< Księga Sędziów 20 >
1 Wyszli tedy wszyscy synowie Izraelscy, a zgromadziło się wszystko pospólstwo jednomyślnie od Dan aż do Beerseba, i do ziemi Galaad do Pana do Masfy.
Gbogbo àwọn ọmọ Israẹli láti Dani dé Beerṣeba, àti láti ilẹ̀ Gileadi jáde bí ẹnìkan ṣoṣo wọ́n sì péjọ síwájú Olúwa ni Mispa.
2 I stanęli przedniejsi wszystkiego ludu i wszystkie pokolenia Izraelskie w zgromadzeniu ludu Bożego, cztery kroć sto tysięcy ludu pieszego, godnego do boju.
Àwọn olórí gbogbo àwọn ènìyàn láti gbogbo ẹ̀yà Israẹli dúró ní ipò wọn ní àpéjọ àwọn ènìyàn Ọlọ́run, ogún ọ̀kẹ́ ọkùnrin ológun ti àwọn àti idà wọn.
3 (I usłyszeli synowie Benjamin, iż się zebrali synowie Izraelscy w Masfa.) Rzekli tedy synowie Izraelscy: Powiedzcie, jako się stał ten zły uczynek?
(Àwọn ẹ̀yà Benjamini gbọ́ wí pé àwọn ọmọ Israẹli yòókù ti gòkè lọ sí Mispa.) Nígbà náà ni àwọn ọmọ Israẹli wí pé, “Ẹ sọ fún wa báwo ni iṣẹ́ búburú ṣe ṣẹlẹ̀.”
4 I odpowiedział on mąż Lewita, małżonek niewiasty zabitej, i rzekł: Do Gabaa, które jest w Benjamin, przyszedłem, ja i założnica moja, abym tam przenocował.
Ará Lefi náà, ọkọ obìnrin tí wọ́n pa fèsì pé, “Èmi àti àlè mi wá sí Gibeah ti àwọn ará Benjamini láti sùn di ilẹ̀ mọ́ níbẹ̀.
5 I powstali przeciwko mnie mężowie z Gabaa, a obstąpili około mnie dom w nocy, umyśliwszy mię zabić; ale założnicę moję tak gwałcili, aż umarła.
Ṣùgbọ́n ní òru àwọn ọkùnrin Gibeah lépa mi wọ́n sì yí ilé náà po pẹ̀lú èrò láti pa mí. Wọ́n fi ipá bá àlè mi lòpọ̀, òun sì kú.
6 Wziąłem tedy założnicę moję, i rozrąbałem ją na sztuki, i rozesłałem ją do wszystkich krain dziedzictwa Izraelskiego; albowiem się dopuścili w Izraelu haniebnego i sprosnego uczynku.
Mo mú àlè mi náà, mo sì gé e sí ekìrí ekìrí, mo sì fi ekìrí kọ̀ọ̀kan ránṣẹ́ sí agbègbè ìní Israẹli kọ̀ọ̀kan, nítorí pé wọ́n ti ṣe ohun tí ó jẹ́ èèwọ̀ àti ohun ìtìjú yìí ní ilẹ̀ Israẹli.
7 Otoście wy wszyscy synowie Izraelscy; uważcież to między sobą, a radźcie o tem.
Nísinsin yìí, gbogbo ẹ̀yin ọmọ Israẹli, ẹ sọ ìmọ̀ràn yín, kí ẹ sì ṣe ìdájọ́ yín.”
8 I powstał wszystek lud jednostajnie, mówiąc: Nie pójdzie nikt do namiotu swego, ani odejdzie kto do domu swego.
Gbogbo àwọn ènìyàn náà sì dìde bí ẹnìkan pẹ̀lú gbólóhùn kan wí pé, “Kò sí ẹnikẹ́ni nínú wa tí yóò lọ sí àgọ́ rẹ̀. Rárá o, kò sí ẹyọ ẹnìkan tí yóò padà lọ sí ilé rẹ̀.
9 Ale teraz to uczynimy miastu Gabaa, rzuciwszy los przeciwko niemu;
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ohun tí àwa yóò ṣe sí Gibeah ní yìí. Àwa yóò lọ kọlù ú bí ìbò bá ṣe darí wa.
10 Weźmiemy dziesięć mężów ze sta w każdem pokoleniu Izraelskiem, a sto z tysiąca, a tysiąc z dziesięciu tysięcy, żeby dodawali żywności ludowi, który przyciągnie do Gabaa Benjamin, i pomści się nad nim wszystkiej sprosności, której się dopuścili w Izraelu.
A yóò mú ọkùnrin mẹ́wàá nínú ọgọ́rùn-ún nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli àti ọgọ́rùn-ún láti inú ẹgbẹ̀rún kan àti ẹgbẹ̀rún kan láti inú ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá láti máa pèsè oúnjẹ fún àwọn ọmọ-ogun. Yóò sì ṣe nígbà tí àwọn jagunjagun bá dé Gibeah ti àwọn ará Benjamini, wọn yóò fún wọn ní ohun tí ó bá tọ́ sí wọn fún gbogbo ìwà búburú àti ìwà ìtìjú tí wọ́n ṣe yìí ní ilẹ̀ Israẹli.”
11 A tak zebrał się wszystek lud Izraelski przeciwko miastu, zmówiwszy się jednostajnie.
Báyìí ni gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli parapọ̀ ṣọ̀kan bí ọkùnrin kan ṣoṣo wọ́n sì dìde sí ìlú náà.
12 I posłały pokolenia Izraelskie posły do wszystkich domów synów Benjaminowych, mówiąc: Co to za zły uczynek, który się stał między wami?
Àwọn ẹ̀yà Israẹli rán àwọn ọkùnrin sí gbogbo ẹ̀yà Benjamini wí pé, “Kí ni ẹ̀rí sí ìwà búburú yìí tí ó ṣẹlẹ̀ ní àárín yín?
13 Przetoż teraz wydajcie męże niepobożne, którzy są w Gabaa, abyśmy je pozabijali, a uprzątnęli złe z Izraela; ale nie chcieli synowie Benjaminowi słuchać głosu braci swych, synów Izraelskich.
Nítorí náà ẹ mú àwọn ẹni ibi ti Gibeah yìí wá fún wa, kí àwa lé pa, kí a sì fọ ìṣe búburú yìí mọ́ kúrò ní Israẹli.” Ṣùgbọ́n àwọn ẹ̀yà Benjamini kò fetí sí ti àwọn arákùnrin wọn ọmọ Israẹli.
14 Owszem zgromadzili się synowie Benjaminowi z miast swoich do Gabaa, aby walczyli przeciw synom Izraelskim.
Àwọn ẹ̀yà Benjamini sì kó ara wọn jọ láti àwọn ìlú wọn sí Gibeah láti bá àwọn ọmọ Israẹli jà.
15 I naliczono synów Benjaminowych dnia onego z miast ich dwadzieścia i sześć tysięcy mężów godnych do boju, oprócz obywateli Gabaa, których naliczono siedem set mężów na wybór.
Ní ẹsẹ̀kẹsẹ̀ àwọn ará Benjamini kó ẹgbàá mẹ́tàlá àwọn ọmọ-ogun tí ń lọ dájọ́ láti àwọn ìlú wọn, yàtọ̀ sí àwọn ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin àṣàyàn ọkùnrin nínú àwọn tí ń gbé Gibeah.
16 Między tym wszystkim ludem było siedem set mężów na wybór, którzy nie używali ręki swej prawej, a każdy z nich ciskając z procy kamieniem, i włosa nie chybiał.
Ní àárín àwọn ọmọ-ogun wọ̀nyí ni ó ti ní àwọn ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin àṣàyàn ọkùnrin tí wọ́n ń lo ọwọ́ òsì, tí ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn dára dé bi pé wọ́n lè fi kànnàkànnà ba fọ́nrán òwú ní àìtàsé (wọ́n jẹ́ atamọ́tàsé).
17 Mężów zasię Izraelskich naliczono, oprócz synów Benjaminowych, cztery kroć sto tysięcy mężów walecznych, i wszystko godnych do boju.
Àwọn ọkùnrin Israẹli, yàtọ̀ sí àwọn ará Benjamini, ka ogún ọ̀kẹ́ àwọn tí ń fi idà jagun, gbogbo wọn jẹ́ akọni ní ogun jíjà.
18 Wstawszy tedy szli do domu Bożego, i radzili się Boga, a mówili synowie Izraelscy: Któż za nas pójdzie wprzód na wojnę przeciw synom Benjaminowym? I odpowiedział Pan: Juda wprzód pójdzie.
Àwọn ọmọ Israẹli lọ sí Beteli, wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run. Wọ́n wí pé, “Ta ni nínú wa tí yóò kọ́ kojú àwọn ará Benjamini láti bá wọn jà?” Olúwa dáhùn pé, “Juda ni yóò kọ́ lọ.”
19 A tak wstawszy synowie Izraelscy rano, położyli się obozem przeciw Gabaa.
Àwọn ọmọ Israẹli dìde ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, wọ́n sì dó ti Gibeah (wọ́n tẹ̀gùn sí ẹ̀bá Gibeah).
20 A wyszedłszy mężowie Izraelscy ku bitwie przeciw synom Benjaminowym, uszykowali się mężowie Izraelscy ku potykaniu przeciw Gabaa.
Àwọn ọkùnrin Israẹli jáde lọ láti bá àwọn ará Benjamini jà wọ́n sì dúró ní ipò ogun sí wọn ní Gibeah.
21 Ale wyszedłszy synowie Benjaminowi z Gabaa, porazili z Izraela dnia onego dwadzieścia i dwa tysiące mężów na głowę.
Àwọn ọmọ Benjamini sì jáde láti Gibeah wá wọ́n sì pa àwọn ọmọ ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ọkùnrin nínú àwọn ọmọ Israẹli ní ojú ogun ní ọjọ́ náà.
22 Potem pokrzepiwszy się mężowie ludu Izraelskiego znowu się uszykowali ku bitwie na onemże miejscu, gdzie się byli uszykowali dnia pierwszego.
Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Israẹli mú ara wọn lọ́kàn le, wọ́n sì tún dúró sí ipò wọn ní ibi tí wọ́n dúró sí ní ọjọ́ àkọ́kọ́.
23 Pierwej jednak poszli synowie Izraelscy, i płakali przed Panem aż do wieczora, i pytali się Pana, mówiąc: Izali jeszcze mamy iść walczyć przeciwko synom Benjamina, brata naszego? I rzekł Pan: Idźcie przeciwko nim.
Àwọn ọmọ Israẹli sì lọ wọ́n sọkún ní iwájú Olúwa títí oòrùn fi wọ̀, wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ Olúwa. Wọ́n ni, “Ṣé kí àwa tún gòkè lọ kí a sì bá àwọn ará Benjamini arákùnrin wa jà?” Olúwa dáhùn pé, “Lọ bá wọn jà.”
24 I ruszyli się synowie Izraelscy przeciwko synom Benjaminowym drugiego dnia.
Àwọn ọmọ Israẹli sì tún súnmọ́ tòsí àwọn ará Benjamini ní ọjọ́ kejì.
25 A wypadłszy synowie Benjaminowi przeciwko nim z Gabaa drugiego dnia, porazili synów Izraelskich znowu osiemnaście tysięcy mężów na głowę, wszystko mężów walecznych.
Ní ọjọ́ yìí nígbà tí ará Benjamini jáde sí wọn láti Gibeah, láti dojúkọ wọn, wọ́n pa ẹgbàá mẹ́sàn ọkùnrin Israẹli, gbogbo wọn jẹ́ jagunjagun tí ń lo idà.
26 Przetoż szli wszyscy synowie Izraelscy, i wszystek lud, a przyszli do domu Bożego, i płacząc trwali tam przed Panem, i pościli dnia onego aż do wieczora, ofiarując całopalenia, i ofiary spokojne przed obliczem Pańskiem.
Nígbà náà ni gbogbo àwọn ọmọ Israẹli àní gbogbo àwọn ènìyàn, gòkè lọ sí Beteli, níbẹ̀ ni wọ́n jókòó tí wọ́n sì ń sọkún níwájú Olúwa. Wọ́n gbààwẹ̀ ní ọjọ́ náà títí di àṣálẹ́, wọ́n sì rú ọrẹ ẹbọ sísun àti ọrẹ àlàáfíà sí Olúwa.
27 I pytali synowie Izraelscy Pana, (bo tam była skrzynia przymierza Bożego na on czas;
Àwọn ọmọ Israẹli sì béèrè lọ́wọ́ Olúwa. (Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run wà níbẹ̀,
28 A Finees, syn Eleazara, syna Aaronowego, stał przed nią na ten czas, ) mówiąc: Mamyli jeszcze wynijść na wojnę przeciwko synom Benjamina, brata naszego, czyli zaniechać? I odpowiedział Pan: Idźcie; bo jutro dam je w ręce wasze.
Finehasi ọmọ Eleasari ọmọ Aaroni, ní ń ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́ ní iwájú rẹ̀.) wọ́n béèrè pé, “Ṣe àwa tún le lọ sí ogun pẹ̀lú Benjamini arákùnrin wa tàbí kí a má lọ?” Olúwa dáhùn pé, “Ẹ lọ nítorí ní ọ̀la ni èmi yóò fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́.”
29 Tedy poczynił Izrael zasadzki przeciw Gabaa zewsząd w około.
Àwọn ọmọ Israẹli sì yàn àwọn ènìyàn tí ó sá pamọ́ yí Gibeah ká.
30 A ruszywszy się synowie Izraelscy przeciwko synom Benjaminowym dnia trzeciego, uszykowali się przeciw Gabaa, jako pierwszy i wtóry raz.
Wọ́n jáde tọ àwọn ọmọ Benjamini lọ ní ọjọ́ kẹta wọ́n sì dúró ní ipò wọn, wọ́n sì dìde ogun sí Gibeah bí wọ́n ti ṣe tẹ́lẹ̀ rí.
31 Wyszli też synowie Benjaminowi przeciwko ludowi, o odsadziwszy się od miasta, poczęli bić lud i siec, jako pierwszy i wtóry raz po drogach, (z których jedna szła do Betel, a druga do Gabaa, ) i po polu, a zabili około trzydziestu mężów z Izraela.
Àwọn ọmọ Benjamini sì jáde láti pàdé wọn, àwọn ọmọ Israẹli sì tàn wọ́n jáde kúrò ní ìlú náà. Wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣẹ́gun àwọn ọmọ Israẹli bí i ti àtijọ́ dé bi pé wọ́n pa bí ọgbọ̀n ọkùnrin ní pápá àti ní àwọn òpópó náà—àwọn ọ̀nà tí ó lọ sí Beteli àti èkejì sí Gibeah.
32 I rzekli synowie Benjaminowi: Porażeni będą od nas jako i pierwej; lecz synowie Izraelscy mówili: Uciekajmy, a uwiedźmy je od miasta, aż na wielkie drogi.
Nígbà tí àwọn Benjamini ń wí pé, “Àwa ti ń ṣẹ́gun wọn bí i ti ìṣáájú,” àwọn ọmọ Israẹli ń wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a sá kí a lè fà wọ́n kúrò ní ìlú sí ojú òpópó náà.”
33 Zatem wszyscy synowie Izraelscy wstawszy z miejsca swego uszykowali się w Baaltamar; zasadzki też Izraelskie wyszły z miejsca swego, z łąk Gabaa.
Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli dìde kúrò ní ipò wọn, wọ́n sì tẹ̀dó ogun ní Baali-Tamari, àwọn ọmọ-ogun Israẹli tí wọ́n sá pamọ́ sínú igbó jáde kúrò níbi tí wọ́n wà ní ìwọ̀-oòrùn Gibeah.
34 A tak przeszło przez Gabaa dziesięć tysięcy mężów na wybór ze wszystkiego Izraela, i była bitwa sroga, a oni nie widzieli, że ich nieszczęście potkać miało.
Nígbà náà ni ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá àwọn àṣàyàn ológun àwọn ọmọ Israẹli gbógun ti Gibeah láti iwájú ogun náà le gidigidi dé bí i pé àwọn ẹ̀yà Benjamini kò funra pé ìparun wà nítòsí.
35 I poraził Pan Benjamina przed twarzą Izraela, a zabili synowie Izraelscy z Benjamina dnia onego dwadzieścia i pięć tysięcy i sto mężów, wszystko godnych do boju.
Olúwa ṣẹ́gun Benjamini níwájú àwọn ọmọ Israẹli, ní ọjọ́ náà àwọn ọmọ Israẹli pa ẹgbàá méjìlá ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀fà ọkùnrin Benjamini, gbogbo wọn fi idà dìhámọ́ra ogun.
36 A widząc synowie Benjaminowi, że byli porażeni, (bo mężowie Izraelscy ustępowali z placu przed Benjaminem, ufając zasadzkom, które byli uczynili przeciw Gabaa;
Àwọn ẹ̀yà Benjamini sì rí pé wọ́n ti ṣẹ́gun àwọn. Àwọn ọkùnrin Israẹli fàsẹ́yìn níwájú àwọn ẹ̀yà Benjamini nítorí pé wọ́n fọkàn tán àwọn tí ó wà ní ibùba ní ẹ̀bá Gibeah.
37 A ci, co byli na zasadzce, pospieszyli się, i uderzyli na Gabaa, a wpadłszy pobili ostrzem miecza wszystkie, którzy byli w mieście.
Àwọn ọkùnrin tí wọ́n lúgọ yára jáde wọ́n sì tètè wọ Gibeah, wọ́n fọ́nká wọ́n sì fi idà pa gbogbo àwọn tí ó wà nínú ìlú náà.
38 Albowiem znak postawiony mieli mężowie Izraelscy z onymi, co byli w zasadzce, mianowicie, że gdyby dym wielki wypuścili z miasta.
Àwọn ọkùnrin Israẹli àti àwọn tí o ba ní ibùba sínú igbó ti fún ara wọn ní àmì pé, kí àwọn tí ó ba ní ibùba fi èéfín ṣe ìkùùkuu ńlá láti inú ìlú náà,
39 Tedy się mężowie Izraelscy obrócili ku bitwie. Synowie zaś Benjaminowi poczęli bić i siec, i zabili z mężów Izraelskich około trzydziestu mężów; bo rzekli: Zaiste porażeni są przed nami jako i w pierwszej bitwie.
nígbà náà ni àwọn ọkùnrin Israẹli yípadà, wọ́n sá gun. Àwọn ọmọ Benjamini sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ṣẹ́gun àti ní pípa àwọn ọkùnrin Israẹli tí ó to ọgbọ̀n, wọ́n sì wí pé, “Àwa ń ṣẹ́gun wọn bí ìgbà ìjà àkọ́kọ́.”
40 Ale gdy płomień i dym jako słup począł wzgórę wstępować z miasta, tedy obejrzawszy się synowie Benjaminowi nazad, uderzyli, a oto, ogień z miasta, wstępował aż ku niebu.)
Ṣùgbọ́n nígbà tí ìkùùkuu èéfín bẹ̀rẹ̀ sí ní rú sókè láti inú ìlú náà wá, àwọn ẹ̀yà Benjamini yípadà wọ́n sì rí èéfín gbogbo ìlú náà ń gòkè sí ojú ọ̀run.
41 A iż się mężowie Izraelscy obrócili, potrwożyli się mężowie Benjaminowi, widząc, że nieszczęście następowało na nie.
Àwọn ọkùnrin Israẹli sì yípadà sí wọn, ẹ̀rù gidigidi sì ba àwọn ará Benjamini nítorí pé wọ́n mọ̀ pé àwọn wà nínú ewu.
42 I uciekli przed mężami Izraelskimi drogą ku puszczy; a wojsko doganiało ich, i ci, którzy wybieżeli z miast, bili je między sobą.
Wọ́n sì sá níwájú àwọn ọmọ Israẹli sí apá àṣálẹ́, ṣùgbọ́n wọn kò le sálà kúrò lọ́wọ́ ogun náà. Àwọn ọkùnrin Israẹli tí ó jáde láti inú àwọn ìlú wọn wá pa wọ́n run níbẹ̀.
43 Ogarnęli tedy Benjamina, i gonili je bez przestanku, a wparli je aż do Gabaa na wschód słońca.
Wọ́n yí àwọn ẹ̀yà Benjamini ká, wọ́n lépa wọn, wọ́n sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìrọ̀rùn ní ibi ìsinmi wọn ní agbègbè ìlà-oòrùn Gibeah.
44 Poległo tedy z Benjamina, osiemnaście tysięcy mężów, wszystko mężów dużych.
Ẹgbàá mẹ́sàn àwọn ẹ̀yà Benjamini ṣubú, gbogbo wọn jẹ́ akọni jagunjagun.
45 A z tych, którzy obróciwszy się uciekali na puszczą, na skałę Remmon, łapiąc je po drogach, zabili pięć tysięcy mężów, a gonili je aż do Giedeon, gdzie zamordowali z nich dwa tysiące mężów.
Bí wọ́n ṣe síjú padà tí wọ́n sì ń sálọ sí apá ijù lọ sí ọ̀nà àpáta Rimoni ni àwọn ọmọ Israẹli pa ẹgbẹ̀rún márùn-ún ọkùnrin ní àwọn òpópónà. Wọ́n lépa àwọn ẹ̀yà Benjamini títí dé Gidomu, wọ́n sì tún bi ẹgbẹ̀rún méjì ọkùnrin ṣubú.
46 A tak było wszystkich, którzy polegli z Benjamina dnia onego, dwadzieścia i pięć tysięcy mężów walecznych, wszystko mężów dużych.
Ní ọjọ́ náà ẹgbàá méjìlá ó lé ẹgbẹ̀rún jagunjagun Benjamini tí ń fi idà jagun ní ó ṣubú, gbogbo wọn jẹ́ akọni ológun.
47 Tylko się obróciło i uciekło na puszczę, na skałę Remmon, sześć set mężów, i zostali na skale Remmon przez cztery miesiące.
Ṣùgbọ́n ẹgbẹ̀ta ọkùnrin yípadà wọ́n sì sá nínú ààlà lọ sí àpáta Rimoni, níbi tí wọ́n wà fún oṣù mẹ́rin.
48 Potem mężowie Izraelscy wróciwszy się do synów Benjaminowych, wybili je ostrzem miecza, w mieście, począwszy od ludzi aż do bydlęcia, i do wszystkiego, co znaleźli; przytem i wszystkie miasta, które pozostały, popalili ogniem.
Àwọn ọkùnrin Israẹli sì padà sí àwọn ìlú Benjamini wọn sì fi idà pa gbogbo ohun tí ó wà nínú àwọn ìlú wọn àti àwọn ẹran àti gbogbo ohun tí wọn ba níbẹ̀. Gbogbo ìlú tí wọ́n bá ní ojú ọ̀nà ni wọ́n fi iná sun.