< Nahuma 3 >

1 Biada miastu krwawemu; wszystko kłamstwa i łupiestwa pełne jest, a ździerstwo z niego nie wychodzi.
Ègbé ni fún ìlú ẹ̀jẹ̀ nì, gbogbo rẹ̀ kún fún èké, ó kún fún olè, ìjẹ kò kúrò!
2 Tam będzie słyszane trzaskanie biczów, i grzmot kół, i tupanie koni, i skakanie wozów.
Ariwo pàṣán àti ariwo kíkùn kẹ̀kẹ́ ogun àti jíjó ẹṣin àti gbígbọn kẹ̀kẹ́ ogun jìgìjìgì!
3 Jezdny dobędzie błyszczącego miecza swego, i lśniącego oszczepa; tam będzie wiele pobitych i wielkie gromady trupów, tak, że nie będzie liczby trupów, a przez ciała pobitych walić się będą:
Ológun orí ẹṣin ń fi ìgbónára ju idà wọn mọ̀nàmọ́ná ọ̀kọ̀ rẹ̀ ti ń dán yanran sí òkè! Ọ̀pọ̀lọpọ̀ si ní àwọn ẹni tí a pa, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ òkú; òkú kò sì ni òpin; àwọn ènìyàn sì ń kọsẹ̀ lára àwọn òkú.
4 Dla wielkości wszeteczeństw nierządnicy rozkosznej, która się bawiła czarami, a zaprzedawała narody wszeteczeństwami swemi, i ludzi gusłami swemi.
Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ panṣágà àgbèrè tí ó rójú rere gbà, ìyá àjẹ́ tí ó ṣọ́ àwọn Orílẹ̀-èdè di ẹrú nípa àgbèrè rẹ̀ àti àwọn ìdílé nípa ìṣe àjẹ́ rẹ̀.
5 Otom Ja przeciwko tobie, mówi Pan zastępów, i odkryję podołek twój na twarz twoję, a okażę narodom sprosność twoję, a królestwom hańbę twoję:
“Èmi dojúkọ ọ́,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Èmi ó si ká aṣọ àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ ní ojú rẹ. Èmi yóò sì fi ìhòhò rẹ̀ han àwọn orílẹ̀-èdè àti ìtìjú rẹ̀ han àwọn ilẹ̀ ọba.
6 I wyrzucę na cię obrzydliwości i zelżę cię, i wystawię cię za dziw,
Èmi yóò da ẹ̀gbin tí ó ni ìríra sí ọ ní ara, èmi yóò sì sọ ọ́ di aláìmọ́, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹlẹ́yà.
7 Tak, że ktokolwiek cię ujrzy, oddali się od ciebie i rzecze: Zburzone jest Niniwe, któżby się go użalił? Gdzieżbym szukał tych, którzyby cię cieszyli?
Gbogbo àwọn tí ó ba sì wò ọ́ yóò sì káàánú fún ọ, wọn yóò sì wí pé, ‘Ninefe ṣòfò, ta ni yóò kẹ́dùn rẹ?’ Níbo ni èmi o ti wá olùtùnú fún ọ?”
8 Izaliś ty lepsza, niż ludne miasto No, które leżało między rzekami, wodami otoczone będąc; którego wałem było morze, i od morza mur jego?
Ǹjẹ́ ìwọ ha sàn ju Tebesi lọ, èyí tí ó wà ní ibi odò Naili, tí omi sì yí káàkiri? Odò náà sì jẹ́ ààbò rẹ̀, omi si jẹ́ odi rẹ̀.
9 Murzyńska ziemia i Egipt były siłą jego, i narody niezliczone, Putczycy i Lubimczycy, były mu na pomocy;
Etiopia àti Ejibiti ni agbára rẹ, kò sí ní òpin; Puti àti Libia ni àwọn olùgbèjà rẹ̀.
10 Wszakże i to w zaprowadzenie i w pojmanie przyszło; maluczkie jego na rogach wszystkich ulic roztrącano a o najsławniejszych jego losy miotano, nawet wszyscy przedniejsi jego okowani są w pęta.
Síbẹ̀síbẹ̀ a kó o ní ìgbèkùn o sì lọ sí oko ẹrú. Àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ rẹ̀ ni a ó fọ́ mọ́lẹ̀ ní orí ìta gbogbo ìgboro. Wọ́n sì di ìbò nítorí àwọn ọlọ́lá rẹ̀ ọkùnrin, gbogbo àwọn ọlọ́lá rẹ ni a sì fi ẹ̀wọ̀n dè.
11 Takżeć i ty opojona będziesz, i skryć się musisz, i ty szukać będziesz pomocy przeciwko nieprzyjacielowi.
Ìwọ pẹ̀lú yóò sì mu àmupara; a ó sì fi ọ́ pamọ́ ìwọ pẹ̀lú yóò máa ṣe àfẹ́rí ààbò nítorí ti ọ̀tá náà.
12 Wszystkie twierdze twoje są jako figowe drzewo z owocem rannym, którym gdy kto zatrząśnie, zaraz wpadają w usta tego, co je jeść chce.
Gbogbo ilé ìṣọ́ agbára rẹ yóò dàbí igi ọ̀pọ̀tọ́ pẹ̀lú àkọ́pọ́n èso wọn; nígbà tí wọ́n bá ń gbọ̀n wọ́n, ọ̀pọ̀tọ́ yóò sì bọ́ sí ẹnu àwọn ọ̀jẹun.
13 Oto lud twój są niewiastami w pośród ciebie; nieprzyjaciołom twoim szeroko otworzone będą bramy ziemi twojej, a ogień pożre zawory twoje.
Kíyèsi gbogbo àwọn jagunjagun! Obìnrin ni gbogbo wọn. Ojú ibodè rẹ ní a ó ṣí sílẹ̀ gbagada, fún àwọn ọ̀tá rẹ; iná yóò jó ọ̀pá ìdábùú ìlẹ̀kùn ibodè rẹ.
14 Naczerpaj sobie wody do oblężenia, zmacniaj twierdze twoje, wleź w błoto, i depcz glinę, oprawiwszy cegielnicę;
Pọn omi nítorí ìhámọ́, mú ilé ìṣọ́ rẹ lágbára sí i wọ inú amọ̀ kí o sì tẹ erùpẹ̀, kí ó sì tún ibi tí a ti ń sun bíríkì-amọ̀ ṣe kí ó le.
15 Tam cię pożre ogień, wytnie cię miecz, pożre cię jako chrząszcze; zgromadź się jako chrząszcze, zbierz się jako szarańcza.
Níbẹ̀ ni iná yóò ti jó ọ́ run; idà yóò sì ké ọ kúrò, yóò sì jẹ ọ́ bí i kòkòrò, yóò sì sọ ara rẹ̀ di púpọ̀ bí i tata, àní, di púpọ̀ bí eṣú!
16 Rozmnożyłeś kupców twoich nad gwiazdy niebieskie; ale jako chrząszcze przypadają i odlatują, tak i ci.
Ìwọ ti sọ àwọn oníṣòwò rẹ di púpọ̀ títí wọn yóò fi pọ̀ ju ìràwọ̀ ojú ọ̀run lọ, ṣùgbọ́n bi eṣú ni wọn yóò sọ ilẹ̀ náà di ahoro, wọn yóò sì fò lọ.
17 Panowie twoi są jako szarańcza, a hetmani twoi jako wielcy chrząszcze, którzy się kładą obozami na płotach czasu zimna, jedno słońce weszło, alić odlatują, i nie znać miejsca ich, gdzie byli.
Àwọn aládé rẹ̀ dàbí eṣú, àwọn ọ̀gágun rẹ dàbí ẹlẹ́ǹgà ńlá, èyí tí ń dó sínú ọgbà ni ọjọ́ òtútù, ṣùgbọ́n nígbà tí oòrùn jáde, wọ́n sálọ, ẹnìkan kò sì mọ ibi tí wọ́n gbé wà.
18 Zdrzemią się pasterze twoi, o królu Assyryjski! leżeć będą sławni twoi; obfitość ludu twego będzie po górach, ale nie będzie, ktoby go zgromadził.
Ìwọ ọba Asiria, àwọn olùṣọ́-àgùntàn rẹ̀ ń tòògbé; àwọn ọlọ́lá rẹ dùbúlẹ̀ láti sinmi. Àwọn ènìyàn rẹ fọ́nká lórí àwọn òkè ńlá, tí ẹnikẹ́ni kò sì kó wọn jọ.
19 Niemasz lekarstwa na ranę twoję, nieuleczona jest plaga twoja; wszyscy, którzy powieść o tobie usłyszą, klaskać będą rękoma nad tobą; bo na kogoż ustawicznie nie przychodziło okrucieństwo twoje?
Kò sì sí ohun tí ó lè wo ọgbẹ́ ẹ̀ rẹ sàn; ọgbẹ́ rẹ kún fún ìrora, Gbogbo ẹni tí ó bá sì gbọ́ ìròyìn rẹ yóò pàtẹ́wọ́ lé ọ lórí, nítorí ta ni kò ní pín nínú ìwà búburú rẹ ti kò ti lópin.

< Nahuma 3 >