< Przysłów 10 >

1 Syn mądry rozwesela ojca: ale syn głupi smutkiem jest matki swojej.
Àwọn òwe Solomoni. Ọlọ́gbọ́n ọmọ ń mú inú baba rẹ̀ dùn, ṣùgbọ́n aṣiwèrè ọmọ ń ba inú ìyá rẹ̀ jẹ́.
2 Nie pomogą skarby niezbożności; ale sprawiedliwość wyrywa od śmierci.
Ìṣúra tí a kójọ nípa ìwà búburú kò ní èrè, ṣùgbọ́n òdodo a máa gbani lọ́wọ́ ikú.
3 Nie dopuści Pan łaknąć duszy sprawiedliwego; ale majętność niezbożników rozproszy.
Olúwa kì í jẹ́ kí ebi máa pa olódodo, ṣùgbọ́n ó ba ète àwọn ènìyàn búburú jẹ́.
4 Do nędzy przywodzi ręka zdradliwa; ale ręka pracowita ubogaca.
Ọwọ́ tí ó lẹ máa ń sọ ènìyàn di tálákà, ṣùgbọ́n ọwọ́ tí ó múra ṣíṣẹ́ a máa sọ ni di ọlọ́rọ̀.
5 Kto zbiera w lecie, jest syn roztropny; kto dosypia we żniwa, jest syn pohańbienia.
Ẹni tí ó kó irúgbìn jọ ní àsìkò òjò jẹ́ ọlọ́gbọ́n ọmọ, ṣùgbọ́n ẹni tí ó sùn ní àsìkò ìkórè jẹ́ adójútini ọmọ.
6 Błogosławieństwo jest nad głową sprawiedliwego; ale usta bezbożnych pokrywają nieprawość.
Ìbùkún ní ó máa ń kún orí olódodo, ṣùgbọ́n ìwà ipá máa ń kún ẹnu ènìyàn búburú.
7 Błogosławiona jest pamiątka sprawiedliwego; ale imię niezbożnych śmierdzi.
Ìrántí olódodo yóò jẹ́ ìbùkún, ṣùgbọ́n orúkọ ènìyàn búburú yóò jẹrà.
8 Mądre serce przyjmuje przykazanie; ale głupi od warg swoich upadnie.
Ẹni tí ó gbọ́n nínú ọkàn rẹ̀ máa ń gba àṣẹ, ṣùgbọ́n ètè wérewère yóò parun.
9 Kto chodzi w szczerości, chodzi bezpiecznie; ale kto jest przewrotnym w drogach swoich, wyjawion będzie.
Ẹni tí ó ń rìn déédé, ń rìn láìléwu, ṣùgbọ́n àṣírí ẹni tí ń rin ọ̀nà pálapàla yóò tú.
10 Kto mruga okiem, przynosi frasunek, ale głupi od warg swoich upadnie.
Ẹni tí ń ṣẹ́jú pàkòpàkò fún ibi ń fa àìbalẹ̀ ọkàn, aláìgbọ́n tí ń ṣàròyé kiri yóò parun.
11 Usta sprawiedliwego są źródło żywota; ale usta niezbożników pokrywają nieprawość.
Ẹnu olódodo jẹ́ orísun ìyè, ṣùgbọ́n ìwà ipá ni ó gba gbogbo ẹnu ènìyàn búburú.
12 Nienawiść wzbudza swary; ale miłość wszystkie przestępstwa pokrywa.
Ìríra a máa dá ìjà sílẹ̀, ṣùgbọ́n ìfẹ́ a máa bo gbogbo àṣìṣe mọ́lẹ̀.
13 W wargach roztropnego znajduje się mądrość; ale kij na grzbiecie szalonego.
Ọgbọ́n ni a ń bá lẹ́nu àwọn olóye, ṣùgbọ́n kùmọ̀ wà fún ẹ̀yìn àwọn aláìlóye.
14 Mądrzy tają umiejętność; ale usta głupiego bliskie upadku.
Ọlọ́gbọ́n ènìyàn kó ìmọ̀ jọ, ṣùgbọ́n ẹnu aláìgbọ́n a máa ṣokùnfà ìparun.
15 Majętność bogatego jest miastem jego mocnem; ale nędza jest ubogich zniszczeniem.
Ọrọ̀ àwọn olódodo ni ìlú olódi wọn, ṣùgbọ́n òsì ni ìparun aláìní.
16 Praca sprawiedliwego jest ku żywotowi; ale dochód niepobożnych jest ku grzechowi.
Èrè olódodo ń mú ìyè wá fún wọn, ṣùgbọ́n èrè ènìyàn búburú ń mú ìjìyà wá fún wọn.
17 Ścieszką żywota idzie, kto przyjmuje karność; ale kto gardzi strofowaniem, w błąd się zawodzi.
Ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí fi ọ̀nà sí ìyè hàn, ṣùgbọ́n ẹni tí ó kọ ìbáwí mú àwọn mìíràn ṣìnà.
18 Kto pokrywa nienawiść wargami kłamliwemi, i kto rozgłasza hańbę, głupi jest.
Ẹni tí ó pa ìkórìíra rẹ̀ mọ́ jẹ́ òpùrọ́ ẹni tí ó sì ń ba ni jẹ́ jẹ́ aláìgbọ́n.
19 Wielomowność nie bywa bez grzechu; ale kto powściąga wargi swoje, ostrożny jest.
Nínú ọ̀rọ̀ púpọ̀ a kò le fẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ kù ṣùgbọ́n ẹni tí ó pa ẹnu rẹ̀ mọ́ jẹ́ ọlọ́gbọ́n.
20 Srebro wyborne jest język sprawiedliwego; ale serce niezbożnych za nic nie stoi.
Ètè olódodo jẹ́ ààyò fàdákà, ṣùgbọ́n ọkàn ènìyàn búburú kò níye lórí.
21 Wargi sprawiedliwego wiele ich żywią; ale głupi dla głupstwa umierają.
Ètè olódodo ń bọ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀, ṣùgbọ́n aláìgbọ́n ń kú nítorí àìlóye.
22 Błogosławieństwo Pańskie ubogaca, a nie przynosi z sobą utrapienia.
Ìbùkún Olúwa ń mú ọrọ̀ wá, kì í sì í fi ìdààmú sí i.
23 Za śmiech sobie ma głupi, popełnić niecnotę, ale mąż roztropny dzierży się mądrości.
Aláìgbọ́n a máa ní inú dídùn sí ìwà búburú, ṣùgbọ́n olóye ènìyàn a máa ní inú dídùn sí ọgbọ́n.
24 Czego się boi niezbożnik, to nań przychodzi; ale czego żądają sprawiedliwi, Bóg im daje.
Ohun tí ènìyàn búburú bẹ̀rù yóò dé bá a; olódodo yóò rí ohun tí ó fẹ́ gbà.
25 Jako przemija wicher, tak się niepobożni nie ostoją; ale sprawiedliwy ma grunt wieczny.
Nígbà tí ìjì bá ti jà kọjá, ènìyàn búburú a kọjá lọ, ṣùgbọ́n olódodo yóò dúró ṣinṣin láéláé.
26 Jako ocet zębom, i jako dym oczom, tak jest leniwy tym, którzy go posyłają.
Bí ọtí kíkan sí eyín, àti èéfín sí ojú, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀lẹ sí ẹni tí ó rán an níṣẹ́.
27 Bojaźń Pańska dni przyczynia; ale lata niezbożnego ukrócone bywają.
Ìbẹ̀rù Olúwa ń mú ọjọ́ ayé gígùn wá, ṣùgbọ́n a gé ọjọ́ ayé ènìyàn búburú kúrú.
28 Oczekiwanie sprawiedliwych jest wesele, ale nadzieja niezbożnych zginie.
Ìrètí olódodo ni ayọ̀, ṣùgbọ́n ìrètí ènìyàn búburú jásí òfo.
29 Droga Pańska jest mocą szczeremu; ale strachem tym, którzy broją złości.
Ọ̀nà Olúwa jẹ́ ààbò fún olódodo, ṣùgbọ́n ìparun ni ó jẹ́ fún àwọn tí ń ṣe ibi.
30 Sprawiedliwy się na wieki nie poruszy; ale niezbożnicy nie będą mieszkali na ziemi.
A kì yóò fa olódodo tu láéláé, ṣùgbọ́n ènìyàn búburú kì yóò dúró pẹ́ lórí ilẹ̀.
31 Usta sprawiedliwego rozmnażają mądrość; ale język przewrotny będzie wycięty.
Ẹnu olódodo ń mú ọgbọ́n jáde wá, ṣùgbọ́n ètè àyípadà ni a ó gé kúrò.
32 Wargi sprawiedliwego znają, co się Bogu podoba; ale usta niepobożnych są przewrotne.
Ètè olódodo mọ ohun ìtẹ́wọ́gbà, ṣùgbọ́n ètè ènìyàn búburú kò mọ̀ ju èké lọ.

< Przysłów 10 >