< Liczb 36 >

1 Tedy przystąpili mężowie przedniejsi z ojców pokolenia synów Galaada, syna Machyrowego, syna Manasesowego, z domów Józefowych, i mówili przed Mojżeszem, i przed książęty przedniejszymi ojców synów Izraelskich, i rzekli:
Àwọn olórí ìdílé Gileadi, ọmọkùnrin Makiri ọmọ Manase tí ó wá láti ara ìdílé ìran Josẹfu wá, wọ́n sì sọ̀rọ̀ níwájú Mose àti àwọn olórí, àwọn ìdílé Israẹli.
2 Tobie, panu memu, rozkazał Pan, abyś podzielił ziemię w dziedzictwo losem synom Izraelskim; nadto panu memu rozkazano od Pana, abyś dał dziedzictwo Salfaada, brata naszego, córkom jego.
Wọ́n sọ pé, “Nígbà tí Olúwa pàṣẹ fún olúwa mi láti fi ilẹ̀ yìí fún àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí ogún nípa kèké ṣíṣẹ́. Ó pa á láṣẹ fún ọ láti fi ogún Selofehadi arákùnrin wa fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀.
3 Które jeźliby kto z inszego pokolenia synów Izraelskich wziął za żony, odjęte będzie ich dziedzictwo od dziedzictwa ojców naszych, a przyłączy się do dziedzictwa onego pokolenia, do którego by je wzięto za żony, a tak z losu dziedzictwa naszego ubędzie.
Wàyí, tí wọn bá fẹ́ ọkùnrin láti ẹ̀yà Israẹli mìíràn; nígbà náà a ó gba ogún un wọn kúrò nínú ogún ìran wa, a ó sì fi kún ogún ẹ̀yà tí a fẹ́ wọn sí. Bẹ́ẹ̀ ni a ó sì gbà á kúrò nínú ìpín ilẹ̀ ogún ti wa.
4 A gdy przyjdzie miłościwe lato synom Izraelskim, tedy przyłączone będzie dziedzictwo ich do dziedzictwa onego pokolenia, do którego by poszły za mąż; a tak od dziedzictwa pokolenia ojców naszych odjęte będzie dziedzictwo ich.
Nígbà tí ọdún ìdásílẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli bá dé, a ó pa ogún wọn pọ̀ mọ́ ẹ̀yà tí wọ́n fẹ́ wọn sí, a ó sì gba ogún ẹ̀yà wọn kúrò lọ́wọ́ baba ńlá wọn.”
5 Tedy powiedział Mojżesz synom Izraelskim według słowa Pańskiego, mówiąc: Dobrze mówi pokolenie synów Józefowych.
Gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa, Mose pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ohun ti ẹ̀yà àwọn ìran Josẹfu ń sọ tọ̀nà.
6 Toć to jest, co rozkazał Pan o córkach Salfaadowych, mówiąc: Jako się im upodoba, niech idą za mąż; tylko w domu pokolenia ojców swoich niech idą za mąż.
Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ fún àwọn ọmọbìnrin Selofehadi: wọ́n lè fẹ́ ẹni tí ọkàn wọn fẹ́, kìkì pé wọ́n fẹ́ nínú ẹ̀yà ìdílé baba wọn.
7 Aby nie było przenoszone dziedzictwo synów Izraelskich z pokolenia na pokolenie; bo każdy z synów Izraelskich zostawać ma przy dziedzictwie pokolenia ojców swych.
Kò sí ogún kan ní Israẹli tí ó gbọdọ̀ kọjá láti ẹ̀yà kan sí ẹ̀yà mìíràn, nítorí gbogbo ọmọ Israẹli ni yóò fi ilẹ̀ ogún ẹ̀yà tí wọ́n jogún láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn pamọ́.
8 I każda córka, która by miała dziedzictwo z pokoleń synów Izraelskich, za kogokolwiek z domu pokolenia ojca swego pójdzie, żeby otrzymali dziedziczenie synowie Izraelscy, każdy dziedzictwo ojców swych.
Gbogbo ọmọbìnrin tí ó bá jogún ilẹ̀ nínú ẹ̀yà Israẹli kọ̀ọ̀kan gbọdọ̀ fẹ́ ènìyàn nínú ẹ̀yà ìdílé baba rẹ̀, kí gbogbo ọmọ Israẹli lè ní ìpín nínú ogún baba wọn.
9 Bo nie ma być przenoszone dziedzictwo, z pokolenia na pokolenie insze; ale każdy przy dziedzictwie swojem zostać ma z pokolenia synów Izraelskich.
Kò sí ogún kankan tí ó gbọdọ̀ kọjá láti ẹ̀yà kan sí ẹ̀yà òmíràn, nítorí olúkúlùkù ẹ̀yà ọmọ Israẹli gbọdọ̀ tọ́jú ilẹ̀ tí ó jogún.”
10 Jako tedy rozkazał Pan Mojżeszowi, tak uczyniły córki Salfaadowe.
Nígbà náà, àwọn ọmọbìnrin Selofehadi ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
11 Bo Mahala, Tersa, i Hegla, i Melcha, i Noa, córki Salfaadowe, szły za mąż, za syny stryjów swoich.
Nítorí pé a gbé Mahila, Tirsa, Hogla, Milka, àti Noa, àwọn ọmọbìnrin Selofehadi ní ìyàwó fún àwọn ọmọ arákùnrin baba wọn.
12 W domy synów Manasesa, syna Józefowego poszły za mąż; i tak zostało dziedzictwo ich przy pokoleniu domu ojca ich.
Wọ́n fẹ́ ọkọ nínú ìdílé ìran Manase, ọmọ Josẹfu ogún wọn kù nínú ìdílé àti ẹ̀yà baba wọn.
13 Teć są przykazania i prawa, które rozkazał Pan przez Mojżesza synom Izraelskim na polach Moabskich, nad Jordanem przeciw Jerychowi.
Wọ̀nyí ni àṣẹ àti ìdájọ́ tí Olúwa ti ipasẹ̀ Mose fún àwọn ọmọ Israẹli ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá Jordani létí Jeriko.

< Liczb 36 >