< Micheasza 7 >
1 Biada mnie! żem jako ostatki po sprzątanieniu owoców letnich, jako pozostałe grona po zbieraniu wina; niemasz grona ku zjedzeniu, pierwocin z owocu pragnie dusza moja.
Ègbé ni fún mi! Nítorí èmi sì dàbí ẹni tí ń kó èso ẹ̀ẹ̀rùn jọ, ìpèsè ọgbà àjàrà; kò sì ṣí odidi àjàrà kankan láti jẹ, kò sì ṣí àkọ́so ọ̀pọ̀tọ́ nítorí tí ebi ń pa mí.
2 Pobożny z ziemi zginął, a szczerego niemasz między ludźmi; wszyscy zgoła o wylaniu krwi myślą, każdy łowi siecią brata swego.
Àwọn olódodo sì ti kúrò ní ilẹ̀ náà, kò sì ṣí ẹnìkan tí ó ṣẹ́kù tí ó jọ olóòtítọ́; gbogbo wọn sì ń purọ́ ní dídúró nítorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀, olúkúlùkù wọ́n sì ń fi àwọ̀n de arákùnrin rẹ̀.
3 Co złego robią rękoma, chcą, aby to za dobre uszło; książę podatków żąda, a sędzia z datku sądzi, a kto możny jest, ten mówi przewrotność duszy swojej, i w gromadę ją plotą.
Ọwọ́ wọn méjèèjì ti múra tán láti ṣe búburú; àwọn alákòóso ń béèrè fún ẹ̀bùn, àwọn onídàájọ́ sì ń gba owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ alágbára sì ń pàṣẹ ohun tí wọ́n fẹ́, gbogbo wọn sì jùmọ̀ ń dìtẹ̀.
4 Najlepszy z nich jest jako oset, najszczerszy przechodzi ciernie; dzień stróżów twoich i nawiedzenia twego przychodzi; już nastanie powikłanie ich.
Ẹni tí ó sàn jùlọ nínú wọn sì dàbí ẹ̀gún, ẹni tí ó jẹ́ olódodo jùlọ burú ju ẹ̀gún ọgbà lọ. Ọjọ́ àwọn olùṣọ́ rẹ̀ ti dé, àti ọjọ́ tí Ọlọ́run bẹ̀ ọ́ wò. Nísinsin yìí ní àkókò ìdààmú wọn.
5 Nie wierzcie przyjacielowi, ani ufajcie wodzowi; przed tą, która leży na łonie twojem, strzeż drzwi ust swoich.
Ẹ má ṣe gba ọ̀rẹ́ kan gbọ́; ẹ má sì ṣe gbẹ́kẹ̀lé amọ̀nà kankan. Pa ìlẹ̀kùn ẹnu rẹ fún ẹni tí ó sùn ní oókan àyà rẹ.
6 Bo syn lekce waży ojca, a córka powstaje przeciwko matce swej, synowa przeciwko świekrze swej, a nieprzyjaciele każdego są domownicy jego.
Nítorí tí ọmọkùnrin kò bọ̀wọ̀ fún baba rẹ̀, ọmọbìnrin sì dìde sí ìyá rẹ̀, aya ọmọ sí ìyá ọkọ rẹ̀, ọ̀tá olúkúlùkù ni àwọn ará ilé rẹ̀.
7 Przetoż ja na Pana patrzyć będę, oczekiwać będę Boga zbawienia mego; Bóg mój wysłucha mię.
Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi ní ìwòye ní ìrètí sí Olúwa, èmi dúró de Ọlọ́run olùgbàlà mi; Ọlọ́run mi yóò sì tẹ́tí sí mi.
8 Nie wesel się ze mnie, nieprzyjaciółko moja! jeźlim upadła, powstanę; jeźli siedzę w ciemnościach, Pan jest światłością moją.
Má ṣe yọ̀ mí, ìwọ ọ̀tá mi. Bí mó bá ṣubú, èmi yóò dìde. Nígbà tí mo bá jókòó sínú òkùnkùn Olúwa yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ fún mi.
9 Gniew Pański poniosę: bom przeciwko niemu zgrzeszył, aż się wżdy zastawi o sprawę moję, a wykona sąd mój: wywiedzie mię na światło, ujrzę sprawiedliwość jego.
Nítorí èmi ti dẹ́ṣẹ̀ sí i, èmi yóò faradà ìbínú Olúwa, títí òun yóò ṣe gba ẹjọ́ mi rò, tí yóò sì ṣe ìdájọ́ mi. Òun yóò sì mú mi wá sínú ìmọ́lẹ̀; èmi yóò sì rí òdodo rẹ̀.
10 Ujrzy to nieprzyjaciółka moja, a wstyd okryje tę, która do mnie mówi: Gdzież jest Pan, Bóg twój? Oczy moje na nią patrzyć będą, gdy jako błoto na ulicach podeptana będzie.
Nígbà náà ni ọ̀tá mi yóò rí i ìtìjú yóò sì bo ẹni tí ó wí fún mi pé, “Níbo ni Olúwa Ọlọ́run rẹ wà?” Ojú mi yóò rí ìṣubú rẹ̀; nísinsin yìí ni yóò di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ bí ẹrẹ̀ òpópó.
11 Dnia onego, którego pobudowane będą parkany twoje, dnia onego, mówię, daleko się wyrok rozejdzie.
Ọjọ́ tí a ó mọ odi rẹ yóò dé, ọjọ́ náà ni àṣẹ yóò jìnnà réré.
12 Onegoż dnia przychodzić będą do ciebie i z Assyryi aż do miast obronnych, i od miast obronnych aż do rzeki, i od morza aż do morza, i od góry aż do góry.
Ní ọjọ́ náà àwọn ènìyàn yóò wá sọ́dọ̀ rẹ láti Asiria àti ìlú ńlá Ejibiti àní láti Ejibiti dé Eufurate láti Òkun dé Òkun àti láti òkè ńlá dé òkè ńlá.
13 Wszakże ta ziemia spustoszona będzie dla obywateli swoich, dla owocu wynalazków ich.
Ilẹ̀ náà yóò di ahoro fún àwọn olùgbé inú rẹ̀, nítorí èso ìwà wọn.
14 Paśże lud twój laską twoją, trzodę dziedzictwa twego, która osobno mieszka w lesie i w pośród pola; niech wypasą Basan i Galaad jako za dni starodawnych.
Fi ọ̀pá rẹ bọ́ àwọn ènìyàn, agbo ẹran ìní rẹ, èyí tí ó ń dágbé nínú igbó ní àárín Karmeli. Jẹ́ kí wọn jẹun ní Baṣani àti Gileadi bí ọjọ́ ìgbàanì.
15 Ukażę mu dziwne rzeczy, jako za dni, którycheś wyszedł z ziemi Egipskiej.
“Bí i ọjọ́ tí ó jáde kúrò ní Ejibiti wá, ni èmi yóò fi ohun ìyanu hàn án.”
16 Co widząc narody zawstydzą się nad wszystką mocą swoją, włożą rękę na usta, a uszy ich ogłuszeją
Orílẹ̀-èdè yóò rí i, ojú yóò sì tì wọ́n, nínú gbogbo agbára wọn. Wọn yóò fi ọwọ́ lé ẹnu wọn, etí wọn yóò sì di.
17 Proch jako wąż lizać będą, jako gadziny ziemskie ruszą się z lochów swoich, do Pana, Boga naszego, z strachem pobieżą, i bać się ciebie będą.
Wọn yóò lá erùpẹ̀ bí ejò, wọn yóò sì jáde kúrò nínú ihò wọn bí ekòló. Wọn yóò bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, wọn yóò sì bẹ̀rù nítorí rẹ̀.
18 Któryż Bóg jest podobny tobie? Któryby nieprawość odpuszczał, i mijał przestępstwa ostatków dziedzictwa swego, któryby nie zatrzymywał na wieki gniewu swego, przeto, że się kocha w miłosierdziu.
Ta ni Ọlọ́run bí rẹ̀, ẹni tí ó dárí ẹ̀ṣẹ̀ jì, tí ó sì fojú fo ìrékọjá èyí tókù ìní rẹ̀? Kì í dúró nínú ìbínú rẹ̀ láéláé nítorí òun ní inú dídùn sí àánú.
19 Nawróci się, a zmiłuje się nad nami; zatłumi nieprawości nasze i wrzuci w głębokość morską wszystkie grzechy nasze.
Òun yóò tún padà yọ́nú sí wa; òun yóò tẹ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa mọ́lẹ̀, yóò sì fa gbogbo àìṣedéédéé wa sínú ibú Òkun.
20 Pokażesz się Jakóbowi prawdomównym, a miłosiernym Abrahamowi, jakoś przysiągł ojcom naszym ode dni dawnych.
Ìwọ yóò fi òtítọ́ hàn sí Jakọbu ìwọ yóò sì fi àánú hàn sí Abrahamu, bí ìwọ ṣe búra fún àwọn baba wa láti ọjọ́ ìgbàanì.