< Liczb 2 >

1 Zatem rzekł Pan do Mojżesza i do Aarona, mówiąc:
Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
2 Każdy z synów Izraelskich kłaść się będą obozem pod chorągwią swoją według znaków domów ojców swych; naprzeciwko około namiotu zgromadzenia kłaść się będą.
“Kí àwọn ọmọ Israẹli pa àgọ́ wọn yí àgọ́ ìpàdé ká, kí wọ́n jẹ́ kí àgọ́ wọn jìnnà sí i díẹ̀, oníkálùkù lábẹ́ ọ̀págun pẹ̀lú àsíá ìdílé wọn.”
3 A ci się obozem położą na wschód słońca: Chorągiew wojska Judowego według hufców swych, a hetmanem nad syny Judowymi Naason, syn Aminadabów;
Ní ìlà-oòrùn, ní ìdojúkọ àtiyọ oòrùn: ni kí ìpín ti Juda pa ibùdó wọn sí lábẹ́ ọ̀págun wọn. Olórí Juda ni Nahiṣoni ọmọ Amminadabu.
4 A w wojsku jego policzonych siedemdziesiąt i cztery tysiące i sześć set.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlógójì ó lé ẹgbẹ̀ta.
5 Podle niego położy się obozem pokolenie Isascharowe, a hetmanem nad syny Isascharowymi Natanael, syn Suharów;
Ẹ̀yà Isakari ni yóò pa ibùdó tẹ̀lé wọn. Olórí Isakari ni Netaneli ọmọ Suari.
6 A w wojsku jego policzonych pięćdziesiąt i cztery tysiące i cztery sta.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlọ́gbọ̀n ó lé irinwó.
7 Podle nich pokolenie Zabulonowe, a hetmanem nad syny Zabulonowymi Elijab, syn Helonów.
Ẹ̀yà Sebuluni ni yóò tẹ̀lé e. Olórí Sebuluni ni Eliabu ọmọ Heloni.
8 A w wojsku jego policzonych pięćdziesiąt i siedem tysięcy i cztery sta.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá méjìdínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
9 Wszystkich policzonych w obozie Judowym sto tysięcy, osiemdziesiąt tysięcy, i sześć tysięcy i cztery sta według hufców ich; ci naprzód pociągną.
Gbogbo àwọn tí a yàn sí ibùdó Juda, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàléláàdọ́rùn-ún ó lé irinwó. Àwọn ni yóò kọ́kọ́ ṣáájú.
10 Chorągiew obozu Rubenowego położy się na południe według hufców swych, a hetmanem nad syny Rubenowymi Elisur, syn Sedeurów;
Ní ìhà gúúsù: ni ìpín ti Reubeni pa ibùdó sí lábẹ́ ọ̀págun wọn. Olórí Reubeni ni Elisuri ọmọ Ṣedeuri.
11 A w wojsku jego policzonych czterdzieści i sześć tysięcy i pięć set.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàlélógún ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
12 Podle niego położy się obozem pokolenie Symeonowe, a hetmanem nad syny Symeonowymi Selumijel, syn Surysaddajów;
Ẹ̀yà Simeoni ni yóò pa ibùdó tẹ̀lé wọn. Olórí Simoni ni Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai.
13 A w wojsku jego policzonych pięćdziesiąt i dziewięć tysięcy i trzy sta.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mọ́kàndínlọ́gbọ̀n ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbéje.
14 Potem pokolenie Gadowe, a hetmanem nad syny Gadowymi Elijazaf, syn Rehuelów;
Ẹ̀yà Gadi ló tẹ̀lé wọn. Olórí Gadi ni Eliasafu ọmọ Deueli.
15 A w wojsku jego policzonych czterdzieści i pięć tysięcy, i sześć set i pięćdziesiąt.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé àádọ́talélẹ́gbẹ̀jọ.
16 Wszystkich policzonych w obozie Rubenowym sto tysięcy, pięćdziesiąt tysięcy i jeden, cztery sta i pięćdziesiąt według hufców ich; a ci w rzędzie wtórym pociągną.
Gbogbo ènìyàn tí a yàn sí ibùdó Reubeni, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbàá márùndínlọ́gọ́rin ó lé àádọ́talélégbèje. Àwọn ni yóò jáde sìkéjì.
17 Potem pójdzie namiot zgromadzenia z wojskiem Lewitów, w pośrodku wojska; jakim porządkiem stawać będą obozem, takim pociągną każdy w szyku swym pod chorągwią swoją.
Nígbà náà ni àwọn ọmọ Lefi àti àgọ́ ìpàdé yóò tẹ̀síwájú láàrín ibùdó àwọn ènìyàn, wọn yóò tẹ̀síwájú ní ṣísẹ̀-n-tẹ̀lé gẹ́gẹ́ bí wọn ṣe pa ibùdó, olúkúlùkù láààyè rẹ̀, àti lábẹ́ ọ̀págun rẹ̀.
18 Chorągiew obozu Efraimowego według hufców swych ku zachodowi, a hetmanem nad syny Efraimowymi Elisama, syn Ammiudów;
Ní ìhà ìlà-oòrùn: ni ìpín Efraimu yóò pa ibùdó rẹ̀ sí lábẹ́ ọ̀págun rẹ̀. Olórí Efraimu ni Eliṣama ọmọ Ammihudu.
19 A w wojsku jego policzonych czterdzieści tysięcy i pięć set.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì lé ó lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
20 A podle niego pokolenie Manasesowe, a hetmanem nad syny Manasesowymi Gamalijel, syn Pedasurów.
Ẹ̀yà Manase ni yóò tẹ̀lé wọn. Olórí Manase ni Gamalieli ọmọ Pedasuri.
21 A w wojsku jego policzonych trzydzieści i dwa tysiące i dwieście.
Iye ìpín rẹ̀ ni ẹgbàá mẹ́rìndínlógún ó lé igba.
22 Podle nich pokolenie Benjaminowe, a hetmanem nad syny Benjaminowymi Abidan, syn Giedeonów;
Ẹ̀yà Benjamini ni yóò tẹ̀lé e. Olórí Benjamini ni Abidani ọmọ Gideoni.
23 A w wojsku jego policzonych trzydzieści i pięć tysięcy i cztery sta.
Iye ìpín rẹ̀ ni ẹgbàá mẹ́tàdínlógún ó lé egbèje.
24 Wszystkich policzonych w obozie Efraimowym sto tysięcy i osiem tysięcy i sto według hufców swoich; a ci w trzecim rzędzie pociągną.
Gbogbo ènìyàn tí a yàn sí ibùdó Efraimu, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn, àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìnléláàádọ́ta ó lé ọgọ́rùn-ún. Àwọn ni yóò jáde sìkẹ́ta.
25 Chorągiew obozu Danowego położy się ku północy według hufców swych, a hetmanem nad syny Danowymi Achiezer, syn Ammisadajów;
Ní ìhà àríwá: ni ìpín Dani yóò pa ibùdó sí lábẹ́ ọ̀págun wọn. Olórí Dani ni Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai.
26 A w wojsku jego policzonych sześćdziesiąt i dwa tysiące i siedem set.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélọ́gbọ̀n ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin.
27 A podle niego położy się obozem pokolenie Aserowe a hetmanem nad syny Aserowymi Pagijel, syn Ochranów;
Ẹ̀yà Aṣeri ni yóò pa ibùdó tẹ̀lé wọn. Olórí Aṣeri ni Pagieli ọmọ Okanri.
28 A w wojsku jego policzonych czterdzieści tysięcy i jeden i pięć set.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ.
29 Potem pokolenie Neftalimowe, a hetmanem nad syny Neftalimowymi Ahira, syn Enanów;
Ẹ̀yà Naftali ni yóò kàn lẹ́yìn wọn. Olórí Naftali ni Ahira ọmọ Enani.
30 A w jego wojsku policzonych pięćdziesiąt i trzy tysiące i cztery sta.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlógún ó lé egbèje.
31 A tak wszystkich policzonych obozu Danowego sto tysięcy, pięćdziesiąt i siedem tysięcy i sześć set; a ci na ostatku pociągną pod chorągwią swoją.
Gbogbo ènìyàn tí a yàn sí ibùdó Dani jẹ́ ẹgbàá méjìdínlọ́gọ̀rin ó lé ẹgbẹ̀jọ. Àwọn ni yóò jáde kẹ́yìn lábẹ́ ọ̀págun wọn.
32 Cić są policzeni synów Izraelskich według domów ojców ich, wszystkich policzonych w obozie według hufców ich sześć kroć sto tysięcy, i trzy tysiące i pięć set i pięćdziesiąt.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Israẹli tí wọ́n kà nípa ìdílé wọn. Gbogbo àwọn tó wà ní ibùdó, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn, wọ́n jẹ́ ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ó lé egbèjìdínlógún dín làádọ́ta.
33 Ale Lewitów nie liczono między syny Izraelskie, jako był Pan rozkazał Mojżeszowi.
Ṣùgbọ́n a kò ka àwọn ọmọ Lefi papọ̀ mọ́ àwọn Israẹli gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
34 I uczynili synowie Izraelscy według wszystkiego; jako rozkazał Pan Mojżeszowi, tak się stanowili obozem przy chorągwiach swych, i ciągnęli każdy według familii swych, i według domów ojców swych.
Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gbogbo ohun tí Olúwa pàṣẹ fún Mose, báyìí ni wọ́n ṣe pa ibùdó lábẹ́ ọ̀págun wọn, bẹ́ẹ̀ náà sì ni wọ́n ṣe jáde, oníkálùkù pẹ̀lú ẹbí àti ìdílé rẹ̀.

< Liczb 2 >