< Jonasza 4 >

1 I nie podobało się to bardzo Jonaszowi, i rozpalił się gniew jego.
Ṣùgbọ́n ó ba Jona nínú jẹ́ gidigidi, ó sì bínú púpọ̀.
2 Przetoż się modlił Panu, i rzekł: Proszę Panie! azażem tego nie mówił, gdym jeszcze był w ziemi mojej? Dlategom się pospieszył, abym uciekł do Tarsu, gdyżem wiedział, żeś ty Bóg łaskawy i litościwy, długo cierpliwy i wielkiego miłosierdzia, a który żałujesz złego.
Ó sì gbàdúrà sí Olúwa, ó sì wí pé, “Èmí bẹ̀ ọ́, Olúwa, ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ ti mo sọ kọ́ ni èyí nígbà tí mo wà ní ilẹ̀ mi? Nítorí èyí ni mo ṣé sálọ sí Tarṣiṣi ní ìṣáájú: nítorí èmi mọ̀ pé, Ọlọ́run olóore-ọ̀fẹ́ ní ìwọ, àti aláàánú, O lọ́ra láti bínú, O sì ṣeun púpọ̀, O sì ronúpìwàdà ibi náà.
3 A teraz, o Panie! proszę, odbierz duszę moję odemnie: bo mi lepiej umrzeć, niżeli żyć.
Ǹjẹ́ báyìí, Olúwa, èmi bẹ̀ ọ, gba ẹ̀mí mi kúrò lọ́wọ́ mi nítorí ó sàn fún mi láti kú ju àti wà láààyè lọ.”
4 I rzekł Pan: A dobrzeż to, że się tak gniewasz?
Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Ìwọ́ ha ni ẹ̀tọ́ láti bínú bí?”
5 Bo wyszedł był Jonasz z miasta, i siedział na wschód słońca przeciwko miastu; a uczyniwszy tam sobie budę, usiadł pod nią w cieniu, ażby ujrzał, coby się działo z onem miastem.
Jona sì jáde kúrò ní ìlú náà, ó sì jókòó níhà ìlà-oòrùn ìlú náà. Ó sì pa àgọ́ kan níbẹ̀ fún ara rẹ̀, ó sì jókòó ni òjìji ní abẹ́ rẹ̀ títí yóò fi rí ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí ìlú náà.
6 A Pan Bóg był zgotował banię, która wyrosła nad Jonaszem, aby zasłaniała głowę jego, i zastawiała go od gorąca; tedy się Jonasz bardzo z onej bani radował.
Olúwa Ọlọ́run sì pèsè ìtàkùn kan, ó ṣe é kí ó gòkè wá sórí Jona; kí ó lè ṣe ìji bò ó lórí; láti gbà á kúrò nínú ìbànújẹ́ rẹ̀. Jona sì yọ ayọ̀ ńlá nítorí ìtàkùn náà.
7 Wtem nazajutrz na świtaniu nagotował Bóg robaka, który podgryzł onę banię, tak, że uschła.
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run pèsè kòkòrò kan nígbà tí ilẹ̀ mọ́ ní ọjọ́ kejì, ó sì jẹ ìtàkùn náà ó sì rọ.
8 I stało się, gdy weszło słońce, wzbudził Bóg wiatr suchy od wschodu słońca, i biło słońce na głowę Jonaszową, tak, iż omdlewał, i życzył sobie śmierci, mówiąc: Lepiej mi umrzeć, niżeli żyć.
Ó sì ṣe, nígbà tí oòrùn yọ, Ọlọ́run pèsè ẹ̀fúùfù gbígbóná tí ìlà-oòrùn; oòrùn sì pa Jona lórí tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi rẹ̀ ẹ́. Ó sì fẹ́ nínú ara rẹ̀ láti kú, ó sì wí pé, “Ó sàn fún mi láti kú ju àti wà láààyè lọ.”
9 I rzekł Bóg do Jonasza: Dobrzeż to, że się tak gniewasz o tę banię? I rzekł: Dobrze, że się gniewam aż na śmierć.
Ọlọ́run sì wí fún Jona pé, “O ha tọ́ fún ọ láti bínú nítorí ìtàkùn náà?” Òun sì wí pé, “Mo ni ẹ̀tọ́, o tọ́ fún mi láti bínú títí dé ikú.”
10 Tedy mu rzekł Pan: Ty żałujesz tej bani, około którejś nie pracował, aniś jej dał wzrost, która jednej nocy urosła, i jednej nocy zginęła;
Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Ìwọ kẹ́dùn ìtàkùn náà, nítorí èyí tí ìwọ kò ṣiṣẹ́ fun, tí ìwọ kò mu dàgbà; tí ó hù jáde ní òru kan tí ó sì kú ni òru kan.
11 A Jabym nie miał żałować Niniwy, miasta tak wielkiego? w którem jest więcej niżeli sto i dwadzieścia tysięcy ludzi, którzy nie umieją rozeznać między prawicą swoją i lewicą swoją, i bydła wiele.
Ṣùgbọ́n Ninefe ní jù ọ̀kẹ́ mẹ́fà ènìyàn nínú rẹ̀, tí wọn kò mọ ọwọ́ ọ̀tún wọn yàtọ̀ sí ti òsì, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun ọ̀sìn pẹ̀lú. Ṣé èmí kò ha ní kẹ́dùn nípa ìlú ńlá náà?”

< Jonasza 4 >