< Nehemiasza 2 >

1 I stało się miesiąca Nisan roku dwudziestego Artakserksesa króla, gdy było wino przed nim, że wziąwszy wino, podałem je królowi, a nie bywałem przedtem tak smutny przed nim.
Ní oṣù Nisani, ní ogún ọdún ìjọba ọba Artasasta, nígbà tí a gbé wáìnì wá fún un, mo gbé wáìnì náà, mo fi fún ọba, ìbànújẹ́ kò hàn ní ojú mi rí ní iwájú rẹ̀.
2 I rzekł mi król: Czemuż twarz twoja tak smutna, gdyż nie chorujesz? Nic to innego, jedno smutek serca. I zlękłem się nader bardzo.
Nítorí náà ni ọba béèrè lọ́wọ́ mi pé, “Èéṣe tí ojú rẹ fi fàro nígbà tí kò rẹ̀ ọ́? Èyí kì í ṣe ohun mìíràn bí kò ṣe ìbànújẹ́ ọkàn.” Ẹ̀rù bà mí gidigidi,
3 I rzekłem do króla: Niech król na wiki żyje. Jakoż nie ma być smutna twarz moja, gdyż miasto, dom grobów ojców moich, zburzono, a bramy jego ogniem popalono?
ṣùgbọ́n mo wí fún ọba pé, “Kí ọba kí ó pẹ́! Èéṣe tí ojú mi ko ṣe ní fàro, nígbà tí ìlú tí a sin àwọn baba mi sí wà ní ahoro, tí a sì ti fi iná run àwọn ibodè rẹ̀?”
4 Znowu rzekł do mnie król: Czegoż ty żądasz? A jam się modlił Bogu niebieskiemu.
Ọba wí fún mi pé, “Kí ni ìwọ ń fẹ́?” Nígbà náà, ni mo gbàdúrà sí Ọlọ́run ọ̀run,
5 I rzekłem do króla: Zdali się to za rzecz dobrą królowi, i jeżli ma łaskę sługa twój przed obliczem twojem, proszę, abyś mię posłał do ziemi Judzkiej, do miasta grobów ojców moich, abym je pobudował.
mo sì dá ọba lóhùn pé, “Ti ó bá wu ọba, tí ìránṣẹ́ rẹ bá sì rí ojúrere ní ojú rẹ, jẹ́ kí ó rán mi lọ sí ìlú náà ní Juda níbi tí a sin àwọn baba mi nítorí kí èmi lè tún un kọ́.”
6 Nadto rzekł mi król (a królowa siedziała podle niego): Długoż będziesz na tej drodze, i kiedy się wrócisz? I podobało się to królowi, i posłał mię, gdym mu zamierzył pewny czas.
Nígbà náà ni ọba, pẹ̀lú ìyàwó rẹ̀ tí ó jókòó lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, bi mí pé, “Báwo ni ìrìnàjò náà yóò ṣe pẹ́ ọ tó, nígbà wo sì ni ìwọ yóò padà?” Ó dùn mọ́ ọba láti rán mi lọ, bẹ́ẹ̀ ni mo dá àkókò kan.
7 Zatemem rzekł do króla: Zdali się to za rzecz dobrą królowi, niech mi dadzą listy do starostów za rzeką, aby mię przeprowadzili, ażbym przyszedł do ziemi Judzkiej;
Mo sì tún wí fún ọba pé, “Bí ó bá wu ọba, kí ó fún mi ní lẹ́tà sí àwọn baálẹ̀ òkè odò Eufurate kí wọ́n le mú mi kọjá títí èmi yóò fi dé Juda láìléwu.
8 I list do Asafa, dozorcy lasów królewskich, aby mi dał drzewa na przykrycie bram pałacu przy domu Bożym, i na mur miejski, i na dom, do którego wnijdę. I dał mi król listy według ręki Boga mego łaskawej nademną.
Kí èmi sì gba lẹ́tà kan lọ́wọ́ fún Asafu, olùṣọ́ igbó ọba, nítorí kí ó lè fún mi ní igi láti fi ṣe àtẹ́rígbà fún ibodè ilé ìṣọ́ tẹmpili àti fún odi ìlú náà àti fún ilé tí èmi yóò gbé?” Nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run mi wà lórí mi, ọba fi ìbéèrè mi fún mi.
9 A gdym przyszedł do starostów za rzeką, oddałem im listy królewskie. Posłał też był ze mną król rotmistrzów i jezdnych:
Bẹ́ẹ̀ ni mo lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn baálẹ̀ agbègbè Eufurate, mo sì fún wọn ní àwọn lẹ́tà ọba. Ọba sì ti rán àwọn ológun àti àwọn ẹlẹ́ṣin ogun pẹ̀lú mi.
10 Co gdy usłyszał Sanballat Horonitczyk, i Tobijasz, sługa Ammonitczyk, bardzo ich to mierziało, że przyszedł człowiek, który się starał o dobro synów Izraelskich.
Nígbà tí Sanballati ará Horoni àti Tobiah ará a Ammoni tí wọ́n jẹ́ ìjòyè gbọ́ nípa èyí pé, ẹnìkan wá láti mú ìtẹ̀síwájú bá àlàáfíà àwọn ará Israẹli inú bí wọn gidigidi.
11 Zatem przyszedłszy do Jeruzalemu, mieszkałem tam przez trzy dni.
Mo sì lọ sí Jerusalẹmu, lẹ́yìn ìgbà tí mo dúró níbẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta.
12 A wstawszy w nocy, ja i mężów trocha ze mną, nie oznajmiłem nikomu, co Bóg mój podał do serca mego, abym uczynił w Jeruzalemie; bydlęcia też nie miałem z sobą, oprócz bydlęcia, na któremem jechał.
Mo jáde ní òru pẹ̀lú àwọn ọkùnrin díẹ̀. Èmi kò sì sọ fún ẹnìkankan ohun tí Ọlọ́run mi ti fi sí ọkàn mi láti ṣe fún Jerusalẹmu. Kò sí ẹranko kankan pẹ̀lú mi, bí kò ṣe ọ̀kan ṣoṣo tí mo gùn.
13 I wyjechałem bramą nad doliną w nocy, ku żródłu smoczemu, i ku bramie gnojowej, i oglądałem mury Jeruzalemskie, które były rozwalone, i bramy jego, które były popalone ogniem.
Ní òru, mo jáde lọ sí àfonífojì ibodè sí ìhà kànga Jakali àti sí ẹnu ibodè Ààtàn àti ẹnu ibodè rẹ̀ èyí tí ó ti wó odi Jerusalẹmu tí ó lulẹ̀, tí a ti fi iná sun.
14 Potem jechałem ku bramie żródła, i ku sadzawce królewskiej, gdzie nie było miejsca bydlęciu, na któremem jechał, aby przejść mogło.
Nígbà náà ni mo lọ sí ẹnu ibodè orísun àti sí adágún omi ọba, ṣùgbọ́n kò sí ààyè tó fún ẹranko mi láti kọjá;
15 Przetoż jechałem nad potokiem w nocy, a oglądałem mury; skąd wracając się, wyjechałem bramą nad doliną, i takiem powrócił.
bẹ́ẹ̀ ni mo gòkè àfonífojì ní òru, mo ń wo odi. Ní ìparí, mo padà sẹ́yìn, mo sì tún wọlé láti ibodè àfonífojì.
16 Ale książęta nie wiedzieli, gdziem jeżdził, i com czynił; bom Żydom, ani kapłanom, ani książętom, ani urzędnikom, ani żadnemu rzemieślnikowi tego aż dotąd nie oznajmił.
Àwọn olórí kò mọ ibi tí mo lọ tàbí mọ ohun tí mo ń ṣe, nítorí èmi kò tí ì sọ fún àwọn ará Júù tàbí àwọn àlùfáà tàbí àwọn ọlọ́lá tàbí àwọn ìjòyè tàbí ẹnikẹ́ni mìíràn tí yóò máa ṣe iṣẹ́ náà.
17 Przetożem rzekł do nich: Wy widzicie, w jakiemeśmy uciśnieniu, a jako Jeruzalem spustoszone, i bramy jego popalone są ogniem. Pójdżcież, a budujmy mury Jeruzalemskie, abyśmy nie byli więcej na hańbę.
Nígbà náà ni mo sọ fún wọn pé, “Ṣé ẹ rí wàhálà tí a ni: Jerusalẹmu wà nínú ìparun, ibodè rẹ̀ ni a sì ti fi iná jó. Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a tún odi Jerusalẹmu mọ, àwa kò sì ní jẹ́ ẹni ẹ̀gàn mọ́”.
18 A gdym im oznajmił, że ręka Boga mego była łaskawa nademną, także i słowa królewskie, które do mnie mówił, rzekli: Wstańmyż a budujmy. I zmocnili ręce swe ku dobremu.
Èmi sì tún sọ fún wọn nípa bí ọwọ́ àánú Ọlọ́run mi ṣe wà lára mi àti ohun tí ọba ti sọ fún mi. Wọ́n dáhùn wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a bẹ̀rẹ̀ àtúnmọ rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rere yìí.
19 Co słysząc Sanballat Horonitczyk, i Tobijasz, sługa Ammonitczyk i Giesem Arabczyk, szydzili z nas, i lekce nas sobie poważyli mówiąc: Cóż to za rzecz, którą czynicie? albo się przeciw królowi buntujecie?
Ṣùgbọ́n nígbà tí Sanballati ará a Horoni, Tobiah ara olóyè Ammoni àti Geṣemu ará a Arabia gbọ́ nípa rẹ̀, wọ́n fi wá ṣe ẹlẹ́yà, wọ́n sì fi wá ṣe ẹ̀sín. Wọ́n béèrè pé, “Kí ni èyí tí ẹ ń ṣe yìí? Ṣé ẹ ń ṣọ̀tẹ̀ sí ọba ni?”
20 I odpowiedziałem im, a rzekłem do nich: Bóg niebieski, ten nam poszczęści, a my słudzy jego, wstańmy a budujmy; ale wy nie macie działu, ani prawa, ani pamiątki w Jeruzalemie.
Mo dá wọn lóhùn, mo wí fún wọn pé, “Ọlọ́run ọ̀run yóò fún wa ní àṣeyọrí. Àwa ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò bẹ̀rẹ̀ láti tún un mọ, ṣùgbọ́n fún un yin, ẹ̀yin kò ní ìpín tàbí ipa tàbí ẹ̀tọ́ ohunkóhun tí ó jẹ mọ́ ìtàn ní Jerusalẹmu.”

< Nehemiasza 2 >