< Kapłańska 20 >

1 Potem rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Powiedz synom Izraelskim: Ktobykolwiek z synów Izraelskich, albo z przychodniów mieszkających w Izraelu ofiarował potomstwo swoje Molochowi, śmiercią niech umrze; lud ziemi niechaj go ukamionuje;
“Sọ fún àwọn ará Israẹli pé, ‘Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ará Israẹli tàbí àwọn àlejò tí ń gbé láàrín Israẹli, tí ó bá fi èyíkéyìí nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún Moleki, kí wọ́n pa á, kí àwọn olùgbé ilẹ̀ náà sọ ọ́ ní òkúta pa.
3 Bo Ja postawię twarz moję rozgniewaną przeciwko temu mężowi, i wytracę go z pośrodku ludu jego, przeto, iż potomstwo swoje ofiarował Molochowi, i splugawił świątnicę moję, a zmazał imię świątobliwości mojej.
Èmi tìkára mi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀, ń ó sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀ fún òrìṣà Moleki ó ti ba ibi mímọ́ mi jẹ́ pẹ̀lú.
4 A jeźliby lud ziemi nie dbając przeglądał mężowi takiemu, który by ofiarował Molochowi potomstwo swe, i nie zabiłby go:
Bí àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà bá mójú kúrò lára irú ẹni bẹ́ẹ̀ tí ó fi ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún òrìṣà Moleki tí wọn kò sì pa irú ẹni bẹ́ẹ̀.
5 Tedy Ja postawię twarz moję zagniewaną przeciw temu mężowi i przeciw domowi jego, i wytracę go i wszystkie, którzy cudzołożąc, szliby za nim, aby cudzołożyli, naśladując Molocha, z pośrodku ludu jego.
Èmi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀ àti gbogbo ìdílé rẹ̀, èmi yóò sì ké wọn kúrò láàrín àwọn ènìyàn wọn, òun àti gbogbo àwọn tí ó jọ ṣe àgbèrè tọ òrìṣà Moleki lẹ́yìn.
6 Człowiek, który by się udał do czarowników, i do wieszczków, aby cudzołożył idąc za nimi, postawię twarz swoję rozgniewaną przeciwko niemu, i wytracę go z pośrodku ludu jego.
“‘Bí ẹnikẹ́ni bá tọ àwọn abókùúsọ̀rọ̀ àti àwọn ẹlẹ́mìí òkùnkùn lọ, tí ó sì ṣe àgbèrè tọ̀ wọ́n lẹ́yìn, Èmi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀, Èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
7 Przetoż poświęcajcie się, a bądźcie świętymi; bom Ja Pan, Bóg wasz.
“‘Torí náà ẹ ya ara yín sí mímọ́ kí ẹ sì jẹ́ mímọ́, torí pé, Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
8 A strzeżcie ustaw moich, i czyńcie je; Jam Pan poświęcający was.
Ẹ máa kíyèsi àṣẹ mi, kí ẹ sì máa pa wọ́n mọ́. Èmi ni Olúwa tí ó sọ yín di mímọ́.
9 Ktobykolwiek złorzeczył ojcu swemu, albo matce swej, śmiercią umrze; ojcu swemu, i matce swej złorzeczył, krew jego będzie na nim.
“‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣépè lé baba tàbí ìyá rẹ̀ ni kí ẹ pa, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wà lórí ara rẹ̀ torí pé ó ti ṣépè lé baba àti ìyá rẹ̀.
10 Kto by się kolwiek cudzołóstwa dopuścił z czyją żoną, ponieważ cudzołożył z żoną bliźniego swego, śmiercią umrze cudzołożnik on i cudzołożnica.
“‘Bí ẹnikẹ́ni bá bá aya aládùúgbò rẹ̀ lòpọ̀: ọkùnrin àti obìnrin náà ni kí ẹ sọ ní òkúta pa.
11 Ktobykolwiek też spał z żoną ojca swego, sromotę ojca swego odkrył, śmiercią umrą oboje; krew ich będzie na nich.
“‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá bá aya baba rẹ̀ lòpọ̀ ti tàbùkù baba rẹ̀. Àwọn méjèèjì ni kí ẹ pa. Ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
12 Jeźliby też kto spał z synową swoją, śmiercią umrą oboje; obrzydliwości się dopuścili, krew ich będzie na nich.
“‘Bí ọkùnrin kan bá bá arábìnrin ìyàwó rẹ̀ lòpọ̀, àwọn méjèèjì ni kí ẹ pa, wọ́n ti ṣe ohun tí ó lòdì, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
13 Mąż także, który by z mężczyzną obcował sposobem niewieścim, obrzydliwość uczynili oba; śmiercią umrą, krew ich będzie na nich.
“‘Bí ọkùnrin kan bá bá ọkùnrin mìíràn lòpọ̀ bí wọ́n ti í bá obìnrin lòpọ̀: àwọn méjèèjì ti ṣe ohun ìríra, pípa ni kí ẹ pa wọ́n, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
14 Kto by też pojął córkę z matką jej, sprośna rzecz jest; ogniem spalą onego i onę, aby nie była ta sprośność między wami.
“‘Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ tìyátọmọ papọ̀, ìwà búburú ni èyí: iná ni kí ẹ fi sun wọ́n, òun àti àwọn méjèèjì, kí ìwà búburú má ba à gbilẹ̀ láàrín yín.
15 Także kto by się złączył z bydlęciem, śmiercią umrze, bydlę też zabijecie.
“‘Bí ọkùnrin kan bá bá ẹranko lòpọ̀, ẹ gbọdọ̀ pa ọkùnrin náà àti ẹranko náà.
16 Niewiasta, która by przystąpiła do jakiego bydlęcia, aby z niem obcowała, zabijesz niewiastę i bydlę; śmiercią umrą, krew ich będzie na nich.
“‘Bí obìnrin kan bá súnmọ́ ẹranko tí ó sì bá a lòpọ̀ obìnrin náà àti ẹranko náà ni kí ẹ pa, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò sì wà lórí ara wọn.
17 Kto by też pojął siostrę swoję, córkę ojca swego, albo córkę matki swej, i widziałby sromotę jej, i ona by widziała sromotę jego, rzecz haniebna jest; przetoż wytraceni będą przed oczyma synów ludu swego; sromotę siostry swej odkrył, nieprawość swoję poniesie.
“‘Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ arábìnrin rẹ̀ yálà ọmọbìnrin baba rẹ̀ tàbí ọmọbìnrin ìyá rẹ̀ tí ó sì bá a lòpọ̀, ohun ìtìjú ni èyí, ẹ ó gé wọn kúrò lójú àwọn ènìyàn wọn, ó ti tàbùkù arábìnrin rẹ̀. Ẹ̀bi rẹ̀ yóò wá sórí rẹ̀.
18 Kto by spał z niewiastą czasu przyrodzonej choroby jej, i odkryłby sromotę jej, i obnażyłby płynienie jej, i ona by też odkrywała płynienie krwi swojej, wytraceni będą oboje z pośrodku ludu swego.
“‘Bí ọkùnrin kan bá súnmọ́ obìnrin, ní àkókò nǹkan oṣù rẹ̀ tí ó sì bá a lòpọ̀. Ó ti tú orísun ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. Òun náà sì gbà á láààyè. Àwọn méjèèjì ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn wọn.
19 Sromoty siostry matki twej i siostry ojca twego nie odkryjesz; bo kto by pokrewną swoję obnażył, nieprawość swoję poniesie.
“‘Má ṣe bá arábìnrin baba tàbí ti ìyá rẹ lòpọ̀, nítorí o ti tú ìhòhò ìbátan rẹ, ẹ̀yin méjèèjì ni yóò ru ẹ̀bi yín.
20 Kto by też spał z żoną stryja swego, sromotę stryja swego odkrył, grzech swój poniosą, bez dzieci pomrą.
“‘Bí ọkùnrin kan bá bá aya arákùnrin baba rẹ̀ lòpọ̀ ó ti tàbùkù arákùnrin baba rẹ̀. A ó jẹ wọ́n ní ìyà; wọn yóò sì kú láìlọ́mọ.
21 Także kto by pojął żonę brata swego, sprośność jest; sromotę brata swego odkrył, bez dzieci będą.
“‘Bí ọkùnrin kan bá gba aya arákùnrin rẹ̀, ohun àìmọ́ ni èyí, ó ti tàbùkù arákùnrin rẹ̀, wọn ó wà láìlọ́mọ.
22 Strzeżcież tedy wszystkich ustaw moich, i wszystkich sądów moich, a czyńcie je, aby was nie wyrzuciła ziemia, do której Ja was wprowadzę, abyście w niej mieszkali.
“‘Kí ẹ pa gbogbo àṣẹ àti òfin mi mọ́, kí ẹ sì máa ṣe wọ́n. Kí ilẹ̀ náà tí èmi ó fi fún yín láti máa gbé má ba à pọ̀ yín jáde.
23 A nie chodźcie w ustawach tego narodu, który Ja wypędzam od oblicza waszego; bo to wszystko czynili, i obrzydziłem je sobie.
Ẹ má ṣe tẹ̀lé àṣà àwọn orílẹ̀-èdè tí mo lé jáde níwájú yín torí pé gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni wọ́n ń ṣe, tí mo kórìíra wọn.
24 Wam zaś powiedziałem: Wy posiądziecie ziemię ich, a Ja wam ją dam w dziedzictwo, ziemię opływającą mlekiem i miodem. Jam Pan, Bóg wasz, którym was wyłączył od innych narodów.
Ṣùgbọ́n mo ti sọ fún yín pé, “Ẹ̀yin ni yóò jogún ilẹ̀ wọn, Èmi yóò sì fi fún yín láti jogún ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.” Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín tí ó ti yà yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn yòókù.
25 A tak wy rozeznawajcie między bydlęciem czystem i nieczystem, i między ptakiem nieczystym i czystym, a nie plugawcie dusz waszych bydłem i ptastwem i wszystkiem, co się czołga po ziemi, którem wam odłączył za nieczyste.
“‘Ẹ gbọdọ̀ pààlà sáàrín ẹran tí ó mọ́ àti àwọn tí kò mọ́. Láàrín ẹyẹ tí ó mọ́ àti àwọn tí kò mọ́. Ẹ má ṣe sọ ara yín di àìmọ́ nípasẹ̀ àwọn ẹranko tàbí ẹyẹ tàbí ohunkóhun tí ń rìn lórí ilẹ̀: èyí tí mo yà sọ́tọ̀ fún yín gẹ́gẹ́ bí ohun àìmọ́.
26 I będziecie mi świętymi, bom Ja święty Pan, i odłączyłem was od innych narodów, abyście byli moimi.
Ẹ gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ fún mi torí pé, Èmi Olúwa fẹ́ mímọ́. Mó sì ti yà yín kúrò nínú àwọn orílẹ̀-èdè yòókù kí ẹ le jẹ́ tèmi.
27 Mąż albo niewiasta, w których by był duch czarnoksięski albo wieszczy, śmiercią umrą: kamieniem ukamionują ich, krew ich będzie na nich.
“‘Ọkùnrin tàbí obìnrin tí ó jẹ́ abókùúsọ̀rọ̀ tàbí oṣó láàrín yín ni kí ẹ pa. Ẹ sọ wọ́n ní òkúta, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.’”

< Kapłańska 20 >