< Liczb 31 >

1 Potem rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Pomścij się krzywdy synów Izraelskich nad Madyjanitami, i potem przyłączon będziesz do ludu twego.
“Gbẹ̀san lára àwọn Midiani fún àwọn ọmọ Israẹli. Lẹ́yìn ìgbà náà a ó kó ọ jọ pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ.”
3 Tedy rzekł Mojżesz do ludu, mówiąc: Wyprawcie z pośrodku siebie męże ku bitwie, aby szli przeciw Madyjanitom, i wykonali pomstę Pańską nad nimi.
Mose sì sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ wọ ogun fún àwọn kan nínú yín láti lọ da ojú ìjà kọ àwọn ọmọ Midiani láti gba ẹ̀san Olúwa lára wọn.
4 Po tysiącu z każdego pokolenia, ze wszystkich pokoleń Izraelskich wyślecie na wojnę.
Rán ẹgbẹ̀rún ọmọ-ogun láti ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan ní Israẹli.”
5 I wyprawili z tysiąców Izraelskich, po tysiącu z każdego pokolenia, dwanaście tysięcy ludzi gotowych do bitwy.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì yan nínú àwọn ẹgbẹẹgbẹ̀rún ènìyàn Israẹli, ẹgbẹ̀rún ènìyàn láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan, ẹgbàá mẹ́fà ènìyàn tí ó wọ ìhámọ́ra ogun.
6 I wysłał je Mojżesz po tysiącu z każdego pokolenia na wojnę; posłał też z nimi Fineesa, syna Eleazara kapłana, na wojnę, a naczynia święte, i trąby do trąbienia były w ręku jego.
Mose rán wọn lọ sí ogun, ẹgbẹ̀rún láti ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan pẹ̀lú Finehasi ọmọ Eleasari, ti ó jẹ́ àlùfáà, ti òun ti ohun èlò ibi mímọ́ àti ìpè wọ̀n-ọn-nì ní ọwọ́ rẹ̀.
7 Tedy zwiedli bitwę z Madyjanitami, jako rozkazał Pan Mojżeszowi, i pobili wszystkie mężczyzny.
Wọ́n dojú ìjà kọ Midiani gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose, kí wọn sì pa gbogbo wọn.
8 Króle też Madyjańskie pobili między inszymi pobitymi ich, Ewiego, i Rechema, i Sura, i Hura, i Rebaha, pięciu królów Madyjańskich, i Balaama, syna Beorowego, zabili mieczem.
Wọ́n sì pa àwọn ọba Midiani pẹ̀lú: àwọn ìyókù tí wọ́n pa lára wọn ni Efi, Rekemu, Suri àti Huri, àti Reba: ọba Midiani márùn-ún, wọ́n sì fi idà pa Balaamu ọmọ Beori.
9 I pobrali w niewolą synowie Izraelscy żony Madyjańczyków, i dziatki ich, i wszystko bydło ich, i wszystkie trzody ich, i wszystkie majętności ich pobrali;
Àwọn ọmọ Israẹli sì mú gbogbo obìnrin Midiani ní ìgbèkùn àti àwọn ọmọ kékeré wọn, wọ́n sì kó gbogbo ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo agbo ẹran wọn àti gbogbo ẹrù wọn.
10 A wszystkie miasta ich, w których mieszkali, i wszystkie zamki ich popalili ogniem;
Wọ́n finá jó gbogbo ìlú wọn àti ibùdó wọn.
11 I pobrali wszystkie łupy, i wszystkie plony z ludzi, i z bydła,
Wọ́n sì kó gbogbo ìní wọn, àti ènìyàn àti ẹran.
12 I przywiedli do Mojżesza i do Eleazara kapłana, i do zgromadzenia synów Izraelskich więźnie, i łupy, i korzyści do obozu na pola Moabskie, które są nad Jordanem przeciw Jerychu.
Wọ́n sì kó gbogbo ohun tí wọ́n bàjẹ́ àti ènìyàn àti ẹran wá sọ́dọ̀ Mose àti Eleasari àlùfáà, àti sọ́dọ̀ ìjọ àwọn ọmọ Israẹli ní ibùdó àgọ́ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu tí ń bẹ lẹ́gbẹ̀ẹ́ Jordani létí Jeriko.
13 I wyszli Mojżesz i Eleazar kapłan, i wszystkie książęta zgromadzenia przeciwko nim przed obóz.
Mose, Eleasari àlùfáà àti gbogbo olórí ìgbèríko lọ láti lọ bá wọn ní ìta ibùdó.
14 I rozgniewał się bardzo Mojżesz na hetmany wojska onego, na pułkowniki, i na rotmistrze, którzy się byli wrócili z onej bitwy.
Inú bí Mose sí àwọn olórí ọmọ-ogun, pẹ̀lú àwọn olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún tí wọ́n ti ogun dé.
15 I mówił do nich Mojżesz: Przeczżeście żywo zachowali wszystkie niewiasty?
Mose sì béèrè wí pé, “Ẹ̀yin ha dá gbogbo àwọn obìnrin sí bí?
16 Gdyż te są, które synom Izraelskim za radą Balaamową dały przyczynę do przestępstwa przeciw Panu przy bałwanie Fegor, skąd była przyszła plaga na zgromadzenie Pańskie.
Àwọn ni wọ́n tẹ̀lé ìmọ̀ràn Balaamu, àwọn ní ó ṣe okùnfà yíyí àwọn ọ̀mọ̀ Israẹli padà kúrò ní ọ̀dọ̀ Olúwa nínú èyí tí ó ṣẹlẹ̀ ní Peori, níbi tí àjàkálẹ̀-ààrùn ti kọlu ìjọ Olúwa.
17 Przetoż teraz pozabijajcie wszystkie mężczyzny z dzieci, i każdą niewiastę, która poznała męża, obcując z nim, zabijcie;
Nísinsin yìí, pa gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin àti àwọn obìnrin tí ó ti súnmọ́ ọkùnrin,
18 Ale wszystkie dzieweczki z białych głów, które nie poznały łoża męskiego, żywo zachowajcie sobie.
ṣùgbọ́n kí o dá obìnrin tí kò bá tí ì súnmọ́ ọkùnrin sí fún ara yín.
19 A wy sami zostańcie w namiecich za obozem przez siedem dni; każdy, który kogo zabił, i który się dotykał zabitego, oczyścicie się dnia trzeciego a dnia siódmego, siebie i więźnie wasze;
“Ẹnikẹ́ni tí ó bá ti pa ènìyàn tàbí fọwọ́ kan ẹni tí a pa gbọdọ̀ dúró ní ìta ibùdó àgọ́ fún ọjọ́ méje. Ní ọjọ́ kẹta àti ọjọ́ keje ẹ gbọdọ̀ ya ara yín àti ẹni tí ẹ kó lẹ́rú sí mímọ́.
20 I wszelką szatę, i wszelkie naczynie skórzane, i wszystko, co urobiono z koziej sierści, i wszelkie naczynie drzewiane oczyścicie.
Kí ẹ̀yin kí ó ya aṣọ yín sí mímọ́ àti gbogbo ohun tí a fi awọ ṣe àti gbogbo iṣẹ́ irun ewúrẹ́ àti ohun tí a fi igi ṣe.”
21 I rzekł Eleazar kapłan do żołnierstwa, które chodziło na wojnę: Tać jest ustawa zakonna, którą był rozkazał Pan Mojżeszowi:
Eleasari àlùfáà sì wí fún àwọn olórí ogun náà pé, “Èyí ní ìlànà òfin tí Olúwa fi lélẹ̀ ní àṣẹ fún Mose.
22 Złoto jednak i srebro, miedź, żelazo, cynę i ołów;
Kìkì i wúrà, fàdákà, idẹ, irin, idẹ àti òjé.
23 I każdą rzecz, która znieść może ogień, wyprawicie przez ogień, a będzie oczyszczona, wszakże pierwej wodą oczyszczenia będzie oczyszczona; ale wszystko, co nie może znieść ognia, wodą oczyścicie.
Ohunkóhun tí ó lè la iná ni kí ẹ̀yin ó mú la iná, nígbà náà ni yóò jẹ́ mímọ́. Ṣùgbọ́n ẹ yóò fi omi ìyàsímímọ́ sọ ọ́ di mímọ́. Àti gbogbo ohun tí kò lè la iná kọjá ni kí a mú la inú omi.
24 Upierzecie też szaty wasze dnia siódmego, i czystymi będziecie, a potem wnijdziecie do obozu.
Ní ọjọ́ keje, ẹ fọ aṣọ yín, ẹ̀yin yóò sì mọ́, nígbà náà ní ẹ̀yin yóò lè wọ inú ibùdó àjọ.”
25 Zatem rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
Olúwa sọ fún Mose pé,
26 Zbierz summę korzyści pobranych z ludzi i z bydła, ty i Eleazar kapłan, i przedniejsi z ojców w ludu;
“Ìwọ àti Eleasari àlùfáà àti àwọn olórí ilé baba ìjọ ni kí o ka iye àwọn ènìyàn àti ẹranko tí a kó ní ìgbèkùn.
27 I rozdzielisz te łupy na dwie części, między żołnierze, którzy na wojnę wychodzili, i między wszystko zgromadzenie.
Pín ohun ìní àti ìkógun náà láàrín àwọn ọmọ-ogun náà tí ó kópa nínú ogun náà àti láàrín gbogbo ìjọ.
28 Odbierzesz też dział na Pana od mężów rycerskich, którzy byli wyszli na wojnę, po jednemu od pięciu set, z ludzi, i z wołów, i z osłów, i z owiec;
Kí o sì gba ìdá ti Olúwa lọ́wọ́ àwọn ológun tí wọn jáde lọ sí ogun náà, ọ̀kan nínú ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta nínú àwọn ènìyàn àti nínú màlúù àti nínú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti nínú agbo ẹran.
29 A z połowy ich weźmiecie, i oddacie Eleazarowi kapłanowi na ofiarę podnoszenia Panu.
Gba ìdá yìí lára ààbọ̀ ìpín tiwọn, kí o sì fún Eleasari àlùfáà, fún ẹbọ ìgbésókè Olúwa.
30 A z połowy synów Izraelskich weźmiesz jedną część z pięciudziesiąt, z ludzi, z wołów, z osłów, i z owiec, i z wszelkiego bydła, i oddasz to Lewitom trzymającym straż w przybytku Pańskim.
Lára ààbọ̀ ti Israẹli, yan ọ̀kan kúrò nínú àádọ́ta, yálà ènìyàn, ẹran ọ̀sìn, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àgùntàn, ewúrẹ́ tàbí ẹ̀yà ẹranko mìíràn. Kó wọn fún àwọn Lefi, tí ó dúró fún olùtọ́jú àgọ́ Olúwa.”
31 I uczynił Mojżesz i Eleazar kapłan, jako rozkazał Pan Mojżeszowi.
Nígbà náà Mose àti Eleasari àlùfáà ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
32 A było onej korzyści z pozostałych łupów, które rozchwycił lud wojenny: Owiec sześć kroć sto tysięcy, i siedemdziesiąt tysięcy i pięć tysięcy;
Èrè tí ó kù lára ìkógun tí àwọn ọmọ-ogun kó jẹ́, ọ̀kẹ́ mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n ó dín ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n àgùntàn.
33 Wołów zaś, siedemdziesiąt i dwa tysiące;
Ẹgbàá méjìléláàádọ́rin màlúù
34 A osłów sześćdziesiąt tysięcy i jeden.
ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé ẹgbẹ̀rin kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,
35 A ludzi z białych głów, które nie poznały obcowania z mężem, wszystkich było trzydzieści i dwa tysiące.
pẹ̀lú obìnrin ẹgbàá mẹ́rìndínlógún, ni kò ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú ọkùnrin rí.
36 I dostała się połowa działu tym, co wychodzili na wojnę, liczba owiec trzy kroć sto tysięcy, i trzydzieści tysięcy, i siedem tysięcy i pięć set.
Ìpín ààbọ̀ àwọn tí ó jáde lọ sí ogun sì jẹ́: ẹgbàá méjìdínláàádọ́sàn-án ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ àgùntàn.
37 Dostało się też działu na Pana owiec sześć set, siedemdziesiąt i pięć;
Tí ìdá ti Olúwa sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n àgùntàn;
38 A z wołów trzydzieści i sześć tysięcy, a działu z nich Panu siedemdziesiąt i dwa;
ẹgbọrọ màlúù jẹ́ ẹgbàá méjìdínlógún, tí ìdá Olúwa sì jẹ́ méjìléláàádọ́rin;
39 Osłów też trzydzieści tysięcy i pięć set, a działu z nich Panu sześćdziesiąt i jeden.
kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta, tí ìdá ti Olúwa sì jẹ́ mọ́kànlélọ́gọ́ta.
40 Przytem ludu szesnaście tysięcy, a działu z nich Panu trzydzieści i dwoje ludzi.
Àwọn ènìyàn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́jọ ìdá ti Olúwa sì jẹ́ méjìlélọ́gbọ̀n.
41 I oddał Mojżesz dział na ofiarę Panu, Eleazarowi kapłanowi, jako był rozkazał Pan Mojżeszowi.
Mose fi ìdá náà fún Eleasari, àlùfáà gẹ́gẹ́ bí ìdá ti Olúwa, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
42 A z drugiej połowy synów Izraelskich, którą wziął Mojżesz od mężów, którzy byli wyszli na wojnę.
Ààbọ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn ọmọ Israẹli, tí Mose yà sọ́tọ̀ kúrò lára àwọn ọkùnrin tí ó ja ogun.
43 (A połowa należąca zgromadzeniu, była: Owiec trzy kroć sto tysięcy, i trzydzieści tysięcy, siedem tysięcy i pięć set;
Ààbọ̀ tí ìjọ jẹ́ ẹgbàá méjìdínláàádọ́sàn-án ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ àgùntàn,
44 A wołów trzydzieści i sześć tysięcy;
pẹ̀lú ẹgbàá méjìdínlógún màlúù
45 A osłów trzydzieści tysięcy i pięć set;
tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
46 A ludu szesnaście tysięcy.)
Àwọn ènìyàn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́jọ.
47 Wziął Mojżesz z tej połowy należącej synom Izraelskim, jednę część z pięciudziesiąt, z ludzi, i z bydła, i dał to Lewitom trzymającym straż przybytku Pańskiego, jako był rozkazał Pan Mojżeszowi.
Lára ààbọ̀ ti àwọn ọmọ Israẹli, Mose yan ọ̀kan lára àádọ́ta ènìyàn àti ẹranko gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún un. Ó sì fi wọ́n fún àwọn ọmọ Lefi, tí ń ṣe olùtọ́jú àgọ́ Olúwa.
48 Tedy przyszli do Mojżesza hetmani wojska, pułkownicy, i rotmistrze.
Pẹ̀lú àwọn olórí tí ó wà lórí ẹgbẹẹgbẹ̀rin ogun náà, àti àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún wá sọ́dọ̀ Mose.
49 I mówili do niego: My słudzy twoi przynieśliśmyć poczet mężów wojennych, którzy byli pod sprawą naszą, a nie zginął z nas i jeden.
Wọ́n sì sọ fún un pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ti ka àwọn ọmọ-ogun náà tí ó wà lábẹ́ ìtọ́jú wa, kò sì sí ọ̀kọ̀ọ̀kan tó dín.
50 A tak przynieśliśmy tu na ofiarę Panu, każdy czego nabył, naczynie złote, zapony, i manele, pierścienie, i nausznice, i łańcuszki, dla oczyszczenia dusz naszych przed Panem.
Nítorí náà làwa ṣe mú ọrẹ ẹbọ wá fún Olúwa, gbogbo ọrẹ wíwà tí a ní, wúrà, ẹ̀wọ̀n, àti júfù, àti òrùka-àmi, àti òrùka etí, àti ìlẹ̀kẹ̀ láti fi ṣe ètùtù fún ọkàn an wa níwájú Olúwa.”
51 Odebrał tedy Mojżesz i Eleazar kapłan ono złoto od nich z wszelakiem naczyniem z niego urobionym.
Mose àti Eleasari àlùfáà, gba wúrà náà lọ́wọ́ wọn pẹ̀lú gbogbo ohun iṣẹ́ ọ̀ṣọ́.
52 A było onego wszystkiego złota ofiarowanego, które ofiarowali Panu, szesnaście tysięcy, siedem set i pięćdziesiąt syklów od pułkowników i od rotmistrzów.
Gbogbo wúrà tí àwọn balógun ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún mú wá fún Mose àti Eleasari, èyí tí ó jẹ́ ẹbọ ìgbésókè fún Olúwa jẹ́ ẹgbàá mẹ́jọ ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó lé àádọ́ta ṣékélì.
53 (Bo żołnierze, co łupem dostali, sobie otrzymali.)
Nítorí ológun kọ̀ọ̀kan ti kó ẹrù fún ara rẹ̀.
54 A wziąwszy Mojżesz i Eleazar kapłan ono złoto od pułkowników i rotmistrzów, wnieśli je do namiotu zgromadzenia, na pamiątkę synów Izraelskich przed Panem.
Mose àti Eleasari àlùfáà gba wúrà náà lọ́wọ́ àwọn balógun ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti lọ́wọ́ balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún wọ́n sì ko wá sínú àgọ́ ìpàdé fún ìrántí àwọn Israẹli níwájú Olúwa.

< Liczb 31 >