< Liczb 34 >

1 Potem rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Rozkaż synom Izraelskim, a powiedz im: Gdy wnijdziecie do ziemi Chananejskiej, (tać jest ziemia, która się wam dostanie za dziedzictwo, ziemia Chananejska z granicami swemi.)
“Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Tí ẹ bá wọ Kenaani, ilẹ̀ tí a ó fi fún yín, gẹ́gẹ́ bí ogún yín yóò ní ààlà wọn yí:
3 Tedy będzie granica wasza ku południowi, od puszczy Syn aż do granic Edomskich, która granica południowa pójdzie od brzegu morza słonego na wschód słońca.
“‘Ìhà gúúsù yín yóò bọ́ sí ara aginjù Sini lẹ́bàá Edomu, àti ìlà-oòrùn, ààlà ìhà gúúsù yóò bẹ̀rẹ̀ láti òpin Òkun Iyọ̀,
4 I okrąży ta granica od południa do Maaleakrabim, i pójdzie aż ku puszczy Syn, i pójdzie od południa do Kades Barne; a stamtąd wynijdzie do wsi Addar, i pójdzie aż do Asmon.
kọjá lọ sí gúúsù Akrabbimu, tẹ̀síwájú lọ si Sini, kó bọ́ si gúúsù Kadeṣi-Barnea, kí o sì dé Hasari-Addari, kí o sì kọjá sí Asmoni.
5 A zakrąży ta granica od Asmon aż do rzeki Egipskiej, a skończy się na zachód.
Kí òpin ilẹ̀ rẹ̀ kí ó sì yíká láti Asmoni lọ dé odò Ejibiti, Òkun Ńlá ni yóò sì jẹ òpin rẹ.
6 Zachodnią zaś granicę będziecie mieli morze wielkie; to wam będzie granicą od zachodu.
Ìhà ìwọ̀-oòrùn yín yóò jẹ́ òpin lórí Òkun Ńlá. Èyí yóò jẹ́ ààlà yín lórí ìhà ìwọ̀-oòrùn.
7 To zaś wasza będzie granica północna; od morza wielkiego wymierzycie sobie do góry Hor.
Fún ààlà ìhà àríwá, fa ìlà láti Òkun Ńlá lọ sí orí òkè Hori,
8 Potem od góry Hor wymierzycie granice, aż gdzie wchodzą do Hemat; a będą się kończyć granice aż do Sedada.
àti láti orí òkè Hori sí Lebo-Hamati. Nígbà náà ààlà náà yóò lọ sí Sedadi,
9 I pójdzie ta granica aż do Zefronu, a skończy się u wsi Enan; tę będziecie mieć granice północną.
tẹ̀síwájú lọ sí Sifroni, kí o sì fò pín si ní Hasari-Enani, èyí yóò jẹ́ ààlà tìrẹ ní ìhà àríwá.
10 Granicę też od wschodu wymierzycie od wsi Enan aż do Sefama.
Kí ẹ sì sàmì sí ilẹ̀ tiyín ní ìhà ìlà-oòrùn láti Hasari-Enani lọ dé Ṣefamu.
11 A pójdzie ta granica od Sefama aż do Reblat, od wschodu miasta Ain; i uda się ta granica i dojdzie do brzegu morza Cyneret na wschód słońca.
Ààlà náà yóò ti Ṣefamu sọ̀kalẹ̀ wá lọ sí Ribla ní ìhà ìlà-oòrùn Aini, kí o sì sọ̀kalẹ̀ lọ dé ìhà Òkun Kinnereti ní ìhà ìlà-oòrùn.
12 A przyjdzie ta granica aż ku Jordanu, a skończy się u morza słonego. Tać będzie ziemia wasza w granicach swoich w około.
Nígbà náà, ààlà náà yóò sọ̀kalẹ̀ lọ sí apá Jordani, yóò sì dópin nínú Òkun Iyọ̀. “‘Èyí yóò jẹ́ ilẹ̀ yín, pẹ̀lú ààlà tirẹ̀ ní gbogbo ọ̀nà.’”
13 Tedy oznajmił Mojżesz synom Izraelskim, mówiąc: Tać jest ziemia, którą dziedzicznie otrzymacie losem, jako rozkazał Pan, abym ją dał dziewięciorgu pokoleniu, i połowie pokolenia Manasesowego.
Mose pa á láṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Yan ilẹ̀ yìí pẹ̀lú kèké gẹ́gẹ́ bí ìní ogún: Olúwa ti pàṣẹ láti fi fún ẹ̀yà mẹ́sàn-án, àti ààbọ̀.
14 Bo wzięło pokolenie synów Rubenowych według domów ojców swych, i pokolenie synów Gadowych według domów ojców swych, i połowa pokolenia Manasesowego wzięli dziedzictwo swoje.
Nítorí ará ilẹ̀ ẹ̀yà ti Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ẹ̀yà ààbọ̀ ti Manase ti gba ogún tiwọn.
15 Dwa pokolenia, i pół pokolenia, wzięły dziedzictwo swoje z tej strony Jordanu przeciw Jerychu, ku stronie na wschód słońca.
Ẹ̀yà méjèèjì àti ààbọ̀ yìí ti gba ogún tiwọn ní ìhà ìhín Jordani létí i Jeriko, ní ìhà ìlà-oòrùn, ní ìdojúkọ Jordani.”
16 I rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
Olúwa sọ fún Mose pé,
17 Teć są imiona mężów, którzy wam podzielą w dziedzictwo ziemię: Eleazar kapłan, i Jozue, syn Nunów.
“Èyí ni orúkọ àwọn ọkùnrin náà tí yóò pín ilẹ̀, náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ogún: Eleasari àlùfáà àti Joṣua ọmọ Nuni.
18 Księcia także jednego z każdego pokolenia weźmiecie dla podzielenia w dziedzictwo ziemi.
Kí o sì yan olórí kan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan láti pín ilẹ̀ náà.
19 A teć są imiona tych mężów: z pokolenia Juda Kaleb, syn Jefunów;
“Èyí ni orúkọ wọn: “Kalebu ọmọ Jefunne, láti ẹ̀yà Juda;
20 A z pokolenia synów Symeonowych Samuel, syn Ammiudów.
Ṣemueli ọmọ Ammihudu, láti ẹ̀yà Simeoni;
21 Z pokolenia Benjamin Eliad, syn Chaselenów.
Elidadi ọmọ Kisloni, láti ẹ̀yà Benjamini;
22 A z pokolenia synów Danowych książę Buki, syn Jogolów.
Bukki ọmọ Jogli, láti ẹ̀yà olórí àwọn ọmọ Dani;
23 Z synów Józefowych z pokolenia synów Manasesowych książę Haniel, syn Efodów.
Hannieli ọmọ Efodu, láti ẹ̀yà Manase, olórí àwọn ọmọ Josẹfu,
24 A z pokolenia synów Efraimowych książę Chemuel, syn Seftanów.
Kemueli ọmọ Ṣiftani, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ, Efraimu, ọmọ Josẹfu;
25 Z pokolenia zaś Zabulonowego książę Elisafan, syn Farnatów.
Elisafani ọmọ Parnaki, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Sebuluni;
26 A z pokolenia synów Isascharowych książę Faltijel, syn Ozanów.
Paltieli ọmọ Assani, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Isakari;
27 Z pokolenia synów Aserowych książę Ahiud, syn Salomiego.
Ahihudu ọmọ Ṣelomi, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Aṣeri;
28 A z pokolenia synów Neftalimowych książę Fedael, syn Ammiudów.
Pedaheli ọmọ Ammihudu, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Naftali.”
29 Cić są, którym rozkazał Pan, aby dali dziedzictwo synom Izraelskim w ziemi Chananejskiej.
Èyí ni àwọn ẹni tí Olúwa yàn láti pín ogún náà fún àwọn ọmọ Israẹli ní ilẹ̀ Kenaani.

< Liczb 34 >