< Łukasza 4 >

1 A Jezus pełen będąc Ducha Świętego, wrócił się od Jordanu, i pędzony jest od Ducha na puszczą.
Jesu sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, ó padà ti Jordani wá, a sì ti ọwọ́ Ẹ̀mí darí rẹ̀ sí ijù,
2 I był przez czterdzieści dni kuszony od dyjabła, a nie jadł nic przez one dni; ale gdy się te skończyły, potem łaknął.
Ogójì ọjọ́ ni a fi dán an wò lọ́wọ́ èṣù. Kò sì jẹ ohunkóhun ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì: nígbà tí wọ́n sì parí, lẹ́yìn náà ni ebi wá ń pa á.
3 I rzekł mu dyjabeł: Jeźliś jest Syn Boży, rzecz kamieniowi temu, aby się stał chlebem.
Èṣù sì wí fún un pé, “Bí ìwọ bá ṣe Ọmọ Ọlọ́run, pàṣẹ fún òkúta yìí kí ó di àkàrà.”
4 Ale Jezus odpowiedział mu, mówiąc: Napisano, iż nie samym chlebem żyć będzie człowiek, ale każdem słowem Bożem.
Jesu sì dáhùn, ó wí fún un pé, “A ti kọ̀wé rẹ̀ pé, ‘Ènìyàn kì yóò wà láààyè nípa àkàrà nìkan.’”
5 I wwiódł go dyjabeł na górę wysoką, i pokazał mu wszystkie królestwa świata we mgnieniu oka.
Lójúkan náà, èṣù sì mú un lọ sí orí òkè gíga, ó sì fi gbogbo ilẹ̀ ọba ayé hàn án.
6 I rzekł mu dyjabeł: Dam ci tę wszystkę moc i sławę ich; bo mi jest dana, a komu chcę, dawam ją.
Èṣù sì wí fún un pé, “Ìwọ ni èmi ó fi gbogbo agbára yìí àti ògo wọn fún: nítorí á sá ti fi fún mi. Ẹnikẹ́ni tí ó bá sì wù mí, èmi a fi í fún.
7 A tak jeźli się ukłonisz przede mną, będzie wszystko twoje.
Ǹjẹ́ bí ìwọ bá foríbalẹ̀ fún mi, gbogbo rẹ̀ ni yóò jẹ́ tìrẹ.”
8 A odpowiadając Jezus rzekł mu: Pójdź precz ode mnie, szatanie! albowiem napisano: Panu, Bogu twemu, kłaniać się będziesz, i jemu samemu służyć będziesz.
Jesu sì dáhùn ó sì wí fún un pé, “Kúrò lẹ́yìn mi, Satani, nítorí tí a kọ̀wé rẹ̀ pé, ‘Ìwọ foríbalẹ̀ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ, òun nìkan ṣoṣo ni kí ìwọ kí ó sì máa sìn.’”
9 Potem wiódł go do Jeruzalemu, i postawił go na ganku kościelnym, i rzekł mu: Jeźliś jest Syn Boży, spuść się stąd na dół;
Èṣù sì mú un lọ sí Jerusalẹmu, ó sì gbé e lé ibi ṣóńṣó tẹmpili, ó sì wí fún un pé, “Bí ìwọ bá ṣe Ọmọ Ọlọ́run, bẹ́ sílẹ̀ fún ara rẹ láti ibí yìí.
10 Albowiem napisano: Że Aniołom swoim przykazał o tobie, aby cię strzegli,
A sá ti kọ̀wé rẹ̀ pé, “‘Yóò pàṣẹ fún àwọn angẹli rẹ̀ nítorí rẹ, láti máa ṣe ìtọ́jú rẹ;
11 A że cię na rękach nosić będą, byś snać nie obraził o kamień nogi twojej.
àti pé ní ọwọ́ wọn ni wọn ó gbé ọ sókè, kí ìwọ kí ó má ba à fi ẹsẹ̀ rẹ gbún òkúta.’”
12 A odpowiadając Jezus rzekł mu: Powiedziano: Nie będziesz kusił Pana, Boga twego.
Jesu sì dáhùn ó wí fún un pé, “A ti kọ́ pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ dán Olúwa Ọlọ́run rẹ wò.’”
13 A gdy dokończył wszystkich pokus dyjabeł, odstąpił od niego do czasu.
Nígbà tí èṣù sì parí ìdánwò náà gbogbo, ó fi í sílẹ̀ lọ fun sá à kan.
14 I wrócił się Jezus w mocy onego Ducha do Galilei. I rozeszła się o nim wieść po wszystkiej onej okolicznej krainie.
Jesu sì fi agbára Ẹ̀mí padà wá sí Galili, òkìkí rẹ̀ sì kàn kálẹ̀ ní gbogbo agbègbè tí ó yí i ká.
15 A on nauczał w bóżnicach ich, i był sławiony od wszystkich.
Ó sì ń kọ́ni nínú Sinagọgu wọn; a ń yìn ín lógo láti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn ènìyàn wá.
16 I przyszedł do Nazaretu, gdzie był wychowany, i wszedł według zwyczaju swego w dzień sabatu do bóżnicy, i wstał, aby czytał.
Ó sì wá sí Nasareti, níbi tí a gbé ti tọ́ ọ dàgbà: bí ìṣe rẹ̀ ti rí, ó sì wọ inú Sinagọgu lọ ní ọjọ́ ìsinmi, ó sì dìde láti kàwé.
17 I podano mu księgi Izajasza proroka; a otworzywszy księgi, znalazł miejsce, gdzie było napisano:
A sì fi ìwé wòlíì Isaiah fún un. Nígbà tí ó sì ṣí ìwé náà, ó rí ibi tí a gbé kọ ọ́ pé:
18 Duch Pański nade mną; przeto mię pomazał, abym opowiadał Ewangieliję ubogim; posłał mię, abym uzdrawiał skruszone na sercu, abym zwiastował pojmanym wyzwolenie, i ślepym przejrzenie, i abym wypuścił uciśnione na wolność;
“Ẹ̀mí Olúwa ń bẹ lára mi, nítorí tí ó fi àmì òróró yàn mí láti wàásù ìyìnrere fún àwọn òtòṣì. Ó ti rán mi wá láti wàásù ìdásílẹ̀ fún àwọn ìgbèkùn, àti ìmúnríran fún àwọn afọ́jú, àti láti jọ̀wọ́ àwọn tí a pa lára lọ́wọ́,
19 Abym opowiadał rok Pański przyjemny.
láti kéde ọdún ojúrere Olúwa.”
20 A zawarłszy księgę i oddawszy ją słudze, usiadł; a oczy wszystkich w bóżnicy pilnie nań patrzały.
Ó sì pa ìwé náà dé, ó fi í fún ìránṣẹ́, ó sì jókòó. Gbogbo àwọn tí ó ń bẹ nínú Sinagọgu sì tẹjúmọ́ ọn.
21 I począł do nich mówić: Dziści się wypełniło to pismo w uszach waszych.
Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í wí fún wọn pé, “Lónìí ìwé mímọ́ yìí ṣẹ ní etí yín.”
22 I wszyscy mu dawali świadectwo, i dziwowali się wdzięczności onych słów, które pochodziły z ust jego, i mówili: Izaż ten nie jest syn Józefowy?
Gbogbo wọn sì jẹ́rìí rẹ̀, háà sì ṣe wọ́n sí ọ̀rọ̀ oore-ọ̀fẹ́ tí ń jáde ní ẹnu rẹ̀, wọ́n sì wí pé, “Ọmọ Josẹfu kọ́ yìí?”
23 I rzekł do nich: Pewnie mi rzeczecie onę przypowieść: Lekarzu! ulecz samego siebie! Cośmy słyszeli, żeś uczynił w Kapernaum, uczyń i tu w ojczyźnie swojej.
Jesu sì wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ ni ẹ̀yin ó pa òwe yìí sí mi pé, ‘Oníṣègùn, wo ara rẹ̀ sàn! Àwọn ohun tí àwa gbọ́ pé o ti ọwọ́ rẹ ṣe ní Kapernaumu, ṣe é níhìn-ín yìí pẹ̀lú ní ilẹ̀ ara rẹ.’”
24 I rzekł do nich: Zaprawdę wam powiadam: Żaden prorok nie jest przyjemnym w ojczyźnie swojej.
Ó sì wí pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún un yín, kò sí wòlíì tí a tẹ́wọ́gbà ní ilẹ̀ baba rẹ̀.
25 Aleć wam w prawdzie powiadam, że wiele wdów było za dni Elijaszowych w ludzie Izraelskim, gdy było zamknione niebo przez trzy lata i sześć miesięcy, tak iż był wielki głód po wszystkiej ziemi;
Ṣùgbọ́n mo wí fún un yín nítòótọ́, opó púpọ̀ ni ó wà ní Israẹli nígbà ọjọ́ wòlíì Elijah, nígbà tí ọ̀run fi sé ní ọdún mẹ́ta òun oṣù mẹ́fà, nígbà tí ìyàn ńlá fi mú ká ilẹ̀ gbogbo.
26 Wszakże do żadnej z nich nie był posłany Elijasz, tylko do Sarepty, miasta Sydońskiego, do jednej wdowy.
Kò sì sí ẹnìkan nínú wọn tí a rán Elijah sí, bí kò ṣe sí obìnrin opó kan ní Sarefati, ìlú kan ní Sidoni.
27 I wiele było trędowatych za Elizeusza proroka, w ludzie Izraelskim, wszakże żaden z nich nie był oczyszczony, tylko Naaman, Syryjczyk.
Adẹ́tẹ̀ púpọ̀ ní sì ń bẹ ní Israẹli nígbà wòlíì Eliṣa; kò sì ṣí ọ̀kan nínú wọn tí a wẹ̀nùmọ́, bí kò ṣe Naamani ará Siria.”
28 Tedy wszyscy w bóżnicy, gdy to słyszeli, napełnieni byli gniewem;
Nígbà tí gbogbo àwọn tí ó wà nínú Sinagọgu gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, inú bi wọ́n gidigidi,
29 A wstawszy, wypchnęli go precz z miasta, i wywiedli go na wierzch góry, na której miasto ich zbudowane było, aby go z niej na dół zrzucili.
wọ́n sì dìde, wọ́n tì í sóde sí ẹ̀yìn ìlú, wọ́n sì fà á lọ sí bèbè òkè níbi tí wọ́n gbé tẹ ìlú wọn dó, kí wọn bá à lè sọ sílẹ̀ ní ògèdèǹgbé.
30 Ale on przeszedłszy przez pośrodek ich, uszedł.
Ṣùgbọ́n ó kọjá láàrín wọn, ó bá tirẹ̀ lọ.
31 I zstąpił do Kapernaum, miasta Galilejskiego, a tam je nauczał w sabaty.
Ó sì sọ̀kalẹ̀ wá sí Kapernaumu, ìlú kan ní Galili, ó sì ń kọ́ wọn ní ọjọ́ ìsinmi.
32 I zdumiewali się nad nauką jego; bo była mocna mowa jego.
Ẹnu sì yà wọ́n sí ẹ̀kọ́ rẹ̀: nítorí tàṣẹtàṣẹ ni ọ̀rọ̀ rẹ̀.
33 A w bóżnicy był człowiek, który miał ducha dyjabła nieczystego, i zawołał głosem wielkim,
Ọkùnrin kan sì wà nínú Sinagọgu, ẹni tí ó ní ẹ̀mí àìmọ́, ó kígbe ní ohùn rara,
34 Mówiąc: Ach! Cóż my z tobą mamy, Jezusie Nazareński? Przyszedłeś, abyś nas wytracił; znam cię, ktoś jest, żeś on Święty Boży.
“Ó wí pé, kín ni ṣe tàwa tìrẹ, Jesu ará Nasareti? Ìwọ́ wá láti pa wá run bí? Èmí mọ ẹni tí ìwọ í ṣe, Ẹni Mímọ́ Ọlọ́run.”
35 I zgromił go Jezus, mówiąc: Umilknij, a wynijdź z niego. Tedy dyjabeł porzuciwszy go w pośrodek, wyszedł z niego, nic mu nie zaszkodziwszy.
Jesu sì bá a wí gidigidi, ó wí fun pe, “Pa ẹnu rẹ mọ́, kí o sì jáde lára rẹ̀.” Nígbà tí ẹ̀mí èṣù náà sì gbé e ṣánlẹ̀ ní àwùjọ, ó jáde kúrò lára rẹ̀, kò sì pa á lára.
36 I przyszedł strach na wszystkie, i rozmawiali między sobą, mówiąc: Cóż to za słowo, że z władzą i z mocą rozkazuje duchom nieczystym, a wychodzą?
Ẹnu sì ya gbogbo wọn, wọ́n sì ń bá ara wọn sọ wí pé, “Irú ẹ̀kọ́ kín ni èyí? Nítorí pẹ̀lú àṣẹ àti agbára ni ó fi bá àwọn ẹ̀mí àìmọ́ wí, wọ́n sì jáde kúrò.”
37 I rozeszła się o nim wieść na wszystkie miejsca okolicznej krainy.
Òkìkí rẹ̀ sì kàn níbi gbogbo ní agbègbè ilẹ̀ náà yíká.
38 A Jezus wstawszy, z bóżnicy wszedł w dom Szymona, a świekra Szymonowa miała gorączkę wielką; i prosili go za nią.
Nígbà tí ó sì dìde kúrò nínú Sinagọgu, ó sì wọ̀ ilé Simoni lọ; ibà sì ti dá ìyá ìyàwó Simoni dùbúlẹ̀, wọ́n sì bẹ̀ ẹ́ nítorí rẹ̀.
39 Tedy on stanąwszy nad nią, zgromił gorączkę, i opuściła ją; a zarazem wstawszy, posługiwała im.
Ó sì súnmọ́ ọ, ó bá ibà náà wí; ibà sì náà sì fi sílẹ̀. O sì dìde lọ́gán, ó ń ṣe ìránṣẹ́ fún wọn.
40 A gdy słońce zachodziło, wszyscy, którzy mieli chorujące na rozmaite niemocy, przywodzili je do niego, a on na każdego z nich ręce włożywszy, uzdrawiał je.
Nígbà tí oòrùn sì ń wọ̀, àwọn ènìyàn gbe àwọn aláìsàn, tó ní onírúurú àìsàn wá sọ́dọ̀ Jesu; ó sì fi ọwọ́ lé olúkúlùkù wọn, ó sì mú wọn láradá.
41 Ku temu wychodzili i dyjabli z wielu ich, wołając i mówiąc: Tyś jest on Chrystus, Syn Boży; ale on zgromiwszy je, nie dopuszczał im mówić; bo wiedzieli, iż on jest Chrystus.
Àwọn ẹ̀mí èṣù sì jáde lára ẹni púpọ̀ pẹ̀lú, wọ́n ń kígbe, wí pé, “Ìwọ ni Ọmọ Ọlọ́run!” Ó sì ń bá wọn wí kò sì jẹ́ kí wọn kí ó fọhùn, nítorí tí wọ́n mọ̀ pé Òun ni Kristi náà.
42 A gdy był dzień, wyszedłszy, szedł na miejsce puste. A lud go szukał, i przyszli aż do niego, i zatrzymywali go, aby nie odchodził od nich.
Nígbà tí ilẹ̀ sì mọ́, Jesu sì jáde lọ, ó sì ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀. Ìjọ ènìyàn sì ń wá a kiri, wọ́n sì tọ̀ ọ́ wá, wọ́n sì dá a dúró, nítorí kí ó má ba à lọ kúrò lọ́dọ̀ wọn.
43 A on rzekł do nich: I innym miastom muszę opowiadać królestwo Boże; bom na to posłany.
Ṣùgbọ́n ó sì wí fún wọn pé, “Èmi kò lè ṣàìmá wàásù ìyìnrere ti ìjọba Ọlọ́run fún àwọn ìlú mìíràn pẹ̀lú, nítorí náà ni a sá ṣe rán mi.”
44 I kazał w bóżnicach Galilejskich.
Ó sì ń wàásù nínú Sinagọgu ti Judea.

< Łukasza 4 >