< Liczb 8 >

1 Potem Pan rzekł do Mojżesza, mówiąc:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Powiedz Aaronowi, a rzecz mu: Gdy zapalisz lampy, siedem lamp przeciwko świecznikowi świecić będą.
“Bá Aaroni sọ̀rọ̀ kí o wí fún un pé. ‘Nígbà tí ó bá ń to àwọn fìtílà, àwọn fìtílà méjèèje gbọdọ̀ tan ìmọ́lẹ̀ sí àyíká níwájú ọ̀pá fìtílà.’”
3 I uczynił tak Aaron, a przeciwko świecznikowi zapalił lampy jego, jako był rozkazał Pan Mojżeszowi.
Aaroni sì ṣe bẹ́ẹ̀; ó to àwọn fìtílà náà tí wọ́n sì fi kojú síwájú lórí ọ̀pá fìtílà gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
4 A była robota świecznika z ciągnionego złota, i słupiec jego, i kwiaty jego ciągnione były; na ten kształt, jaki był Pan ukazał Mojżeszowi, tak urobił świecznik.
Bí a ṣe ṣe ọ̀pá fìtílà náà nìyìí, a ṣe é láti ara wúrà lílù: láti ìsàlẹ̀ títí dé ibi ìtànná rẹ̀. Wọ́n ṣe ọ̀pá fìtílà náà gẹ́gẹ́ bí bátànì tí Olúwa fihan Mose.
5 Potem rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
Olúwa sọ fún Mose pé,
6 Weźmij Lewity z pośród synów Izraelskich, a oczyść je.
“Yọ àwọn ọmọ Lefi kúrò láàrín àwọn ọmọ Israẹli yòókù, kí o sì wẹ̀ wọ́n mọ́.
7 A to uczynisz oczyszczając je: Pokropisz je wodą oczyszczenia; ciż ogolą brzytwą wszystko ciało swoje, a uprawszy szaty swe, czystymi będą.
Báyìí ni kí o ṣe wẹ̀ wọ́n mọ́. Wọ́n omi ìwẹ̀nùmọ́ sí wọn lára, mú kí wọn ó fá irun ara wọn, kí wọn ó fọ aṣọ wọn, kí wọn ó ba à lè wẹ ara wọn mọ́ nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀.
8 Potem wezmą cielca młodego, z ofiarą jego śniedną, mąki pszennej, zagniecionej z oliwą, a cielca młodego drugiego weźmiesz na ofiarę za grzech.
Jẹ́ kí wọn ó mú akọ ọ̀dọ́ màlúù pẹ̀lú ẹbọ ohun jíjẹ rẹ̀ tí í ṣe ìyẹ̀fun ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára tí a fi òróró pò, kí ìwọ náà mú akọ ọ̀dọ́ màlúù kejì fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
9 I przywiedziesz Lewity przed namiot zgromadzenia, a przyzowiesz wszystkiego zgromadzenia synów Izraelskich;
Ìwọ ó sì mú àwọn ọmọ Lefi wá síwájú àgọ́ ìpàdé, kí o sì kó gbogbo àpapọ̀ ọmọ Israẹli jọ síbẹ̀ pẹ̀lú.
10 I postawisz Lewity przed Panem, i włożą synowie Izraelscy ręce swe na Lewity;
Báyìí ni kí o mú àwọn ọmọ Lefi wá síwájú Olúwa, gbogbo ọmọ Israẹli yóò sì gbọ́wọ́ lé àwọn ọmọ Lefi lórí.
11 I ofiarować będzie Aaron Lewity na ofiarę przed panem od synów Izraelskich, aby sprawowali posługi Pańskie.
Aaroni yóò sì mú àwọn ọmọ Lefi wá síwájú Olúwa gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fífì láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Israẹli wá, kí wọn lè máa ṣiṣẹ́ Olúwa.
12 Lewitowie zaś będą kłaść ręce swe na głowy onych cielców, a ofiarować będziesz jednego za grzech, a drugiego na ofiarę całopalenia Panu ku oczyszczeniu Lewitów.
“Lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Lefi bá gbé ọwọ́ wọn lé orí àwọn akọ ọmọ màlúù náà, ìwọ yóò sì fi ọ̀kan rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun sí Olúwa, láti ṣe ètùtù fún àwọn ọmọ Lefi.
13 Potem postawisz Lewity przed Aaronem, i przed syny jego, a ofiarować je będziesz na ofiarę Panu.
Mú kí àwọn ọmọ Lefi dúró níwájú Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ kí ó sì gbé wọn kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fífì sí Olúwa.
14 I odłączysz Lewity z pośród synów Izraelskich, i będą moimi Lewitowie.
Báyìí ni ìwọ yóò ṣe ya ọmọ Lefi sọ́tọ̀, kúrò láàrín àwọn ọmọ Israẹli yòókù, àwọn ọmọ Lefi yóò sì jẹ́ tèmi.
15 A potem przyjdą Lewitowie, aby służyli w namiocie zgromadzenia, gdy oczyścisz i poświęcisz je na ofiarę.
“Lẹ́yìn tí ó ti wẹ àwọn ọmọ Lefi mọ́, tí ó sì ti gbé wọn kalẹ̀ bí ẹbọ fífì nígbà náà ni kí wọn ó lọ máa ṣiṣẹ́ nínú àgọ́ ìpàdé.
16 Albowiem właśnie oddani są mnie z pośród synów Izraelskich; za każde otwierające żywot, za każde pierworodne z synów Izraelskich obrałem je sobie,
Nítorí pé àwọn ni ó jẹ́ ti Èmi pátápátá nínú àwọn ọmọ Israẹli. Mo ti gbà wọ́n fún ara mi dípò àwọn àkọ́bí àní àkọ́bí ọkùnrin gbogbo Israẹli.
17 Gdyż wszyscy pierworodni z synów Izraelskich moi są z ludzi i z bydła: ode dnia, któregom pobił wszystkie pierworodne w ziemi Egipskiej, poświęciłem je sobie.
Nítorí pé gbogbo àkọ́bí ọmọ lọ́kùnrin ní Israẹli jẹ́ tèmi, ti ènìyàn àti ti ẹranko, láti ọjọ́ tí mo ti pa gbogbo àkọ́bí ní ilẹ̀ Ejibiti ni mo ti yà wọ́n sọ́tọ̀ fún ara mi.
18 A przyjąłem Lewity miasto wszelkiego pierworodnego z synów Izraelskich.
Mo sì ti gba àwọn ọmọ Lefi dípò gbogbo àkọ́bí ọmọ ọkùnrin nínú Israẹli.
19 I dałem Lewity darem Aaronowi i synom jego z pośród synów Izraelskich, aby odprawowali służby miasto synów Izraelskich w namiocie zgromadzenia, i oczyszczali syny Izraelskie, aby nie przyszło na syny Izraelskie karanie, gdyby przystępowali synowie Izraelscy do świątnicy.
Nínú Israẹli, mo fi àwọn ọmọ Lefi fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀bùn láti máa ṣiṣẹ́ nínú àgọ́ ìpàdé fun àwọn ọmọ Israẹli àti láti máa ṣe ètùtù fún wọn kí àjàkálẹ̀-ààrùn má ba à kọlu àwọn ọmọ Israẹli nígbà tí wọ́n bá súnmọ́ ibi mímọ́.”
20 Uczynili tedy Mojżesz i Aaron i wszystko zgromadzenie synów Izraelskich z Lewitami wszystko, co rozkazał Pan Mojżeszowi o Lewitach, tak uczynili z nimi synowie Izraelscy.
Mose, Aaroni àti gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì ṣe fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
21 I oczyścili się Lewitowie, a uprali szaty swoje, i ofiarował je Aaron na ofiarę przed Panem, i oczyścił je Aaron, aby byli czystymi.
Àwọn ọmọ Lefi wẹ ara wọn mọ́, wọ́n sì fọ aṣọ wọn. Aaroni sì mú wọn wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fífì níwájú Olúwa, Aaroni sì ṣe ètùtù fún wọn láti wẹ̀ wọ́n mọ́.
22 Dopiero potem przystąpili Lewitowie ku sprawowaniu urzędu swego w namiocie zgromadzenia przed Aaronem i przed syny jego; jako rozkazał Pan Mojżeszowi o Lewitach, tak im uczynili.
Lẹ́yìn èyí àwọn ọmọ Lefi lọ sínú àgọ́ ìpàdé láti lọ máa ṣiṣẹ́ wọn lábẹ́ àbojútó Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀. Wọ́n ṣe fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
23 Rzekł nadto Pan do Mojżesza, mówiąc:
Olúwa sọ fún Mose pé,
24 To też Lewitom należy: Od dwudziestego i piątego roku i wyżej każdy przystąpi, aby sprawował urząd przy posłudze namiotu zgromadzenia.
“Èyí ni ohun tó jẹ mọ́ àwọn ọmọ Lefi, láti ọmọ ọdún kẹẹdọ́gbọ̀n tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ ni kí ó máa kópa nínú iṣẹ́ àgọ́ ìpàdé.
25 A w pięćdziesiąt lat przestanie pracować w urzędzie, i więcej służyć nie będzie.
Ṣùgbọ́n ẹni tó bá ti pé ọmọ àádọ́ta ọdún gbọdọ̀ ṣíwọ́ nínú iṣẹ́ ojoojúmọ́ wọn nínú àgọ́, kí wọ́n sì má ṣiṣẹ́ mọ́.
26 Ale nadsługować będzie braci swej w namiocie zgromadzenia straż trzymającym, lecz służby samej odprawować nie będzie. Tak sobie postąpisz z Lewitami w urzędziech ich.
Wọ́n le máa ran àwọn arákùnrin wọn lọ́wọ́ nínú àgọ́ ìpàdé ṣùgbọ́n àwọn fúnra wọn kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan. Báyìí ni kí o ṣe pín iṣẹ́ fún àwọn ọmọ Lefi.”

< Liczb 8 >