< Micheasza 4 >

1 Ale się stanie w ostateczne dni, że utwierdzona będzie góra domu Pańskiego na wierzchu gór, i wywyższona nad pagórki, a narody się do niej zbiegać będą.
Ní ọjọ́ ìkẹyìn a ó fi òkè ilé Olúwa lélẹ̀ lórí àwọn òkè ńlá, a ó sì gbé e ga ju àwọn òkè kéékèèké lọ, àwọn ènìyàn yóò sì máa wọ̀ sínú rẹ̀.
2 I pójdzie wiele narodów, mówiąc: Pójdźcie, a wstąpmy na górę Pańską, to jest do domu Boga Jakóbowego, a będzie nas nauczał dróg swoich, i będziemy chodzili ścieszkami jego; bo zakon z Syonu wyjdzie, a słowo Pańskie z Jeruzalemu.
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè yóò wá, wọn yóò sì wí pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á gòkè ńlá Olúwa, àti sí ilé Ọlọ́run Jakọbu. Òun yóò sì kọ́ wa ní ọ̀nà rẹ̀, kí àwa kí ó lè rìn ní ọ̀nà rẹ̀.” Òfin yóò jáde láti Sioni wá, àti ọ̀rọ̀ Olúwa láti Jerusalẹmu.
3 Onci sądzić będzie między wieloma narodami, a karać będzie narody mocne na długie czasy; i przekują miecze swe na lemiesze, a oszczepy swe na kosy: nie podniesie miecza naród przeciwko narodowi, ani się więcej ćwiczyć będą do boju
Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ láàrín ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, yóò sì parí aáwọ̀ fún orílẹ̀-èdè alágbára jíjìn réré. Wọn yóò sì fi idà wọn rọ ohun èlò ìtulẹ̀ àti ọ̀kọ̀ wọn di dòjé orílẹ̀-èdè kì yóò gbé idà sókè sí orílẹ̀-èdè mọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kì yóò kọ́ ogun jíjà mọ́.
4 Ale każdy będzie siedział pod winną macicą swoją, i pod figowem drzewem swojem, a nie będzie nikt, coby ich przestraszył; bo to usta Pana zastępów mówiły.
Ṣùgbọ́n olúkúlùkù yóò jókòó lábẹ́ àjàrà rẹ̀ àti lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀, ẹnìkan kì yóò sì dẹ́rùbà wọ́n, nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti sọ̀rọ̀.
5 Bo wszystkie narody chodzić będą, każdy w imieniu boga swego; ale my chodzić będziemy w imieniu Pana, Boga naszego, na wieki wieków.
Gbogbo àwọn ènìyàn ń rìn, olúkúlùkù ni orúkọ ọlọ́run tirẹ̀, ṣùgbọ́n àwa yóò máa rìn ní orúkọ Olúwa. Ọlọ́run wa láé àti láéláé.
6 Dnia onego, mówi Pan, zgromadzę chromą i wygnaną zbiorę, i onę, którejm był źle uczynił:
“Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí, “Èmi yóò kó àwọn arọ jọ; èmi yóò sì ṣà àwọn tí a lé kúrò ní ìlú jọ, àti àwọn ẹni tí èmi ti pọ́n lójú.
7 A dam tej chromej potomstwo, a precz wygnanej naród możny; i będzie Pan królował nad nimi na górze Syon odtąd aż na wieki.
Èmi yóò dá àwọn arọ sí fún èyí tókù, èmi yóò sì sọ àwọn tí a lé kúrò ní ìlú di orílẹ̀-èdè alágbára. Olúwa yóò sì jẹ ọba lórí wọn ní òkè ńlá Sioni láti ìsinsin yìí lọ àti títí láéláé.
8 A ty, wieżo trzody, baszto córki Syońskiej! wiedz, że aż do ciebie przyjdzie; przyjdzie mówię, pierwsze państwo, i królestwo córki Jeruzalemskiej.
Ní ti ìwọ, ilé ìṣọ́ agbo àgùntàn, odi alágbára ọmọbìnrin Sioni, a ó mú ìjọba ìṣáájú padà bọ̀ sípò fún un yín; ìjọba yóò sì wà sí ọ̀dọ̀ ọmọbìnrin Jerusalẹmu.”
9 Czemuż teraz tak bardzo krzyczysz? Izali króla niemasz w tobie? Izali radca twój zginął, że cię zjął ból, jako rodzącą?
Kí ni ìwọ ha ń kígbe sókè sí nísinsin yìí? Ǹjẹ́ ìwọ kò ní ọba bí? Àwọn ìgbìmọ̀ rẹ ṣègbé bí? Nítorí ìrora ti dì ọ́ mú bí obìnrin tí ń rọbí.
10 Bolej a stękaj, córko Syońska? jako rodząca; bo już wyjdziesz z miasta, i będziesz mieszkała w polu, a przyjdziesz aż do Babilonu; tam będziesz wybawiona, tam cię Pan odkupi z rąk nieprzyjaciół twoich.
Máa yí síyìn-ín sọ́hùn-ún nínú ìrora, ìwọ obìnrin Sioni, bí ẹni tí ń rọbí, nítorí nísinsin yìí ìwọ yóò jáde lọ kúrò ní ìlú, ìwọ yóò sì máa gbé inú igbó. Ìwọ yóò lọ sí Babeli; níbẹ̀ ni ìwọ yóò sì ti rí ìgbàlà. Níbẹ̀ ni Olúwa yóò ti rà ọ́ padà kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá rẹ.
11 A choć się teraz zebrało przeciwko tobie wiele narodów, które mówią: Niech będzie splugawiony Syon, a niech na to patrzy oko nasze,
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ọ̀pọ̀lọpọ̀ Orílẹ̀-èdè kó ara wọn jọ sí ọ. Wọ́n sì wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a sọ ọ́ di àìmọ́, ẹ jẹ́ kí ojú wa kí ó wo Sioni!”
12 Wszakże one nie znają myśli Pańskich, ani rozumieją rady jego, iż je zgromadza jako snopy na bojewisko.
Ṣùgbọ́n wọn kò mọ èrò inú Olúwa; bẹ́ẹ̀ ni òye ìmọ̀ rẹ̀ kò yé wọn, nítorí ó ti kó wọn jọ bí i ìtí sínú ìpakà.
13 Wstańże, a młóć, córko Syońska! bo róg twój uczynię żelazny, a kopyta twoje uczynię miedziane, i pokruszysz wiele narodów; i poświęcę Panu korzyści ich, a majętności ich Panu wszystkiej ziemi.
“Dìde, kí ó sì máa pa ọkà ìwọ ọmọbìnrin Sioni, nítorí èmi yóò sọ ìwo rẹ̀ di irin, èmi yóò sì sọ pátákò rẹ̀ di idẹ ìwọ yóò run ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè pátápátá.” Èmi yóò sì ya èrè wọn sọ́tọ̀ fún Olúwa àti ọrọ̀ wọn sí Olúwa gbogbo ayé.

< Micheasza 4 >