w nocy pochodnia jej.
Ó rí i pé òwò òun pé fìtílà rẹ̀ kì í sì í kú ní òru.
19 Ręce swoje obraca do kądzieli, a palcami swemi trzyma wrzeciono.
Ní ọwọ́ rẹ̀, ó di kẹ̀kẹ́ òwú mú ó sì na ọwọ́ rẹ̀ di ìrànwú mú.
20 Rękę swą otwiera ubogiemu, a ręce swoje wyciąga ku nędznemu.
O la ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn tálákà ó sì na ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn aláìní.
21 Nie boi się o czeladź swoję czasu śniegu; albowiem wszystka czeladź jej obłoczy się w szatę dwoistą.
Nígbà tí òjò-dídì rọ̀, kò bẹ̀rù nítorí ìdílé rẹ̀ nítorí gbogbo wọn ni ó wọ aṣọ tí ó nípọn.
22 Kobierce sobie robi; płótno subtelne i szarłat jest odzieniem jej.
Ó ṣe aṣọ títẹ́ fún ibùsùn rẹ̀; ẹ̀wù dáradára àti elése àlùkò ni aṣọ rẹ̀.
23 Znaczny jest w bramach mąż jej, gdy siedzi między starszymi ziemi.
A bọ̀wọ̀ fún ọkọ rẹ̀ ní ẹnu ibodè ìlú níbi tí ó ń jókòó láàrín àwọn àgbàgbà ìlú.
24 Płótno robi, i sprzedaje, także pasy sprzedaje kupcowi.
Ó ń ṣe àwọn aṣọ dáradára ó sì ń tà wọ́n ó sì ń kó ọjà fún àwọn oníṣòwò.
25 Moc i przystojność jest odzieniem jej; nie frasuje się o czasy przyszłe.
Agbára àti ọlá ni ó wò ọ́ láṣọ ó le fi ọjọ́ iwájú rẹ́rìn-ín.
26 Mądrze otwiera usta swe, a nauka miłosierdzia jest na języku jej.
A sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọgbọ́n ìkọ́ni òtítọ́ sì ń bẹ létè e rẹ̀
27 Dogląda rządu w domu swym, a chleba próżnując nie je.
Ó ń bojútó gbogbo ètò ilé rẹ̀ kì í sì í jẹ oúnjẹ ìmẹ́lẹ́.
28 Powstawszy synowie jej błogosławią jej; także i mąż jej chwali ją,
Àwọn ọmọ rẹ̀ dìde wọ́n sì pè é ní alábùkún ọkọ rẹ̀ pẹ̀lú ń gbóríyìn fún un.
29 Mówiąc: Wiele niewiast grzecznie sobie poczynały; ale je ty przechodzisz wszystkie.
“Ọ̀pọ̀lọpọ̀ obìnrin ní ń ṣe nǹkan ọlọ́lá ṣùgbọ́n ìwọ ju gbogbo wọn lọ.”
30 Omylna jest wdzięczność, i marna piękność; ale niewiasta, która się Pana boi, ta pochwały godna.
Ojú dáradára a máa tan ni, ẹwà sì jẹ́ asán nítorí obìnrin tí ó bẹ̀rù Olúwa yẹ kí ó gba oríyìn.
31 Dajcie jej z owocu ręku jej, a niechaj ją chwalą w bramach uczynki jej.
Sì fún un ní èrè tí ó tọ́ sí i kí o sì jẹ́ kí iṣẹ́ rẹ̀ fún un ní ìyìn ní ẹnu ibodè ìlú.

< Przysłów 31 >