< Liczb 12 >
1 Tedy mówiła Maryja i Aaron przeciw Mojżeszowi dla żony Murzyńskiej, którą pojął; bo żonę murzynkę był pojął;
Miriamu àti Aaroni sọ̀rọ̀-òdì sí Mose nítorí pé ó fẹ́ obìnrin ará Etiopia.
2 I mówili: Izali tylko przez Mojżesza mówił Pan? azaż też nie mówił przez nas? a to usłyszał Pan.
Wọ́n sì wí pé, “Nípa Mose nìkan ni Olúwa ti sọ̀rọ̀ bí, kò ha ti ipa wa sọ̀rọ̀ bí?” Olúwa sì gbọ́ èyí.
3 A Mojżesz był mąż najpokorniejszy ze wszystkich ludzi, którzy mieszkali na ziemi.
(Mose sì jẹ́ ọlọ́kàn tútù ju gbogbo ènìyàn tó wà lórí ilẹ̀ ayé lọ).
4 A natychmiast rzekł Pan do Mojżesza, i do Aarona, i do Maryi: Wynijdźcie was troje przed namiot zgromadzenia; i wyszli samo troje.
Lẹ́ẹ̀kan náà ni Olúwa sọ fún Mose, Aaroni àti Miriamu pé, “Ẹ̀yin mẹ́tẹ̀ẹ̀ta, jáde wá sínú àgọ́ ìpàdé.” Àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta sì jáde síta.
5 Zatem zstąpił Pan w słupie obłokowym, i stanął we drzwiach namiotu, i zawołał Aarona i Maryi, i przyszli oboje.
Nígbà náà ni Olúwa sọ̀kalẹ̀ nínú ọ̀wọ́n ìkùùkuu, ó sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́, ó ké sí Aaroni àti Miriamu. Àwọn méjèèjì sì bọ́ síwájú,
6 I rzekł do nich: Słuchajcie teraz słów moich: Jeźli między wami będzie prorok, Ja Pan w widzeniu ukażę mu się we śnie będę mówił z nim;
Ó wí pé, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, “Bí wòlíì Olúwa bá wà láàrín yín, Èmi Olúwa a máa fi ara à mi hàn án ní ojúran, Èmi a máa bá a sọ̀rọ̀ nínú àlá.
7 Ale nie taki jest sługa mój Mojżesz, który we wszystkim domu moim najwierniejszy jest.
Ṣùgbọ́n èyí kò rí bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú Mose ìránṣẹ́ mi; ó jẹ́ olóòtítọ́ nínú gbogbo ilé mi.
8 Usty do ust mawiam z nim: nie w widzeniu, ani w zagadaniu, ani w podobieństwach Pana widywa; czemużeście się nie bali, mówić przeciw słudze memu Mojżeszowi?
Mo sì ń bá a sọ̀rọ̀ ní ojúkojú, ọ̀rọ̀ yékéyéké tí kì í ṣe òwe, ó rí àwòrán Olúwa. Kí ló wá dé tí ẹ̀yin kò ṣe bẹ̀rù láti sọ̀rọ̀-òdì sí Mose ìránṣẹ́ mi?”
9 A tak zapalił się gniewem przeciwko nim Pan, i odszedł.
Ìbínú Olúwa sì ru sókè sí wọn Olúwa sì fi wọ́n sílẹ̀.
10 Obłok także odstąpił od namiotu, a oto, Maryja otrędowaciała, zbielawszy jako śnieg; a wejrzawszy Aaron na Maryję, ujrzał trędowatą.
Nígbà tí ìkùùkuu kúrò lórí àgọ́ lójijì ni Miriamu di adẹ́tẹ̀, ó funfun bí i yìnyín. Aaroni sì padà wo Miriamu ó sì rí i pé ó ti di adẹ́tẹ̀,
11 Potem rzekł Aaron do Mojżesza: Proszę panie mój, nie kładź teraz na nas grzechu tego, żeśmy głupio uczynili, a żeśmy zgrzeszyli.
Aaroni sì wí fún Mose pé, “Jọ̀wọ́ olúwa mi, má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀, èyí tí a fi ìwà òmùgọ̀ dá sí wa lọ́rùn.
12 Niech proszę nie będzie jako martwy płód, który gdy wychodzi z żywota matki swej, połowa ciała jego zepsowana bywa.
Má ṣe jẹ́ kí ó dàbí òkú ọmọ tí a bí, tí ìdajì ara rẹ̀ ti rà dànù.”
13 Tedy zawołał Mojżesz do Pana mówiąc: Boże, proszę uzdrów ją teraz.
Torí èyí Mose sì kígbe sí Olúwa, “Ọlọ́run, jọ̀wọ́, mú un láradá!”
14 I odpowiedział Pan Mojżeszowi: Gdyby ojciec jej plunął na twarz jej, azażby nie miała się wstydać przez siedem dni? niech będzie wyłączona przez siedem dni z obozu, a potem przyjęta będzie.
Olúwa sì dá Mose lóhùn, “Bí baba rẹ̀ bá tutọ́ sí i lójú, ojú kò wa ní í tì í fún ọjọ́ méje? Dá a dúró sí ẹ̀yìn ibùdó fún ọjọ́ méje, lẹ́yìn èyí ki a tó ó le mú wọlé.”
15 I wyłączona była Maryja z obozu przez siedem dni; a lud się nie ruszył, aż była Maryja przyjęta.
Miriamu sì dúró sí ẹ̀yìn ibùdó fún ọjọ́ méje, àwọn ènìyàn kò sì tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò wọn títí tí Miriamu fi wọ inú ibùdó padà.
16 Potem ruszył się lud z Haserotu, a położyli się obozem na puszczy Faran.
Lẹ́yìn èyí, àwọn ènìyàn kúrò ní Haserotu, wọ́n sì pa ibùdó sí aginjù Parani.