< Mateusza 15 >
1 Tedy przystąpili do Jezusa z Jeruzalemu nauczeni w Piśmie i Faryzeuszowie, mówiąc:
Nígbà náà ní àwọn Farisi àti àwọn olùkọ́ òfin tọ Jesu wá láti Jerusalẹmu,
2 Czemu uczniowie twoi przestępują ustawę starszych? albowiem nie umywają rąk swych, gdy mają jeść chleb.
wọn béèrè pé, “Èéṣe tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ fi ń rú òfin àtayébáyé àwọn alàgbà? Nítorí tí wọn kò wẹ ọwọ́ wọn kí wọ́n tó jẹun!”
3 A on odpowiadając, rzekł im: Czemuż i wy przestępujecie przykazanie Boże dla ustawy waszej?
Jesu sì dá wọn lóhùn pé, “Èéha ṣe tí ẹ̀yin fi rú òfin Ọlọ́run, nítorí àṣà yín?
4 Albowiem Bóg przykazał, mówiąc: Czcij ojca twego i matkę; i kto by złorzeczył ojcu albo matce, śmiercią niechaj umrze.
Nítorí Ọlọ́run wí pé, ‘Bọ̀wọ̀ fún Baba òun ìyá rẹ,’ àti pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ ọ̀rọ̀-òdì sí baba tàbí ìyá rẹ̀, ní láti kú.’
5 Ale wy powiadacie: Kto by rzekł ojcu albo matce: Dar, którykolwiek jest ode mnie, tobie pożyteczny będzie; a nie uczciłby ojca swego albo matki swojej, bez winy będzie.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin wí pé, ẹnikẹ́ni tí ó bá wí fún baba tàbí ìyá rẹ̀ pé, ‘Ẹ̀bùn fún Ọlọ́run ni ohunkóhun tí ìwọ ìbá fi jèrè lára mi,’
6 I wzruszyliście przykazania Boże dla ustawy waszej.
tí Òun kò sì bọ̀wọ̀ fún baba tàbí ìyá rẹ̀, ó bọ́; bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin sọ òfin Ọlọ́run di asán nípa àṣà yín.
7 Obłudnicy! dobrze o was prorokował Izajasz, mówiąc:
Ẹ̀yin àgàbàgebè, ní òtítọ́ ni Wòlíì Isaiah sọtẹ́lẹ̀ nípa yín wí pé:
8 Lud ten przybliża się do mnie usty swemi, i wargami czci mię; ale serce ich daleko jest ode mnie.
“‘Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ń fi ẹnu lásán bu ọlá fún mi, ṣùgbọ́n ọkàn wọn jìnnà réré sí mi.
9 Lecz próżno mię czczą, nauczając nauk, które są przykazania ludzkie.
Lásán ni ìsìn wọn; nítorí pé wọ́n ń fi òfin ènìyàn kọ́ ni ní ẹ̀kọ́.’”
10 A zawoławszy do siebie ludu, rzekł im: Słuchajcie, a rozumiejcie.
Jesu pe ọ̀pọ̀ ènìyàn wá sí ọ̀dọ̀ rẹ, ó wí pé, “Ẹ tẹ́tí, ẹ sì jẹ́ kí nǹkan tí mo sọ yé yín.
11 Nie to, co wchodzi w usta, pokala człowieka; ale co wychodzi z ust, to pokala człowieka.
Ènìyàn kò di aláìmọ́ nípa ohun tí ó wọ ẹnu ènìyàn, ṣùgbọ́n èyí tí ó ti ẹnu jáde wá ni ó sọ ní di aláìmọ́.”
12 Tedy przystąpiwszy uczniowie jego, rzekli mu: Wiesz, iż Faryzeuszowie, usłyszawszy tę mowę, zgorszyli się?
Nígbà náà, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ tọ̀ ọ́ wá, wọ́n wí fún un pé, “Ǹjẹ́ ìwọ mọ̀ pé inú bí àwọn Farisi lẹ́yìn tí wọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ tí ó sọ yìí?”
13 A on odpowiadając rzekł: Wszelki szczep, którego nie szczepił Ojciec mój niebieski, wykorzeniony będzie.
Jesu dá wọn lóhùn pé, “Gbogbo igi tí Baba mi ti ń bẹ ni ọ̀run kò bá gbìn ni á ó fàtu tigbòǹgbò tigbòǹgbò,
14 Zaniechajcie ich; ślepi są wodzowie ślepych, a ślepy jeźliby ślepego prowadził, obadwa w dół wpadną.
ẹ fi wọ́n sílẹ̀; afọ́jú tí ń fi ọ̀nà han afọ́jú ni wọ́n. Bí afọ́jú bá sì ń fi ọ̀nà han afọ́jú, àwọn méjèèjì ni yóò jìn sí kòtò.”
15 A odpowiadając Piotr, rzekł mu: Wyłóż nam to podobieństwo.
Peteru wí, “Ṣe àlàyé òwe yìí fún wa.”
16 I rzekł Jezus: Jeszczeż i wy bezrozumni jesteście?
Jesu béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéha ṣe tí ìwọ fi jẹ́ aláìmòye síbẹ̀”?
17 Jeszczeż nie rozumiecie, iż wszystko, co wchodzi w usta, w brzuch idzie, i do wychodu bywa wyrzucono?
“Ẹyin kò mọ̀ pé ohunkóhun tí ó gba ẹnu wọlé, yóò gba ti ọ̀nà oúnjẹ lọ, a yóò sì yà á jáde?
18 Ale co z ust pochodzi, z serca wychodzi, a toć pokala człowieka.
Ṣùgbọ́n ohun tí a ń sọ jáde láti ẹnu, inú ọkàn ni ó ti ń wá, èyí sì ni ó ń sọ ènìyàn di aláìmọ́.
19 Albowiem z serca wychodzą złe myśli, mężobójstwa, cudzołóstwa, wszeteczeństwa, złodziejstwa, fałszywe świadectwa, bluźnierstwa.
Ṣùgbọ́n láti ọkàn ni èrò búburú ti wá, bí ìpànìyàn, panṣágà, àgbèrè, olè jíjà, irọ́ àti ọ̀rọ̀ ìbàjẹ́.
20 Toć jest, co pokala człowieka: ale jeść nieumytemi rękoma, toć nie pokala człowieka.
Àwọn tí a dárúkọ wọ̀nyí ni ó ń sọ ènìyàn di aláìmọ́. Ṣùgbọ́n láti jẹun láì wẹ ọwọ́, kò lè sọ ènìyàn di aláìmọ́.”
21 A wyszedłszy Jezus stamtąd, ustąpił w strony Tyru i Sydonu.
Jesu sì ti ibẹ̀ kúrò lọ sí Tire àti Sidoni.
22 A oto niewiasta Chananejska z onych granic wyszedłszy, wołała, mówiąc do niego: Zmiłuj się nade mną Panie, synu Dawidowy! córka moja ciężko bywa od dyjabła dręczona.
Obìnrin kan láti Kenaani, tí ó ń gbé ibẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀. Ó ń bẹ̀bẹ̀, ó sì kígbe pé, “Olúwa, ọmọ Dafidi, ṣàánú fún mi; ọmọbìnrin mi ní ẹ̀mí èṣù ti ń dá a lóró gidigidi.”
23 A on jej nie odpowiedział i słowa. Tedy przystąpiwszy uczniowie jego, prosili go, mówiąc: Odpraw ją, boć woła za nami.
Ṣùgbọ́n Jesu kò fún un ní ìdáhùn, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì gbà á níyànjú pé, “Lé obìnrin náà lọ, nítorí ó ń kígbe tọ̀ wá lẹ́yìn.”
24 A on odpowiadając rzekł: Nie jestem posłany, tylko do owiec, które zginęły z domu Izraelskiego.
Ó dáhùn pé, “Àgùntàn ilẹ̀ Israẹli tí ó nù nìkan ni a rán mi sí.”
25 Lecz ona przystąpiwszy, pokłoniła mu się, mówiąc: Panie, ratuj mię!
Obìnrin náà wá, ó wólẹ̀ níwájú rẹ̀, ó bẹ̀bẹ̀ sí i pé, “Olúwa ṣàánú fún mi.”
26 A on odpowiadając rzekł: Niedobra jest brać chleb dziecinny, a miotać szczeniętom.
Ó sì dáhùn wí pé, “Kò tọ́ kí a gbé oúnjẹ àwọn ọmọ fún àwọn ajá.”
27 A ona rzekła: Tak jest, Panie! a wszakże i szczenięta jedzą odrobiny, które padają z stołu panów ich.
Obìnrin náà sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, síbẹ̀síbẹ̀ àwọn ajá a máa jẹ èrúnrún tí ó ti orí tábìlì olówó wọn bọ́ sílẹ̀.”
28 Tedy odpowiadając Jezus rzekł jej: O niewiasto! wielka jest wiara twoja; niechaj ci się stanie, jako chcesz. I uzdrowiona jest córka jej od onejże godziny.
Jesu sì sọ fún obìnrin náà pé, “Ìgbàgbọ́ ńlá ni tìrẹ! A sì ti dáhùn ìbéèrè rẹ.” A sì mú ọmọbìnrin rẹ̀ láradá ní wákàtí kan náà.
29 A Jezus poszedłszy stamtąd, przyszedł nad morze Galilejskie, a wstąpiwszy na górę, siedział tam.
Jesu ti ibẹ̀ lọ sí Òkun Galili. Ó gun orí òkè, o sì jókòó níbẹ̀.
30 I przyszedł do niego wielki lud, mając z sobą chrome, ślepe, nieme, ułomne i inszych wiele, i kładli je u nóg Jezusowych, i uzdrawiał je,
Ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn sì tọ̀ ọ́ wá, àti àwọn arọ, afọ́jú, amúnkùn ún, odi àti ọ̀pọ̀ àwọn aláìsàn mìíràn. Wọ́n gbé wọn kalẹ̀ lẹ́sẹ̀ Jesu. Òun sì mú gbogbo wọn láradá.
31 Tak iż się on lud dziwował, widząc, że niemi mówią, ułomni uzdrowieni są, chromi chodzą, a ślepi widzą; i wielbili Boga Izraelskiego.
Ẹnu ya ọ̀pọ̀ ènìyàn nígbà tí wọ́n rí àwọn odi tó ń sọ̀rọ̀, amúnkùn ún tó di alára pípé, arọ tí ó ń rìn àti àwọn afọ́jú tí ó ríran. Wọ́n sì ń fi ìyìn fún Ọlọ́run Israẹli.
32 Lecz Jezus zwoławszy uczniów swoich, rzekł: Żal mi tego ludu; albowiem już trzy dni przy mnie trwają, a nie mają, co by jedli, a nie chcę ich rozpuścić głodnych, by snać nie pomdleli na drodze.
Jesu pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sọ́dọ̀, ó wí pé, “Àánú àwọn ènìyàn wọ̀nyí ṣe mí; nítorí wọ́n ti wà níhìn-ín pẹ̀lú mi fún ọjọ́ mẹ́ta gbáko báyìí. Wọn kò sì tún ní oúnjẹ mọ́. Èmi kò fẹ́ kí wọn padà lébi, nítorí òyì lè kọ́ wọn lójú ọ̀nà.”
33 Tedy mu rzekli uczniowie jego: Skądże byśmy wzięli tak wiele chleba na tej puszczy, abyśmy tak wielki lud nasycili?
Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn sì dá a lóhùn pé, “Níbo ni àwa yóò ti rí oúnjẹ ní ijù níhìn-ín yìí láti fi bọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn yìí?”
34 I rzekł im Jezus: Wieleż macie chlebów? A oni rzekli: Siedm, i trochę rybek.
Jesu sì béèrè pé, “Ìṣù àkàrà mélòó ni ẹ̀yin ní?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Àwa ní ìṣù àkàrà méje pẹ̀lú àwọn ẹja wẹ́wẹ́ díẹ̀.”
35 Tedy rozkazał ludowi, aby siedli na ziemi.
Jesu sì sọ fún gbogbo ènìyàn kí wọn jókòó lórí ilẹ̀.
36 A wziąwszy one siedm chlebów i one ryby, uczyniwszy dzięki, łamał i dał uczniom swoim, a uczniowie ludowi.
Òun sì mú ìṣù àkàrà méje náà àti ẹja náà. Ó sì fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run, ó bù wọ́n sì wẹ́wẹ́, ó sì fi wọ́n fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀. Wọ́n sì pín in fún àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn náà.
37 I jedli wszyscy i nasyceni są, i zebrali, co zbyło ułomków, siedm koszów pełnych.
Gbogbo wọn jẹ, wọ́n sì yó. Lẹ́yìn náà, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn sì ṣa èyí tókù, ẹ̀kún agbọ̀n méje ni èyí tó ṣẹ́kù jẹ́.
38 A było tych, którzy jedli, cztery tysiące mężów, oprócz niewiast i dziatek.
Gbogbo wọn sì jẹ́ ẹgbàajì ọkùnrin láì kan àwọn obìnrin àti ọmọdé.
39 Tedy rozpuściwszy lud, wstąpił w łódź, i przyszedł na granice Magdalańskie.
Lẹ́yìn náà, Jesu rán àwọn ènìyàn náà lọ sí ilé wọn, ó sì bọ́ sínú ọkọ̀, ó rékọjá lọ sí ẹkùn Magadani.