< Księga Sędziów 19 >

1 I stało się w one dni, gdy króla nie było w Izraelu, że mąż niektóry Lewita, mieszkający przy stronie góry Efraim, pojął sobie żonę założnicę z Betlehem Juda.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì Israẹli kò ní ọba. Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Lefi tí ń gbé ibi tí ó sá pamọ́ nínú àwọn agbègbè òkè Efraimu, mú àlè kan láti Bẹtilẹhẹmu ní Juda.
2 A bawiła się nierządem przy nim założnica jego; potem odeszła od niego do domu ojca swego, do Betlehem Juda; i była tam u niego przez cztery miesiące.
Ṣùgbọ́n àlè rẹ̀ náà sì ṣe panṣágà sí i, òun fi sílẹ̀, ó sì padà lọ sí ilé baba rẹ̀ ní Bẹtilẹhẹmu ti Juda, ó sì wà ní ibẹ̀ ní ìwọ̀n oṣù mẹ́rin,
3 Wstawszy tedy mąż jej, szedł za nią, aby ją ubłagawszy zasię ją przywiódł, mając z sobą sługę swego, i parę osłów. Tedy ona wwiodła go w dom ojca swego, którego gdy ujrzał ojciec onej dziewki, radował się z przyjścia jego.
ọkọ rẹ̀ lọ sí ibẹ̀ láti rọ̀ ọ́ pé kí ó padà sí ọ̀dọ̀ òun. Nígbà tí ó ń lọ ó mú ìránṣẹ́ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ méjì lọ́wọ́, obìnrin náà mú un wọ inú ilé baba rẹ̀ lọ, nígbà tí baba obìnrin náà rí i ó fi tayọ̀tayọ̀ gbà á.
4 I przyjął go wdzięcznie świekier jego, ojciec dziewki onej, a mieszkał u niego, przez trzy dni, i jedli i pili i nocowali tam.
Àna rẹ̀, baba ọmọbìnrin náà rọ̀ ọ́, ó sì borí rẹ̀ láti dá a dúró fún ìgbà díẹ̀, òun sì dúró fún ọjọ́ mẹ́ta, ó ń jẹ, ó ń mu, ó sì ń sùn níbẹ̀.
5 A dnia czwartego, gdy wstali bardzo rano, wstał i on, aby odszedł. Ale rzekł ojciec onej dziewki do zięcia swego: Posil serce twoje trochą chleba, a potem pójdziecie.
Ní ọjọ́ kẹrin, wọ́n dìde ní òwúrọ̀ kùtùkùtù òun sì múra láti padà lọ, ṣùgbọ́n baba ọmọbìnrin náà wí fún àna rẹ̀ pé, “Fi ohun jíjẹ díẹ̀ gbé inú ró nígbà náà kí ìwọ máa lọ.”
6 Tedy siedli i jedli oboje wespół, i napili się. Zatem rzekł ojciec onej dziewki do męża jej: Zostań proszę, a przenocuj tu, i bądź dobrej myśli.
Àwọn méjèèjì sì jùmọ̀ jókòó láti jọ jẹun àti láti jọ mu. Lẹ́yìn èyí ni baba ọmọbìnrin wí pé, “Jọ̀wọ́ dúró ní alẹ́ yìí kí o sì gbádùn ara rẹ.”
7 A gdy wstał on mąż, chcąc przecię iść w drogę, gwałtem przymusił go świekier jego, iż się wróciwszy został tam na noc.
Nígbà tí ọkùnrin náà dìde láti máa lọ, baba ìyàwó rẹ̀ rọ̀ ọ́, torí náà ó sùn níbẹ̀ ní alẹ́ ọjọ́ náà.
8 Wstał potem bardzo rano dnia piątego, chcąc iść; ale mówił ojciec onej dziewki: Posil proszę serce twoje; i zabawili się, aż się dzień nachylił, a jedli oba społu.
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ karùn-ún nígbà tí ó dìde láti lọ, baba ọmọbìnrin wí pé, “Fi oúnjẹ gbé ara ró. Dúró de ọ̀sán!” Àwọn méjèèjì sì jùmọ̀ jọ jẹun.
9 Wstał tedy on mąż, aby szedł sam i założnica jego, i sługa jego, któremu rzekł świekier jego, ojciec onej dziewki: Oto się już dzień nachylił ku wieczorowi, przenocujcież tu proszę; oto schodzi dzień, przenocuje tu, a bądź dobrej myśli, a jutro rano wyprawicie się w drogę swą, i pójdziesz do przybytku twego.
Nígbà tí ọkùnrin náà, pẹ̀lú àlè àti ìránṣẹ́ rẹ̀, dìde láti máa lọ, àna rẹ̀, baba ọmọbìnrin náà ní, “Wò ó ilẹ̀ ti ń ṣú lọ, dúró níbí, ọjọ́ ti lọ. Dúró kí o sì gbádùn ara rẹ. Ìwọ lè jí ní àárọ̀ kùtùkùtù ọ̀la kí ìwọ sì máa lọ ilé.”
10 Tedy on mąż nie chciał zostać na noc, ale wstał i odszedł, a przyszedł aż ku Jebus, (które jest Jeruzalem) mając z sobą dwóch osłów z brzemiony, i założnicę swoję.
Ṣùgbọ́n nítorí pé òun kò fẹ́ dúró mọ́ níbẹ̀ ní òru náà ọkùnrin náà kúrò ó sì gba ọ̀nà Jebusi: ọ̀nà Jerusalẹmu pẹ̀lú àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ méjèèjì tí ó fi dì í ní gàárì àti àlè rẹ̀.
11 A gdy byli blisko Jebus, a dzień się już bardzo nachylił, tedy rzekł sługa do pana swego: Pójdź proszę, a wstąpmy do tego miasta Jebuzejczyków, i przenocujmy w niem.
Nígbà tí wọ́n súnmọ́ Jebusi tí ilẹ̀ ti fẹ́ ṣú tan, ìránṣẹ́ náà sọ fún ọ̀gá rẹ̀ pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a dúró ní ìlú yìí tí í ṣe ti àwọn ará Jebusi kí a sì sùn níbẹ̀.”
12 Któremu odpowiedział pan jego: Nie wstępujmy do miasta cudzoziemców, które nie jest z synów Izraelskich, ale idźmy aż do Gabaa.
Ọ̀gá rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Rárá o, àwa kì yóò wọ ìlú àwọn àjèjì, àwọn tí olùgbé ibẹ̀ kì í ṣe ọmọ Israẹli, a yóò dé Gibeah.”
13 Nadto rzekł do sługi swego: Pójdź, abyśmy przyszli na jedno z tych miejsc, i przenocowali albo w Gabaa albo w Rama.
Ó fi kún un pé, ẹ wá ẹ jẹ́ kí a gbìyànjú kí a dé Gibeah tàbí Rama kí a sùn ní ọ̀kan nínú wọn.
14 A minąwszy poszli: i zaszło im słońce u Gabaa, które jest pokolenia Benjaminowego.
Wọ́n sì tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò wọn, oòrùn wọ̀ bí wọ́n ti súnmọ́ Gibeah tí ṣe ti àwọn Benjamini.
15 I udali się tam, aby wszedłszy przenocowali w Gabaa; a gdy wszedł, usiadł na ulicy w mieście, przeto że nie był, kto by je przyjął w dom i przenocował.
Wọ́n yípadà wọ́n lọ sí inú ìlú Gibeah láti wọ̀ síbẹ̀ ní òru náà, wọ́n lọ wọ́n sì jókòó níbi gbọ̀ngàn ìlú náà, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó gbà wọ́n sínú ilé rẹ̀ láti wọ̀ sí.
16 A oto, mąż stary szedł od roboty swojej z pola w wieczór; a ten mąż był z góry Efraim, będąc przychodniem w Gabaa, ale ludzie miejsca onego byli synowie Jemini.
Ní alẹ́ ọjọ́ náà ọkùnrin arúgbó kan láti àwọn òkè Efraimu, ṣùgbọ́n tí ń gbé ní Gibeah (ibẹ̀ ni àwọn ẹ̀yà Benjamini ń gbé) ń ti ibi iṣẹ́ rẹ̀ bọ̀ láti inú oko.
17 Ten podniósłszy oczy swe ujrzał męża onego podróżnego na ulicy miasta, i rzekł do niego starzec: Dokąd idziesz, i skądeś przyszedł?
Nígbà tí ó wòkè ó rí arìnrìn-àjò náà ní gbọ̀ngàn ìlú náà, ọkùnrin arúgbó yìí bi í léèrè pé, “Níbo ni ò ń lọ? Níbo ni o ti ń bọ̀?”
18 Któremu on odpowiedział: Idziemy z Betlehem Juda aż ku stronie góry Efraimowej, skądem jest; bom chodził do Betlehem Judskiego; a teraz idę do domu Pańskiego, ale nie masz nikogo, coby mię przyjął w dom;
Ọmọ Lefi náà dá a lóhùn pé, “Bẹtilẹhẹmu ti Juda ni àwa ti ń bọ̀, àwa sì ń lọ sí agbègbè tí ó sá pamọ́ ní àwọn òkè Efraimu níbi ti mo ń gbé. Mo ti lọ sí Bẹtilẹhẹmu ti Juda, èmi sì ń lọ sí ilé Olúwa nísinsin yìí. Kò sí ẹni tí ó gbà mí sí ilé rẹ̀.
19 Choć i plewy i siano mam dla osłów naszych, także chleb i wino mam dla siebie i dla służebnicy twej i dla sługi, który jest ze mną, sługą twoim; nie mam niedostatku z żadnej rzeczy.
Àwa ní koríko àti oúnjẹ tó tó fún àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wa àti oúnjẹ àti wáìnì fún àwa ìránṣẹ́ rẹ—èmi, ìránṣẹ́bìnrin rẹ àti ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú wa. A ò ṣe aláìní ohun kankan.”
20 Tedy mu rzekł on mąż stary: Nie frasuj się; czegoćkolwiek nie dostanie, to ja opatrzę; tylko na ulicy nie zostawaj przez noc.
Ọkùnrin arúgbó náà sì wí pé. “Àlàáfíà fún ọ, bí ó ti wù kí ó rí, èmi yóò pèsè gbogbo ohun tí o nílò, kìkì pé kí ìwọ má ṣe sun ní ìgboro.”
21 Wwiódł go tedy do domu swego, i dał osłom obrok; potem umywszy nogi swoje, jedli i pili.
Òun sì mú wa sí ilé rẹ̀, ó ń bọ́ àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti wẹ ẹsẹ̀ wọn, àwọn àlejò náà jẹ, wọ́n mu.
22 A gdy rozweselili serce swoje, oto, mężowie miasta tego, mężowie niepobożni, obstąpili dom, kołacąc we drzwi, i rzekli do gospodarza domu onego, do męża starego, mówiąc: Wywiedź męża, który wszedł w dom twój, abyśmy go poznali.
Ǹjẹ́ bí wọ́n ti ń ṣe àríyá, kíyèsi i, àwọn ọkùnrin ìlú náà, àwọn ọmọ Beliali kan, yí ilé náà ká, wọ́n sì ń lu ìlẹ̀kùn; wọ́n sì sọ fún baálé ilé náà ọkùnrin arúgbó náà pé, “Mú ọkùnrin tí ó wọ̀ sínú ilé rẹ wá, kí àwa lè mọ̀ ọ́n.”
23 A wyszedłszy do nich on mąż, gospodarz domu, rzekł im: Nie tak bracia moi: nie czyńcie proszę tej złości, gdyż wszedł ten mąż do domu mego, nie czyńcież tej sprosności.
Ọkùnrin, baálé ilé náà sì jáde tọ̀ wọ́n lọ, ó sì wí fún un pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́ ẹ̀yin arákùnrin mi, èmi bẹ̀ yín, ẹ má ṣe hùwà búburú; nítorí tí ọkùnrin yìí ti wọ ilé mi, ẹ má ṣe hùwà òmùgọ̀ yìí.
24 Oto córka moja panna, i założnica jego, wywiodę je zaraz, że je obelżycie, a uczynicie z niemi, co się wam będzie dobrego zdało; tylko mężowi temu nie czyńcie tej zelżywości.
Kíyèsi i, ọmọbìnrin mi ni èyí, wúńdíá, àti àlè rẹ̀; àwọn ni èmi ó mú jáde wá nísinsin yìí, kí ẹ̀yin tẹ̀ wọ́n lógo, kí ẹ̀yin ṣe sí wọn bí ó ti tọ́ lójú yín: ṣùgbọ́n ọkùnrin yìí ni kí ẹ̀yin má ṣe hùwà òmùgọ̀ yìí sí.”
25 Ale nie chcieli oni mężowie słuchać głosu jego; przetoż wziąwszy on mąż założnicę swoję, wywiódł ją do nich na dwór; i poznali ją, a czynili jej gwałt przez całą noc aż do zaranku, a potem puścili ją, gdy wschodziła zorza.
Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin náà kò fetí sí tirẹ̀. Nítorí náà ọkùnrin náà mú àlè rẹ̀ ó sì tari rẹ̀ jáde sí wọn, wọ́n sì bá a fi ipá lòpọ̀, wọ́n sì fi gbogbo òru náà bá a lòpọ̀, nígbà tí ó di àfẹ̀mọ́júmọ́ wọ́n jọ̀wọ́ rẹ̀ lọ́.
26 A przyszedłszy ona niewiasta na świtaniu, upadła u drzwi domu onegoż męża, gdzie był pan jej, aż się rozedniało.
Nígbà tí ojúmọ́ bẹ̀rẹ̀ sí là obìnrin náà padà lọ sí ilé tí ọ̀gá rẹ̀ wà, ó ṣubú lulẹ̀ lọ́nà, ó sì wà níbẹ̀ títí ó fi di òwúrọ̀.
27 Potem wstawszy pan jej rano, otworzył drzwi u domu, i wyszedł, chcąc iść w drogę swoję, a oto, ona niewiasta, założnica jego, leżała u drzwi domu, a ręce jej był na progu.
Nígbà tí ọ̀gá rẹ̀ jí tí ó sì dìde ní òwúrọ̀ tí ó sì ṣí ìlẹ̀kùn ilé náà, tí ó sì bọ́ sí òde láti tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò rẹ̀, kíyèsi i àlè rẹ̀ wà ní ṣíṣubú ní iwájú ilé, tí ọwọ́ rẹ̀ sì di òpó ẹnu-ọ̀nà ibẹ̀ mú,
28 I rzekł do niej: Wstań a pójdźmy; ale nic nie odpowiedziała. Wziąwszy ją tedy na osła, wstał on mąż, i szedł do miejsca swego.
òun sì wí fún obìnrin náà pé, “Dìde jẹ́ kí a máa bá ọ̀nà wa lọ.” Ṣùgbọ́n òun kò dá a lóhùn. Nígbà náà ni ọkùnrin náà gbé e lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, ó sì kọjá lọ sí ilé e rẹ̀.
29 Tam przyszedłszy w dom swój, porwał miecz, a zdjąwszy założnicę swoję rozrąbał ją z kościami jej na dwanaście sztuk, i rozesłał ją po wszystkich granicach Izraelskich.
Nígbà tí ó dé ilé, ó mú ọ̀bẹ ó sì gé àlè rẹ̀ ní oríkeríke sí ọ̀nà méjìlá, ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí gbogbo agbègbè Israẹli.
30 A ktokolwiek to widział, mówił: Nigdy się to nie stało, ani co takowego widziano od onego dnia, jako wyszli synowie Izraelscy z ziemi Egipskiej, aż do tego dnia; uważajcież to z pilnością, a radźcie i mówcie o tem.
Gbogbo ẹni tí ó rí i sì wí pé, “A kò ti rí i, bẹ́ẹ̀ a kò tí ì ṣe irú nǹkan yìí rí, kì í ṣe láti ọjọ́ tí Israẹli ti jáde tí Ejibiti wá títí di òní olónìí. Ẹ rò ó wò, ẹ gbìmọ̀ràn, kí ẹ sọ fún wa ohun tí a yóò ṣe!”

< Księga Sędziów 19 >