< Malachiasza 1 >

1 Brzemię słowa Pańskiego przeciwko Izraelowi, przez Malachyjasza.
Ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀: ọ̀rọ̀ Olúwa sí Israẹli láti ẹnu Malaki.
2 Umiłowałem was, mówi Pan, a wy mówicie: W czemżeś nas umiłował? Izali Ezaw nie był bratem Jakóbowi? mówi Pan; wszakżem umiłował Jakóba,
“Èmí ti fẹ́ ẹ yín,” ni Olúwa wí. “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni ìwọ ṣe fẹ́ wa?’ “Esau kì í ha ṣe arákùnrin Jakọbu bí?” ni Olúwa wí. “Síbẹ̀ èmi fẹ́ràn Jakọbu,
3 A Ezawa miałem w nienawiści, i podałem góry jego na spustoszenie, a dziedzictwo jego smokom na pustyni.
ṣùgbọ́n Esau ni mo kórìíra, mo ti sọ àwọn òkè ńlá rẹ̀ di aṣálẹ̀, mo sì fi ìní rẹ̀ fún àwọn akátá aginjù.”
4 Jeźliby rzekła ziemia Edomska: Staliśmy się ubogimi, ale wrócimy się, i pobudujemy miejsca popustoszone, tedy tak mówi Pan zastępów: Niechaj oni budują, a Ja rozwalę; i nazwię ich granicą niepobożności i ludem, który sobie zbrzydził Pan aż na wiek i.
Edomu lè wí pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a run wá, àwa yóò padà wá, a ó sì tún ibùgbé náà kọ́.” Ṣùgbọ́n èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: “Àwọn lè kọ́, ṣùgbọ́n èmi yóò wó palẹ̀. Wọn yóò sì pè wọ́n ní ilẹ̀ búburú, àwọn ènìyàn tí wọ́n máa ń wà ní ìbínú Olúwa.
5 To oglądają oczy wasze, a wy rzeczecie: Niech będzie Pan uwielbiony w granicach Izraelskich.
Ẹ̀yin yóò sì fi ojú yín rí i, ẹ̀yin yóò sì wí pé, ‘Títóbi ni Olúwa, títóbi rẹ̀ tayọ kọjá agbègbè Israẹli.’
6 Syn ma w uczciwości ojca, a sługa pana swego; jaźlim tedy Ja ojcem, gdzież jest cześć moja? i jeźliżem Ja panem, gdzież jest bojaźń moja? mówi Pan zastępów wam, o kapłani! którzy lekce poważacie imię moje, a wszakże mówicie: W czemże lekce poważamy imię twoje?
“Ọmọ a máa bu ọ̀wọ̀ fún baba rẹ̀, ọmọ ọ̀dọ̀ a sì máa bu ọlá fún olúwa rẹ̀. Ǹjẹ́ bí èmí bá jẹ́ baba, ọlá tí ó tọ́ sí mi ha dà? Bí èmi bá sì jẹ́ olúwa, ẹ̀rù tí ó tọ́ sí mi dà?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Ẹ̀yin ni, ẹ̀yin àlùfáà, ni ẹ ń gan orúkọ mi. “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni àwa ṣe gan orúkọ rẹ?’
7 Którzy przynosząc na ołtarz mój ofiarę splugawioną, mówicie: Czemżeśmy cię splugawili? Tem, że mówicie: Stół Pański splugawiony jest.
“Ẹ̀yin gbé oúnjẹ àìmọ́ sí orí pẹpẹ mi. “Ẹ̀yin sì tún béèrè pé, ‘Báwo ni àwa ṣe ṣe àìmọ́ sí ọ?’ “Nípa sísọ pé tábìlì Olúwa di ẹ̀gàn.
8 Bo gdy przywodzicie, co ślepego jest, na ofiarę, izali to nie zła rzecz? I gdy przywodzicie chrome i chore, izali to nie zła rzecz? Ofiaruj to jedno książęciu twemu, obaczysz, jeżeli mu się to podobać będzie, a przyjmieli twarz twoję, mówi Pan zas tępów.
Nígbà tí ẹ̀yin mú afọ́jú ẹran wá fún ìrúbọ, ṣé èyí kò ha burú bí? Nígbà tí ẹ̀yin fi amúnkùn ún àti aláìsàn ẹran rú ẹbọ, ṣé èyí kò ha burú gidigidi bí? Ẹ dán an wò, ẹ fi wọ́n rú ẹbọ sí àwọn baálẹ̀ yín! Ṣé inú rẹ̀ yóò dùn sí yín? Ṣé yóò gbà yín?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
9 Przetoż teraz błagajcie, proszę, oblicze Boże, aby się zmiłował nad nami; ale póki się to dzieje z ręki waszej, izali przyjmie oblicze którego z was? mówi Pan zastępów.
“Ní ìsinsin yìí, ẹ bẹ Ọlọ́run kí ó ṣàánú fún wa. Ṣùgbọ́n pẹ̀lú irú àwọn ẹbọ wọ̀nyí láti ọwọ́ yín wá, ṣé yóò gbà yín?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
10 Owszem, kto jest między wami, aby zawarł drzwi, albo darmo zapalił na ołtarzu moim? Nie mam chęci do was, mówi Pan zastępów, i ofiary nie przyjmię z ręki waszej.
“Hó ò! Ẹnìkan ìbá jẹ́ wà láàrín yín ti yóò sé ìlẹ̀kùn tẹmpili, pé kí ẹ má ba à ṣe dá iná asán lórí pẹpẹ mi mọ́! Èmi kò ní inú dídùn sí i yín,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò gba ọrẹ kan lọ́wọ́ yín.
11 Albowiem od wschodu słońca aż do zachodu jego wielkie jest imię moje między narodami, a na wszelkiem miejscu przyniesione będzie kadzenie imieniowi memu i ofiara czysta; wielkie zaiste imię moje będzie między narodami, mówi Pan zastępów.
Orúkọ mi yóò tóbi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, láti ìlà-oòrùn títí ó sì fi dé ìwọ̀-oòrùn. Ní ibi gbogbo ni a ó ti mú tùràrí àti ọrẹ mímọ́ wá fún orúkọ mi, nítorí orúkọ mi tóbi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
12 Lecz wy plugawicie je, gdy mówicie: Stół Pański splugawiony jest; a co nań kładą, jest wzgardzonym pokarmem.
“Nítorí ẹ̀yin ti sọ ọ́ di àìmọ́, nínú èyí tí ẹ wí pé, ‘Tábìlì Olúwa di àìmọ́ àti èso rẹ̀,’ àní oúnjẹ rẹ̀ ni ohun ẹ̀gàn.
13 Mówicie też: O jakaż to praca! choćbyście to zdmuchnąć mogli mówi Pan zastępów; bo przynosicie to, co jest wydartego, i chromego i schorzałego, a przynosicie to na ofiarę: izali to przyjmę z ręki waszej? mówi Pan.
Ẹ̀yin wí pẹ̀lú pé, ‘Wò ó, irú àjàgà kín ni èyí!’ Ẹ̀yin sì yínmú sí i,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Nígbà tí ẹ̀yin sì mú èyí tí ó fi ara pa, arọ àti ọlọkùnrùn ẹran tí ẹ sì fi rú ẹbọ, Èmi o ha gba èyí lọ́wọ́ yín?” ni Olúwa wí.
14 I owszem przeklęty jest zdradliwy, który mając w trzodzie swej samca, a przecię czyniąc śluby ofiaruje Panu to, co jest ułomnego; bom Ja królem wielkim mówi Pan zastępów, a imię moje straszne jest między narody.
“Ṣùgbọ́n ègún ni fún ẹlẹ́tàn náà, tí ó ni akọ nínú ọ̀wọ́ ẹran rẹ̀, tí ó sì ṣe ìlérí láti fi lélẹ̀ tí ó sì fi ẹran tó lábùkù rú ẹbọ sí Olúwa; nítorí ọba ńlá ni Èmi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “ẹ̀rù sì ni orúkọ mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.

< Malachiasza 1 >