< Liczb 11 >

1 I stało się, że się lud uskarżał niesłusznie, co się nie podobało Panu. Przetoż usłyszawszy to Pan bardzo się rozgniewał, i zapalił się przeciwko nim ogień Pański, i popalił ostatnią część obozu.
Àwọn ènìyàn ń ṣe àròyé nípa wàhálà wọn sí etí ìgbọ́ Olúwa. Ìbínú Olúwa sì ru sókè nígbà tí ó gbọ́ àròyé yìí. Nígbà náà ni iná jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa bọ́ sí àárín wọn, ó sì run àwọn tó wà ní òpin ibùdó.
2 Tedy wołał lud na Mojżesza; i modlił się Mojżesz Panu, i zgasł ogień.
Nígbà náà ni àwọn ènìyàn kígbe sí Mose, Mose sì gbàdúrà sí Olúwa iná náà sì kú.
3 I nazwał imię miejsca onego Tabera: bo się zapalił przeciwko nim ogień Pański.
Wọ́n sì ń pe ibẹ̀ ní Tabera nítorí pé, iná láti ọ̀dọ̀ Olúwa jó láàrín wọn.
4 A lud pospolity, który był między nimi, chciwością wielką zjęty odwracał się; i płakali też synowie Izraelscy, mówiąc: Któż nas nakarmi mięsem?
Àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn aláìníláárí tó wà láàrín àwọn ọmọ Israẹli pẹ̀lú ọkàn ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wọn fi ìtara béèrè fún oúnjẹ mìíràn, àwọn ọmọ Israẹli náà bá bẹ̀rẹ̀ sí í sọkún wí pé, “Bí i pé kí á rí ẹran jẹ báyìí!
5 Wspominamy sobie na ryby, któreśmy jadali w Egipcie darmo, na ogórki, i na melony, i na łuczek, i na cebulę, i na czosnek.
Àwa rántí ẹja tí à ń jẹ lọ́fẹ̀ẹ́ ní Ejibiti, apálà, bàrà, ewébẹ̀, àlùbọ́sà àti àwọn ẹ̀fọ́ mìíràn.
6 A teraz dusza nasza wywiędła nic inszego nie mając, oprócz tej manny, przed oczyma swemi.
Ṣùgbọ́n báyìí gbogbo ara wa ti gbẹ, kò sí ohun mìíràn láti jẹ àfi manna nìkan tí a rí yìí!”
7 A manna była jako nasienie koryjandrowe, a barwa tej jako barwa Bdelijowa.
Manna náà dàbí èso korianderi, ìrísí rẹ̀ sì dàbí oje igi.
8 I wychodził lud, a zbierali ją, i mełli w żarnach, albo tłukli w moździerzach a warzyli w kotłach i czynili z niej podpłomyki; a był smak jej jako smak świeżej oliwy.
Àwọn ènìyàn náà ń lọ káàkiri láti kó o, wọn ó lọ̀ ọ́ lórí ọlọ tàbí kí wọ́n gún un nínú odó. Wọ́n le sè é nínú ìkòkò tàbí kí wọn ó fi ṣe àkàrà, adùn rẹ̀ yóò sì dàbí adùn ohun tí a fi òróró ṣe.
9 Gdy bowiem padała rosa na obóz w nocy, padała też manna nań.
Nígbà tí ìrì bá ẹ̀ sí ibùdó lórí ni manna náà máa ń bọ́ pẹ̀lú rẹ̀.
10 Tedy usłyszał Mojżesz, że lud płakał po domach swych, każdy u drzwi namiotu swego; dla czego zapaliła się popędliwość Pańska wielce, i nie podobało się też to Mojżeszowi.
Mose sì gbọ́ tí àwọn ènìyàn ń sọkún ní gbogbo ìdílé wọn, oníkálùkù ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ tirẹ̀. Olúwa sì bínú gidigidi. Inú Mose sì bàjẹ́ pẹ̀lú.
11 I rzekł Mojżesz do Pana: Czemużeś tak źle uczynił słudze twemu? czemużem nie znalazł łaski w oczach twoich, żeś włożył ciężar tego wszystkiego ludu na mię?
Mose sì béèrè lọ́wọ́ Olúwa pé, “Kí ló dé tí o fi mú wàhálà yìí bá ìránṣẹ́ rẹ? Kí ni mo ṣe tí n kò fi tẹ ọ lọ́rùn tí ìwọ fi di ẹrù àwọn ènìyàn wọ̀nyí lé mi lórí.
12 Izalim ja począł ten wszystek lud? izalim go ja zrodził, iż mi mówisz: Nieś je na łonie twojem, jako piastun nosi niemowlątko, do ziemi, o którąś przysiągł ojcom ich?
Èmi ni mo ha lóyún gbogbo àwọn ènìyàn wọ̀nyí bí? Àbí èmi ló bí wọn? Tí ìwọ fi sọ fún mi pé, máa gbé wọn sí oókan àyà rẹ, gẹ́gẹ́ bí abiyamọ ti máa ń gbe ọmọ ọmú lọ sí ilẹ̀ tí o ti búra láti fún àwọn baba ńlá wọn.
13 Gdzież mam mięso, abym dał wszystkiemu temu ludowi? bo płaczą na mię, mówiąc: Daj nam mięsa, abyśmy jedli.
Níbo ni n ó ti rí ẹran fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí? Nítorí wọ́n ń sọkún sí mi pé, ‘Fún wa lẹ́ran jẹ́!’
14 Nie mogę ja sam znieść wszystkiego ludu tego; bo to nad możność moję.
Èmi nìkan kò lè dágbé wàhálà àwọn ènìyàn wọ̀nyí, ẹrù wọn ti wúwo jù fún mi.
15 A jeźli się tak ze mną obchodzić chcesz, proszę raczej mię zabij, jeźlim znalazł łaskę w oczach twoich, abym nie patrzył na swoje złe.
Bí ó bá sì ṣe pé báyìí ni ìwọ ó ṣe máa ṣe fún mi, kúkú pa mí báyìí, tí mo bá ti bá ojúrere rẹ pàdé—kí ojú mi má ba à rí ìparun mi.”
16 I rzekł Pan do Mojżesza: Zbierz mi siedemdziesiąt mężów z starszych Izraelskich, które znasz, że są starszymi ludu, i książęta jego, a przywiedź je przed namiot zgromadzenia, i stać tam będę z tobą;
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú àádọ́rin ọkùnrin nínú àwọn àgbàgbà àwọn ọmọ Israẹli, àwọn tí o mọ̀ gẹ́gẹ́ bí olórí àti olóyè láàrín àwọn ènìyàn wá sínú àgọ́ ìpàdé, kí wọ́n lé dúró níwájú mi.
17 A Ja zstąpię, i będę tam mówił z tobą, i wziąwszy z Ducha, który jest w tobie, udzielę im; i poniosą z tobą brzemię ludu, a nie poniesiesz go ty sam.
Èmi ó sì sọ̀kalẹ̀ wá bá yín sọ̀rọ̀ níbẹ̀. Èmi ó sì mú díẹ̀ nínú agbára Ẹ̀mí tí ń bẹ lára rẹ láti fi sí orí àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Wọn ó sì máa ràn ọ́ lọ́wọ́ láti ru àjàgà àwọn ènìyàn kí ó má ṣe pé ìwọ nìkan ni ó o máa ru àjàgà náà.
18 A do ludu rzeczesz: Poświęćcie się na jutro, a będziecie jeść mięso; boście płakali w uszach Pańskich, mówiąc: Któż nas nakarmi mięsem? bo nam lepiej było w Egipcie; i da wam Pan mięsa, i będziecie jedli.
“Sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, ‘Ẹ ya ara yín sí mímọ́ ní ìmúrasílẹ̀ fún ọ̀la, ẹ ó sì jẹ ẹran. Nítorí pé Olúwa ti gbọ́ igbe ẹkún yín, èyí tí ẹ sun pé, “Ìbá ṣe pé a lè rí ẹran jẹ ni! Ó sàn fún wa ní Ejibiti jù báyìí lọ!” Nítorí náà ni Olúwa yóò fi fún yín ní ẹran, ẹ ó sì jẹ ẹ́.
19 Nie przez jeden dzień jeść będziecie, ani przez dwa dni, ani przez pięć, ani przez dziesięć dni, ani przez dwadzieścia dni:
Ẹ kò ní i jẹ ẹ́ fún ọjọ́ kan, ọjọ́ méjì, ọjọ́ márùn-ún, ọjọ́ mẹ́wàá tàbí ogúnjọ́ lásán,
20 Ale przez cały miesiąc, aż polezie przez nozdrza wasze, a zbrzydzi się wam, przeto żeście pogardzili Panem, który jest między wami, a płakaliście przed nim mówiąc: Na cóżeśmy wyszli z Egiptu?
ṣùgbọ́n fún odidi oṣù kan, títí tí ẹran náà yóò fi máa yọ ní imú yín, tí yóò sì sú yín, nítorí pé ẹ ti kẹ́gàn Olúwa tí ó wà láàrín yín, ẹ sì ti sọkún fún un wí pé, “Kí ló dé tí a fi kúrò ní Ejibiti gan an?”’”
21 I rzekł Mojżesz: Sześć kroć sto tysięcy pieszych jest ludu, między którym ja mieszkam, a tyś powiedział: Dam im mięsa, że będą jeść cały miesiąc.
Ṣùgbọ́n Mose sọ pé, “Mo wà láàrín ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ènìyàn ni ìrìnkiri, ó sì sọ pé, ‘Èmi ó fún wọn ní ẹran láti jẹ fún oṣù kan gbáko!’
22 Izali im owiec i wołów nabiją, aby się im dostało? Izali wszystkie ryby morskie zbiorą im, aby dostatek mieli?
Ǹjẹ́ bí a tilẹ̀ pa àgbò ẹran àti ọmọ ẹran, yóò ha tó wọn bí? Tàbí bí a tilẹ̀ pa gbogbo ẹja inú omi fún wọn, yóò wa tó bí?”
23 I rzekł Pan do Mojżesza: Azaż ręka Pańska jest skurczona? teraz ujrzysz, jeśli się wypełni słowo moje, czyli nie.
Olúwa sì dá Mose lóhùn pé, “Ọwọ́ Olúwa ha kúrú bí? Ìwọ yóò ri nísinsin yìí bóyá ọ̀rọ̀ tí mo sọ yóò ṣẹ tàbí kò ni í ṣẹ.”
24 Tedy wyszedł Mojżesz, i opowiedział ludowi słowa Pańskie; a zebrawszy siedemdziesiąt mężów starszych z ludu, postawił je około namiotu.
Mose sì jáde, ó sọ ohun tí Olúwa wí fún àwọn ènìyàn. Ó mú àwọn àádọ́rin àgbàgbà Israẹli dúró yí àgọ́ ká.
25 I zstąpił Pan w obłoku, i mówił do niego, a wziąwszy z Ducha, który był w nim, podzielił go między siedemdziesiąt mężów starszych; i stało się, gdy odpoczął nad nimi on Duch, tedy prorokowali, a potem nigdy.
Nígbà náà ni Olúwa sọ̀kalẹ̀ nínú àwọ̀ sánmọ̀ ó sì bá wọn sọ̀rọ̀, ó sì mú lára Ẹ̀mí tó wà lára Mose sí ara àwọn àádọ́rin àgbàgbà náà, Ó sì ṣẹlẹ̀ pé nígbà tí Ẹ̀mí náà bà lé wọn, wọ́n sọtẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n lẹ́yìn èyí wọn kò sọtẹ́lẹ̀ mọ́.
26 Ale zostali byli dwa mężowie w obozie, imię jednego Eldad, a imię drugiego Medad; na których też odpoczął on Duch, bo oni byli napisani, choć byli nie przyszli do namiotu; a tak ci prorokowali w obozie.
Àwọn ọkùnrin méjì, tí orúkọ wọn ń jẹ́ Eldadi àti Medadi kò kúrò nínú àgọ́. Orúkọ wọn wà lára àádọ́rin àgbàgbà yìí ṣùgbọ́n wọn kò jáde nínú àgọ́ síbẹ̀ Ẹ̀mí náà bà lé wọn, wọ́n sì sọtẹ́lẹ̀ nínú àgọ́.
27 Tedy przybieżało pacholę, i oznajmiło Mojżeszowi, mówiąc: Eldad i Medad prorokują w obozie.
Ọmọkùnrin kan sì sáré lọ sọ fún Mose pé, “Eldadi àti Medadi ń sọtẹ́lẹ̀ nínú àgọ́.”
28 Ale odpowiedziawszy Jozue, syn Nunów, sługa Mojżeszów, jeden z młodzieńców jego, rzekł: Panie mój Mojżeszu, zabroń im.
Joṣua ọmọ Nuni tí í ṣe ìránṣẹ́ Mose, láti kékeré tó jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ dáhùn pé, “Mose olúwa mi, dá wọn lẹ́kun!”
29 Któremu odpowiedział Mojżesz: Czemuż im ty zazdrościsz dla mnie? Boże daj, aby wszystek lud Pański prorokował, a iżby dał Pan Ducha swego na nie!
Mose sì wí fún un pé, “Àbí ìwọ ń jowú nítorí mi? Ìbá ti wù mí tó, kí gbogbo àwọn ènìyàn Olúwa jẹ́ wòlíì, kí Olúwa sì fi Ẹ̀mí rẹ̀ sí wọn lára!”
30 Wrócił się tedy Mojżesz do obozu, on i starsi Izraelscy.
Mose àti àwọn àgbàgbà Israẹli yìí sì padà sínú àgọ́.
31 Zatem wyszedł wiatr od Pana, i porwawszy przepiórki od morza, spuścił je na obóz, z jednej strony jako na jeden dzień chodu, z drugiej strony także jako na jeden dzień chodu, około obozu, a jakoby na dwa łokcie były nad ziemią.
Afẹ́fẹ́ sì jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa ó sì kó àparò wá láti inú Òkun. Ó sì dà wọ́n káàkiri gbogbo ibùdó ní ìwọ̀n gíga ẹsẹ̀ bàtà mẹ́ta sórí ilẹ̀, bí ìwọ̀n ìrìn ọjọ́ kan ní gbogbo àyíká.
32 Tedy wstawszy lud przez cały on dzień i przez całą noc, i nazajutrz przez wszystek dzień zbierali one przepiórki, a kto najmniej nazbierał, miał dziesięć homerów: i nawieszali ich wszędy sobie około obozu.
Ní gbogbo ọjọ́ náà àti òru, títí dé ọjọ́ kejì ni àwọn ènìyàn fi ń kó àparò yìí, ẹni tó kó kéré jùlọ kó ìwọ̀n homeri mẹ́wàá, wọ́n sì ṣà wọ́n sílẹ̀ fún ara wọn yí gbogbo ibùdó.
33 Mięso jeszcze było między zębami ich nie zeżwane, gdy gniew Pański zapalił się na lud, i pobił Pan lud on plagą bardzo wielką.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹran náà sì wà láàrín eyín wọn, kó tó di pé wọ́n jẹ ẹ́, ìbínú Olúwa sì ru sí àwọn ènìyàn, ó sì pa wọ́n pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn.
34 I nazwane jest imię miejsca onego Kibrot Hataawa; albowiem tam pogrzebli lud, który pożądał mięsa.
Torí èyí ni wọ́n ṣe pe ibẹ̀ ní Kibirotu-Hattaafa nítorí pé níbẹ̀ ni wọ́n gbé sìnkú àwọn ènìyàn tó ní ọ̀kánjúwà oúnjẹ sí.
35 A z Kibrot Hataawy ruszył się lud do Haserotu, i mieszkali w Haserocie.
Àwọn ènìyàn yòókù sì gbéra láti Kibirotu-Hattaafa lọ pa ibùdó sí Haserotu wọ́n sì dúró níbẹ̀.

< Liczb 11 >