< Nehemiasza 7 >

1 A gdy był dobudowany mur, i wystawiłem wrota, i postanowieni byli odźwierni, i śpiewacy, i Lewitowie:
Lẹ́yìn ìgbà tí a tún odi mọ tán tí mo sì ri àwọn ìlẹ̀kùn sí ààyè wọn, a sì yan àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin àti àwọn Lefi.
2 Rozkazałem Chananijemu, bratu memu, i Chananijaszowi, staroście zamku Jeruzalemskiego: (bo ten był mąż wierny, i bojący się Boga nad wielu innych; )
Mo fún Hanani arákùnrin mi pẹ̀lú Hananiah olórí ilé ìṣọ́ ní àṣẹ lórí Jerusalẹmu, nítorí tí ó jẹ́ ènìyàn olóòtítọ́, ó sì bẹ̀rù Ọlọ́run jù bí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ti ṣe lọ.
3 I rzekłem do nich: Niech nie otwierają bram Jeruzalemskich, aż ogrzeje słońce; a gdy ci, co tu stawają, zamkną bramę, opatrzcież ją. A tak postanowiłem straż z obywateli Jeruzalemskich, każdego na straży jego, i każdego na przeciwko domowi jego.
Mo sọ fún wọn pé, “A kò gbọdọ̀ ṣí ìlẹ̀kùn Jerusalẹmu títí oòrùn yóò fi mú. Nígbà tí àwọn aṣọ́bodè bá sì wà lẹ́nu iṣẹ́, jẹ́ kí wọn ti ìlẹ̀kùn kí wọn sì há wọn. Bákan náà, yàn nínú àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́. Àwọn mìíràn níbi tí a pín wọn sí àti àwọn mìíràn ní tòsí ilé e wọn.”
4 A miasto było szerokie i wielkie, ale ludu mało w murach jego, a jeszcze nie były domy pobudowane.
Ìlú náà tóbi ó sì ní ààyè, ṣùgbọ́n ènìyàn inú rẹ̀ kéré, a kò sì tí ì tún àwọn ilé inú rẹ̀ kọ́.
5 Przetoż podał Bóg mój do serca mego, abym zebrał przedniejszych, i przełożonych, i lud, aby byli obliczeni podług rodzaju. I znalazłem księgi rodu tych, którzy się tu najpierwej przyprowadzili, i znalazłem w nich to opisanie.
Nígbà náà ni Ọlọ́run mi fi sí mi ní ọkàn láti kó àwọn ọlọ́lá, àwọn ìjòyè, àti àwọn ènìyàn jọ fún ìforúkọsílẹ̀ ní ìdílé ìdílé. Mo rí ìwé àkọsílẹ̀ ìtàn ìran àwọn tí ó kọ́ gòkè padà wá láti ìgbèkùn. Èyí ni ohun tí mo rí tí a kọ sínú ìwé náà.
6 Cić są ludzie onej krainy, którzy wyszli z pojmania i z niewoli, w którą ich był zaprowadził Nabuchodonozor, król Babiloński; a wrócili się do Jeruzalemu i do Judy, każdy do miasta swego.
Èyí ni àwọn ènìyàn agbègbè náà tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ wá láti ìgbèkùn, àwọn tí Nebukadnessari ọba Babeli ti kó ní ìgbèkùn (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú u rẹ̀.
7 Którzy przyszli z Zorobabelem, z Jesuą, Nehemijaszem, Azaryjaszem, Rahamijaszem, Nechamanem, Mardocheuszem, Bilsanem, Misperetem, Bigwajem, Nechumem, Baaną.
Wọ́n jọ rìn wá pẹ̀lú u Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Asariah, Raamiah, Nahamani, Mordekai, Bilṣani, Misperi, Bigfai, Nehumu, àti Baanah). Àkọsílẹ̀ orúkọ àwọn ọkùnrin Israẹli,
8 A poczet mężów ludu Izraelskiego taki jest: Synów Farosowych dwa tysiące sto i siedmdziesiąt i dwa;
àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
9 Synów Sefatyjaszowych trzy sta siedmdziesiąt i dwa;
Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
10 Synów Arachowych sześć set pięćdziesiąt i dwa;
Arah jẹ́ ẹgbẹ̀tàléláàádọ́ta ó lé méjì
11 Synów Pachatmoabowych, synów Jesui, i Joabowych dwa tysiące ośm set i ośmnaście;
Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìnlá ó lé méjìdínlógún
12 Synów Elamowych tysiąc dwieście pięćdziesiąt i cztery;
Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
13 Synów Zattuowych ośm set czterdzieści i pięć;
Sattu jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
14 Synów Zachajowych siedm set i sześćdziesiąt;
Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
15 Synów Binnujowych sześć set czterdzieści i ośm;
Binnui jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́jọ
16 Synów Bebajowych sześć set dwadzieścia i ośm;
Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé méjìdínlọ́gbọ̀n
17 Synów Azgadowych dwa tysiące trzy sta dwadzieścia i dwa;
Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó dín méjìdínlọ́gọ́rin
18 Synów Adonikamowych sześć set sześćdziesiąt i siedm;
Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méje
19 Synów Bigwajowych dwa tysiące sześćdziesiąt i siedm;
Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́tàdínláàádọ́rin
20 Synów Adynowych sześć set pięćdziesiąt i pięć;
Adini jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé márùn-ún
21 Synów Aterowych, co poszli z Ezechyjasza, dziewięćdziesiąt i ośm;
Ateri (láti ipasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́rùn-ún
22 Synów Hasumowych trzy sta dwadzieścia i ośm;
Haṣumu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́jọ
23 Synów Besajowych trzy sta dwadzieścia i cztery;
Besai jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́rin
24 Synów Charyfowych sto i dwanaście;
Harifu jẹ́ méjìléláàádọ́fà
25 Synów z Gabaonu dziewięćdziesiąt i pięć.
Gibeoni jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
26 Mężów z Betlehemu i Netofatu sto ośmdziesiąt i ośm;
Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu àti Netofa jẹ́ igba ó dín méjìlélógún
27 Mężów z Anatotu sto dwadzieścia i ośm;
Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
28 Mężów z Bet Azmawetu czterdzieści i dwa;
Beti-Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
29 Mężów z Karyjatyjarymu, z Kafiry i z Beerotu siedm set czterdzieści i trzy;
Kiriati-Jearimu, Kefira, àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
30 Mężów z Ramy i z Gabaa sześć set dwadzieścia i jeden;
Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
31 Mężów z Machmas sto i dwadzieścia i dwa;
Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
32 Mężów z Betela i z Haj sto dwadzieścia i trzy;
Beteli àti Ai jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
33 Mężów z Nebo drugiego pięćdziesiąt i dwa.
Nebo mìíràn jẹ́ méjìléláàádọ́ta
34 Synów Elama drugiego tysiąc dwieście pięćdziesiąt i cztery;
Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
35 Synów Harymowych trzy sta i dwadzieścia;
Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó
36 Synów Jerechowych trzy sta czterdzieści i pięć;
Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún.
37 Synów Lodowych, Hadydowych, i Onowych siedm set i dwadzieścia i jeden.
Lodi, Hadidi, àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé ọ̀kan
38 Synów Senaa trzy tysiące dziewięć set i trzydzieści.
Senaa jẹ́ ẹgbàajì ó dín àádọ́rin.
39 Kapłanów: Synów Jedajaszowych, z domu Jesui, dziewięć set siedmdziesiąt i trzy;
Àwọn àlùfáà: àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
40 Synów Immerowych tysiąc pięćdziesiąt i dwa;
Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
41 Synów Passurowych tysiąc dwieście czterdzieści i siedm;
Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
42 Synów Harymowych tysiąc i siedmnaście;
Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
43 Lewitów: Synów Jesuego, i Kadmielowych, synów Hodowijaszowych siedmdziesiąt i cztery.
Àwọn ọmọ Lefi: àwọn ọmọ Jeṣua (láti ipasẹ̀ Kadmieli, láti ipasẹ̀ Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
44 Śpiewaków: Synów Asafowych sto czterdzieści i ośm.
Àwọn akọrin: àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádọ́jọ.
45 Odźwiernych: Synów Sallumowych, synów Aterowych, synów Talmonowych, synów Akkubowych, synów Hatytowych, synów Sobajowych sto trzydzieści i ośm.
Àwọn aṣọ́nà: àwọn ọmọ Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita, àti Ṣobai jẹ́ méjìdínlógóje.
46 Z Netynejczyków: Synów Sycha, synów Chasufa, synów Tabbaota,
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ Siha, Hasufa, Tabboati,
47 Synów Kierosa, synów Syjaa, synów Fadona,
Kerosi, Sia, Padoni,
48 Synów Lebana, synów Hagaba, synów Salmaja,
Lebana, Hagaba, Ṣalmai,
49 Synów Hanana, synów Giddela, synów Gachara,
Hanani, Giddeli, Gahari,
50 Synów Raajasza, synów Rezyna, synów Nekoda,
Reaiah, Resini, Nekoda,
51 Synów Gazama, synów Uzy, synów Faseacha.
Gassamu, Ussa, Pasea,
52 Synów Besaja, synów Mechynima, synów Nefusesyma,
Besai, Mehuni, Nefisimu,
53 Synów Bakbuka, synów Chakufa, synów Charchura,
Bakbu, Hakufa, Harhuri,
54 Synów Basluta, synów Mechyda, synów Charsa,
Basluti, Mehida, Harṣa,
55 Synów Barkosa, synów Sysera, synów Tamacha,
Barkosi, Sisera, Tema,
56 Synów Nezyjacha, synów Chatyfa,
Nesia, àti Hatifa.
57 Synów sług Salomonowych, synów Sotaja, synów Soferata, synów Peruda.
Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni: àwọn ọmọ Sotai, Sofereti; Perida,
58 Synów Jahala, synów Darkona, synów Giddela,
Jaala, Darkoni, Giddeli,
59 Synów Sefatyjasza, synów Chatyla, synów Pochereta z Hasebaim, synów Amona:
Ṣefatia, Hattili, Pokereti-Haṣṣebaimu, àti Amoni.
60 Wszystkich Netynejczyków i synów sług Salomonowych trzy sta dziewięćdziesiąt i dwa.
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
61 A cić są, którzy wyszli z Telmelachu i z Telcharsa: Cherub, Addan, i Immer: ale nie mogli okazać domu ojców swoich i nasienia swego, jeźli z Izraela byli.
Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
62 Synów Delajaszowych, synów Tobijaszowych, synów Nekodowych sześć set czterdzieści i dwa.
Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
63 A z kapłanów synowie Hobajowi, synowie Kozowi, synowie Barsylajego; który był pojął z córek Barsylaja Galaadczyka żonę, i nazwany był od imienia ich.
Lára àwọn àlùfáà ni: àwọn ọmọ Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi, ẹni tí a ń fi orúkọ yìí pè).
64 Ci szukali opisania swego, wywodząc ród swój, ale nie znaleźli; przetoż zrzuceni są z kapłaństwa.
Àwọn wọ̀nyí wá àkọsílẹ̀ orúkọ ìran wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí í níbẹ̀, fún ìdí èyí, a yọ wọ́n kúrò nínú àwọn tí ń ṣiṣẹ́ àlùfáà gẹ́gẹ́ bí aláìmọ́.
65 I zakazał im Tyrsata, aby nie jedli z rzeczy najświętszych, ażby powstał kapłan z Urym i z Tummim.
Baálẹ̀ sọ fún wọn nítorí náà pé wọn kò gbọdọ̀ kópa nínú jíjẹ oúnjẹ mímọ́ títí tí àlùfáà tí yóò wá tí ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu yóò fi dé.
66 Wszystkiego zgromadzenia w jednym poczcie było czterdzieści tysięcy dwa tysiące trzy sta i sześćdziesiąt;
Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó,
67 Oprócz sług ich i służebnic ich, których było siedm tysięcy trzy sta trzydzieści i siedm; a między nimi było śpiewaków i śpiewaczek dwieście i czterdzieści i pięć.
yàtọ̀ sí àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin tí wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀ta dín lẹ́gbàárin ó dín ẹ̀tàlélọ́gọ́ta; wọ́n sì tún ní àwọn akọrin ọkùnrin àti obìnrin tí wọ́n jẹ́ òjìlúgba ó lé márùn-ún.
68 Koni ich siedm set trzydzieści i sześć; mułów ich dwieście czterdzieści i pięć.
Ẹṣin wọn jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin, ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlúgba ó dín márùn-ún;
69 Wielbłądów cztery sta trzydzieści i pięć; osłów sześć tysięcy siedm set i dwadzieścia.
ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlénírinwó ó dín márùn-ún; kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀rìnlélọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
70 A niektórzy przedniejsi z domów ojcowskich dawali na robotę. Tyrsata dał do skarbu złota tysiąc łótów, czasz pięćdziesiąt, szat kapłańskich pięć set i trzydzieści.
Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé náà kópa nínú ṣíṣe iṣẹ́ náà. Baálẹ̀ fún ilé ìṣúra ní ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, àádọ́ta àwo koto àti ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀ta lé mẹ́wàá ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
71 Niektórzy też z przedniejszych domów ojcowskich dali do skarbu na robotę złota dwadzieścia tysięcy łótów, a srebra grzywien dwa tysiące i dwieście.
Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé fún ilé ìṣúra ní ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà àti ẹgbọ̀kànlá mina fàdákà.
72 A co dał inszy lud, było złota dwadzieścia tysięcy łótów, a srebra dwa tysiące grzywien, a szat kapłańskich sześćdziesiąt i siedm.
Àròpọ̀ gbogbo ohun tí àwọn ènìyàn tókù fi sílẹ̀ jẹ́ ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún méjì mina fàdákà àti ẹẹ́tàdínláàdọ́rin ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
73 A tak osiedli kapłani i Lewitowie, i odźwierni, i śpiewacy, i lud pospolity, i Netynejczycy, i wszystek Izrael miasta swoje. A gdy nastał miesiąc siódmy, byli synowie Izraelscy w miastach swoich.
Àwọn àlùfáà, àwọn Lefi, àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin, àwọn ènìyàn díẹ̀, àwọn ìránṣẹ́ ilé Ọlọ́run, àti gbogbo ènìyàn Israẹli wà ní ìlú wọn. Nígbà tí ó di oṣù keje, tí àwọn ọmọ Israẹli sì ti wà nínú ìlú u wọn,

< Nehemiasza 7 >