< Przysłów 28 >

1 Uciekają niezbożni, choć ich nikt nie goni: ale sprawiedliwi jako lwię młode są bez bojaźni.
Ènìyàn búburú ń sá bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹnìkan kò lé e ṣùgbọ́n olódodo láyà bí i kìnnìún.
2 Dla przestępstwa ziemi wiele bywa książąt jej; ale dla człowieka roztropnego i umiejętnego trwałe bywa państwo.
Nígbà tí orílẹ̀-èdè bá ní orí kunkun, àwọn ọba rẹ̀ a máa pọ̀, ṣùgbọ́n olóye àti onímọ̀ a máa pa òfin mọ́.
3 Mąż ubogi, który uciska nędznych, podobny jest dżdżowi gwałtownemu, po którym chleba nie bywa.
Ọba tí ó ni àwọn tálákà lára dàbí àgbàrá òjò tí ó ń gbá gbogbo ọ̀gbìn lọ.
4 Którzy opuszczają zakon, chwalą niezbożnika; ale ci, którzy strzegą zakonu, są im odpornymi.
Àwọn tí ó kọ òfin sílẹ̀ a máa gbóríyìn fún ènìyàn búburú ṣùgbọ́n àwọn tí ó pa òfin mọ́ kọjú ìjà sí ènìyàn búburú.
5 Ludzie źli nie zrozumiewają sądu; ale którzy Pana szukają, rozumieją wszystko.
Òye ìdájọ́ òdodo kò yé àwọn ẹni ibi ṣùgbọ́n ó yé àwọn tí ń wá Olúwa dáradára.
6 Lepszy jest ubogi, który chodzi w uprzejmości swojej, niżeli przewrotny na drogach swych, chociaż jest bogaty.
Ó sàn láti jẹ́ tálákà tí ìrìn rẹ̀ jẹ́ aláìlábùkù ju ọlọ́rọ̀ tí ọ̀nà rẹ̀ rí pálapàla.
7 Kto strzeże zakonu, jest synem roztropnym; ale kto karmi obżercę, czyni zelżywość ojcu swemu.
Ẹni tí ó pa òfin mọ́ jẹ́ olóye ọmọ ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ẹ́ jẹgúdújẹrá kẹ́gbẹ́ dójútì baba rẹ̀.
8 Kto rozmnaża majętność swoję z lichwy i z płatu, temu ją zbiera, który ubogiemu szczodrze będzie dawał.
Ẹni tí ó mú ọrọ̀ rẹ̀ di púpọ̀ nípa èrè àjẹjù ń kó jọ fún ẹlòmíràn, tí yóò ní àánú àwọn tálákà.
9 Kto odwraca ucho swe, aby nie słuchał zakonu, i modlitwa jego jest obrzydliwością.
Bí ẹnikẹ́ni bá kọ etí ikún sí òfin, kódà àdúrà rẹ̀ jẹ́ ìríra.
10 Kto zawodzi uprzejmych na drogę złą, w dół swój sam wpadnie; ale uprzejmi odziedziczą rzeczy dobre.
Ẹni tí ó mú olódodo rìn ọ̀nà búburú yóò bọ́ sínú pàkúté ara rẹ̀ ṣùgbọ́n aláìlẹ́gàn yóò gba ogún rere.
11 Mąż bogaty zda się sobie być mądrym; ale ubogi roztropny dochodzi go.
Ọlọ́rọ̀ ènìyàn le è gbọ́n lójú ara rẹ̀ ṣùgbọ́n tálákà tí ó ní òye rí ìdí, rẹ̀.
12 Gdy się radują sprawiedliwi, wielka jest sława; ale gdy powstawają niepobożni, kryje się człowiek.
Nígbà tí olódodo ń lékè ariwo ayọ̀ ta; ṣùgbọ́n nígbà tí ènìyàn búburú gorí òye, àwọn ènìyàn a na pápá bora.
13 Kto pokrywa przestępstwa swe, nie poszczęści mu się; ale kto je wyznaje i opuszcza, miłosierdzia dostąpi.
Ẹni tí ó bo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ kì yóò ṣe rere, ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá jẹ́wọ́ tí ó sì kọ̀ wọ́n sílẹ̀ máa ń rí àánú gbà.
14 Błogosławiony człowiek, który się zawsze boi; ale kto zatwardza serce swoje, wpada w złe.
Ìbùkún ni fún ènìyàn náà tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run nígbà gbogbo ṣùgbọ́n ẹni tí ó sé ọkàn rẹ̀ le bọ́ sínú wàhálà.
15 Pan niezbożny, panujący nad ludem ubogim jest jako lew ryczący, i jako niedźwiedź głodny.
Bí kìnnìún tí ń ké tàbí Beari tí ń halẹ̀ ni ènìyàn búburú tí ń jẹ ọba lórí àwọn aláìlágbára.
16 Książę bezrozumny wielkim jest drapieżcą: ale kto nienawidzi łakomstwa, przedłuży dni swoje.
Ọmọ-aládé tí ó ṣe aláìmòye púpọ̀ ní ń ṣe ìwà ìkà púpọ̀ pẹ̀lú, ṣùgbọ́n èyí tí ó kórìíra ojúkòkòrò yóò mú ọjọ́ rẹ̀ pẹ́.
17 Człowieka, który gwałt czyni krwi ludzkiej, choćby i do dołu uciekał, nikt nie zatrzyma.
Ẹni tí ọkàn rẹ̀ kò balẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ìpànìyàn yóò máa joró rẹ̀ títí ikú má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni ràn án lọ́wọ́.
18 Kto chodzi w uprzejmości, zachowany będzie; ale przewrotny na drogach swoich oraz upadnie.
Ẹni tí ń rìn déédéé ní yóò là, ṣùgbọ́n ẹni tí ọ̀nà rẹ̀ jẹ́ àyídáyidà ni yóò ṣubú lójijì.
19 Kto sprawuje ziemię swoję, chlebem nasycony bywa; ale kto naśladuje próżnujących, ubóstwem nasycony bywa.
Ẹni tí ó bá ro ilẹ̀ rẹ̀ yóò ní oúnjẹ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ ṣùgbọ́n ẹni tí ń lé ohun asán yóò kún fún òsì.
20 Mąż wierny przyczyni błogosławieństwa; ale kto się prędko chce zbogacić, nie bywa bez winy.
Olóòtítọ́ ènìyàn yóò rí ìbùkún gbà gan an ṣùgbọ́n ẹni tí ojú ń kán láti di ọlọ́rọ̀ kì yóò lọ láìjìyà.
21 Mieć wzgląd na osobę, rzecz niedobra; bo nie jeden dla kęsa chleba staje się przewrotnym.
Ojúsàájú ṣíṣe kò dára, síbẹ̀ ènìyàn kan ń ṣẹ̀ nítorí òkèlè oúnjẹ kan.
22 Prędko chce człowiek zazdrościwy zbogatnieć, a nie wie, iż nać niedostatek przyjdzie.
Ahun ń sáré àti là kò sì funra pé òsì dúró de òun.
23 Kto strofuje człowieka, większą potem łaskę znajduje, niż ten, co pochlebia językiem.
Ẹni tí ó bá ènìyàn kan wí yóò rí ojúrere ni nígbẹ̀yìn ju ẹni tí ó ní ètè ẹ̀tàn lọ.
24 Kto łupi ojca swego, albo matkę swoją, a mówi, iż to nie grzech: towarzyszem jest mężobójcy.
Ẹni tí ó ja baba tàbí ìyá rẹ̀ lólè tí ó sì wí pé, “Kì í ṣe ẹ̀ṣẹ̀,” irú kan ni òun àti ẹni tí ń pa ni run.
25 Wysokomyślny wszczyna zwadę; ale kto nadzieję ma w Panu, dostatek mieć będzie.
Ọ̀kánjúwà ènìyàn a máa dá ìjà sílẹ̀, ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé Olúwa yóò gbilẹ̀.
26 Kto ufa w sercu swem, głupi jest; ale kto sobie mądrze poczyna, ten ujdzie nieszczęścia.
Ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀lé ara rẹ̀ jẹ́ aláìgbọ́n ṣùgbọ́n ẹni tí ń rìn nínú ọgbọ́n wà láìléwu.
27 Kto daje ubogiemu, nie będzie miał niedostatku; ale kto od niego odwraca oczy swe, wielkie przeklęstwa nań przyjdą.
Ẹni tí ó ń fi fún tálákà kì yóò ṣe aláìní ohunkóhun, ṣùgbọ́n ẹni tí ó di ojú rẹ̀ sí wọn gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ ègún.
28 Gdy niepobożni powstawają, kryje się człowiek; ale gdy giną, sprawiedliwi się rozmnażają.
Nígbà tí ènìyàn búburú bá dórí ìjọba, àwọn ènìyàn a na pápá bora; ṣùgbọ́n nígbà tí ènìyàn búburú bá ṣègbé, àwọn olódodo ń gbilẹ̀ sí i.

< Przysłów 28 >