< Hioba 9 >

1 I odpowiedział Ijob, a rzekł:
Jobu sì dáhùn ó sì wí pé,
2 Prawdziwieć wiem, że tak jest; bo jakożby miał być usprawiedliwiony człowiek przed Bogiem?
“Èmi mọ̀ pe bẹ́ẹ̀ ni ní òtítọ́. Báwo ní ènìyàn yóò ha ti ṣe jẹ́ aláre níwájú Ọlọ́run?
3 Jeźliby się z nim chciał spierać, nie odpowie mu z tysiąca na jednę rzecz.
Bí ó bá ṣe pé yóò bá a jà, òun kì yóò lè dalóhùn kan nínú ẹgbẹ̀rún ọ̀rọ̀.
4 Mądry jest sercem, i mocny siłą; któż użył pokoju, stawiwszy się mu upornie?
Ọlọ́gbọ́n nínú àwọn alágbára ní ipa ní Òun. Ta ni ó ṣe agídí sí i tí ó sì gbé fún rí?
5 On przenosi góry, a nie wiedzą ludzie, kto je podwraca w gniewie swym.
Ẹni tí ó sí òkè nídìí tí wọn kò sì mọ́: tí ó taari wọn ṣubú ní ìbínú rẹ̀.
6 On wzrusza ziemię z miejsca swego, a słupy jej trzęsą się.
Tí ó mi ilẹ̀ ayé tìtì kúrò ní ipò rẹ̀, ọwọ̀n rẹ̀ sì mì tìtì.
7 Gdy on zakaże słońcu, nie wschodzi; i gwiazdy pieczętuje.
Ó pàṣẹ fún oòrùn kò sì le è ràn, kí ó sì dí ìmọ́lẹ̀ ìràwọ̀ mọ́.
8 On sam rozpościera niebiosa, i depcze po wałach morskich.
Òun nìkan ṣoṣo ni ó ta ojú ọ̀run, ti ó sì ń rìn lórí ìgbì Òkun.
9 On sprawił wóz niebieski z gwiazd, Oryjona i Hyjady, i inne gwiazdy skryte na południe.
Ẹni tí ó dá ìràwọ̀ Beari àti Orioni, Pleiadesi àti ìràwọ̀ púpọ̀ ti gúúsù.
10 On czyni rzeczy wielkie, a niewybadane i dziwne, którym niemasz liczby.
Ẹni tí ń ṣe ohun tí ó tóbi jù àwárí lọ, àní ohun ìyanu láìní iye.
11 Oto, idzieli mimo mię, nie widzę go; a przychodzili, nie baczę go.
Kíyèsi i, ó ń kọjá lọ ní ẹ̀bá ọ̀dọ̀ mi, èmi kò sì rí i, ó sì kọjá síwájú, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò rí ojú rẹ̀.
12 Oto gdy co porwie, któż go przymusi, aby przywrócił? Albo któż mu rzecze: Cóż czynisz?
Kíyèsi i, ó já a gbà lọ, ta ni ó lè fà á padà? Ta ni yóò bi í pé kí ni ìwọ ń ṣe nì?
13 Gdyby Bóg nie odwrócił gniewu swego, upadliby przed nim pomocnicy hardzi.
Ọlọ́run kò ní fa ìbínú rẹ̀ sẹ́yìn, àwọn onírànlọ́wọ́ ti Rahabu a sì tẹríba lábẹ́ rẹ̀.
14 Jakoż mu ja tedy odpowiem? Jakie słowa obiorę przeciwko niemu?
“Kí ní ṣe tí èmi ti n o fi ba ṣàròyé? Tí èmi yóò fi ma ṣe àwáwí?
15 Któremu, chociażbym był sprawiedliwym, nie odpowiem; owszem się sędziemu memu upokorzę.
Bí ó tilẹ̀ ṣe pé mo ṣe aláìlẹ́bi, èmi kò gbọdọ̀ dá a lóhùn; ṣùgbọ́n èmi ó gbàdúrà fún àánú.
16 Choćbym go wzywał, a onby mi się ozwał, przecię nie wierzę, aby przypuścił do uszów głos mój:
Bí èmi bá sì ké pè é, tí Òun sì dá mi lóhùn, èmi kì yóò sì gbàgbọ́ pé, Òun ti fetí sí ohùn mi.
17 Bo mię starł w wichrze, i rozmnożył rany moje bez przyczyny;
Nítorí pé òun yóò lọ̀ mí lúúlúú pẹ̀lú ìjì ńlá, ó sọ ọgbẹ́ mi di púpọ̀ láìnídìí.
18 Nie dopuszcza mi odetchnąć, owszem mię nasyca gorzkościami.
Òun kì yóò jẹ́ kí èmi kí ó rí ẹ̀mí mi, ṣùgbọ́n ó mú ohun kíkorò kún un fún mi.
19 Jeźli się udam do mocy, oto on najmocniejszy; a jeźli do sądu, któż mię z nim sprowadzi?
Bí mo bá sọ ti agbára, wò ó! Alágbára ni, tàbí ní ti ìdájọ́, ta ni yóò dá àkókò fún mi láti rò?
20 Jeźlibym się usprawiedliwiał, usta moje potępią mię; jeźlibym się doskonałym czynił, tedy mię przewrotnym być pokaże.
Bí mo tilẹ̀ dá ara mi láre, ẹnu ara mi yóò dá mi lẹ́bi; bí mo wí pé olódodo ni èmi yóò sì fi mí hàn ní ẹni ẹ̀bi.
21 Chociażbym był doskonały, przecież ja tego do siebie znać nie będę; ale dam naganę żywotowi memu.
“Olóòótọ́ ni mo ṣe, síbẹ̀ èmi kò kíyèsi ara mi, ayé mi ní èmi ìbá máa gàn.
22 Jedno jest, dla czegom to mówił: że tak doskonałego, jako i niezbożnego on niszczy;
Ohùn kan náà ni, nítorí náà ni èmi ṣe sọ: ‘Òun a pa ẹni òtítọ́ àti ènìyàn búburú pẹ̀lú.’
23 Jeźli biczem nagle zabija, z pokuszenia niewinnych naśmiewa się;
Bí ìjàǹbá bá pa ni lójijì, yóò rẹ́rìn-ín nínú ìdààmú aláìṣẹ̀.
24 Ziemia podana bywa w ręce niezbożnika, oblicze sędziów jej zakrywa. A jeźliż nie on, któż tedy inny jest, co to czyni?
Nígbà tí a bá fi ayé lé ọwọ́ ènìyàn búburú; ó sì bo àwọn onídàájọ́ rẹ̀ lójú; bí kò bá rí bẹ́ẹ̀ ǹjẹ́ ta ni?
25 Ale dni moje prędsze były niż poseł; uciekły, a nie widziały nic dobrego.
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí ọjọ́ mi yára ju oníṣẹ́ lọ, wọ́n fò lọ, wọn kò rí ayọ̀.
26 Przeminęły jako prędkie łodzie, jako orzeł lecący do żeru.
Wọ́n kọjá lọ bí ọkọ̀ eèsún papirusi tí ń sáré lọ; bí idì tí ń yára si ohùn ọdẹ.
27 Jeźli rzekę: Zapomnę narzekania mego, zaniecham gniewu swego, a posilę się:
Bí èmi bá wí pé, ‘Èmi ó gbàgbé arò ìbìnújẹ́ mi, èmi ó fi ọkàn lélẹ̀, èmi ó sì rẹ ara mi lẹ́kún.’
28 Tedy się lękam wszystkich boleści moich, widząc, że mię z nich nie wypuścisz.
Ẹ̀rù ìbànújẹ́ mi gbogbo bà mí, èmi mọ̀ pé ìwọ kì yóò mú mi bí aláìṣẹ̀.
29 Jeźlim ja niezbożny, przeczże próżno pracuję?
Bí ó bá ṣe pé ènìyàn búburú ni èmi, ǹjẹ́ kí ni èmi ń ṣe làálàá lásán sí?
30 A choćbym się umywał wodami śnieżnemi, i oczyściłbym mydłem ręce moje:
Bí mo tilẹ̀ fi ọṣẹ dídì wẹ ara mi, tí mo fi omi aró wẹ ọwọ́ mi mọ́,
31 Wszakże w dole zanurzysz mię, i brzydzić się mną będą szaty moje.
síbẹ̀ ìwọ ó gbé mi wọ inú ihò ọ̀gọ̀dọ̀ aṣọ ara mi yóò sọ mi di ìríra.
32 Albowiem on nie jest człowiekiem jako ja, abym mu śmiał odpowiedzieć, albo żebym z nim miał iść w prawo.
“Nítorí Òun kì í ṣe ènìyàn bí èmi, tí èmi ó fi dá a lóhùn tí àwa o fi pàdé ní ìdájọ́.
33 Bo nie masz między nami rozjemcy, któryby mógł rozwieść sprawę naszę.
Bẹ́ẹ̀ ni kò sí alátúnṣe kan ní agbede-méjì wa tí ìbá fi ọwọ́ rẹ̀ lé àwa méjèèjì lára.
34 Niech tylko zdejmie zemnie rózgę swoję, a strach jego niech mię nie straszy;
Kí ẹnìkan sá à mú ọ̀pá Ọlọ́run kúrò lára mi, kí ìbẹ̀rù rẹ̀ kí ó má sì ṣe dáyà fò mí.
35 Tedy będę mówił, a nie będę się go bał; bom ja nie jest taki sam u siebie.
Nígbà náà ni èmi ìbá sọ̀rọ̀, èmi kì bá sì bẹ̀rù rẹ̀; ṣùgbọ́n bí ó tí dúró tì mí, kò ri bẹ́ẹ̀ fún mi.

< Hioba 9 >