< Jana 13 >

1 A przed świętem wielkanocnem wiedząc Jezus, iż przyszła godzina jego, aby przeszedł z tego świata do Ojca, umiłowawszy swoje, którzy byli na świecie, aż do końca umiłował je.
Ǹjẹ́ kí àjọ ìrékọjá tó dé, nígbà tí Jesu mọ̀ pé, wákàtí rẹ̀ dé tan, tí òun ó ti ayé yìí kúrò lọ sọ́dọ̀ Baba, fífẹ́ tí ó fẹ́ àwọn tirẹ̀ tí ó wà ní ayé, ó fẹ́ wọn títí dé òpin.
2 A gdy była wieczerza, a dyjabeł już był wrzucił w serce Judasza, syna Szymonowego Iszkaryjoty, aby go wydał;
Bí wọ́n sì ti ń jẹ oúnjẹ alẹ́, tí èṣù ti fi í sí ọkàn Judasi Iskariotu ọmọ Simoni láti fi í hàn;
3 Widząc Jezus, iż wszystko Ojciec podał do rąk jego, a iż od Boga wyszedł i do Boga idzie,
tí Jesu sì ti mọ̀ pé Baba ti fi ohun gbogbo lé òun lọ́wọ́, àti pé lọ́dọ̀ Ọlọ́run ni òun ti wá, òun sì ń lọ sọ́dọ̀ Ọlọ́run;
4 Wstał od wieczerzy i złożył szaty, a wziąwszy prześcieradło, przepasał się.
Ó dìde ní ìdí oúnjẹ alẹ́, ó sì fi agbádá rẹ̀ lélẹ̀ ní apá kan; nígbà tí ó sì mú aṣọ ìnura, ó di ara rẹ̀ ní àmùrè.
5 Potem nalał wody do miednicy, i począł nogi umywać uczniom i ucierać prześcieradłem, którem był przepasany.
Lẹ́yìn náà, ó bu omi sínú àwokòtò kan, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í máa wẹ ẹsẹ̀ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ó sì ń fi aṣọ ìnura tí ó fi di àmùrè nù wọ́n.
6 Tedy przyszedł do Szymona Piotra; a on mu rzekł: Panie! i tyż mnie masz nogi umywać?
Nígbà náà ni ó dé ọ̀dọ̀ Simoni Peteru, òun sì wí fún un pé, “Olúwa, ìwọ yóò ha wẹ ẹsẹ̀ mi?”
7 Odpowiedział Jezus, i rzekł mu: Co ja czynię, ty nie wiesz teraz, ale się potem dowiesz.
Jesu dá a lóhùn, ó sì wí fún un pé, “Ohun tí èmi ń ṣe ni ìwọ kò mọ̀ nísinsin yìí; ṣùgbọ́n yóò yé ọ ní ìkẹyìn.”
8 Rzekł mu Piotr: Nie będziesz ty nóg moich umywał na wieki. Odpowiedział mu Jezus: Jeźli cię nie umyję, nie będziesz miał cząstki ze mną. (aiōn g165)
Peteru wí fún un pé, “Ìwọ kì yóò wẹ̀ ẹsẹ̀ mi láé.” Jesu sì dalóhùn pé, “Bí èmi kò bá wẹ̀ ọ́, ìwọ kò ní ìpín ní ọ̀dọ̀ mi.” (aiōn g165)
9 Tedy mu rzekł Szymon Piotr: Panie! nie tylko nogi moje, ale i ręce, i głowę.
Simoni Peteru wí fún ún pé, “Olúwa, kì í ṣe ẹsẹ̀ mi nìkan, ṣùgbọ́n àti ọwọ́ àti orí mi pẹ̀lú.”
10 Rzekł mu Jezus: Ktoć jest umyty, nie potrzebuje, jedno aby nogi umył, bo czysty jest wszystek; i wy jesteście czystymi, ale nie wszyscy;
Jesu wí fún un pé, “Ẹni tí a wẹ̀ kò tún fẹ́ ju kí a ṣan ẹsẹ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ó mọ́ níbi gbogbo: ẹ̀yin sì mọ́, ṣùgbọ́n kì í ṣe gbogbo yín.”
11 Albowiem wiedział, który go wydać miał; dlategoż rzekł: Nie wszyscy jesteście czystymi.
Nítorí tí ó mọ ẹni tí yóò fi òun hàn; nítorí náà ni ó ṣe wí pé, kì í ṣe gbogbo yín ni ó mọ́.
12 Gdy tedy umył nogi ich i wziął szaty swoje, usiadłszy zasię za stół, rzekł im: Wiecież, com wam uczynił?
Nítorí náà lẹ́yìn tí ó wẹ ẹsẹ̀ wọn tán, tí ó sì ti mú agbádá rẹ̀, tí ó tún jókòó, ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin mọ ohun tí mo ṣe sí yín bí?
13 Wy mię nazywacie nauczycielem i Panem, a dobrze mówicie; bomci jest nim.
Ẹ̀yin ń pè mí ní ‘Olùkọ́’ àti ‘Olúwa,’ ẹ̀yin wí rere; bẹ́ẹ̀ ni mo jẹ́.
14 Ponieważem ja tedy umył nogi wasze, Pan i nauczyciel, i wyście powinni jedni drugim nogi umywać.
Ǹjẹ́ bí èmi tí í ṣe Olúwa àti olùkọ́ yín bá wẹ ẹsẹ̀ yín, ó tọ́ kí ẹ̀yin pẹ̀lú sì máa wẹ ẹsẹ̀ ara yín.
15 Albowiem dałem wam przykład, abyście jakom ja wam uczynił, i wy czynili.
Nítorí mo fi àpẹẹrẹ fún yín, kí ẹ̀yin lè máa ṣe gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe sí yín.
16 Zaprawdę, zaprawdę powiadam wam: Nie jest sługa większy nad pana swego, ani poseł jest większy nad onego, który go posłał.
Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ọmọ ọ̀dọ̀ kò tóbi ju ọ̀gá rẹ̀ lọ, bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí a rán kò tóbi ju ẹni tí ó rán an lọ.
17 Jeźlić to wiecie, błogosławieni jesteście, jeźli to uczynicie.
Bí ẹ̀yin bá mọ nǹkan wọ̀nyí, alábùkún fún ni yín, bí ẹ̀yin bá ń ṣe wọ́n!
18 Nie o wszystkichci was mówię, jać wiem, którem obrał; ale żeby się wypełniło Pismo: Który je ze mną chleb, podniósł przeciwko mnie piętę swoję.
“Kì í ṣe ti gbogbo yín ni mo ń sọ, èmi mọ àwọn tí mo yàn, ṣùgbọ́n kí Ìwé Mímọ́ bá à lè ṣẹ, ‘Ẹni tí ń bá mi jẹun pọ̀ sì gbé gìgísẹ̀ rẹ̀ sí mi.’
19 Teraz wam powiadam, przedtem niż się to stanie, abyście gdy się to stanie, uwierzyli, żem ja jest.
“Láti ìsinsin yìí lọ ni mo wí fún un yín kí ó tó dé, pé nígbà tí ó bá dé, kí ẹ̀yin lè gbàgbọ́ pé èmi ni.
20 Zaprawdę, zaprawdę powiadam wam: Kto przyjmuje tego, którego bym posłał, mię przyjmuje; a kto mię przyjmuje, onego przyjmuje, który mię posłał.
Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún un yín, ẹni tí ó bá gba ẹnikẹ́ni tí mo rán, ó gbà mí; ẹni tí ó bá sì gbà mí, ó gba ẹni tí ó rán mi.”
21 To rzekłszy Jezus, zasmucił się w duchu, i oświadczył, a rzekł: Zaprawdę, zaprawdę powiadam wam, że jeden z was wyda mię.
Nígbà tí Jesu ti wí nǹkan wọ̀nyí tán, ọkàn rẹ̀ dàrú nínú rẹ̀, ó sì jẹ́rìí, ó sì wí pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún un yín pé, ọ̀kan nínú yín yóò dà mí.”
22 Tedy uczniowie spoglądali po sobie, wątpiąc, o kim by to mówił.
Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ń wò ara wọn lójú, wọ́n ń ṣiyèméjì ti ẹni tí ó wí.
23 A był jeden z uczniów jego, który się był położył na łonie Jezusowem, ten, którego miłował Jezus.
Ǹjẹ́ ẹnìkan rọ̀gbọ̀kú sí àyà Jesu, ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ẹni tí Jesu fẹ́ràn.
24 Przetoż na tego skinął Szymon Piotr, aby się wypytał, który by to był, o którym mówił.
Nítorí náà ni Simoni Peteru ṣàpẹẹrẹ sí i, ó sì wí fún un pé, “Wí fún wa ti ẹni tí o ń sọ.”
25 A on położywszy się na piersiach Jezusowych, rzekł mu: Panie! któryż to jest?
Ẹni tí ó ń rọ̀gún ní àyà Jesu wí fún un pé, “Olúwa, ta ni í ṣe?”
26 Odpowiedział Jezus: Ten jest, któremu ja omoczywszy sztuczkę chleba, podam; a omoczywszy sztuczkę chleba, dał Judaszowi, synowi Szymona, Iszkaryjotowi.
Nítorí náà Jesu dáhùn pé, “Òun náà ni, ẹni tí mo bá fi àkàrà fún nígbà tí mo bá fi run àwo.” Nígbà tí ó sì fi run ún tan, ó fi fún Judasi Iskariotu ọmọ Simoni.
27 A zaraz po onej sztuczce chleba wstąpił weń szatan. Tedy mu rzekł Jezus: Co czynisz, czyń rychło.
Ní kété tí Judasi gba àkàrà náà ni Satani wọ inú rẹ̀ lọ. Nítorí náà Jesu wí fún un pé, “Ohun tí ìwọ ń ṣe nì, yára ṣe é kánkán.”
28 A tego żaden nie zrozumiał z spółsiedzących, na co mu to rzekł.
Kò sì sí ẹnìkan níbi tábìlì tí ó mọ ìdí tí ó ṣe sọ èyí fún un.
29 Albowiem niektórzy mniemali, gdyż Judasz miał mieszek, iż mu rzekł Jezus: Nakup, czego nam potrzeba na święto, albo iżby co dał ubogim.
Nítorí àwọn mìíràn nínú wọn rò pé, nítorí Judasi ni ó ni àpò, ni Jesu fi wí fún un pé, ra nǹkan wọ̀n-ọn-nì tí a kò le ṣe aláìní fún àjọ náà; tàbí kí ó lè fi nǹkan fún àwọn tálákà.
30 Tedy on wziąwszy onę sztuczkę chleba, zarazem wyszedł; a noc była.
Nígbà tí ó sì ti gbà òkèlè náà tan, ó jáde lójúkan náà àkókò náà si jẹ òru.
31 A gdy wyszedł, rzekł Jezus: Teraz jest uwielbiony Syn człowieczy, a Bóg uwielbiony jest w nim.
Nítorí náà nígbà tí ó jáde lọ tan, Jesu wí pé, “Nísinsin yìí ni a yin Ọmọ Ènìyàn lógo, a sì yin Ọlọ́run lógo nínú rẹ̀.
32 A ponieważ Bóg uwielbiony jest w nim, tedy go też Bóg uwielbi sam w sobie, i wnetże uwielbi go.
Bí a bá yin Ọlọ́run lógo nínú rẹ̀, Ọlọ́run yóò sì yìn ín lógo nínú òun tìkára rẹ̀, yóò sì yìn ín lógo nísinsin yìí.
33 Synaczkowie! jeszcze maluczko jestem z wami; będziecie mię szukać, ale ja jakom rzekł Żydom: Gdzie ja idę, wy przyjść nie możecie; tak i wam teraz powiadam.
“Ẹ̀yin ọmọ mi, nígbà díẹ̀ sí i ni èmi wà pẹ̀lú yín. Ẹ̀yin yóò wá mi, àti gẹ́gẹ́ bí mo ti wí fún àwọn Júù pé, níbi tí èmi gbé ń lọ, ẹ̀yin kì yóò le wà; bẹ́ẹ̀ ni mo sì wí fún yín nísinsin yìí.
34 Przykazanie nowe daję wam, abyście się społecznie miłowali; jakom i ja was umiłował, abyście się i wy społecznie miłowali.
“Òfin tuntun kan ni mo fi fún yín, kí ẹ̀yin kí ó fẹ́ ọmọnìkejì yín; gẹ́gẹ́ bí èmi ti fẹ́ràn yín, kí ẹ̀yin kí ó sì fẹ́ràn ọmọnìkejì yín.
35 Stądci poznają wszyscy, żeście uczniami moimi, jeźli miłość mieć będziecie jedni przeciwko drugim.
Nípa èyí ni gbogbo ènìyàn yóò fi mọ̀ pé, ọmọ-ẹ̀yìn mi ni ẹ̀yin ń ṣe, nígbà tí ẹ̀yin bá ní ìfẹ́ sí ọmọ ẹnìkejì yín.”
36 Rzekł mu Szymon Piotr: Panie! dokądże idziesz? Odpowiedział mu Jezus: Dokąd ja idę, ty teraz za mną iść nie możesz, ale potem pójdziesz za mną.
Simoni Peteru wí fún un pé, “Olúwa, níbo ni ìwọ ń lọ?” Jesu dá a lóhùn pé, “Níbi tí èmi ń lọ, ìwọ kì yóò lè tẹ̀lé mí nísinsin yìí; ṣùgbọ́n ìwọ yóò tọ̀ mí lẹ́yìn ní ìkẹyìn.”
37 Tedy mu rzekł Piotr: Panie! czemuż teraz za tobą iść nie mogę? Duszę moję za cię położę.
Peteru wí fún un pé, “Olúwa èéṣe tí èmi kò fi le tọ̀ ọ́ lẹ́hìn nísinsin yìí? Èmi ó fi ẹ̀mí mi lélẹ̀ nítorí rẹ.”
38 Odpowiedział mu Jezus: Duszę twoję za mię położysz? Zaprawdę, zaprawdę powiadam ci: Nie zapieje kur, aż się mnie po trzykroć zaprzesz.
Jesu dalóhùn wí pé, “Ìwọ ó ha fi ẹ̀mí rẹ lélẹ̀ nítorí mi? Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, àkùkọ kì yóò kọ, kí ìwọ kí ó tó ṣẹ́ mi nígbà mẹ́ta!

< Jana 13 >