< Księga Sędziów 3 >

1 A teć są narody, które pozostawił Pan, aby kusił przez nie Izraela, wszystkie, którzy nie wiedzieli o żadnych walkach Chananejskich;
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa fi sílẹ̀ láti dán àwọn ìran tuntun ní Israẹli wò, àwọn ìran tí kò ì tí ì ní ìrírí ogun àwọn ará Kenaani.
2 Aby wżdy wiedzieli potomkowie synów Izraelskich, i poznali, co jest walka, którzy jej zgoła przedtem nie znali.
(Ó ṣe èyí láti fi kọ́ àwọn ìran Israẹli tí kò rí ogun rí níbí a ti ṣe ń jagun).
3 Pięcioro książąt Filistyńskich i wszystkie Chananejczyki, i Sydończyki i Hewejczyki, mieszkające na górze Libanie, od góry Baal Hermon aż tam, gdzie wchodzą do Hemat.
Àwọn ìjòyè ìlú Filistini márààrún, gbogbo àwọn ará Kenaani, àwọn ará Sidoni, àti àwọn ará Hifi tí ń gbé ní àwọn òkè Lebanoni bẹ̀rẹ̀ láti òkè Baali-Hermoni títí dé Lebo-Hamati.
4 Cić byli, przez które doświadczał Izraela, aby się dowiedział, będąli posłuszni przykazaniom Pańskim, które rozkazał ojcom ich przez Mojżesza.
A fi àwọn ènìyàn náà sílẹ̀ láti dán àwọn Israẹli wò bóyá wọn yóò gbọ́rọ̀ sí àwọn òfin Olúwa, èyí tí ó ti fi fún àwọn baba wọn láti ipasẹ̀ Mose.
5 A tak synowie Izraelscy mieszkali w pośród Chananejczyków, Hetejczyków, i Amorejczyków, i Ferezejczyków i Hewejczyków, i Jebuzejczyków.
Àwọn ọmọ Israẹli gbé láàrín àwọn ará Kenaani, àwọn ará Hiti àwọn ará Amori, àwọn ará Peresi, àwọn ará Hifi àti àwọn ará Jebusi.
6 I brali sobie córki ich za żony, a córki swe dawali synom ich, i służyli bogom ich.
Dípò kí wọ́n run àwọn ènìyàn wọ̀nyí, Israẹli ń fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn, wọ́n sì ń fi àwọn ọmọbìnrin Israẹli fún àwọn ará ilẹ̀ náà ní aya, wọ́n sì ń sin àwọn òrìṣà wọn.
7 I czynili Izraelscy synowie złe przed oczyma Pańskiemi: zapomniawszy Pana, Boga swego, służyli Baalom, i święconym gajom.
Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe èyí tí ó burú níwájú Olúwa, wọ́n gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn, wọ́n sì ń sin Baali àti Aṣerah.
8 Tedy się zapalił gniew Pański przeciw Izraelowi, i podał je w rękę Chusanrasataima, króla Syrskiego w Mezopotamii: A służyli synowie Izraelscy Chusanrasataimowi przez osiem lat.
Ìbínú Olúwa sì ru sí Israẹli tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi jẹ́ kí Kuṣani-Riṣataimu ọba Aramu-Naharaimu bá wọn jà kí ó sì ṣẹ́gun wọn, Israẹli sì ṣe ẹrú rẹ̀ fún ọdún mẹ́jọ.
9 Potem wołali synowie Izraelscy do Pana; I wzbudził Pan wybawiciela synom Izraelskim, aby je wybawił, Otonijela, syna Kenezowego, brata Kalebowego młodszego.
Ṣùgbọ́n nígbà tí Israẹli kígbe sí Olúwa, Òun gbé olùgbàlà kan dìde fún wọn, ẹni náà ni Otnieli ọmọ Kenasi àbúrò Kalebu tí ó jẹ́ ọkùnrin, ẹni tí ó gbà wọ́n sílẹ̀.
10 I był nad nim Duch Pański, a sądził Izraela; a gdy się ruszył na wojnę, podał Pan w rękę jego Chusanrasataima, króla Syryjskiego, i zmocniła się ręka jego nad Chusanrasataimem.
Ẹ̀mí Olúwa bà lé e, òun sì ṣe ìdájọ́ Israẹli, ó sì síwájú wọn lọ sí ogun. Olúwa sì fi Kuṣani-Riṣataimu ọba Aramu lé Otnieli lọ́wọ́, ẹni tí ọwọ́ rẹ̀ sì borí Kuṣani-Riṣataimu.
11 A tak była w pokoju ziemia przez czterdzieści lat, aż umarł Otonijel, syn Kenezów.
Ilẹ̀ náà sì wà ní àlàáfíà fún ogójì ọdún títí tí Otnieli ọmọ Kenasi sì kú.
12 Potem znowu synowie Izraelscy czynili złe przed oczyma Pańskiemi. I zmocnił Pan Eglona, króla Moabskiego, przeciw Izraelowi, przeto iż czynili złe przed oczyma Pańskiemi.
Àwọn ọmọ Israẹli sì tún padà sí ìwà ẹ̀ṣẹ̀ wọn, wọ́n sì ṣe èyí tí ó burú ní iwájú Olúwa, fún ìdí iṣẹ́ búburú yìí, Olúwa fún Egloni, ọba àwọn Moabu ní agbára ní orí Israẹli.
13 Bo zebrawszy do siebie syny Ammonowe i Amalekowe ruszył się, i poraził Izraela, i opanował miasto Palm.
Pẹ̀lú ìfi ọwọ́ ṣowọ́pọ̀ ogun àwọn Ammoni àti àwọn ọmọ-ogun Amaleki ní Egloni gbógun ti àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì gba ìlú Ọ̀pẹ tí i se Jeriko.
14 Służyli tedy synowie Izraelscy Eglonowi, królowi Moabskiemu, osiemnaście lat.
Àwọn ọmọ Israẹli sì sin Egloni ọba Moabu fún ọdún méjìdínlógún.
15 Potem wołali synowie Izraelscy do Pana. I wzbudził im Pan wybawiciela, Aoda, syna Gery, syna Jemini, męża ręką prawą niewładającego; i posłali synowie Izraelscy przezeń dar Eglonowi, królowi Moabskiemu.
Ṣùgbọ́n nígbà tí Israẹli tún ké pe Olúwa, Olúwa rán olùgbàlà kan sí wọn, Ehudu ẹni tí ń lo ọwọ́ òsì, ọmọ Gera ti ẹ̀yà Benjamini. Àwọn ọmọ Israẹli fi ẹ̀bùn rán sí Egloni ọba Moabu.
16 I uczynił sobie Aod miecz z obu stron ostry, na łokieć wzdłuż, i przypasał go pod szaty swe do prawego biodra swojego.
Ehudu sì rọ idà kan olójú méjì, ìgbọ̀nwọ́ kan ní gígùn; òun sì sán an ní abẹ́ aṣọ rẹ̀ ní itan rẹ̀ ọ̀tún.
17 I przyniósł dar Eglonowi, królowi Moabskiemu: a Eglon był człowiek bardzo otyły.
Ó sì mú ọrẹ náà wá fún Egloni ọba Moabu, Egloni ẹni tí ó sanra púpọ̀.
18 A gdy oddał dar, odprawił lud, który był dar przyniósł;
Lẹ́yìn tí Ehudu ti fi ẹ̀bùn náà fún ọba tan, ó rán àwọn tí ó kó ẹrú náà wá lọ sí ọ̀nà wọn.
19 A sam wróciwszy się do gór kamiennych, które były w Galgal, rzekł: Rzecz tajemną mam do ciebie, o królu! któremu on odpowiedział: Milcz; i wyszli od niego wszyscy, którzy stali przed nim.
Ṣùgbọ́n nígbà tí òun fúnra rẹ̀ dé ibi ère fínfín tí ó wà létí Gilgali, ó padà sí Egloni, ó sì wí pé, “Ọba, mo ní ọ̀rọ̀ àṣírí láti bá ọ sọ.” Ọba sì wí pé, “Ẹ dákẹ́!” Gbogbo àwọn tí ń ṣọ sì jáde síta kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ̀.
20 I wszedłszy Aod do niego, (a on sam siedział na sali letniej, którą miał sam dla siebie, ) i rzekł Aod: Mam rozkazanie Boże do ciebie. I powstał z stolicy swojej.
Ehudu lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ níbi tí ó ti jókòó ní iyàrá ìtura rẹ̀, Ehudu sì wí fún un pé, “Mo ní ọ̀rọ̀ kan fún ọ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.” Bí ọba sì ti dìde ní orí ìtẹ́ rẹ̀,
21 Tedy Aod wyciągnąwszy lewą rękę swą, dobył miecza od prawego biodra swego, i wraził go w brzuch jego,
Ehudu fi ọwọ́ òsì rẹ̀ yọ idà láti ibi itan ọ̀tún rẹ̀ ó sì fi gún ọba nínú ikùn rẹ̀.
22 Tak iż wpadła i rękojeść za żelazem, i zawarło się w sadle żelazo; bo był nie wyjął miecza z brzucha jego, aż się i gnój rzucił.
Àti idà àti èèkù rẹ̀ sì wọlé ó sì yọ ní ẹ̀yìn rẹ̀. Ehudu kò yọ idà náà, ọ̀rá sì bo idà náà.
23 Wyszedł potem Aod przez przysionek, a zamknął drzwi gmachu za sobą, i zawarł zamkiem.
Ehudu ti àwọn ìlẹ̀kùn ní àtì-sínú òun sì bá yàrá òkè jáde, ó sì sálọ.
24 A gdy on wyszedł, słudzy jego przyszli, a widząc, iż drzwi gmachu zamknione były, rzekli: Podobno sobie król czyni wczas na sali letniej.
Lẹ́yìn tí ó ti lọ àwọn ìránṣẹ́ ọba dé, ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n rí ìlẹ̀kùn yàrá òkè ní títì, wọ́n rò pé, “Bóyá ó wà ní ilé ìyàgbẹ́ ní yàrá nínú ilé.”
25 A naczekawszy się, aż się wstydzili, widząc, że on nie otwiera drzwi sali, wziąwszy klucz otworzyli; a oto, pan ich leżał na ziemi umarły.
Nígbà tí wọ́n dúró dé ibi pé ó jẹ́ ìyanu fún wọn, wọ́n mú kọ́kọ́rọ́, wọ́n sì ṣí ìlẹ̀kùn. Níbẹ̀ ni wọ́n ti rí Olúwa wọn tí ó ti ṣubú, ó sì ti kú.
26 Lecz Aod uszedł, póki się oni bawili, a minąwszy góry kamienne, szedł do Seiratu.
Nígbà tí wọ́n dúró tí wọn sì ń retí, Ehudu ti sálọ. Ó ti gba ibi tí wọ́n ti ń gbẹ́ òkúta lére, ó sì sálọ sí Seira.
27 A gdy przyszedł, zatrąbił w trąbę na górze Efraim; i zstąpili z nim synowie Izraelscy z góry, a on przed nimi.
Nígbà tí ó dé ibẹ̀, ó fọn ìpè ní orí òkè Efraimu, àwọn ọmọ Israẹli sì ba sọ̀kalẹ̀ lọ láti òkè náà wá, òun sì wà níwájú wọn.
28 I rzekł do nich: Pójdźcie za mną: albowiem podał Pan nieprzyjacioły wasze Moabity w ręce wasze. Tedy szli za nim, a odjąwszy bród Jordański Moabitom, nie dopuszczali nikomu przeprawy.
Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ máa tẹ̀lé mi, nítorí Olúwa ti fi Moabu ọ̀tá yín lé yín lọ́wọ́.” Wọ́n sì tẹ̀lé e, wọ́n sì gba ìwọdò Jordani tí ó lọ sí ilẹ̀ Moabu, wọn ò jẹ́ kí ẹnikẹ́ni kọjá.
29 I pobili Moabitów na ten czas około dziesięciu tysięcy mężów, wszystko bogatych, i wszystko mężów dużych, a nikt nie uszedł.
Ní báyìí, wọ́n ti pa tó ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ọkùnrin ará Moabu tí wọ́n jẹ́ alágbára àti onígboyà ènìyàn, kò sí ènìyàn tí ó sálà.
30 I poniżony jest Moab dnia onego pod ręką Izraela, a była w pokoju ziemia przez osiemdziesiąt lat.
Ní ọjọ́ náà ni Israẹli ṣẹ́gun àwọn ará Moabu, ilẹ̀ náà sì wà ní àlàáfíà fún ọgọ́rin ọdún.
31 A po nim był Samgar, syn Anatów, który poraził z Filistynów sześć set mężów stykiem wołowym, a wybawił i ten Izraela.
Lẹ́yìn Ehudu, ni Ṣamgari ọmọ Anati ẹni tí ó pa ẹgbẹ̀ta Filistini pẹ̀lú ọ̀pá tí a fi ń da akọ màlúù, òun pẹ̀lú sì gba Israẹli kúrò nínú ìpọ́njú.

< Księga Sędziów 3 >