< Jozuego 14 >
1 A toć jest, co dziedzictwem wzięli synowie Izraelscy w ziemi Chananejskiej, a co prawem dziedzicznem oddali im w osiadłość Eleazar kapłan i Jozue, syn Nunów, i przedniejsi z ojców z pokolenia synów Izraelskich.
Ìwọ̀nyí ni ilẹ̀ tí àwọn ọmọ Israẹli gbà gẹ́gẹ́ bí ogún ní ilẹ̀ Kenaani, tí Eleasari àlùfáà, Joṣua ọmọ Nuni àti olórí ẹ̀yà àwọn agbo ilé Israẹli pín fún wọn.
2 Losem dzieląc dziedzictwo ich, jako był rozkazał Pan przez Mojżesza, dziewięciorgu pokoleniu i połowie pokolenia.
Ìbò ni a fi pín ìní wọn fún àwọn ẹ̀yà mẹ́sàn-án ààbọ̀ gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ láti ọwọ́ Mose.
3 Albowiem Mojżesz był oddał dziedzictwo dwom pokoleniom i połowie pokolenia za Jordanem; ale Lewitom nie dał był dziedzictwa między nimi.
Mose ti fún àwọn ẹ̀yà méjì àti ààbọ̀ ní ogún wọn ní ìlà-oòrùn Jordani, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Lefi ni kò fi ìní fún ní àárín àwọn tí ó kù.
4 Bo było synów Józefowych dwa pokolenia, Manasesowe i Efraimowe; ani dali działu Lewitom w ziemi, oprócz miast ku mieszkaniu, z przedmieściami ich dla bydła ich i dla trzód ich.
Àwọn ọmọ Josẹfu sì di ẹ̀yà méjì, Manase àti Efraimu. Àwọn ọmọ Lefi kò gba ìpín ní ilẹ̀ náà bí kò ṣe àwọn ìlú tí wọn yóò máa gbé, pẹ̀lú pápá oko tútù fún ọ̀wọ́ ẹran àti agbo ẹran wọn.
5 Jako rozkazał Pan Mojżeszowi, tak uczynili synowie Izraelscy, i podzielili ziemię.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ará Israẹli pín ilẹ̀ náà, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
6 Tedy przyszli synowie Judowi do Jozuego w Galgal; i rzekł do niego Kaleb, syn Jefuna Kenezejskiego: Ty wiesz, co mówił Pan do Mojżesza, męża Bożego, o mnie i o tobie w Kades Barnie.
Àwọn ọkùnrin Juda wá sí ọ̀dọ̀ Joṣua ní Gilgali. Kalebu ọmọ Jefunne ti Kenissiti wí fún un pé, “Ìwọ rántí ohun tí Olúwa sọ fún Mose ènìyàn Ọlọ́run ní Kadeṣi-Barnea nípa ìwọ àti èmi.
7 Czterdzieści mi lat było, gdy mnie słał Mojżesz, sługa Pański, z Kades Barny ku przeszpiegowaniu ziemi, i odniosłem mu tę rzecz, jako było w sercu mojem.
Mo jẹ́ ọmọ ogójì ọdún nígbà tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa rán mi láti Kadeṣi-Barnea lọ rin ilẹ̀ náà wò. Mo sì mú ìròyìn wá fún un gẹ́gẹ́ bí o ti dá mi lójú,
8 Lecz bracia moi, którzy chodzili ze mną, skazili serce ludowi; alem ja przecię szedł statecznie za Panem, Bogiem moim.
ṣùgbọ́n àwọn arákùnrin mi tí wọ́n bá mi lọ mú àyà àwọn ènìyàn já. Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi fi gbogbo ọkàn tẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run mi.
9 I przysiągł Mojżesz dnia onego, mówiąc: Zaiste ziemia, którą deptała noga twoja, przyjdzie tobie w dziedzictwo, i synom twoim aż na wieki, przeto żeś statecznie chodził za Panem, Bogiem moim.
Ní ọjọ́ náà, Mose búra fún mi pé, ‘Ilẹ̀ tí ẹsẹ̀ rẹ ti rìn ni yóò jẹ́ ìní rẹ àti ti àwọn ọmọ rẹ láéláé, nítorí pé ìwọ fi tọkàntọkàn wà pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run mi.’
10 A teraz oto przedłużył żywota mego Pan, jako powiedział; już są czterdzieści i pięć lat od onego czasu, jako to mówił Pan do Mojżesza, a jako chodzili Izraelczycy po puszczy; a teraz oto ja dziś mam osiemdziesiąt i pięć lat:
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, kíyèsi i Olúwa dá mi sí gẹ́gẹ́ bí ó ti wí, láti ọdún márùndínláàádọ́ta yìí wá, láti ìgbà tí Olúwa ti sọ ọ̀rọ̀ yìí fún Mose, nígbà tí Israẹli ń rìn kiri nínú aginjù, sì kíyèsi i nísinsin yìí, èmi nìyìí lónìí, ọmọ àrùndínláàdọ́rùn-ún ọdún.
11 A jeszcze i dziś takiem duży, jakom był w on czas, gdy mię wysłał Mojżesz; a jako moc moja była na on czas, taka jest moc moja i teraz ku bojowaniu, i ku wychodzeniu i przychodzeniu.
Síbẹ̀ èmi ní agbára lónìí, bí ìgbà tí Mose rán mi jáde. Èmi sì ní agbára láti jáde fún ogun nísinsin yìí gẹ́gẹ́ bí mo ti wà ní ìgbà náà.
12 A tak teraz daj mi tę górę, o której powiedział Pan dnia onego; boś ty słyszał dnia onego, iż tam są Enakitowie, i miasta wielki a obronne; będzieli Pan ze mną, wypędzę je, jako mi obiecał Pan.
Nísinsin yìí fi ìlú orí òkè fún mi èyí tí Olúwa ṣe ìlérí fún mi ní ọjọ́ náà. Ìwọ gbọ́ ní ìgbà náà pé àwọn ọmọ Anaki ti wà ní ibẹ̀, àti àwọn ìlú wọn tóbi, pé ó sì ṣe olódi, ṣùgbọ́n bí Olúwa ba fẹ́, èmi yóò lé wọn jáde, gẹ́gẹ́ bí ó ti sọ.”
13 I błogosławił mu Jozue, a dał Hebron Kalebowi, synowi Jefunowemu, w dziedzictwo.
Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua súre fun Kalebu ọmọ Jefunne ó si fun un ní Hebroni ni ilẹ̀ ìní.
14 A tak dostał się Hebron Kalebowi, synowi Jefuna Kenezejskiego, w dziedzictwo aż do dnia tego, przeto że statecznie chodził za Panem, Bogiem Izraelskim.
Bẹ́ẹ̀ ni Hebroni jẹ́ ti Kalebu ọmọ Jefunne ará Kenissiti láti ìgbà náà, nítorí tí ó tẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run Israẹli tọkàntọkàn.
15 A zwano przedtem Hebron miasto Arba, który Arba był człowiekiem wielkim między Enakity; i uspokoiła się ziemia od wojen
(Hebroni a sì máa jẹ́ Kiriati-Arba ní ẹ̀yìn Arba, èyí tí ó jẹ́ ènìyàn ńlá nínú àwọn ọmọ Anaki.) Nígbà náà ni ilẹ̀ náà sinmi ogun.