< Księga Sędziów 12 >

1 I zebrali się mężowie Efraimscy, a przyszedłszy ku północy, rzekli do Jeftego: Przeczżeś szedł walczyć przeciwko synom Ammonowym, a nie wezwałeś nas, abyśmy szli z tobą? przetoż dom twój i ciebie spalimy ogniem.
Àwọn ọkùnrin Efraimu pe àwọn ológun wọn jáde, wọ́n sì rékọjá sí ìhà àríwá, wọ́n sì bi Jefta pé, “Èéṣe tí o fi lọ bá àwọn ará Ammoni jagun láì ké sí wa láti bá ọ lọ? Àwa yóò sun ilé rẹ mọ́ ọ lórí.”
2 I rzekł Jefte do nich: Miałem nie mały spór ja i lud mój z syny Ammonowymi, i wzywałem was, a nie wybawiliście mię z rąk ich.
Jefta dáhùn pé, “Èmi àti àwọn ènìyàn ní ìyọnu ńlá pẹ̀lú àwọn ará Ammoni, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo pè yín, ẹ̀yin kò gbà mí sílẹ̀ ní ọwọ́ wọn.
3 A widząc, żeście mię wybawić nie chcieli, odważyłem zdrowie swoje, i ciągnąłem przeciw synom Ammonowym, a podał je Pan w ręce moje, i przeczżeście przyszli do mnie dnia tego, abyście walczyli przeciwko mnie?
Nígbà tí mo rí i pé ẹ̀yin kò gbà mí, mo fi ẹ̀mí mi wéwu. Mó sì gòkè lọ láti bá àwọn ará Ammoni jà, Olúwa sì fún mi ní ìṣẹ́gun lórí wọn, èéṣe báyìí tí ẹ fi dìde wá lónìí láti bá mi jà?”
4 A tak zebrawszy Jefte wszystkie męże z Galaad, walczył z Efraimem; i porazili mężowie z Galaad Efraima, przeto iż mówili: Wy Galaadczycy, którzy się bawicie między Efraimitami i między Manasesytami, zbiegowieście od Efraimitów.
Nígbà náà ni Jefta kó gbogbo ọkùnrin Gileadi jọ, ó sì bá Efraimu jà. Àwọn ọkùnrin Gileadi sì kọlù Efraimu, nítorí wọ́n ti sọtẹ́lẹ̀ pé, “Ẹ̀yin ará Gileadi jẹ́ àsáwọ̀ àwọn ará Efraimu àti ti Manase.”
5 I odjęli Galaadczycy brody Jordańskie Efraimowi; a gdy mówili uciekający z Efraimczyków: Niech przejdę, tedy pytali mężowie Galaadscy: A Efratejczykieś ty: A jeźli rzekł: Nie.
Àwọn ará Gileadi gba à bá wọ odò Jordani tí wọ́n máa gbà lọ sí Efraimu, nígbàkígbà tí àwọn ará Efraimu bá wí pé, “Jẹ́ kí ń sálọ sí òkè,” lọ́hùn ún àwọn ará Gileadi yóò bi í pé, “Ṣé ará Efraimu ni ìwọ ń ṣe?” Tí ó bá wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́,”
6 Tedy mu mówili: Wymówże teraz Szybolet; jeźli rzekł: Sybolet, a inaczej nie mógł wymówić, tedy pojmawszy go, zabijali go u brodu Jordańskiego. I poległo na on czas z Efraima czterdzieści i dwa tysiące.
wọ́n ó wí fún un pé, “Ó dá à wí pé ‘Ṣibolẹti.’” Tí ó bá ní, “Sibolẹti,” torí pé kò ní mọ̀ ọ́n pé dáradára, wọ́n á mú un wọn, a sì pa á ni à bá wọ odò Jordani. Àwọn ará Efraimu tí wọn pa ní àkókò yìí jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjìlélógójì ọkùnrin.
7 A tak sądził Jefte Galaadczyk Izraela przez sześć lat; potem umarł Jefte Galaadczyk, a pogrzebion jest w jednem z miast Galaadskich.
Jefta ṣe ìdájọ́ Israẹli ní ọdún mẹ́fà. Lẹ́yìn náà Jefta ará Gileadi kú, wọ́n sì sin ín sí ọ̀kan nínú àwọn ìlú Gileadi.
8 Potem sądził po nim Izraela Abesan z Betlehem.
Lẹ́yìn Jefta, Ibsani ará Bẹtilẹhẹmu ṣe ìdájọ́ àwọn ọmọ Israẹli.
9 A miał trzydzieści synów, i trzydzieści córek, które powydawał od siebie, trzydzieści żon przywiódł synom swoim zinąd, i sądził Izraela przez siedem lat.
Ó ní ọgbọ̀n ọmọkùnrin àti ọgbọ̀n ọmọbìnrin fún àwọn tí kì í ṣe ẹ̀yà rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìyàwó, ó sì fẹ́ ọgbọ̀n àwọn ọmọbìnrin fún àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin lára àwọn tí kì í ṣe ẹ̀yà rẹ̀. Ibsani ṣe ìdájọ́ Israẹli fún ọdún méje.
10 Umarł potem Abesan, i pogrzebion jest w Betlehem.
Lẹ́yìn náà ni Ibsani kú, wọ́n sì sin ín sí Bẹtilẹhẹmu.
11 A po nim sądził Izraela Elon Zabulończyk, i sądził Izraela przez dziesięć lat.
Lẹ́yìn rẹ̀, Eloni ti ẹ̀yà Sebuluni ṣe àkóso Israẹli fún ọdún mẹ́wàá.
12 Potem umarł Elon Zabulończyk, i pogrzebiony jest w Ajalon w ziemi Zabulon.
Eloni sì kú, wọ́n sì sin ín sí Aijaloni ní ilẹ̀ Sebuluni.
13 A po nim sądził Izraela Abdon, syn Hellelów, Faratończyk.
Lẹ́yìn rẹ̀ ni Abdoni ọmọ Hileli tí Piratoni n ṣe àkóso Israẹli.
14 A ten miał czterdzieści synów, i trzydzieści wnuków, którzy jeździli na siedemdziesięciu oślętach; i sądził Izraela przez osiem lat.
Òun ní ogójì ọmọkùnrin àti ọgbọ̀n ọmọ ọmọ àwọn tí ó ń gun àádọ́rin kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Ó ṣe ìdájọ́ Israẹli ní ọdún mẹ́jọ.
15 Umarł potem Abdon, syn Hellelów, Faratończyk, i pogrzebiony jest w Faratonie w ziemi Efraimskiej, na górze Amalekitów.
Abdoni ọmọ Hileli sì kú, wọ́n sin ín sí Piratoni ní ilé Efraimu ní ìlú òkè àwọn ará Amaleki.

< Księga Sędziów 12 >