< Przysłów 2 >

1 Synu mój! jeźli przyjmiesz słowa moje, a przykazanie moje zachowasz u siebie;
Ọmọ mi, bí ìwọ bá gba ọ̀rọ̀ mi, tí ìwọ sì pa òfin mi mọ́ sí inú rẹ,
2 Nadstawiszli mądrości ucha twego, i nakłoniszli serca twego do roztropności;
tí ìwọ dẹtí rẹ sílẹ̀ sí ọgbọ́n tí ìwọ sì fi ọkàn rẹ sí òye,
3 Owszem, jeźli na rozum zawołasz, a roztropności wezwieszli głosem swoim;
àní, bí ìwọ bá ké tọ ìmọ̀ lẹ́yìn, tí ìwọ sì gbé ohùn rẹ sókè fún òye
4 Jeźli jej szukać będziesz jako srebra, a jako skarbów skrytych pilnie szukać będziesz:
bí ìwọ bá ṣàfẹ́rí rẹ̀ bí i fàdákà tí ìwọ sì wa kiri bí ìṣúra tí a fi pamọ́.
5 Tedy zrozumiesz bojaźń Pańską, a znajomość Bożą znajdziesz.
Nígbà náà ni ìwọ yóò bẹ̀rù Olúwa, ìwọ yóò sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run.
6 Albowiem Pan daje mądrość, z ust jego pochodzi umiejętność i roztropność.
Nítorí Olúwa ni ó ń fún ni ní ọgbọ́n, láti ẹnu rẹ̀ sì ni ìmọ̀ àti òye ti ń wá.
7 On zachowuje uprzejmym prawdziwą mądrość; on jest tarczą chodzącym w szczerości,
Ó to ìgbàlà fún àwọn olódodo, Òun ni asà fún àwọn tí ń rìn déédé,
8 Aby strzegli ścieżek sądu; on drogi świętych swoich strzeże.
Ó pa ipa ọ̀nà ìdájọ́ mọ́ Ó sì ń pa ọ̀nà àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ mọ́.
9 Tedy wyrozumiesz sprawiedliwość, i sąd, i prawość, i wszelką ścieszkę dobrą.
Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ òdodo àti ìdájọ́, àti àìṣègbè—gbogbo ipa ọ̀nà rere.
10 Gdy wnijdzie mądrośu w serce twoje, a umiejętność duszy twojej wdzięczna będzie:
Nítorí ọgbọ́n yóò wọ inú ọkàn rẹ ìmọ̀ yóò sì jẹ́ ìtura fún ọkàn rẹ.
11 Tedy cię ostrożność strzedz będzie, a opatrzność zachowa cię.
Ìmòye yóò pa ọ mọ́ òye yóò sì máa ṣọ́ ọ.
12 Wyrywając cię od drogi złej, i od człowieka mówiącego przewrotności;
Ọgbọ́n yóò gbà ọ́ là kúrò ní ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú, lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn tí ọrọ̀ ọ wọn jẹ́ àyídáyidà,
13 Od tych, którzy opuszczają ścieszki proste, udawając się drogami ciemnemi;
ẹni tí ó kúrò ní ọ̀nà ìdúró ṣinṣin láti rìn ní ọ̀nà tí ó ṣókùnkùn,
14 Którzy się radują, gdy czynią złe, a weselą się w złośliwych przewrotnościach;
ẹni tí ó yọ̀ nínú ṣíṣe búburú, tí ó ṣe inú dídùn sí àyídáyidà àwọn ènìyàn ibi,
15 Których ścieszki są krzywe, a sami są przewrotnymi na drogach swoich;
ọ̀nà ẹni tí ó wọ́ tí wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ní ọ̀nà wọn.
16 Wyrywając cię od niewiasty postronnej i obcej, która pochlebia łagodnemi słowy;
Yóò gba ìwọ pẹ̀lú là kúrò lọ́wọ́ àwọn àjèjì obìnrin, àní, lọ́wọ́ obìnrin àjèjì tí ń fi ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ tannijẹ,
17 Która opuszcza wodza młodości swojej, a przymierza Boga swojego zapomina.
ẹni tí ó ti kọ ọkọ àkọ́fẹ́ ìgbà èwe rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì gbàgbé májẹ̀mú tí ó ti dá níwájú Ọlọ́run rẹ̀.
18 Bo się nachyla ku śmierci dom jej, a do umarłych ścieszki jej.
Nítorí ilé rẹ̀ jẹ́ ọ̀nà sí ikú ipa ọ̀nà rẹ̀ sọ́dọ̀ àwọn òkú.
19 Wszyscy, którzy do niej wchodzą, nie wracają się, ani trafiają na ścieszkę żywota.
Kò sẹ́ni tó lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ tí ó padà bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í dé ọ̀nà ìyè.
20 A przetoż będziesz chodził drogą dobrych, a ścieżek sprawiedliwych będziesz przestrzegał.
Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò rìn ní ọ̀nà àwọn ènìyàn rere kí ìwọ kí ó sì pa ọ̀nà àwọn olódodo mọ́.
21 Albowiem cnotliwi będą mieszkali na ziemi, a szczerzy trwać będą na niej;
Nítorí ẹni dídúró ṣinṣin yóò gbé ní ilé náà àwọn aláìlẹ́gàn sì ni yóò máa wà nínú rẹ̀.
22 Ale niepobożni z ziemi wykorzenieni będą, a przewrotni będą z niej wygładzeni.
Ṣùgbọ́n a ó ké ènìyàn búburú kúrò lórí ilẹ̀ náà a ó sì fa àwọn aláìṣòótọ́ tu kúrò lórí rẹ̀.

< Przysłów 2 >