< Jozuego 1 >

1 I stało się po śmierci Mojżesza, sługi Pańskiego, że mówił Pan do Jozuego syna Nunowego, sługi Mojżeszowego, i rzekł:
Lẹ́yìn ikú u Mose ìránṣẹ́ Olúwa, Olúwa sọ fún Joṣua ọmọ Nuni, olùrànlọ́wọ́ ọ Mose,
2 Mojżesz, sługa mój, umarł; przetoż teraz wstań, przepraw się przez ten Jordan, ty, i wszystek lud ten, do ziemi, którą Ja im, synom Izraelskim, dawam.
“Mose ìránṣẹ́ mi ti kú. Nísinsin yìí, ìwọ àti gbogbo àwọn ènìyàn wọ̀nyí, ẹ múra láti kọjá odò Jordani lọ sí ilẹ̀ tí Èmi ó fi fún wọn fún àwọn ará Israẹli.
3 Każde miejsce, po którem deptać będzie stopa nogi waszej, dałem wam, jakom obiecał Mojżeszowi.
Èmi yóò fún un yín ní gbogbo ibi tí ẹ bá fi ẹsẹ̀ ẹ yín tẹ̀, gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe ìlérí fún Mose.
4 Od puszczy i od Libanu tego, i aż do rzeki wielkiej, rzeki Eufrates, i wszystka ziemia Hetejczyków, i aż do morza wielkiego na zachód słońca, będzie granica wasza.
Ilẹ̀ ẹ yín yóò fẹ̀ láti aginjù Lebanoni, àti láti odò ńlá, ti Eufurate—gbogbo orílẹ̀-èdè Hiti títí ó fi dé Òkun Ńlá ní ìwọ̀-oòrùn.
5 Nie ostoi się nikt przed tobą po wszystkie dni żywota twego; jakom był z Mojżeszem, tak będę z tobą, nie odstąpię cię, ani cię opuszczę.
Kì yóò sí ẹnikẹ́ni tí yóò le è dúró níwájú rẹ ní ọjọ́ ayé è rẹ gbogbo. Bí mo ti wà pẹ̀lú u Mose, bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ, Èmi kì yóò fi ọ́ sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Èmi kì yóò kọ̀ ọ́.
6 Zmacniajże się i mężnie sobie poczynaj; albowiem ty podasz w dziedzictwo ludowi temu ziemię, o którąm przysiągł ojcom ich, że im ją dam.
“Jẹ́ alágbára kí o sì mú àyà le, nítorí ìwọ ni yóò ṣe amọ̀nà àwọn ènìyàn wọ̀nyí, láti lè jogún ilẹ̀ tí mo ti búra fún àwọn baba ńlá a wọn láti fi fún wọn.
7 Tylko się zmacniaj, i bardzo mężnie sobie poczynaj, abyś strzegł, i czynił wszystko według zakonu, któryć rozkazał Mojżesz, sługa mój; nie uchylaj się od niego ani na prawo ani na lewo, żebyś się roztropnie sprawował we wszystkiem, do czego się udasz.
Jẹ́ alágbára, kí o sì mú àyà le gidigidi. Kí o sì ṣọ́ra láti pa gbogbo òfin tí Mose ìránṣẹ́ mi fún ọ mọ́, má ṣe yà kúrò nínú u rẹ̀ sí ọ̀tún tàbí sí òsì, kí ìwọ kí ó lè ṣe rere níbikíbi tí ìwọ bá ń lọ.
8 Niech nie odstępują księgi zakonu tego od ust twoich; ale rozmyślaj w nich we dnie i w nocy, abyś strzegł i czynił wszystko, co napisano w nim; albowiem na ten czas poszczęścią się drogi twoje, i na ten czas roztropnym będziesz.
Má ṣe jẹ́ kí ìwé òfin yìí kúrò ní ẹnu rẹ, máa ṣe àṣàrò nínú u rẹ̀ ní ọ̀sán àti ní òru, kí ìwọ kí ó lè ṣọ́ra láti ṣe gbogbo nǹkan tí a kọ sí inú u rẹ̀. Nígbà náà ni yóò dára fún ọ, ìwọ yóò sì ní àṣeyọrí.
9 Azażemci nie rozkazał: Zmocnij się, i mężnie sobie poczynaj, nie lękaj się, a nie trwóż sobą, albowiem z tobą jest Pan, Bóg twój, we wszystkiem, do czegokolwiek się obrócisz?
Èmi kò ha ti pàṣẹ fún ọ bí? Jẹ́ alágbára kí o sì mú àyà le. Má ṣe bẹ̀rù, má sì ṣe rẹ̀wẹ̀sì, nítorí pé Olúwa à rẹ yóò wà pẹ̀lú rẹ ní ibikíbi tí ìwọ bá ń lọ.”
10 A przetoż rozkazał Jozue przełożonym nad ludem, mówiąc:
Báyìí ni Joṣua pàṣẹ fún olórí àwọn ènìyàn rẹ̀,
11 Przejdźcie przez pośrodek obozu, a rozkażcie ludowi, mówiąc: Gotujcie sobie żywność; albowiem po trzech dniach przejdziecie przez ten Jordan, abyście weszli, a posiedli ziemię, którą Pan, Bóg wasz, dawa wam w osiadłość.
“Ẹ la ibùdó já, kí ẹ sì sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Ẹ pèsè oúnjẹ yín sílẹ̀. Ní ìwòyí ọ̀túnla, ẹ̀yin yóò la Jordani yìí kọjá, láti gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín láti ní.’”
12 Rubenitom też, i Gadytom, i połowie pokolenia Manasesowego rzekł Jozue mówiąc:
Ṣùgbọ́n Joṣua sọ fún àwọn ará a Reubeni, àwọn ará Gadi àti fún ìdajì ẹ̀yà Manase pé,
13 Pamiętajcie na słowo, które wam rozkazał Mojżesz, sługa Pański, mówiąc: Pan, Bóg wasz, sprawił wam odpoczynienie, i dał wam tę ziemię;
“Rántí àṣẹ tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa pa fún yín: ‘Olúwa Ọlọ́run yín á fún yin ní ìsinmi, òun yóò sì fún un yín ní ilẹ̀ yìí.’
14 Żony wasze, dziatki wasze, i bydła wasze niech zostaną w ziemi, którą wam dał Mojżesz z tej strony Jordanu; ale wy pójdziecie zbrojni przed bracią waszą, wszyscy duży w sile, a będziecie ich posiłkować,
Àwọn ìyàwó yín, àwọn ọmọ yín àti àwọn ẹran ọ̀sìn yín lè dúró ní ilẹ̀ tí Mose fún un yin ní ìlà-oòrùn Jordani; ṣùgbọ́n gbogbo àwọn jagunjagun un yín, pẹ̀lú ìhámọ́ra ogun gbọdọ̀ kọjá síwájú àwọn arákùnrin yín. Ẹ̀yin yóò sì rán àwọn arákùnrin yín lọ́wọ́
15 Aż odpoczynienie sprawi Pan braci waszym jako i wam, a oni posiędą ziemię, którą im dawa Pan, Bóg wasz; potem się wrócicie do ziemi osiadłości waszej, a będziecie ją trzymać, którą wam dał Mojżesz, sługa Pański, z tej strony Jordanu na wschód słońca.
títí Olúwa yóò fi fún wọn ní ìsinmi, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fún un yín, àti títí tí àwọn pẹ̀lú yóò fi gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún wọn. Lẹ́yìn náà, ẹ̀yin lè padà sí ilẹ̀ ìní in yín, tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún un yin ní agbègbè ìlà-oòrùn ti Jordani.”
16 I odpowiedzieli Jozuemu, mówiąc: Wszystko, coś nam rozkazał, uczynimy, a gdziekolwiek nas poślesz, pójdziemy.
Nígbà náà ni wọ́n dá Joṣua lóhùn pé, “Ohunkóhun tí ìwọ pàṣẹ fún wa ni àwa yóò ṣe, ibikíbi tí ìwọ bá rán wa ni àwa yóò lọ.
17 Jakośmy byli posłuszni Mojżeszowi, tak posłuszni będziemy i tobie; tylko niech będzie Pan, Bóg twój, z tobą, jako był z Mojżeszem.
Gẹ́gẹ́ bí àwa ti gbọ́rọ̀ sí Mose nínú ohun gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni àwa yóò máa gbọ́ tìrẹ. Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe wà pẹ̀lú u Mose.
18 Ktobykolwiek przeciwił się ustom twoim, a nie byłby posłusznym słowom twoim we wszystkiem, co mu rozkażesz, niechaj umrze; tylko się zmacniaj, a mężnie sobie poczynaj.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá tàpá sí ọ̀rọ̀ rẹ, tí kò sì ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ nínú ohun gbogbo tí ìwọ yóò pàṣẹ fún wọn, pípa ni a ó pa á. Kí ìwọ sá à ṣe gírí, kí ó sì mú àyà le!”

< Jozuego 1 >