< Jozuego 7 >

1 Ale zgrzeszyli synowie Izraelscy przestępstwem przy rzeczach przeklętych; albowiem Achan, syn Charmiego, syna Zabdy, syna Zare, z pokolenia Juda, wziął nieco z rzeczy przeklętych; zaczem zapalił się gniew Pański przeciw synom Izraelskim.
Ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli ṣe àìṣòótọ́ nípa ohun ìyàsọ́tọ̀, Akani ọmọ Karmi, ọmọ Sabdi, ọmọ Sera, ẹ̀yà Juda, mú nínú wọn. Bẹ́ẹ̀ ni ìbínú Olúwa ru sí àwọn ará Israẹli.
2 Bo gdy posłał Jozue kilka mężów z Jerycha do Haj, które było blisko Betawen na wschód słońca od Betel, i rzekł do nich, mówiąc: Idźcie, a wyszpiegujcie ziemię; tedy szedłszy oni mężowie, wyszpiegowali Haj.
Joṣua rán àwọn ọkùnrin láti Jeriko lọ sí Ai, tí ó súnmọ́ Beti-Afeni ní ìlà-oòrùn Beteli, ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ gòkè lọ kí ẹ sì ṣe ayọ́lẹ̀wò.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn arákùnrin náà lọ, wọ́n sì yọ́ Ai wò.
3 A wróciwszy się do Jozuego, rzekli mu: Niech nie ciągnie wszystek lud; około dwóch tysięcy mężów, albo około trzech tysięcy mężów niech idą, a zburzą Haj; nie trudź tam wszystkiego ludu, bo ich tam trocha.
Nígbà tí wọ́n padà sí ọ̀dọ̀ Joṣua, wọ́n wí pé, “Kì í ṣe gbogbo àwọn ènìyàn ni ó ni láti gòkè lọ bá Ai jà. Rán ẹgbẹ̀rún méjì tàbí ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkùnrin láti gbà á, kí ó má ṣe dá gbogbo àwọn ènìyàn ní agara, nítorí ìba ọkùnrin díẹ̀ ní ó wà níbẹ̀.”
4 Poszło tedy około trzech tysięcy mężów z ludu, i uciekli przed mężami z Haj.
Bẹ́ẹ̀ ní àwọn bí ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkùnrin lọ; ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Ai lé wọn sá.
5 A porazili z nich mężowie z Haj około trzydziestu i sześciu mężów, goniąc je od bramy aż do Sabarym, a porazili je, gdy uciekali z góry, i dla tego rozpłynęło się serce ludu, i było jako woda.
Àwọn ènìyàn Ai sì pa àwọn bí mẹ́rìndínlógójì nínú wọn. Wọ́n sì ń lépa àwọn ará Israẹli láti ibodè ìlú títí dé Ṣebarimu, wọ́n sì pa àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀. Àyà àwọn ènìyàn náà sì já, ọkàn wọn sì pami.
6 Tedy rozdarłszy Jozue odzienie swoje, upadł twarzą swoją na ziemię przed skrzynią Pańską, a leżał aż do wieczora, on i starsi Izraelscy, posypawszy prochem głowy swoje.
Joṣua sì fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì dojúbolẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa títí di àṣálẹ́. Àwọn àgbà Israẹli sì ṣe bákan náà, wọ́n ku eruku sí orí wọn.
7 Zatem rzekł Jozue: Ach! Panie Panujący, przeczżeś przeprowadził lud ten za Jordan, abyś nas podał w rękę Amorejczyka na wytracenie? O byśmy byli raczej mieszkali za Jordanem!
Joṣua sì wí pé, “Háà, Olúwa Olódùmarè, nítorí kín ni ìwọ ṣe mú àwọn ènìyàn yìí kọjá Jordani, láti fi wọ́n lé àwọn ará Amori lọ́wọ́, láti pa wọn run? Àwa ìbá mọ̀ kí a dúró ní òdìkejì Jordani?
8 O Panie, cóż rzekę, ponieważ podawa Izrael tył nieprzyjaciołom swoim?
Olúwa, kín ni èmi yóò sọ nísinsin yìí tí Israẹli sì ti sá níwájú ọ̀tá a rẹ̀?
9 Bo usłyszawszy Chananejczycy, i wszyscy obywatele tej ziemi, obtoczą nas zewsząd, a wytracą imię nasze z ziemi. I cóż to uczynisz imieniowi twemu wielkiemu?
Àwọn Kenaani àti àwọn ènìyàn ìlú tí ó kù náà yóò gbọ́ èyí, wọn yóò sì yí wa ká, wọn yóò sì ké orúkọ wa kúrò ní ayé. Kí ni ìwọ ó ha ṣe fún orúkọ ńlá à rẹ?”
10 Tedy rzekł Pan do Jozuego: Wstań; przeczżeś upadł na oblicze twoje?
Olúwa sì sọ fún Joṣua pé, “Dìde! Kín ni ìwọ ń ṣe tí ó fi dojúbolẹ̀?
11 Zgrzeszył Izrael, i przestąpili przymierze moje, którem im przykazał; albowiem wzięli z rzeczy przeklętych, a ukradli je, i skłamali, i schowali je między naczynie swoje.
Israẹli ti ṣẹ̀, wọ́n sì ti ba májẹ̀mú mi jẹ́, èyí tí mo pàṣẹ fún wọn pé kí wọn pamọ́. Wọ́n ti mú nínú ohun ìyàsọ́tọ̀, wọ́n ti jí, wọ́n pa irọ́, wọ́n ti fi wọ́n sí ara ohun ìní wọn.
12 A dla tegoć synowie Izraelscy nie będą się mogli ostać przed nieprzyjacioły swymi, tył będą podawali nieprzyjaciołom swym, bo się zmazali rzeczą przeklętą; nie będę więcej z wami, jeźli nie wykorzenicie przeklęstwa tego z pośrodku was.
Ìdí nì èyí tí àwọn ará Israẹli kò fi lè dúró níwájú àwọn ọ̀tá wọn; wọ́n yí ẹ̀yìn wọn padà, wọ́n sì sálọ níwájú ọ̀tá a wọn nítorí pé àwọn gan an ti di ẹni ìparun. Èmi kì yóò wà pẹ̀lú u yín mọ́, bí kò ṣe pé ẹ̀yin pa ohun ìyàsọ́tọ̀ run kúrò ní àárín yín.
13 Wstań, poświęć lud i rzeczy: Poświęćcie się na jutro; bo tak mówi Pan, Bóg Izraelski: Przeklęstwo jest w pośrodku ciebie, Izraelu; nie ostoisz się przed nieprzyjacioły twymi, aż odejmiecie przeklęstwo z pośrodku siebie.
“Lọ, ya àwọn ènìyàn náà sí mímọ́. Sọ fún wọn pé, ‘Ẹ ya ara yín sí mímọ́ fún ọ̀la, nítorí báyìí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí, ohun ìyàsọ́tọ̀ kan ń bẹ ní àárín yín, Israẹli. Ẹ̀yin kì yóò lè dúró níwájú àwọn ọ̀tá a yín títí ẹ̀yin yóò fi mú kúrò.
14 A tak przystąpcie rano według pokoleń waszych; a pokolenie, które okaże Pan, przystąpi według familii; a familija, którą okaże Pan, przystąpi według domów; a dom, który okaże Pan, przystąpi według osób.
“‘Ní òwúrọ̀, kí ẹ mú ará yín wá síwájú ní ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan. Ẹ̀yà tí Olúwa bá mú yóò wá sí iwájú ní agbo ilé kọ̀ọ̀kan, agbo ilé tí Olúwa bá mú yóò wá sí iwájú ní ìdílé kọ̀ọ̀kan, ìdílé tí Olúwa bá sì mú yóò wá sí iwájú ní ẹni kọ̀ọ̀kan.
15 A kto będzie znaleziony w przeklęstwie, będzie spalony ogniem, on, i wszystko, co jego jest, dla tego że przestąpił przymierze Pańskie, a dopuścił się niegodnej rzeczy w Izraelu.
Ẹnikẹ́ni tí a bá ká mọ́ pẹ̀lú ohun ìyàsọ́tọ̀ náà, a ó fi iná pa á run, pẹ̀lú gbogbo ohun tí ó ní. Ó ti ba májẹ̀mú Olúwa jẹ́, ó sì ti ṣe nǹkan ìtìjú ní Israẹli!’”
16 Przetoż wstawszy Jozue rano, rozkazał przystępować Izraelowi według pokoleń ich; i znalazło się pokolenie Juda.
Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Joṣua mú Israẹli wá síwájú ní ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan, a sì mú ẹ̀yà Juda.
17 I kazał przystąpić familii Juda, i znalazła się familija Zare, i kazał przystąpić familii Zarego według osób, i znalazł się dom Zabdy.
Àwọn agbo ilé e Juda wá sí iwájú, ó sì mú agbo ilé Sera. Ó sì mú agbo ilé Sera wá síwájú ní ìdílé kọ̀ọ̀kan, a sì mú ìdílé Sabdi.
18 I kazał przystąpić domowi jego według osób, i znalazł się Achan, syn Charmiego, syna Zabdy, syna Zare, z pokolenia Juda.
Joṣua sì mú ìdílé Simri wá síwájú ní ọkùnrin kọ̀ọ̀kan, a sì mú Akani ọmọ Karmi, ọmọ Sabdi, ọmọ Sera ti ẹ̀yà Juda.
19 I rzekł Jozue do Achana: Synu mój, daj proszę chwałę Panu, Bogu Izraelskiemu, i wyznaj przed nim, a oznajmij mi proszę, coś uczynił, nie taj przede mną.
Nígbà náà ní Joṣua sọ fún Akani pé, “Ọmọ mi fi ògo fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, kí o sì fi ìyìn fún un. Sọ fún mi ohun tí ìwọ ti ṣe, má ṣe fi pamọ́ fún mi.”
20 Tedy odpowiedział Achan Jozuemu, mówiąc: Zaprawdę, jam zgrzeszył Panu, Bogu Izraelskiemu, tak a tak uczyniłem.
Akani sì dáhùn pé, “Òtítọ́ ni! Mo ti ṣẹ̀ sí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli. Nǹkan tí mo ṣe nìyìí,
21 Widziałem między łupy płaszcz babiloński jeden, piękny, i dwieście syklów srebra, i pręt złoty jeden, pięćdziesiąt syklów ważący, i pożądałem tego, i wziąłem to, a oto, te rzeczy są zakopane w ziemi, w pośród namiotu mego, a srebro pod niemi.
nígbà tí mo rí ẹ̀wù Babeli kan tí ó dára nínú ìkógun, àti igba ṣékélì fàdákà àti odindi wúrà olóṣùnwọ́n àádọ́ta ṣékélì, mo ṣe ojúkòkòrò wọn mo sì mú wọn. Mo fi wọ́n pamọ́ ní abẹ́ àgọ́ mi àti fàdákà ní abẹ́ rẹ̀.”
22 Tedy posłał Jozue posły, którzy bieżeli do namiotu, a oto te rzeczy były skryte w namiocie jego, a srebro pod niemi.
Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua ran àwọn òjíṣẹ́, wọ́n sì sáré wọ inú àgọ́ náà, ó sì wà níbẹ̀, a sì fi pamọ́ nínú àgọ́ ọ rẹ̀, àti fàdákà ní abẹ́ ẹ rẹ̀.
23 A wziąwszy je z namiotu przynieśli je do Jozuego, i do wszystkich synów Izraelskich, a położyli je przed obliczem Pańskiem.
Wọ́n sì mú àwọn nǹkan náà jáde láti inú àgọ́ rẹ̀, wọ́n mú wọn wá fún Joṣua àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì fi wọ́n lélẹ̀ níwájú Olúwa.
24 A tak wziąwszy Jozue, i wszystek Izrael z nim, Achana, syna Zarego, i srebro, i płaszcz, i pręt złoty, i syny jego, i córki jego, i woły jego, i osły jego, i owce jego, i namiot jego, i wszystko co miał, wywiedli je na dolinę Achor.
Nígbà náà ni Joṣua pẹ̀lú gbogbo Israẹli, mú Akani ọmọ Sera, fàdákà, ẹ̀wù àti wúrà tí a dà, àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin àti obìnrin, màlúù rẹ̀, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti àgùntàn àgọ́ rẹ̀ àti gbogbo ohun tí ó ni, wọ́n sì kó wọn lọ sí ibi àfonífojì Akori.
25 I rzekł Jozue: Przeczżeś nas potrwożył? niechże cię też Pan zatrwoży dnia tego. I ukamionował go wszystek Izrael, i spalili je ogniem, ukamionowawszy je kamieńmi;
Joṣua sì wí pé, “Èéṣe tí ìwọ mú wàhálà yìí wá sí orí wa? Olúwa yóò mú ìpọ́njú wá sí orí ìwọ náà lónìí.” Nígbà náà ni gbogbo Israẹli sọ ọ́ ní òkúta pa, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sọ àwọn tókù ní òkúta pa tán, wọ́n sì jó wọn níná.
26 Potem wystawili na nim wielką kupę kamieni, która trwa aż do dnia tego. I odwrócił się Pan od gniewu zapalczywości swojej; przetoż nazwane jest imię miejsca onego, dolina Achor, aż do dnia dzisiejszego.
Wọ́n sì kó òkìtì òkúta ńlá lé Akani lórí títí di òní yìí. Nígbà náà ní Olúwa sì yí ìbínú gbígbóná rẹ̀ padà. Nítorí náà ni a ṣe ń pe orúkọ ibẹ̀ ní àfonífojì Akori láti ìgbà náà.

< Jozuego 7 >