< Jana 12 >

1 Tedy Jezus szóstego dnia przed wielkanocą przyszedł do Betanii, kędy był Łazarz, który był umarł, którego wzbudził od umarłych.
Nítorí náà, nígbà tí àjọ ìrékọjá ku ọjọ́ mẹ́fà, Jesu wá sí Betani, níbi tí Lasaru wà, ẹni tí ó ti kú, tí Jesu jí dìde kúrò nínú òkú.
2 Tamże mu sprawili wieczerzę, a Marta posługiwała, a Łazarz był jednym z onych, którzy z nim społem u stołu siedzieli.
Wọ́n sì ṣe àsè alẹ́ fún un níbẹ̀. Marta sì ń ṣe ìránṣẹ́, ṣùgbọ́n Lasaru jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn tí ó jókòó níbi tábìlì rẹ̀.
3 A Maryja wziąwszy funt maści szpikanardowej bardzo drogiej, namaściła nogi Jezusowe, i utarła włosami swojemi nogi jego, i napełniony był on dom wonnością onej maści.
Nígbà náà ni Maria mú òróró ìkunra nadi, òsùwọ̀n lita kan, àìlábùlà, olówó iyebíye, ó sì ń fi kun Jesu ní ẹsẹ̀, ó sì ń fi irun orí rẹ̀ nu ẹsẹ̀ rẹ̀ nù. Ilé sì kún fún òórùn ìkunra náà.
4 Tedy rzekł jeden z uczniów jego, Judasz, syn Szymona, Iszkaryjot, który go miał wydać:
Nígbà náà ni ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, Judasi Iskariotu, ọmọ Simoni ẹni tí yóò fi í hàn, wí pé,
5 Przeczże tej maści nie sprzedano za trzysta groszy, a nie dano ubogim?
“Èéṣe tí a kò ta òróró ìkunra yìí ní ọ̀ọ́dúnrún owó idẹ kí a sì fi fún àwọn tálákà?”
6 A to mówił, nie iżby miał pieczą o ubogich, ale iż był złodziejem, i mieszek miał, a cokolwiek włożono, nosił.
Ṣùgbọ́n ó wí èyí, kì í ṣe nítorí tí ó náání àwọn tálákà; ṣùgbọ́n nítorí tí ó jẹ́ olè, òun ni ó ni àpò, a sì máa jí ohun tí a fi sínú rẹ̀ láti fi ran ara rẹ lọ́wọ́.
7 Tedy rzekł Jezus: Zaniechaj jej; na dzień pogrzebu mego to chowała.
Nígbà náà ni Jesu wí pé, “Ẹ fi í sílẹ̀, ó ṣe é sílẹ̀ de ọjọ́ ìsìnkú mi.
8 Albowiem ubogie zawsze z sobą macie, ale mnie nie zawsze mieć będziecie.
Nígbà gbogbo ni ẹ̀yin sá à ní tálákà pẹ̀lú yín; ṣùgbọ́n èmi ni ẹ kò ní nígbà gbogbo.”
9 Dowiedział się tedy lud wielki z Żydów, iż tam był, i przyszli nie tylko dla Jezusa, ale też aby Łazarza widzieli, którego był wzbudził od umarłych.
Nítorí náà, ìjọ ènìyàn nínú àwọn Júù ni ó mọ̀ pé ó wà níbẹ̀; wọ́n sì wá, kì í ṣe nítorí Jesu nìkan, ṣùgbọ́n kí wọn lè rí Lasaru pẹ̀lú, ẹni tí ó ti jí dìde kúrò nínú òkú.
10 I radzili się przedniejsi kapłani, żeby i Łazarza zabili.
Ṣùgbọ́n àwọn olórí àlùfáà gbìmọ̀ kí wọn lè pa Lasaru pẹ̀lú,
11 Bo wiele z Żydów dla niego odstępowali i wierzyli w Jezusa.
nítorí pé nípasẹ̀ rẹ̀ ni ọ̀pọ̀ nínú àwọn Júù jáde lọ, wọ́n sì gbà Jesu gbọ́.
12 Nazajutrz wielki lud, który był przyszedł na święto, usłyszawszy, iż Jezus idzie do Jeruzalemu,
Ní ọjọ́ kejì nígbà tí ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ó wá sí àjọ gbọ́ pé, Jesu ń bọ̀ wá sí Jerusalẹmu.
13 Nabrali gałązek palmowych i wyszli naprzeciwko niemu i wołali: Hosanna! błogosławiony, który idzie w imieniu Pańskiem, król Izraelski!
Wọ́n mú imọ̀ ọ̀pẹ, wọ́n sì jáde lọ pàdé rẹ̀, wọ́n sì ń kígbe pé, “Hosana!” “Olùbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa!” “Olùbùkún ni ọba Israẹli!”
14 A dostawszy Jezus oślęcia, wsiadł na nie, jako jest napisane:
Nígbà tí Jesu sì rí ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan, ó gùn ún; gẹ́gẹ́ bí a ti kọ̀wé pé,
15 Nie bój się, córko Syońska! oto król twój idzie, siedząc na oślęciu.
“Má bẹ̀rù, ọmọbìnrin Sioni; wò ó, ọba rẹ ń bọ̀ wá, o jókòó lórí ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.”
16 Ale tego z przodku nie zrozumieli uczniowie jego, ale gdy był Jezus uwielbiony, tedy wspomnieli, iż to było o nim napisane, a że mu to uczynili.
Nǹkan wọ̀nyí kò tètè yé àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ṣùgbọ́n nígbà tí a ṣe Jesu lógo, nígbà náà ni wọ́n rántí pé, a kọ̀wé nǹkan wọ̀nyí nípa rẹ̀ sí i.
17 Świadczył tedy lud, który z nim był, iż Łazarza zawołał z grobu i wzbudził go od umarłych.
Nítorí náà, ìjọ ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ nígbà tí o pé Lasaru jáde nínú ibojì rẹ̀, tí ó sì jí i dìde kúrò nínú òkú, jẹ́rìí sí i.
18 Dlatego też wyszedł przeciwko niemu lud, że słyszał, iż on ten cud uczynił.
Nítorí èyí ni ìjọ ènìyàn sì ṣe lọ pàdé rẹ̀, nítorí tí wọ́n gbọ́ pé ó ti ṣe iṣẹ́ àmì yìí.
19 Tedy mówili Faryzeuszowie między sobą: Widzicie, że nic nie sprawicie; oto świat za nim poszedł.
Nítorí náà àwọn Farisi wí fún ara wọn pé, “Ẹ kíyèsi bí ẹ kò ti lè borí ní ohunkóhun? Ẹ wo bí gbogbo ayé ti ń wọ́ tọ̀ ọ́!”
20 A byli niektórzy Grekowie z tych, którzy przychodzili do Jeruzalemu, żeby się modlili w święto.
Àwọn Giriki kan sì wà nínú àwọn tí ó gòkè wá láti sìn nígbà àjọ,
21 Ci tedy przyszli do Filipa, który był z Betsaidy Galilejskiej, i prosili go, mówiąc: Panie, chcemy Jezusa widzieć.
Àwọn wọ̀nyí ni ó tọ Filipi wá, ẹni tí í ṣe ará Betisaida tí Galili, wọ́n sì ń béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, pé, “Alàgbà, àwa ń fẹ́ rí Jesu!”
22 Przyszedł Filip i powiedział Andrzejowi, a Andrzej zasię i Filip powiedzieli Jezusowi.
Filipi wá, ó sì sọ fún Anderu; Anderu àti Filipi wá, wọ́n sì sọ fún Jesu.
23 A Jezus odpowiedział im, mówiąc: Przyszła godzina, aby był uwielbiony Syn człowieczy.
Jesu sì dá wọn lóhùn pé, “Wákàtí náà dé, tí a ó ṣe Ọmọ Ènìyàn lógo.
24 Zaprawdę, zaprawdę powiadam wam: Jeźliby ziarno pszeniczne wpadłszy do ziemi, nie obumarło, ono samo zostaje; lecz jeźliby obumarło, wielki pożytek przynosi.
Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, bí kò ṣe pé alikama bá bọ́ sí ilẹ̀, tí ó bá sì kú, ó wà ní òun nìkan; ṣùgbọ́n bí ó bá kú, yóò sì so ọ̀pọ̀lọpọ̀ èso.
25 Kto miłuje duszę swoję, utraci ją, a kto nienawidzi duszy swojej na tym świecie, ku wiecznemu żywotowi strzeże jej. (aiōnios g166)
Ẹni tí ó bá fẹ́ ẹ̀mí rẹ̀ yóò sọ ọ́ nù; ẹni tí ó bá sì kórìíra ẹ̀mí rẹ̀ láyé yìí ni yóò sì pa á mọ́ títí ó fi di ìyè àìnípẹ̀kun. (aiōnios g166)
26 Jeźli mnie kto służy, niechże mię naśladuje, a gdziem ja jest, tam i sługa mój będzie; a jeźli mnie kto służyć będzie, uczci go Ojciec mój.
Bí ẹnikẹ́ni bá ń sìn mí, kí ó máa tọ̀ mí lẹ́yìn, àti pe níbi tí èmi bá wà, níbẹ̀ ni ìránṣẹ́ mi yóò wà pẹ̀lú, bí ẹnikẹ́ni bá ń sìn mí, òun ni Baba yóò bu ọlá fún.
27 Terazci dusza moja zatrwożona jest; i cóż rzekę? Ojcze! zachowaj mię od tej godziny; alemci dlatego przyszedł na tę godzinę.
“Ní ìsinsin yìí ni a ń pọ́n ọkàn mi lójú; kín ni èmi ó sì wí? ‘Baba, gbà mí kúrò nínú wákàtí yìí’? Rárá, ṣùgbọ́n nítorí èyí ni mo ṣe wá sí wákàtí yìí.
28 Ojcze! uwielbij imię twoje. Przyszedł tedy głos z nieba: Uwielbiłem i jeszcze uwielbię.
Baba, ṣe orúkọ rẹ lógo!” Nígbà náà ni ohùn kan ti ọ̀run wá, wí pé, “Èmi ti ṣe é lógo!”
29 A lud ten, który stał i słyszał, mówił: Zagrzmiało; a drudzy mówili: Anioł do niego mówił.
Nítorí náà ìjọ ènìyàn tí ó dúró níbẹ̀, tí wọ́n sì gbọ́ ọ, wí pé, “Àrá ń sán.” Àwọn ẹlòmíràn wí pé, “Angẹli kan ni ó ń bá a sọ̀rọ̀.”
30 Odpowiedział Jezus i rzekł: Nie dla mnie się ten głos stał, ale dla was.
Jesu sì dáhùn wí pé, “Kì í ṣe nítorí mi ni ohùn yìí ṣe wá, bí kò ṣe nítorí yín.
31 Teraz jest sąd świata tego, teraz książę świata tego precz wyrzucony będzie.
Ní ìsinsin yìí ni ìdájọ́ ayé yìí dé: nísinsin yìí ni a ó lé aládé ayé yìí jáde.
32 A ja jeźli będę podwyższony od ziemi, pociągnę wszystkich do siebie.
Àti èmi, bí a bá gbé mi sókè kúrò ní ayé, èmi ó fa gbogbo ènìyàn sọ́dọ̀ ara mi!”
33 (A mówił to, oznajmując, jaką śmiercią miał umrzeć.)
Ṣùgbọ́n ó wí èyí, ó ń ṣe àpẹẹrẹ irú ikú tí òun yóò kú.
34 Odpowiedział mu on lud: Myśmy słyszeli z zakonu, iż Chrystus trwa na wieki; a jakoż ty mówisz, że musi być podwyższony Syn człowieczy? i któryż to jest Syn człowieczy? (aiōn g165)
Nítorí náà àwọn ìjọ ènìyàn dá a lóhùn pé, “Àwa gbọ́ nínú òfin pé, Kristi wà títí láéláé, ìwọ ha ṣe wí pé, ‘A ó gbé Ọmọ Ènìyàn sókè’? Ta ni ó ń jẹ́ ‘Ọmọ Ènìyàn yìí’?” (aiōn g165)
35 Tedy im rzekł Jezus: Jeszcze do małego czasu jest z wami światłość; chodźcież tedy, póki światłość macie, żeby was ciemność nie ogarnęła; bo kto w ciemności chodzi, nie wie, kędy idzie.
Nígbà náà ni Jesu wí fún wọn pé, “Nígbà díẹ̀ sí i ni ìmọ́lẹ̀ wà láàrín yín, ẹ máa rìn nígbà tí ẹ̀yin ní ìmọ́lẹ̀, kí òkùnkùn má ṣe bá yín, ẹni tí ó bá sì ń rìn ní òkùnkùn kò mọ ibi òun ń lọ.
36 Póki światłość macie, wierzcie w światłość, abyście byli synami światłości. To powiedział Jezus, a odszedłszy schronił się od nich.
Nígbà tí ẹ̀yin ní ìmọ́lẹ̀, ẹ gba ìmọ́lẹ̀ gbọ́, kí ẹ lè jẹ́ ọmọ ìmọ́lẹ̀!” Nǹkan wọ̀nyí ni Jesu sọ, ó sì jáde lọ, ó fi ara pamọ́ fún wọn.
37 A choć tak wiele cudów uczynił przed nimi, przecię nie uwierzyli weń,
Ṣùgbọ́n bí ó ti ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ àmì tó báyìí lójú wọn, wọn kò gbà á gbọ́.
38 Aby się wypełniło słowo Izajasza proroka, które powiedział: Panie! i któż uwierzył kazaniu naszemu, a ramię Pańskie komuż jest objawione?
Kí ọ̀rọ̀ wòlíì Isaiah lè ṣẹ, èyí tí ó sọ pé, “Olúwa, ta ni ó gba ìwàásù wa gbọ́ Àti ta ni a sì fi apá Olúwa hàn fún?”
39 Dlatego uwierzyć nie mogli, iż jeszcze powiedział Izajasz:
Nítorí èyí ni wọn kò fi lè gbàgbọ́, nítorí Isaiah sì tún sọ pé,
40 Zaślepił oczy ich, i zatwardził serce ich, aby oczyma nie widzieli i sercem nie zrozumieli, i nie nawrócili się, abym je uzdrowił.
“Ó ti fọ́ wọn lójú, Ó sì ti sé àyà wọn le; kí wọn má ba à fi ojú wọn rí, kí wọn má ba à fi ọkàn wọn mọ̀, kí wọn má ba à yípadà, kí èmi má ba à mú wọn láradá.”
41 To powiedział Izajasz, gdy widział chwałę jego, i mówił o nim.
Nǹkan wọ̀nyí ni Isaiah wí, nítorí ó ti rí ògo rẹ̀, ó sì sọ̀rọ̀ rẹ̀.
42 Wszakże jednak i z książąt wiele ich weń uwierzyło; ale dla Faryzeuszów nie wyznali, aby z bóżnicy nie byli wyłączeni.
Síbẹ̀ ọ̀pọ̀ nínú àwọn olórí gbà á gbọ́ pẹ̀lú; ṣùgbọ́n nítorí àwọn Farisi wọn kò jẹ́wọ́ rẹ̀, kí a má ba à yọ wọ́n kúrò nínú Sinagọgu,
43 Bo umiłowali chwałę ludzką więcej, niż chwałę Bożą.
nítorí wọ́n fẹ́ ìyìn ènìyàn ju ìyìn ti Ọlọ́run lọ.
44 I wołał Jezus, a mówił: Kto wierzy w mię, nie w mię wierzy, ale w onego, który mię posłał.
Jesu sì kígbe ó sì wí pé, “Ẹni tí ó bá gbà mí gbọ́, èmi kọ́ ni ó gbàgbọ́ ṣùgbọ́n ẹni tí ó rán mi.
45 I kto mię widzi, widzi onego, który mię posłał.
Ẹni tí ó bá sì rí mi, ó rí ẹni tí ó rán mi.
46 Ja światłość przyszedłem na świat, aby żaden, kto wierzy w mię, w ciemnościach nie został.
Èmi ni ìmọ́lẹ̀ tí ó wá sí ayé, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà mí gbọ́ má ṣe wà nínú òkùnkùn.
47 A jeźliby kto słuchał słów moich, a nie uwierzyłby, jać go nie sądzę; bom nie przyszedł, ażebym sądził świat, ale ażebym zbawił świat.
“Bí ẹnikẹ́ni bá sì gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, tí kò sì pa wọ́n mọ́, èmi kì yóò ṣe ìdájọ́ rẹ̀ nítorí tí èmi kò wá láti ṣe ìdájọ́ ayé, bí kò ṣe láti gba ayé là.
48 Kto mną gardzi, a nie przyjmuje słów moich, ma kto by go sądził; słowa, którem ja mówił, one go osądzą w ostateczny dzień.
Ẹni tí ó bá kọ̀ mí, tí kò sì gba ọ̀rọ̀ mi, ó ní ẹnìkan tí ń ṣe ìdájọ́ rẹ̀; ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ, òun náà ni yóò ṣe ìdájọ́ rẹ̀ ní ọjọ́ ìkẹyìn.
49 Bom ja z siebie samego nie mówił, ale ten, który mię posłał, Ojciec, on mi rozkazanie dał, co bym mówił i co bym powiadać miał;
Nítorí èmi kò dá ọ̀rọ̀ sọ fún ara mi, ṣùgbọ́n Baba tí ó rán mi, ni ó ti fún mi ní àṣẹ, ohun tí èmi ó sọ, àti èyí tí èmi ó wí.
50 I wiem, że rozkazanie jego jest żywot wieczny; przetoż to, co ja wam mówię, jako mi powiedział Ojciec, tak mówię. (aiōnios g166)
Èmi sì mọ̀ pé ìyè àìnípẹ̀kun ni òfin rẹ̀, nítorí náà, àwọn ohun tí mo bá wí, gẹ́gẹ́ bí Baba ti sọ fún mi, bẹ́ẹ̀ ni mo wí!” (aiōnios g166)

< Jana 12 >