< Liczb 9 >

1 I rzekł Pan do Mojżesza na puszczy Synaj, roku wtórego po wyjściu ich z ziemi Egipskiej, miesiąca pierwszego, mówiąc:
Olúwa sọ fún Mose nínú aginjù Sinai ní oṣù kìn-ín-ní ọdún kejì lẹ́yìn tí wọ́n kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti wí pé,
2 Niech obchodzą synowie Izraelscy święto przejścia czasu naznaczonego.
“Mú kí àwọn ọmọ Israẹli máa pa àjọ ìrékọjá mọ́ ní àsìkò rẹ̀.
3 Czternastego dnia miesiąca tego, między dwoma wieczorami, obchodzić je będziecie czasu naznaczonego; według wszystkich obrzędów jego, i według wszystkich ceremonii jego, obchodzić je będziecie.
Ẹ ṣe é ní àsìkò rẹ̀ gan an ní ìdajì ọjọ́ kẹrìnlá oṣù yìí ní ìbámu pẹ̀lú àwọn òfin àti ìlànà rẹ̀.”
4 Mówił tedy Mojżesz do synów Izraelskich, aby obchodzili święto przejścia.
Mose sì sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kí wọ́n máa pa àjọ ìrékọjá mọ́.
5 I obchodzili święto przejścia, pierwszego miesiąca, czternastego dnia, między dwoma wieczorami, na puszczy Synaj; według wszystkiego, jak rozkazał Pan Mojżeszowi, tak uczynili synowie Izraelscy.
Wọ́n sì ṣe àjọ ìrékọjá ní aginjù Sinai ní ìdajì ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kìn-ín-ní. Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gbogbo nǹkan gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
6 I byli niektórzy ludzie, którzy się byli splugawili nad umarłym człowiekiem, i nie mogli obchodzić święta przejścia dnia onego; tedy przystąpili do Mojżesza i do Aarona w tenże dzień;
Àwọn díẹ̀ nínú wọn kò lè ṣe àjọ ìrékọjá lọ́jọ́ náà nítorí pé wọ́n di aláìmọ́ nítorí òkú ènìyàn. Nítorí èyí wọ́n wá sọ́dọ̀ Mose àti Aaroni lọ́jọ́ náà.
7 I rzekli oni ludzie do niego: Zmazaliśmy się nad umarłym: i nie będzież nam wolno oddać ofiary Panu czasu naznaczonego wespół z synami Izraelskimi?
Wọ́n sọ fún Mose pé, “A di aláìmọ́ nípa òkú ènìyàn, ṣùgbọ́n kí ló dé tí a kò fi ní í le è fi ọrẹ wa fún Olúwa pẹ̀lú àwọn ará Israẹli yòókù ní àsìkò tí a ti yàn.”
8 Którym odpowiedział Mojżesz: Postójcie, aż usłyszę, co rozkaże Pan o was.
Mose sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ dúró kí n ba lè mọ ohun tí Olúwa yóò pàṣẹ nípa yín.”
9 Tedy rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé,
10 Powiedz synom Izraelskim i rzecz: Jeźliby się kto zmazał nad umarłym, alboby na drodze dalekiej był, tak z was, jako i z potomstwa waszego, przecię będzie odprawował święto przejścia Panu.
“Sọ fún àwọn ará Israẹli: ‘Bí ẹnìkan nínú yín tàbí nínú ìran yín bá di aláìmọ́ nípa òkú ènìyàn tàbí bí ó bá lọ sí ìrìnàjò síbẹ̀ yóò pa àjọ ìrékọjá Olúwa mọ́.
11 Miesiąca wtórego, czternastego dnia, między dwoma wieczorami, odprawować je będą; z przaśnemi chleby, i z gorzkiemi zioły jeść je będą:
Wọn yóò ṣe tiwọn ní ìdajì ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kejì. Wọn yóò jẹ ẹran náà, pẹ̀lú àkàrà aláìwú àti ewúro.
12 Nie zostawią nic z niego do jutra, i kości nie złamią w nim; według wszystkiego postanowienia święta przejścia odprawować je będą:
Wọn kò gbọdọ̀ ṣẹ́ ọ̀kankan kù di àárọ̀, wọn kò sì gbọdọ̀ ṣẹ́ eegun rẹ̀. Wọ́n gbọdọ̀ tẹ̀lé gbogbo ìlànà fún ṣíṣe àjọ ìrékọjá.
13 Ale człowiek, któryby był czysty, a nie byłby w drodze, i nie obchodziłby święta przejścia, tedy dusza ona wykorzeniona będzie z ludu swego, bo ofiary Pańskiej nie odprawował czasu naznaczonego; grzech swój poniesie on człowiek.
Ṣùgbọ́n bí ẹnìkan tó wà ní mímọ́ tí kò sì lọ sí ìrìnàjò bá kọ̀ láti pa àjọ ìrékọjá mọ́, irú ẹni bẹ́ẹ̀ ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀ nítorí pé kò mú ọrẹ Olúwa wá ní àsìkò tí ó yẹ. Ẹni náà yóò sì ru ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.
14 A jeźliby przychodzień mieszkający między wami obchodził święto przejścia Panu, według ustawy święta przejścia i według obrzędów jego obchodzić je będzie; ustawa jedna będzie, wam i przychodniowi, i zrodzonemu w ziemi.
“‘Bí àlejò tí ń gbé láàrín yín bá fẹ́ ṣe àjọ ìrékọjá Olúwa, ó gbọdọ̀ pa á mọ́ ní ìbámu pẹ̀lú ìlànà àti òfin rẹ̀. Ìlànà kan náà ni kí ẹ ní fún àlejò àti àwọn ọmọ bíbí ilẹ̀ yín.’”
15 Dnia tedy onego, którego wystawiony był przybytek, obłok okrył przybytek nad namiotem świadectwa, a wieczór bywało nad przybytkiem jako widzenie ognia aż do poranku.
Ní ọjọ́ tí wọ́n gbé àgọ́ ró, èyí tí í ṣe àgọ́ ẹ̀rí, dúró, ìkùùkuu àwọsánmọ̀ bò ó mọ́lẹ̀. Ìkùùkuu náà sì dàbí iná ní orí àgọ́ láti ìrọ̀lẹ́ títí di òwúrọ̀.
16 Tak bywało ustawicznie; we dnie okrywał go obłok, a jako widzenie ognia w nocy.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì rí nígbà gbogbo; ìkùùkuu bò ó, àti pé ní alẹ́ ìrísí rẹ̀ sì dàbí iná.
17 A gdy się podnaszał obłok od namiotu, tedy się ruszali synowie Izraelscy; a gdziekolwiek stawał obłok, tamże stanowili obóz synowie Izraelscy.
Nígbàkígbà tí ìkùùkuu yìí bá ká sókè kúrò lórí àgọ́ ni àwọn ọmọ Israẹli yóò dìde láti máa lọ; ibikíbi tí ìkùùkuu náà bá dúró sí ni àwọn ọmọ Israẹli yóò pa ibùdó wọn sí.
18 Na rozkazanie Pańskie ciągnęli synowie Izraelscy, i na rozkazanie Pańskie stanowili obóz; po wszystkie dni, których zostawał obłok nad przybytkiem, i oni leżeli obozem.
Nípa àṣẹ Olúwa ni àwọn ọmọ Israẹli ń jáde lọ, nípa àṣẹ Olúwa náà sì ni wọ́n ń pa ibùdó wọn. Nígbà tí ìkùùkuu bá dúró sórí àgọ́, àwọn náà yóò dúró sí ibùdó.
19 A gdy trwał obłok nad przybytkiem przez wiele dni, tedy odprawowali synowie Izraelscy straż Panu, a nie ruszali się.
Nígbà tí ìkùùkuu bá dúró sórí àgọ́ fún ìgbà pípẹ́, síbẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli gbọ́rọ̀ sí àṣẹ Olúwa wọn kò sì ní gbéra láti lọ.
20 Ale gdy nie długo trwał obłok nad przybytkiem, na rozkazanie Pańskie stanowili obóz, i na rozkazanie Pańskie ciągnęli.
Ìgbà mìíràn ìkùùkuu lè wà lórí àgọ́ fún ọjọ́ díẹ̀; síbẹ̀ ní àṣẹ Olúwa, wọn yóò dúró ní ibùdó, bí ó sì tún yá, ní àṣẹ rẹ̀ náà ni wọn yóò gbéra.
21 A gdy bywał obłok od wieczora aż do poranku, a podnosił się zaś poranku, tedy ciągnęli; tak we dnie jako i w nocy, gdy się podniósł obłok, ciągnęli.
Ìgbà mìíràn ìkùùkuu lè dúró láti ìrọ̀lẹ́ di àárọ̀, nígbà tó bá ṣí kúrò ní àárọ̀, wọn ó gbéra. Ìbá à ṣe ní ọ̀sán tàbí òru, ìgbàkígbà tí ìkùùkuu bá tó kúrò náà ni wọn ó tó gbéra.
22 A jeźli przez dwa dni, albo przez miesiąc, albo też przez rok trwał obłok nad przybytkiem, zostawając nad nim, obozem leżeli synowie Izraelscy, i nie ruszali się; ale gdy się on podnosił, i oni się ruszali.
Ìbá à ṣe fún ọjọ́ méjì, oṣù kan tàbí ọdún kan ni ìkùùkuu fi dúró sórí àgọ́, àwọn ọmọ Israẹli yóò dúró ní ibùdó wọn, wọn kò ní gbéra; ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá lọ sókè ni wọn ó tó o gbéra.
23 Na rozkazanie Pańskie stanowili obóz, i na rozkazanie Pańskie ciągnęli, straż Pańską trzymając, jako im Pan rozkazał przez Mojżesza.
Nípa àṣẹ Olúwa ni wọ́n ń pa ibùdó wọn, nípa àṣẹ Olúwa náà sì ni wọ́n ń gbéra. Wọ́n gbọ́rọ̀ sí àṣẹ Olúwa ní ìbámu pẹ̀lú àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose.

< Liczb 9 >