< Liczb 14 >
1 Tedy wzruszywszy się wszystko mnóstwo krzyczeli i płakał lud przez onę noc.
Gbogbo ìjọ ènìyàn sì gbóhùn sókè, wọ́n sì sọkún ní òru ọjọ́ náà.
2 I szemrali przeciwko Mojżeszowi, i przeciwko Aaronowi wszyscy synowie Izraelscy; i mówiło do nich wszystko mnóstwo: Obyśmy byli pomarli w ziemi Egipskiej, albo na tej puszczy!
Gbogbo ọmọ Israẹli sì kùn sí Mose àti Aaroni, gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì wí fún wọn pé, “Àwa ìbá kúkú ti kú ní ilẹ̀ Ejibiti. Tàbí kí a kúkú kú sínú aginjù yìí.
3 Obyśmy byli pomarli! Czemuż wżdy Pan prowadzi nas do tej ziemi, abyśmy padli od miecza? żony nasze, i dziatki nasze aby były na łup? Izali nam nie lepiej wrócić się do Egiptu?
Kí ló dé tí Olúwa fi mú wa wá sí ilẹ̀ yìí láti fi idà pa wá? Àwọn ìyàwó wa, àwọn ọmọ wa yóò sì di ìjẹ. Ǹjẹ́ kò wa, ní í dára fún wa bí a bá padà sí Ejibiti?”
4 I mówili między sobą: Postanówmy sobie wodza, a wróćmy się do Egiptu.
Wọ́n sì sọ fún ara wọn pé, “Ẹ jẹ́ kí á yan olórí kí á sì padà sí Ejibiti.”
5 Tedy upadł Mojżesz i Aaron na oblicze swoje przed wszystkiem zgromadzeniem synów Izraelskich.
Nígbà náà ni Mose àti Aaroni dojúbolẹ̀ níwájú gbogbo ìjọ ọmọ Israẹli.
6 A Jozue, syn Nunów, i Kaleb, syn Jefunów, którzy szpiegowali ziemię, rozdarli szaty swoje;
Joṣua ọmọ Nuni àti Kalebu ọmọ Jefunne, tí wọ́n wà lára àwọn to lọ yẹ ilẹ̀ wò sì fa aṣọ wọn ya.
7 I rzekli do wszystkiego zgromadzenia synów Izraelskich, mówiąc: Ziemia, którąśmy przeszli, i przeszpiegowali ją, ziemia jest bardzo dobra.
Wọ́n sì sọ fún gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli pé, “Ilẹ̀ tí a là kọjá láti yẹ̀ wò náà jẹ́ ilẹ̀ tí ó dára lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
8 Będzieli nam Pan miłościw, tedy nas wprowadzi do tej ziemi, a da ją nam, ziemię tę, która opływa mlekiem i miodem.
Bí inú Olúwa bá dùn sí wa, yóò mú wa dé ilẹ̀ náà, ilẹ̀ tó ń sàn fún wàrà àti fún oyin, yóò fún wa ní ilẹ̀ náà.
9 Jedno Panu nie bądźcie odpornymi, ani się wy bójcie ludu onej ziemi, bo jako chleb pojeść je możemy; odstąpiła obrona ich od nich, ale Pan jest z nami; nie bójcież się ich.
Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa. Kí ẹ sì má bẹ̀rù àwọn ènìyàn ìlú náà, nítorí pé a ó gbé wọn mì, ààbò wọn ti fi wọ́n sílẹ̀, Olúwa sì wà pẹ̀lú àwa, ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn.”
10 I mówiło wszystko zgromadzenie, aby je ukamionowano; ale chwała Pańska okazała się nad namiotem zgromadzenia wszystkim synom Izraelskim.
Ṣùgbọ́n gbogbo ìjọ ènìyàn sì ń sọ pé àwọn yóò sọ wọ́n lókùúta pa. Nígbà náà ni ògo Olúwa fi ara hàn ní àgọ́ ìpàdé níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
11 I rzekł Pan do Mojżesza: Dokądże mię draźnić będzie ten lud? I dokądże mi wierzyć nie będą dla tych wszystkich znaków, którem czynił między nimi?
Olúwa sọ fún Mose pé, “Fún ìgbà wo ni àwọn ènìyàn yìí yóò ti kẹ́gàn mi tó? Báwo ni yóò ti pẹ́ tó tí wọ́n ó fi kọ̀ jálẹ̀ láti gbà mí gbọ́, pẹ̀lú gbogbo iṣẹ́ àmì tí mo ṣe láàrín wọn?
12 Porażę je morem, i rozproszę je; a ciebie uczynię w naród wielki i możniejszy, niż ten jest.
Èmi ó kọlù wọ́n pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn, èmi ó gba ogún wọn lọ́wọ́ wọn, èmi ó sì pa wọ́n run ṣùgbọ́n èmi ó sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá tó sì lágbára jù wọ́n lọ.”
13 Ale rzekł Mojżesz do Pana: Oto, usłyszą Egipczanie, z których pośrodku wywiodłeś mocą swoją ten lud;
Ṣùgbọ́n Mose sọ fún Olúwa pé, “Nígbà náà ni àwọn ará Ejibiti yóò gbọ́! Nítorí pé nípa agbára rẹ ni ìwọ fi mú àwọn ènìyàn wọ̀nyí jáde kúrò láàrín wọn.
14 I mówić będą z obywatelami ziemi tej, bo słyszeli, żeś ty Panie był w pośrodku ludu tego; żeś okiem w oko widziany był, o Panie, a obłok twój stawał nad nimi, a iż w słupie obłokowym chodziłeś przed nimi we dnie, a w słupie ognistym w nocy.
Wọ́n ó sì sọ fún àwọn olùgbé ilẹ̀ yìí. Àwọn tó ti mọ̀ tẹ́lẹ̀ pé ìwọ Olúwa wà láàrín àwọn ènìyàn wọ̀nyí àti pé wọ́n rí ìwọ, Olúwa, ní ojúkojú, àti pé ìkùùkuu àwọsánmọ̀ rẹ dúró lórí wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ sì ń lọ níwájú wọn pẹ̀lú ìkùùkuu àwọsánmọ̀ ní ọ̀sán àti pẹ̀lú ọ̀wọ́n iná ní òru.
15 Gdybyś tedy pobił lud ten wszystek aż do jednego, rzekliby poganie, którzy o twej sławie słychali, mówiąc:
Bí ìwọ bá pa àwọn ènìyàn wọ̀nyí lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo, àwọn orílẹ̀-èdè tó bá gbọ́ ìròyìn yìí nípa rẹ yóò wí pé,
16 Iż nie mógł wprowadzić Pan ludu tego do ziemi, o którą im przysiągł: przeto je pobił na puszczy.
‘Nítorí pé Olúwa kò le è mú àwọn ènìyàn wọ̀nyí dé ilẹ̀ tí ó ṣèlérí fún wọn; torí èyí ló ṣe pa wọ́n sínú aginjù yìí.’
17 A tak teraz niech proszę uwielbiona będzie moc Pańska, jakoś rzekł, mówiąc:
“Báyìí, mo gbàdúrà, jẹ́ kí agbára Olúwa tóbi gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti sọ pé,
18 Pan nie rychły ku gniewowi a wielki w miłosierdziu, znosząc nieprawość i przestępstwo, który winnego nie czyni niewinnym, karząc nieprawość ojców w synach do trzeciego i do czwartego pokolenia;
‘Olúwa lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní ìfẹ́ tó dúró ṣinṣin, tí ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ àti ìrékọjá jì. Bẹ́ẹ̀ ni kì í jẹ́ kí ẹlẹ́bi lọ láìjìyà; tó ń fi ìyà ẹ̀ṣẹ̀ baba jẹ ọmọ títí dé ìran kẹta àti ìran kẹrin.’
19 Odpuść proszę nieprawość ludu tego według wielkości miłosierdzia twego, tak jakoś odpuszczał ludowi temu z Egiptu aż dotąd.
Dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn yìí jì wọ́n, mo bẹ̀ ọ́, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ńlá rẹ, bí o ti ṣe ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n láti ìgbà tí o ti kó wọn kúrò ní Ejibiti di ìsin yìí.”
20 Tedy rzekł Pan: Odpuściłem według słowa twego.
Olúwa sì dáhùn pé, “Mo ti dáríjì wọ́n gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
21 A wszakże, jako Ja żyję, i napełniona jest chwałą Pańską wszystka ziemia:
Ṣùgbọ́n nítòótọ́ bí mo ti wà láààyè, gbogbo ayé yóò kún fún ògo Olúwa.
22 Tak wszyscy, którzy widzieli chwałę moję, i znaki moje, którem czynił w Egipcie, i na puszczy, a kusili mię już po dziesięć kroć, ani byli posłuszni głosowi memu,
Kò sí ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn tó rí ògo mi àti àwọn iṣẹ́ àmì tí mo ṣe ní ilẹ̀ Ejibiti àti nínú aginjù ṣùgbọ́n tí wọ́n ṣe àìgbọ́ràn sí mi, tí wọn sì dán mi wò ní ìgbà mẹ́wàá yìí,
23 Nie oglądają ziemi tej, o którąm przysiągł ojcom ich, a żaden z tych, którzy mię draźnili, nie oglądają jej.
ọ̀kan nínú wọn kò ní rí ilẹ̀ náà tí mo ṣe ìlérí ní ìbúra láti fún baba ńlá wọn. Kò sí ọ̀kan nínú àwọn tó kẹ́gàn mi tí yóò rí ilẹ̀ náà.
24 Ale sługę mego Kaleba, gdyż był w nim duch inakszy, i trwał statecznie przy mnie, wprowadzę do ziemi, do której chodził, a nasienie jego odziedziczy ją.
Ṣùgbọ́n nítorí pé Kalebu ìránṣẹ́ mi ní ẹ̀mí ọ̀tọ̀, tí ó sì tún tẹ̀lé mi tọkàntọkàn, èmi ó mu dé ilẹ̀ náà tó lọ yẹ̀ wò, irú àwọn ọmọ rẹ̀ yóò sì jogún rẹ̀.
25 Ale ponieważ Amalekita i Chananejczyk mieszkają w dolinie, przetoż jutro obróćcie się, a idźcie na puszczą, drogą ku morzu czerwonemu.
Níwọ́n ìgbà tí àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani ń gbé ní àfonífojì, ẹ yípadà lọ́la kí ẹ sì dojúkọ aginjù lọ́nà Òkun Pupa.”
26 Nad to rzekł Pan do Mojżesza i do Aarona, mówiąc:
Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
27 I dokądże znosić mam ten zły lud, który szemrze przeciwko mnie? długoż szemrania synów Izraelskich, którzy szemrzą przeciwko mnie, słuchać będę?
“Báwo ni yóò ti pẹ́ tó tí àwọn ìjọ ènìyàn búburú yìí yóò fi máa kùn sí mi? Mo ti gbọ́ kíkùn tí àwọn ọmọ Israẹli ń kùn sí mi.
28 Mów do nich: Żyję Ja, mówi Pan, że jakoście mówili w uszy moje, tak uczynię wam.
Sọ fún wọn, bí mo ti wà láààyè nítòótọ́ ni Olúwa wí, gẹ́gẹ́ bí ohun tí ẹ wí létí mi ni èmi ó ṣe fún un yín.
29 Na tej puszczy polegą ciała wasze, i wszyscy policzeni wasi według wszystkiej liczby waszej od dwudziestego roku i wyżej, którzyście szemrali przeciwko mnie.
Nínú aginjù yìí ni ẹ ó kú sí, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ kùn láti ọmọ ogún ọdún ó lé àní gbogbo ẹ̀yin tí a kà.
30 A wy nie wnijdziecie do ziemi tej, o którąm podniósł rękę moję, abym ją wam dał na mieszkanie, okrom Kaleba, syna Jefunowego, i Jozuego, syna Nunowego;
Ọ̀kan nínú yín kò ní í dé ilẹ̀ tí mo búra nípa ìgbọ́wọ́sókè láti fi ṣe ibùgbé yín, bí kò ṣe Kalebu ọmọ Jefunne àti Joṣua ọmọ Nuni.
31 A dziatki wasze, o którycheście mówili, że będą na łup, te wprowadzę, i oglądają tę ziemię, którąście wy wzgardzili.
Ṣùgbọ́n ní ti àwọn ọmọ yín tí ẹ wí pé wọn ó di ìjẹ, àwọn ni n ó mú dé bẹ̀ láti gbádùn ilẹ̀ tí ẹ kọ̀sílẹ̀.
32 Ale trupy wasze, wasze trupy mówię, polegą na tej puszczy;
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin, òkú yín yóò ṣubú ní aginjù yìí.
33 A synowie wasi będą się tułali po tej puszczy przez czterdzieści lat, i poniosą karanie za cudzołóstwa wasze, aż wyginą trupy wasze na puszczy.
Àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ yín yóò sì máa rin kiri nínú aginjù fun ogójì ọdún wọn ó máa jìyà nítorí àìnígbàgbọ́ yín, títí tí ọkàn gbogbo yín yóò fi ṣòfò tán ní aginjù.
34 Według liczby dni, w którycheście szpiegowali ziemię, to jest czterdzieści dni, dzień każdy za rok licząc, poniesiecie nieprawości wasze czterdzieści lat, i poznacie pomstę swego odstąpienia ode mnie.
Fún ogójì ọdún èyí jẹ́ ọdún kan fún ọjọ́ kọ̀ọ̀kan nínú ogójì ọjọ́ tí ẹ fi yẹ ilẹ̀ náà wò ẹ̀yin ó sì jìyà fún ẹ̀ṣẹ̀ yín, ẹ ó sì mọ bí ó ti rí láti lòdì sí mi.
35 Ja Pan mówiłem, że to uczynię temu wszystkiemu zgromadzeniu złemu, które się spiknęło przeciwko mnie; na tej puszczy poginą, i tu pomrą.
Èmi, Olúwa, lo sọ bẹ́ẹ̀; Èmi ó sì ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí sí ìjọ ènìyàn búburú yìí tí wọ́n kó ra wọn jọ lòdì sí mi. Nínú aginjù yìí ni òpin yóò dé bá wọn, ibẹ̀ ni wọn yóò kú sí.”
36 Oni tedy mężowie, których słał Mojżesz na przeszpiegowanie ziemi, którzy wróciwszy się pobudzili do szemrania przeciwko niemu wszystek lud, puszczając złą sławę o ziemi onej;
Àwọn ọkùnrin tí Mose rán láti yẹ ilẹ̀ wò, tí wọ́n sì mú gbogbo ìjọ kùn sí i nípa ìròyìn búburú tí wọ́n mú wá nípa ilẹ̀ náà;
37 Pomarli mężowie oni, którzy puszczali sławę złą o ziemi, srogą plaga przed Panem.
Olúwa sì kọlu àwọn ọkùnrin tó mú ìròyìn búburú wá nípa ilẹ̀ náà, àjàkálẹ̀-ààrùn sì pa wọ́n níwájú Olúwa.
38 Ale Jozue, syn Nunów, i Kaleb, syn Jefunów, zostali żywi z mężów onych, którzy chodzili ku przeszpiegowaniu ziemi.
Nínú gbogbo àwọn tó lọ yẹ ilẹ̀ náà wò, Joṣua ọmọ Nuni àti Kalebu ọmọ Jefunne ló yè é.
39 I opowiedział Mojżesz te słowa wszystkim synom Izraelskim, i płakał lud bardzo.
Nígbà tí Mose sọ gbogbo ọ̀rọ̀ yìí fún àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì sọkún gidigidi.
40 Tedy rano wstawszy wstąpili na wierzch góry, mówiąc: Oto my pójdziemy na to miejsce, o którem nam Pan powiedział; bośmy zgrzeszyli.
Wọ́n dìde ní àárọ̀ ọjọ́ kejì wọ́n sì gòkè lọ sí ìlú orí òkè, wọ́n wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀, àwa yóò lọ sí ibi tí Olúwa ṣèlérí fún wa.”
41 Ale im powiedział Mojżesz: Przeczże wy przestępujecie słowo Pańskie? to się wam nie nada.
Mose sì dá wọn lóhùn pé, “Kí ló dé tí ẹ fi ṣẹ̀ sí òfin Olúwa? Èyí kò le yọrí sí rere!
42 Nie chodźcie; bo nie masz Pana między wami, abyście nie byli pobici od nieprzyjaciół waszych.
Ẹ má ṣe gòkè lọ nítorí pé Olúwa kò sí láàrín yín. Ki á má ba à lù yín bolẹ̀ níwájú àwọn ọ̀tá yín.
43 Bo Amalekita i Chananejczyk tuż przed wami są, i polężecie od miecza; bo dla tego, żeście się odwrócili od Pana, nie będzie Pan z wami.
Nítorí pé àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani ń bẹ níwájú yín, ẹ̀yin yóò sì ti ipa idà ṣubú. Nítorí pé, ẹ ti yà kúrò ní ọ̀nà Olúwa, Olúwa kò sì ní í wà pẹ̀lú yín.”
44 A oni przecię kusili się wnijść na wierzch góry; lecz skrzynia przymierza Pańskiego i Mojżesz nie odchodzili od obozu.
Síbẹ̀síbẹ̀, pẹ̀lú àìfarabalẹ̀ wọn, wọ́n gòkè lọ sórí òkè náà, láìjẹ́ pé àpótí ẹ̀rí Olúwa tàbí Mose kúrò nínú ibùdó.
45 Tedy zstąpił Amalekita i Chananejczyk, mieszkający na onej górze, a porazili je, i gonili je aż do Hormy.
Àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani tó ń gbé lórí òkè sọ̀kalẹ̀ tọ̀ wọ́n, wọ́n bá wọn jà, wọ́n sì lé wọn títí dé Horma.