< Kapłańska 7 >

1 Tać jest ustawa ofiary za występek, która jest najświętsza.
“‘Wọ̀nyí ni àwọn ìlànà fún rírú ẹbọ ẹ̀bi, tí ó jẹ́ mímọ́ jùlọ.
2 Na miejscu, gdzie biją ofiary całopalenia, zabiją ofiarę za występek, a krwią jej pokropią ołtarz z wierzchu w około.
Níbi tí wọn ti ń pa ẹran ẹbọ sísun ni kí ẹ ti pa ẹran ẹbọ ẹ̀bi, kí ẹ sì wọ́n ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yí pẹpẹ náà ká.
3 A wszystkę tłustość jej ofiarować będzie z niej, ogon i tłustość okrywającą wnętrzności;
Gbogbo ọ̀rá rẹ̀ ni kí ẹ sun, ọ̀rá ìrù rẹ̀ àti ọ̀rá tí ó bo nǹkan inú rẹ̀.
4 Obiedwie też nerki z tłustością, która jest na nich, i na polędwicach, i odzieczkę, która jest na wątrobie i na nerkach, odejmie.
Kíndìnrín méjèèjì pẹ̀lú ọ̀rá tí ó wà lẹ́bàá ìhà rẹ̀, àti ọ̀rá tí ó bo ẹ̀dọ̀, kí ó yọ ọ́ pẹ̀lú àwọn kíndìnrín.
5 I spali to kapłan na ołtarzu na ofiarę ognistą Panu; ofiara to jest za występek.
Àlùfáà yóò sun wọ́n lórí pẹpẹ gẹ́gẹ́ bí ọrẹ tí a fi iná sun sí Olúwa. Ẹbọ ẹ̀bi ni.
6 Wszelki mężczyzna z kapłanów będzie ją jadł, na miejscu świętem jedzona będzie; rzecz to najświętsza.
Gbogbo ọkùnrin ní ìdílé àlùfáà ló lè jẹ ẹ́ ní ibi mímọ́, ó jẹ́ mímọ́ jùlọ.
7 Jako ofiara za grzech, tak ofiara za występek jednaką ustawę mają; kapłanowi, który by go oczyszczał, należeć będzie.
“‘Òfin yìí kan náà ló wà fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti ẹbọ ẹ̀bi: méjèèjì jẹ́ tí àlùfáà, tó fi wọ́n ṣe ètùtù.
8 Kapłanowi, który by czyję ofiarę całopaloną ofiarował, skóra tejże ofiary, którą ofiarował, należeć będzie.
Àlùfáà tó rú ẹbọ sísun fún ẹnikẹ́ni le è mú awọ ẹran ìrúbọ náà.
9 Także każda ofiara śniedna w piecu upieczona, i wszystko, co na pańwi albo w kotle gotowane będzie, kapłanowi, który to ofiaruje, należeć będzie.
Gbogbo ẹbọ ohun jíjẹ tí a bá yan lórí ààrò, àti gbogbo èyí tí a yan nínú apẹ, àti nínú àwopẹ̀tẹ́, ni kí ó jẹ́ ti àlùfáà tí ó rú ẹbọ náà.
10 Przytem wszelaka ofiara śniedna, zagnieciona z oliwą albo prażona, wszystkim synom Aaronowym należeć będzie, tak jednemu, jako drugiemu.
Bẹ́ẹ̀ náà ni ẹbọ ohun jíjẹ yálà a fi òróró pò ó tàbí èyí tó jẹ́ gbígbẹ, wọ́n jẹ́ ti gbogbo ọmọ Aaroni.
11 Tać też jest ustawa ofiary spokojnej, którą będą ofiarowali Panu.
“‘Wọ̀nyí ni àwọn ìlànà fún ọrẹ àlàáfíà tí ẹnikẹ́ni bá gbé wá síwájú Olúwa.
12 Jeźliby kto ofiarował na ofiarę dziękczynienia, tedy ofiarować będzie na ofiarę dziękczynienia placki przaśne, zagniatane z oliwą, i kreple przaśne, pomazane oliwą, i mąkę pszenną, smażoną z temi plackami w oliwie zagniecionemi.
“‘Bí ẹni náà bá gbé e wá gẹ́gẹ́ bí àfihàn ọkàn ọpẹ́, pẹ̀lú ẹbọ ọpẹ́ yìí, ó gbọdọ̀ mú àkàrà aláìwú tí a fi òróró pò wá àti àkàrà aláìwú fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ tí a dà òróró sí àti àkàrà tí a fi ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára tí a fi òróró pò ṣe.
13 Przy tych plackach będzie też chleb kwaszony ofiarował na ofiarę swoję z ofiarą dziękczynienia spokojnych ofiar swoich.
Pẹ̀lú ọrẹ àlàáfíà rẹ̀, kí ó tún mú àkàrà wíwú wá fún ọpẹ́,
14 I będzie ofiarował z niego jeden chleb z każdej ofiary na podnoszenie Panu. Kapłanowi, który kropi krwią ofiar spokojnych, należeć to będzie.
kí ó mú ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú oríṣìíríṣìí ọrẹ àlàáfíà rẹ wá gẹ́gẹ́ bí ẹ̀bùn fún Olúwa, ó jẹ́ tí àlùfáà tí ó wọ́n ẹ̀jẹ̀ ọrẹ àlàáfíà.
15 Mięso zaś ofiary dziękczynienia, która jest spokojna, w dzień ofiarowania ofiary jego jedzone będzie; nie zostawią z niego nic do jutra.
Ẹran ọrẹ àlàáfíà ti ọpẹ́ yìí ni wọ́n gbọdọ̀ jẹ ní ọjọ́ gan an tí wọ́n rú ẹbọ, kò gbọdọ̀ ṣẹ́ ẹran kankan kù di àárọ̀ ọjọ́ kejì.
16 A jeźliby kto ślubną albo dobrowolną przyniósł ofiarę swoją, w dzień ofiarowania ofiary jego jedzone będzie; a nazajutrz, coby zostało z niej, zjedzą.
“‘Ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ pé ó mú ọrẹ wá, nítorí ẹ̀jẹ́ tó jẹ́ tàbí kí ó jẹ́ ọrẹ àtinúwá, wọn yóò jẹ ẹbọ náà ní ọjọ́ tí wọ́n rú ẹbọ yìí, ṣùgbọ́n wọ́n lè jẹ èyí tó ṣẹ́kù ní ọjọ́ kejì.
17 Ale jeźliby co zostało mięsa z tej ofiary do trzeciego dnia, ogniem spalone będzie.
Gbogbo ẹran tó bá ṣẹ́kù di ọjọ́ kẹta ní ẹ gbọdọ̀ sun.
18 A jeźliby kto przecię jadł mięso tej ofiary spokojnej dnia trzeciego, nie będzie przyjemny ten, który ją ofiarował; nie będzie mu płatna, owszem obrzydliwością będzie; a kto by jadł z niej, nieprawość swoję poniesie.
Bí ẹ bá jẹ ọ̀kankan nínú ẹran ọrẹ àlàáfíà ní ọjọ́ kẹta, kò ni jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà. A kò ní í kà á sí fún ẹni tó rú ẹbọ náà, nítorí pé ó jẹ́ àìmọ́, ẹnikẹ́ni tó bá sì jẹ ẹ́, ni a ó di ẹ̀bi rẹ̀ rù.
19 Mięso też, które by się dotknęło czego nieczystego, nie będzie jedzone, ale ogniem spalone będzie; mięso zaś inne, każdy czysty jeść je będzie.
“‘Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹran tí ó bá ti kan ohun tí a kà sí àìmọ́, sísun ni kí ẹ sun ún. Ẹnikẹ́ni tí a ti kà sí mímọ́ le è jẹ nínú ẹran tí ó kù.
20 A ktobykolwiek jadł mięso z ofiary spokojnej, ofiarowanej Panu, a byłby nieczysty, wytracony będzie człowiek ten z ludu swego.
Ṣùgbọ́n bí ẹni tí kò mọ́ bá jẹ́ ẹran ọrẹ àlàáfíà tí ó jẹ́ tí Olúwa, a ó gé irú ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn rẹ̀.
21 Jeźliby się też kto dotknął czego nieczystego, bądź nieczystości człowieczej, bądź nieczystości bydlęcej, bądź jakiejkolwiek obrzydliwości nieczystej, a jadłby mięso z ofiary spokojnej, ofiarowanej Panu, tedy wytracony będzie człowiek ten z ludu swego.
Bí ẹnikẹ́ni bá fọwọ́ kan ohun aláìmọ́ yálà ohun àìmọ́ ti ènìyàn, ẹranko aláìmọ́, ohun àìmọ́ yówù kí ó jẹ́ tàbí ohunkóhun tí ó jẹ́ ìríra, tí ó sì tún jẹ́ ẹran ọrẹ àlàáfíà tó jẹ́ ti Olúwa, a ó gé irú ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn rẹ.’”
22 Rzekł jeszcze Pan do Mojżesza, mówiąc:
Olúwa sọ fún Mose pé,
23 Powiedz synom Izraelskim, i rzecz: Żadnej tłustości z wołu, ani z owiec, ani z kozy, nie będziesz jadł,
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ẹ má ṣe jẹ ọ̀rá màlúù, àgùntàn tàbí ewúrẹ́.
24 Aczkolwiek tłustość bydlęcia zdechłego, albo tłustość rozszarpanego może być do wszelakiej potrzeby; ale jeść jej żadnym sposobem nie będziecie.
Ẹ lè lo ọ̀rá ẹran tó kú fúnra rẹ̀ tàbí èyí tí ẹranko igbó pa, fún nǹkan mìíràn, ṣùgbọ́n ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹ́.
25 Albowiem ktobykolwiek jadł tłustość z bydlęcia, które ofiarować będzie człowiek na ofiarę ognistą Panu, niechaj wytracony będzie człowiek ten, który jadł, z ludu swego.
Ẹnikẹ́ni tó bá jẹ ọ̀rá ẹran tí a fi rú ẹbọ sísun sí Olúwa ni ẹ gbọdọ̀ gé kúrò lára àwọn ènìyàn rẹ̀.
26 Także żadnej krwi jeść nie będziecie we wszystkich mieszkaniach waszych, tak z ptaków, jako i z bydląt.
Ẹ kò sì gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀ ẹyẹ tàbí ẹran ní gbogbo ibi tí ẹ bá ń gbé.
27 Wszelki człowiek, który by jadł jakąkolwiek krew, wytracony będzie człowiek on z ludu swego.
Bí ẹnikẹ́ni bá jẹ ẹ̀jẹ̀, a ó gé ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn rẹ̀.’”
28 Rzekł jeszcze Pan do Mojżesza, mówiąc:
Olúwa sọ fún Mose pé,
29 Mów do synów Izraelskich, a rzecz im: Kto by ofiarował ofiarę spokojną swoję Panu, przyniesie ofiarę swoję Panu z ofiary spokojnej swojej.
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ẹnikẹ́ni tó bá mú ọrẹ àlàáfíà wá fún Olúwa.
30 Ręka jego przyniesie ofiarę ognistą Panu; tłustość z mostkiem przyniesie, a mostek niech będzie tam i sam obracany na ofiarę przed Panem.
Pẹ̀lú ọwọ́ ara rẹ̀ ni kí ó fi mú ọrẹ tí a fi iná sun wá fún Olúwa, kí ó mú ọ̀rá àti igẹ̀, kí ó sì fi igẹ̀ yìí níwájú Olúwa bí ọrẹ fífì.
31 Potem spali kapłan tłustość na ołtarzu; ale mostek zostanie Aaronowi i synom jego.
Àlùfáà yóò sun ọ̀rá náà lórí pẹpẹ ṣùgbọ́n igẹ̀ ẹran náà jẹ́ ti Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀,
32 A łopatkę prawą oddacie na podnoszenie kapłanowi z ofiar spokojnych waszych.
kí ẹ fún àlùfáà ní itan ọ̀tún lára ọrẹ àlàáfíà yín gẹ́gẹ́ bí ìpín tiyín fún àlùfáà.
33 Kto też z synów Aaronowych ofiarować będzie krew ofiar spokojnych i tłustość, temu się dostanie łopatka prawa działem.
Ọmọ Aaroni ẹni tí ó rú ẹbọ ẹ̀jẹ̀ àti ọ̀rá ọrẹ àlàáfíà ni kí ó ni itan ọ̀tún gẹ́gẹ́ bí ìpín tirẹ̀.
34 Albowiem mostek sam i tam obracania, i łopatkę podnoszenia, wziąłem od synów Izraelskich z ofiar ich spokojnych, i dałem je Aaronowi kapłanowi, i synom jego prawem wiecznem od synów Izraelskich.
Nínú ọrẹ àlàáfíà àwọn ọmọ Israẹli, mo ti ya igẹ̀ tí a fi àti itan tí ẹ mú wá sọ́tọ̀ fún Aaroni àlùfáà àti àwọn ọmọ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn ní gbogbo ìgbà láti ọ̀dọ̀ ara Israẹli.’”
35 Toć jest dział pomazanego Aarona, i pomazanych synów jego z ofiar ognistych Pańskich, od dnia, któregom im przystąpić rozkazał ku sprawowaniu urzędu kapłańskiego Panu.
Èyí ni ìpín tí a yà sọ́tọ̀ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ nínú ẹbọ tí a finá sun sí Olúwa lọ́jọ́ tí wọ́n mú wọn wá láti sin Olúwa gẹ́gẹ́ bí àlùfáà.
36 I rozkazał Pan, aby im to dawano było od dnia, którego je pomazał, od synów Izraelskich prawem wiecznem w narodziech ich.
Lọ́jọ́ tí a fi òróró yàn wọ́n, ni Olúwa ti pa á láṣẹ pé kí àwọn ọmọ Israẹli máa fún wọn ní àwọn nǹkan wọ̀nyí gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn ìgbà gbogbo fún àwọn ìran tó ń bọ̀.
37 Tać jest ustawa ofiary całopalenia, ofiary śniednej, i ofiary za grzech, i za występek, i poświęcenia, i ofiary spokojnej.
Nítorí náà, àwọn nǹkan wọ̀nyí jẹ́ ìlànà fún ẹbọ sísun, ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, ẹbọ ẹ̀bi, ìfinijoyè àlùfáà àti ẹbọ àlàáfíà
38 Którą rozkazał Pan Mojżeszowi na górze Synaj, dnia, którego przykazywał synom Izraelskim, aby ofiarowali ofiary swe Panu na puszczy Synaj.
èyí tí Olúwa fún Mose lórí òkè Sinai lọ́jọ́ tí Olúwa pa á láṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kí wọ́n máa mú ọrẹ wọn wá fún Olúwa ni ijù Sinai.

< Kapłańska 7 >