< Łukasza 8 >
1 I stało się potem, że on chodził po miastach i po miasteczkach każąc i opowiadając królestwo Boże, a oni dwunastu byli z nim,
Ó sì ṣe lẹ́yìn náà, tí ó ń lá gbogbo ìlú àti ìletò kọjá lọ, ó ń wàásù, ó ń ròyìn ayọ̀ ìjọba Ọlọ́run. Àwọn méjìlá sì ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀,
2 I niektóre niewiasty, które był uzdrowił od duchów złych i od niemocy ich, jako Maryja, którą zwano Magdaleną, z której było siedm dyjabłów wyszło;
àti àwọn obìnrin kan, tí a ti mú láradá kúrò lọ́wọ́ àwọn ẹ̀mí búburú àti nínú àìlera wọn, Maria tí a ń pè ní Magdalene, lára ẹni tí ẹ̀mí èṣù méje ti jáde kúrò.
3 I Joanna, żona Chuzego, urzędnika Herodowego, i Zuzanna, i inszych wiele, które mu służyły z majętności swoich.
Àti Joanna aya Kusa tí í ṣe ìríjú Herodu, àti Susana, àti àwọn púpọ̀ mìíràn, tí wọ́n ń ṣe ìránṣẹ́ fún un nínú ohun ìní wọn.
4 A gdy się schodził wielki lud, i z różnych miast garnęli się do niego, rzekł przez podobieństwo;
Nígbà tí ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn péjọpọ̀, àwọn ènìyàn láti ìlú gbogbo sì tọ̀ ọ́ wá, ó fi òwe bá wọn sọ̀rọ̀ pé,
5 Wyszedł rozsiewca, aby rozsiewał nasienie swoje; a gdy on rozsiewał, tedy jedno padło podle drogi i podeptane jest, a ptaki niebieskie podziobały je.
“Afúnrúgbìn kan jáde lọ láti fún irúgbìn rẹ̀: bí ó sì ti ń fúnrúgbìn, díẹ̀ bọ́ sí ẹ̀bá ọ̀nà, a sì tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ṣà á jẹ.
6 A drugie padło na opokę, a gdy wzeszło, uschło, przeto iż nie miało wilgotności.
Òmíràn sì bọ́ sórí àpáta; bí ó sì ti hù jáde, ó gbẹ nítorí tí kò ní omi.
7 A drugie padło między ciernie; ale ciernie wespół z niem wzrosły, i zadusiły je.
Òmíràn sì bọ́ sínú ẹ̀gún; ẹ̀gún sì dàgbà pẹ̀lú rẹ̀ sókè, ó sì fún un pa.
8 A drugie padło na ziemię dobrą, a gdy wzeszło, przyniosło pożytek stokrotny. To mówiąc wołał: Kto ma uszy ku słuchaniu, niechaj słucha!
Òmíràn sì bọ́ sí ilẹ̀ rere, ó sì hù sókè, ó sì so èso ọ̀rọ̀ọ̀rún ju èyí ti a gbin lọ.” Nígbà tí ó sì wí nǹkan wọ̀nyí tán, ó pariwo sókè pé, “Ẹni tí ó bá ní etí láti fi gbọ́, kí ó gbọ́!”
9 I pytali go uczniowie jego, mówiąc: Co by to było za podobieństwo?
Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì bi í léèrè, pé, “Kí ni a lè mọ òwe yìí sí?”
10 A on im rzekł: Wam dano wiedzieć tajemnicę królestwa Bożego; ale innym w podobieństwach, aby widząc nie widzieli, a słysząc nie rozumieli.
Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ni a fi fún láti mọ ohun ìjìnlẹ̀ ìjọba Ọlọ́run; ṣùgbọ́n fún àwọn ẹlòmíràn wọn yóò jẹ́ òwe, pé ní rí rí, “‘kí wọn má ba à rí, àti ní gbígbọ́ kí ó má lè yé wọn.’
11 A to podobieństwo takie jest: nasienie jest słowo Boże.
“Ǹjẹ́ òwe náà ni èyí: irúgbìn ni ọ̀rọ̀ Ọlọ́run.
12 A którzy podle drogi, ci są, którzy słuchają, zatem przychodzi dyjabeł, i wybiera słowo z serca ich, aby uwierzywszy, nie byli zbawieni.
Àwọn ti ẹ̀bá ọ̀nà ni àwọn tí ó gbọ́ nígbà náà ni èṣù wá ó sì mú ọ̀rọ̀ náà kúrò ní ọkàn wọn, kí wọn má ba à gbàgbọ́, kí a sì gbà wọ́n là.
13 A którzy na opoce, ci są, którzy gdy słuchają, z radością słowo przyjmują, ale ci korzenia nie mają, ci do czasu wierzą, a czasu pokusy odstępują.
Àwọn ti orí àpáta ni àwọn, tí wọ́n gbọ́, wọ́n fi ayọ̀ gba ọ̀rọ̀ náà, àwọn wọ̀nyí kò sì ní gbòǹgbò, wọ́n á gbàgbọ́ fún sá à díẹ̀; nígbà ìdánwò, wọn á padà sẹ́yìn.
14 A które padło między ciernie, ci są, którzy słuchają słowa: ale odszedłszy, od pieczołowania i bogactw, i rozkoszy żywota bywają zaduszeni, i nie przynoszą pożytku.
Àwọn tí ó bọ́ sínú ẹ̀gún ni àwọn, tí wọ́n gbọ́ tán, wọ́n ti n lọ, wọn a sì fi ìtọ́jú àti ọrọ̀ àti ìrora ayé fún un pa, wọn kò sì lè so èso àsogbó.
15 Ale które padło na ziemię dobrą, ci są, którzy w sercu uprzejmem i dobrem słyszane słowo zachowują, i owoc przynoszą w cierpliwości.
Ṣùgbọ́n ti ilẹ̀ rere ni àwọn tí wọ́n fi ọkàn òtítọ́ àti rere gbọ́ ọ̀rọ̀ náà, wọ́n dìímú ṣinṣin, wọ́n sì fi sùúrù so èso.
16 A żaden zapaliwszy świecę, nie nakrywa jej naczyniem, ani jej kładzie pod łoże, ale ją stawia na świeczniku, aby ci, którzy wchodzą, widzieli światło.
“Kò sí ẹnikẹ́ni, nígbà tí ó bá tán fìtílà tan, tí yóò fi ohun èlò bò ó mọ́lẹ̀, tàbí tí yóò gbé e sábẹ́ àkéte; bí kò ṣe kí ó gbé e ka orí ọ̀pá fìtílà, kí àwọn tí ń wọ ilé lè rí ìmọ́lẹ̀.
17 Bo nie masz nic tajemnego, co by nie miało być objawiono; i nie masz nic skrytego, czego by się nie dowiedziano, i co by na jaw nie wyszło.
Nítorí kò sí ohun tí ó fi ara sin, tí a kì yóò fihàn, tàbí ohun tí a fi pamọ́, ti a kì yóò sì mọ̀ kí ó sì yọ sí gbangba.
18 Przetoż patrzcie, jako słuchacie: albowiem kto ma, temu będzie dane, a kto nie ma, i to, co mniema, że ma, będzie odjęte od niego.
Ǹjẹ́ kí ẹ̀yin máa kíyèsára bí ẹ̀yin ti ń gbọ́: nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá ní, lọ́wọ́ rẹ̀ ni a ó sì gba èyí tí ó ṣe bí òun ní.”
19 Tedy przyszli do niego matka i bracia jego; ale do niego przystąpić nie mogli dla ludu.
Nígbà náà ní ìyá rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ tọ̀ ọ́ wá, wọn kò sì lè súnmọ́ ọn nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn.
20 I dano mu znać, mówiąc: Matka twoja i bracia twoi stoją przed domem, chcąc cię widzieć.
Wọ́n sì wí fún un pé, “Ìyá rẹ àti àwọn arákùnrin rẹ dúró lóde, wọn fẹ́ rí ọ.”
21 A on odpowiadając, rzekł do nich: Matka moja i bracia moi są ci, którzy słowa Bożego słuchają i czynią je.
Ó sì dáhùn wí fún wọn pé, “Ìyá mi àti àwọn arákùnrin mi ni àwọn wọ̀nyí tí wọ́n ń gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, tí wọ́n sì ń ṣe é.”
22 I stało się dnia jednego, że on wstąpił w łódź i uczniowie jego, i rzekł do nich: Przeprawmy się na drugą stronę jeziora. I puścili się.
Ní ọjọ́ kan, ó sì wọ ọkọ̀ ojú omi kan lọ òun pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀. O sì wí fún wọn pé, “Ẹ jẹ́ kí a rékọjá lọ sí ìhà kejì adágún.” Wọ́n sì ṣíkọ̀ láti lọ.
23 A gdy płynęli, usnął. I przypadła nawałność wiatru na jezioro, i łódź się zalewała, tak że byli w niebezpieczeństwie.
Bí wọ́n sì ti ń lọ, ó sùn; ìjì ńlá sì dé, ó ń fẹ́ lójú adágún; omi si wọ inú ọkọ, wọ́n sì wà nínú ewu.
24 A przystąpiwszy, obudzili go, mówiąc: Mistrzu, mistrzu! giniemy. A on ocknąwszy się, zgromił wiatr i wały wodne, i uśmierzyły się, i stało się uciszenie.
Wọ́n sì tọ̀ ọ́ wá wọ́n sì jí i, wí pé, “Olùkọ́, Olùkọ́, àwa yóò ṣègbé!” Nígbà náà ni ó dìde, ó sì bá ìjì líle àti ríru omi wí; wọ́n sì dúró, ìdákẹ́rọ́rọ́ sì dé.
25 Tedy im rzekł: Gdzież jest wiara wasza? A bojąc się, dziwowali się, mówiąc jedni do drugich: Któż wżdy jest ten, że i wiatrom rozkazuje i wodom, a są mu posłuszne?
Ó sì wí fún wọn pé, “Ìgbàgbọ́ yín dà?” Bí ẹ̀rù ti ń ba gbogbo wọn, tí hà sì ń ṣe wọ́n, wọ́n ń bi ara wọn pé, “Irú ọkùnrin wo ni èyí, nítorí ó bá ìjì líle àti ríru omi wí, wọ́n sì gbọ́ tirẹ̀?”
26 I przewieźli się do krainy Gadareńczyków, która jest przeciw Galilei.
Wọ́n sì gúnlẹ̀ ní ilẹ̀ àwọn ará Gadara, tí ó kọjú sí Galili.
27 A gdy wstąpił na ziemię, zabieżał mu mąż niektóry z onego miasta, co miał dyjabły od niemałego czasu, a nie obłóczył się w szaty, i nie mieszkał w domu, tylko w grobach.
Nígbà tí ó sì sọ̀kalẹ̀, ọkùnrin kan pàdé rẹ̀ lẹ́yìn ìlú náà, tí ó ti ní àwọn ẹ̀mí èṣù fún ìgbà pípẹ́, tí kì í wọ aṣọ, bẹ́ẹ̀ ni kì í jókòó ní ilé kan, bí kò ṣe ní ibojì.
28 Ten ujrzawszy Jezusa, zakrzyknął, i upadł przed nim, a głosem wielkim rzekł: Cóż ja mam z tobą, Jezusie, Synu Boga najwyższego? proszę cię, nie dręcz mię.
Nígbà tí ó rí Jesu, ó ké, ó wólẹ̀ níwájú rẹ̀, ó wí lóhùn rara, pé, “Kí ni mo ní í ṣe pẹ̀lú rẹ, Jesu, ìwọ Ọmọ Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo? Èmi bẹ̀ ọ́ má ṣe dá mi lóró.”
29 Albowiem rozkazał onemu duchowi nieczystemu, aby wyszedł z onego człowieka: bo od wielu czasów porywał go; a chociaż go wiązano łańcuchami i w pętach strzeżono, jednak on porwawszy okowy, bywał od dyjabła na pustynię pędzony.
(Nítorí tí ó ti wí fún ẹ̀mí àìmọ́ náà pé, kí ó jáde kúrò lára ọkùnrin náà. Nígbàkígbà ni ó ń mú un: wọn a sì fi ẹ̀wọ̀n àti ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ dè é; a sì ja gbogbo ìdè náà, ẹ̀mí èṣù náà a sì darí rẹ̀ sí ijù).
30 I pytał go Jezus, mówiąc: Co masz za imię? A on rzekł: Wojsko; albowiem wiele dyjabłów wstąpiło było weń.
Jesu sì bi í pé, “Kí ni orúkọ rẹ?” Ó sì dáhùn pé, “Ligioni,” nítorí ẹ̀mí èṣù púpọ̀ ni ó wa nínú rẹ.
31 Tedy go prosili, aby im nie rozkazywał stamtąd odejść w przepaść. (Abyssos )
Wọ́n sì bẹ̀ ẹ́ pé, kí ó má ṣe rán wọn lọ sínú ọ̀gbun. (Abyssos )
32 A była tam trzoda wielka świń, która się pasła na górze, i prosili go, aby im dopuścił wstąpić w nie. I dopuścił im.
Agbo ẹlẹ́dẹ̀ púpọ̀ sì ń bẹ níbẹ̀ tí ń jẹ lórí òkè: wọ́n sì bẹ̀ ẹ́ kí ó jẹ́ kí àwọn wọ inú wọn lọ. Ó sì gba fún wọn.
33 A wyszedłszy dyjabli z onego człowieka, weszli w świnie; i porwała się ona trzoda pędem z przykra do jeziora, i utonęła.
Nígbà tí àwọn ẹ̀mí èṣù sì jáde kúrò lára ọkùnrin náà, wọ́n sì wọ inú àwọn ẹlẹ́dẹ̀ lọ. Agbo ẹlẹ́dẹ̀ sì tú ka, wọ́n sí súré rọ́ gììrì sọ̀kalẹ̀ sì bèbè odò bọ́ sínú adágún náà, wọ́n sì rì sínú rẹ̀.
34 A widząc pasterze, co się stało, uciekli; a poszedłszy, oznajmili to w mieście i we wsiach.
Nígbà tí àwọn tí n bọ́ wọn rí ohun tí ó ṣẹlẹ̀, wọ́n sá, wọ́n sì lọ, wọ́n sì ròyìn ní ìlú àti ní ilẹ̀ náà.
35 I wyszli, aby oglądali to, co się stało; a przyszedłszy do Jezusa, znaleźli człowieka onego, z którego wyszli dyjabli, obleczonego, przy dobrem baczeniu, siedzącego u nóg Jezusowych, i bali się.
Nígbà náà ni wọ́n jáde lọ wo ohun náà tí ó ṣẹlẹ̀, wọ́n sì tọ Jesu wá, wọ́n sì rí ọkùnrin náà, lára ẹni tí àwọn ẹ̀mí èṣù ti jáde lọ, ó jókòó lẹ́bàá ẹsẹ̀ Jesu, ó wọ aṣọ, iyè rẹ̀ sì bọ́ sí ipò: ẹ̀rù sì bà wọ́n.
36 Opowiedzieli im tedy ci, którzy widzieli, jako uzdrowiono tego, który był opętany.
Àwọn tí ó rí i ròyìn fún wọn bí ó ti ṣe mú ẹni tí ó ní ẹ̀mí èṣù náà láradá.
37 I prosiło go wszystko mnóstwo onej okolicznej krainy Gadareńczyków, aby odszedł od nich; albowiem ich był wielki strach ogarnął. A on wstąpiwszy w łódź, wrócił się.
Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn láti ilẹ̀ Gadara yíká bẹ̀ ẹ́ pé, kí ó lọ kúrò lọ́dọ̀ wọn; nítorí ẹ̀rù bà wọ́n gidigidi. Ó sì bọ́ sínú ọkọ̀ ojú omi, ó si kúrò.
38 I prosił go on mąż, z którego wyszli dyjabli, aby był przy nim; ale go Jezus odprawił, mówiąc:
Ǹjẹ́ ọkùnrin náà tí ẹ̀mí èṣù jáde kúrò lára rẹ̀, bẹ̀ ẹ́ kí òun lè máa bá a gbé: ṣùgbọ́n Jesu rán an lọ, wí pé,
39 Wróć się do domu twego, a opowiadaj, jakoć wielkie rzeczy Bóg uczynił. I odszedł, po wszystkiem mieście opowiadając, jako mu wielkie rzeczy Jezus uczynił.
“Padà lọ sí ilé rẹ, kí o sì sọ ohun tí Ọlọ́run ṣe fún ọ bí ó ti pọ̀ tó.” Ó sì lọ, o sì ń ròyìn ka gbogbo ìlú náà bí Jesu ti ṣe ohun ńlá fún òun tó.
40 I stało się, gdy się wrócił Jezus, że go przyjął lud; albowiem nań wszyscy oczekiwali.
Ó sì ṣe, nígbà tí Jesu padà lọ, àwọn ènìyàn tẹ́wọ́gbà á; nítorí tí gbogbo wọn ti ń retí rẹ̀.
41 A oto przyszedł mąż imieniem Jairus, a ten był przełożonym bóżnicy; a przypadłszy do nóg Jezusowych, prosił go, aby wszedł w dom jego.
Sì kíyèsi i, ọkùnrin kan tí a ń pè ní Jairu, ọ̀kan nínú àwọn olórí Sinagọgu wá; ó sì wólẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ Jesu, ó bẹ̀ ẹ́ pé, kí ó wá sí ilé òun,
42 Albowiem miał córkę jedyną około dwunastu lat, która już konała. (A gdy on szedł, cisnął go lud.)
nítorí ó ní ọmọbìnrin kan ṣoṣo, ọmọ ìwọ̀n ọdún méjìlá, ti ó ń kú lọ. Bí ó sì ti ń lọ àwọn ènìyàn ko fun ni ààyè.
43 A niewiasta, która płynienie krwi cierpiała od lat dwunastu, i wynałożyła była na lekarzy wszystko swoje pożywienie, a nie mogła być od nikogo uleczona,
Obìnrin kan tí ó sì ní ìsun ẹ̀jẹ̀ láti ìgbà ọdún méjìlá, tí ó ná ohun gbogbo tí ó ní fún àwọn oníṣègùn, tí kò sì sí ẹnìkan tí ó lè mú un láradá,
44 Przystąpiwszy z tyłu, dotknęła się podołka szaty jego, a zarazem się zastanowiło płynienie krwi jej.
Ó wá sí ẹ̀yìn rẹ̀, ó fi ọwọ́ tọ́ ìṣẹ́tí aṣọ rẹ̀; lọ́gán ni ìsun ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sì ti gbẹ.
45 I rzekł Jezus: Któż jest, co się mnie dotknął? a gdy się wszyscy zapierali, rzekł Piotr, i ci, którzy z nim byli: Mistrzu! lud cię ciśnie i tłoczy, a ty mówisz: Kto się mnie dotknął?
Jesu sì wí pé, “Ta ni ó fi ọwọ́ kàn mí?” Nígbà tí gbogbo wọn sẹ́ Peteru àti àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ sọ pé, “Olùkọ́, àwọn ènìyàn ko ní ààyè, wọ́n sì ń kọlù ọ́, ìwọ sì wí pé, Ta ni ó fi ọwọ́ kàn mi?”
46 I rzekł Jezus: Dotknął się mnie ktoś, bom poznał, że moc ode mnie wyszła.
Jesu sì wí pé, “Ẹnìkan fi ọwọ́ kàn mí: nítorí tí èmí mọ̀ pé, àṣẹ jáde lára mi.”
47 A widząc ona niewiasta, że się nie utaiła, ze drżeniem przystąpiła i upadła przed nim, i dlaczego się go dotknęła, powiedziała mu przed wszystkim ludem, i jako zaraz uzdrowiona była.
Nígbà tí obìnrin náà sì mọ̀ pé òun kò fi ara sin, ó wárìrì, ó wá, ó sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀, ó sì sọ fún un lójú àwọn ènìyàn gbogbo nítorí ohun tí ó ṣe, tí òun fi fi ọwọ́ kàn án, àti bí a ti mú òun láradá lójúkan náà.
48 A on jej rzekł: Ufaj, córko! wiara twoja ciebie uzdrowiła; idźże w pokoju.
Ó sì wí fún un pé, “Ọmọbìnrin, ìgbàgbọ́ rẹ mú ọ láradá, máa lọ ní Àlàáfíà.”
49 A gdy on to jeszcze mówił, przyszedł niektóry od przełożonego bóżnicy, powiadając mu: Iż umarła córka twoja, nie trudź Nauczyciela.
Bí ó sì ti ń sọ̀rọ̀ lẹ́nu, ẹnìkan ti ilé olórí Sinagọgu wá, ó wí fún un pé, “Ọmọbìnrin rẹ kú; má yọ olùkọ́ni lẹ́nu mọ́.”
50 Ale Jezus usłyszawszy to, odpowiedział mu, mówiąc: Nie bój się, tylko wierz, a będzie uzdrowiona.
Ṣùgbọ́n nígbà tí Jesu gbọ́, ó dá a lóhùn, pé, “Má bẹ̀rù: sá gbàgbọ́ nìkan, a ó sì mú un láradá.”
51 A wszedłszy w dom, nie dopuścił z sobą wnijść nikomu, tylko Piotrowi, i Jakóbowi, i Janowi, i ojcu i matce onej dzieweczki.
Ṣùgbọ́n nígbà tí Jesu sì wọ ilé, kò jẹ́ kí ẹnikẹ́ni wọlé, bí kò ṣe Peteru, àti Jakọbu, àti Johanu, àti baba àti ìyá ọmọbìnrin náà.
52 A płakali wszyscy, i narzekali nad nią. Ale on rzekł: Nie płaczcież! Nie umarłać, ale śpi.
Gbogbo wọn sì sọkún, wọ́n pohùnréré ẹkún rẹ̀: ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ má sọkún mọ́; kò kú, sísùn ni ó sùn.”
53 I naśmiewali się z niego, wiedząc, iż była umarła.
Wọ́n sì fi í ṣẹ̀fẹ̀, wọ́n sá mọ̀ pé ó kú.
54 A on wygnawszy precz wszystkich, i ująwszy ją za rękę, zawołał, mówiąc: Dzieweczko, wstań!
Nígbà tí ó sì sé gbogbo wọn mọ́ òde, ó mú un lọ́wọ́, ó sì wí pé, “Ọmọbìnrin, dìde!”
55 I wrócił się duch jej; i wstała zaraz; i rozkazał, aby jej jeść dano.
Ẹ̀mí rẹ̀ sì padà bọ̀, ó sì dìde lọ́gán: ó ní kí wọn fún un ní oúnjẹ.
56 I zdumieli się rodzice jej. A on im zakazał, aby nikomu nie powiadali tego, co się było stało.
Ẹnu sì ya àwọn òbí rẹ̀: ṣùgbọ́n ó kìlọ̀ fún wọn pé, kí wọn má ṣe wí fún ẹnìkan ohun tí a ṣe.