< Liczb 25 >
1 Potem gdy mieszkał Izrael w Syttim, począł lud cudzołożyć z córkami Moabskiemi,
Nígbà tí àwọn Israẹli dúró ní Ṣittimu, àwọn ènìyàn sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe àgbèrè pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin Moabu,
2 Które wzywały ludu ku ofiarom bogów swoich; a jedząc lud kłaniał się bogom ich.
tí ó pè wọ́n sí ibi ẹbọ òrìṣà wọn. Àwọn ènìyàn náà jẹun wọ́n sì foríbalẹ̀ níwájú òrìṣà wọn.
3 I przyłączył się Izrael do służby Baal Fegora; skąd się rozgniewał Pan bardzo na Izraela.
Báyìí ni Israẹli ṣe darapọ̀ mọ́ wọn tí wọ́n sì jọ ń sin Baali-Peori. Ìbínú Olúwa sì ru sí wọn.
4 Rzekł tedy Pan do Mojżesza: Zbierz wszystkie książęta z ludu, a każ im, te przestępce powieszać Panu przed słońcem, aby się odwrócił gniew popędliwości Pańskiej od Izraela.
Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú gbogbo àwọn olórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, pa wọ́n kí o sì fi wọ́n kọ́ sórí igi ní gbangba nínú oòrùn níwájú Olúwa, kí ìbínú Olúwa lè kúrò ní ọ̀dọ̀ Israẹli.”
5 Przetoż rzekł Mojżesz do sędziów Izraelskich: Zabijcie każdy z was męże swe, którzy się spospolitowali z Baal Fegorem.
Mose sọ fún àwọn onídàájọ́ Israẹli, “Ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbọdọ̀ pa arákùnrin rẹ̀ èyí tí ó darapọ̀ ní fífi orí balẹ̀ fún Baali-Peori.”
6 A oto, niektóry z synów Izraelskich przyszedł i przywiódł do braci swej Madyjanitkę przed oczyma Mojżeszowemi, i przed oczyma wszystkiego zgromadzenia synów Izraelskich; a oni płakali przed drzwiami namiotu zgromadzenia.
Nítòótọ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọkùnrin Israẹli sì mú obìnrin Midiani wá síwájú ojú Mose àti gbogbo ìjọ ti Israẹli wọ́n sì ń sọkún ní àbáwọlé àgọ́ ìpàdé.
7 Co gdy ujrzał Finees, syn Eleazara, syna Aarona kapłana, wstawszy z pośrodku zgromadzenia, wziął oszczep w ręce swoje.
Nígbà tí Finehasi, ọmọ Eleasari, ọmọ Aaroni, àlùfáà, rí èyí, ó fi ìjọ sílẹ̀, pẹ̀lú ọ̀kọ̀ ní ọwọ́ rẹ̀.
8 A wszedłszy za onym mężem Izraelskim do namiotu, przebił oboje, męża Izraelskiego, i niewiastę przez żywot jej, i odwrócona była plaga od synów Izraelskich.
Ó sì tẹ̀lé arákùnrin Israẹli yìí lọ sínú àgọ́. Ó sì fi ọ̀kọ̀ gún àwọn méjèèjì ní àgúnyọ láti ara ọkùnrin Israẹli àti sí ara obìnrin náà. Nígbà náà ni àjàkálẹ̀-ààrùn lórí àwọn ọmọ Israẹli sì dúró;
9 A było tych, co pomarli oną plagą, dwadzieścia i cztery tysiące.
ṣùgbọ́n gbogbo àwọn tí ó kú nínú àjàkálẹ̀-ààrùn náà jẹ́ ẹgbàá méjìlá.
10 Potem rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
Olúwa sì tún sọ fún Mose pé,
11 Finees syn Eleazara, syna Aarona kapłana odwrócił gniew mój od synów Izraelskich, będąc wzruszony zapalczywą miłością ku mnie w pośrodku ich, tak iżem nie wytracił synów Izraelskich w zapalczywości mojej.
“Finehasi ọmọ Eleasari ọmọ Aaroni, àlùfáà, ti yí ìbínú mi padà kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọmọ Israẹli, nítorí tí ó ní ìtara bí èmi náà ti ní ìtara fún iyì mi láàrín wọn, kí ó lè jẹ́ pé èmi ló pa wọ́n run nínú ìtara mi sí wọn.
12 Przetoż powiedz mu: Oto, Ja stanowię z nim przymierze moje, przymierze pokoju;
Nítorí náà sọ fún un pé èmi ṣe májẹ̀mú àlàáfíà mi pẹ̀lú rẹ̀.
13 I przyjdzie nań, i na nasienie jego po nim, przymierze kapłaństwa wiecznego, że się wzruszył zapalczywością za Boga swego, i oczyścił syny Izraelskie
Òun àti irú-ọmọ rẹ̀ yóò ní májẹ̀mú láéláé fún iṣẹ́ àlùfáà, nítorí pé ó ní ìtara fún Ọlọ́run rẹ̀ láti fi yẹ́ Ọlọ́run sí, ó sì ṣe ètùtù fún àwọn ọmọ Israẹli.”
14 A imię onego męża Izraelskiego zabitego, który zabity był z Madyjanitką, było Zamry, syn Salów, książę domu ojca swego, z pokolenia Symeonowego.
Orúkọ ọmọ Israẹli tí a pa pẹ̀lú obìnrin Midiani náà ni Simri, ọmọ Salu, olórí ilé kan nínú àwọn ọmọ Simeoni.
15 Imię też niewiasty zabitej Madyjanitki było Kozba, córka Sury, książęcia w narodzie swym, w domu ojczystym między Madyjanity.
Orúkọ ọmọbìnrin Midiani náà tí a pa ní Kosbi ọmọbìnrin Suri, tí ṣe olóyè àwọn ẹ̀yà kan nínú ìdílé kan ní Midiani.
16 I rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
Olúwa sì tún sọ fún Mose pé,
17 Staw się nieprzyjacielem Madyjanitom, a pobijcie je,
“Ka àwọn ará Midiani sí ọ̀tá, kí o sì pa wọ́n,
18 Ponieważ i oni stawili się wam nieprzyjaciołmi zdradami swemi, a podeszli was przez Baal Fegora, i przez Kozbę, córkę książęcia Madyjańskiego, siostrę swą, która zabita jest w dzień kaźni dla bałwana Fegor.
nítorí pé wọ́n ṣe sí yín gẹ́gẹ́ bí ọ̀tá nígbà tí wọ́n tàn yín nípa ìṣẹ̀lẹ̀ Peori, àti arábìnrin wọn Kosbi ọmọbìnrin ìjòyè Midiani kan, obìnrin tí a pa nígbà tí àjàkálẹ̀-ààrùn ṣẹlẹ̀ nítorí Peori.”