< Hioba 42 >

1 Tedy odpowiedział Ijob Panu, i rzekł:
Nígbà náà ní Jobu dá Olúwa lóhùn, ó sì wí pé,
2 Wiem, że wszystko możesz, i nie może być zahamowany zamysł twój.
“Èmi mọ̀ pé, ìwọ lè e ṣe ohun gbogbo, àti pé, kò si ìrò inú tí a lè fa sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ.
3 Któż jest ten, pytasz, który zaciemnia radę Bożą nieumiejętnie? Dlatego przyznaję, żem nie zrozumiał; dziwniejsze są te rzeczy, niżbym je mógł pojąć i zrozumieć.
Ìwọ béèrè, ta ni ẹni tí ń fi ìgbìmọ̀ pamọ́ láìní ìmọ̀? Nítorí náà ní èmi ṣe ń sọ èyí tí èmi kò mọ̀, ohun tí ó ṣe ìyanu jọjọ níwájú mi, ti èmi kò mòye.
4 Wysłuchajże, proszę, gdybym mówił; a gdy się będę pytał, oznajmijże mi.
“Ìwọ wí pé, ‘Gbọ́ tèmi báyìí, èmi ó sì sọ; èmi ó béèrè lọ́wọ́ rẹ, ìwọ yóò sì dá mi lóhùn.’
5 Przedtem tylko ucho słyszało o tobie; ale teraz oko moje widzi cię.
Etí mi sì ti gbọ́ nípa rẹ, ṣùgbọ́n nísinsin yìí ojú mi ti rí ọ.
6 Przetoż żałuję i pokutuję w prochu i w popiele.
Ǹjẹ́ nítorí náà èmi kórìíra ara mi, mo sì ronúpìwàdà nínú ekuru àti eérú.”
7 A gdy odmówił Pan te słowa do Ijoba, rzekł Pan do Elifasa Tamańczyka: Rozpalił się gniew mój przeciw tobie, i przeciw dwom przyjaciołom twoim, żeście o mnie nie mówili tak przystojnie, jako Ijob, sługa mój.
Bẹ́ẹ̀ ó sì rí, lẹ́yìn ìgbà tí Olúwa ti sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún Jobu, Olúwa sì wí fún Elifasi, ará Temani pé, mo bínú sí ọ, àti sí àwọn ọ̀rẹ́ rẹ méjèèjì, nítorí pé ẹ̀yin kò sọ̀rọ̀, ní ti èmi, ohun tí ó tọ́, bí Jobu ìránṣẹ́ mi ti sọ.
8 Przetoż teraz, weźmijcie sobie siedm cielców, i siedm baranów, a idźcie do sługi mego Ijoba, i ofiarujcie całopalenie za się; a Ijob, sługa mój, niech się modli za wami; bo oblicze jego przyjmę, abym nie uczynił z wami według głupstwa waszego; boście nie mówili tak przystojnie o mnie, jako Ijob, sługa mój.
Nítorí náà, ẹ mú akọ ẹgbọrọ màlúù méje, àti àgbò méje, kí ẹ sì tọ̀ Jobu ìránṣẹ́ mi lọ, kí ẹ sì fi rú ẹbọ sísun fún ara yín; Jobu ìránṣẹ́ mi yóò sì gbàdúrà fún yin; nítorí pé àdúrà rẹ̀ ní èmi yóò gbà; kí èmi kí ó má ba ṣe si yín bí ìṣìnà yín, ní ti pé ẹ̀yin kò sọ̀rọ̀ ohun tí ó tọ́ sí mi bi Jobu ìránṣẹ́ mi ti ṣe.
9 A tak odeszli Elifas Temańczyk, i Bildad Suhitczyk, i Sofar Naanatczyk, i uczynili, jako im rozkazał Pan; i przyjął Pan oblicze Ijobowe.
Bẹ́ẹ̀ ní Elifasi, ara Temani, àti Bilidadi, ará Ṣuhi, àti Sofari, ará Naama lọ, wọ́n sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún wọn. Olúwa sì gbọ́ àdúrà Jobu.
10 Zatem Pan przywrócił to, co było pobrane Ijobowi, gdy się modlił za przyjaciół swoich; i rozmnożył Pan wszystko, cokolwiek miał Ijob, w dwójnasób.
Olúwa sì yí ìgbèkùn Jobu padà, nígbà tí ó gbàdúrà fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀; Olúwa sì bùsi ohun gbogbo ti Jobu ní rí ní ìṣẹ́po méjì ohun tí ó ní tẹ́lẹ̀ rí.
11 Zeszli się tedy do niego wszyscy bracia jego, i wszystki siostry jego, i inni wszyscy, którzy go przedtem znali, i jedli z nim chleb w domu jego, a żałując go cieszyli go z strony wszystkiego złego, które był Pan nań przywiódł; i dał mu każdy z nich upominek jeden, i każdy nausznicę złotą jedne.
Nígbà náà ní gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀, àti gbogbo àwọn arábìnrin rẹ̀, àti gbogbo àwọn tí ó ti ṣe ojúlùmọ̀ rẹ̀ rí; wọ́n bá a jẹun nínú ilé rẹ̀. Wọ́n sì ṣe ìdárò rẹ̀, wọ́n sì ṣìpẹ̀ fún un nítorí ibi gbogbo tí Olúwa ti mú bá a. Olúkúlùkù ènìyàn pẹ̀lú sì fún un ní ẹyọ owó kọ̀ọ̀kan àti olúkúlùkù ni òrùka wúrà etí kọ̀ọ̀kan.
12 A tak Pan błogosławił ostatnim czasom Ijobowym, więcej niż początkom jego. Bo miał czternaście tysięcy owiec, i sześć tysięcy wielbłądów, i tysiąc jarzm wołów, i tysiąc oślic.
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa bùkún ìgbẹ̀yìn Jobu ju ìṣáájú rẹ̀ lọ; ẹgbàá méje àgùntàn, ẹgbẹ̀rún mẹ́fà ìbákasẹ, àti ẹgbẹ̀rún àjàgà ọ̀dá màlúù, àti ẹgbẹ̀rún abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
13 Miał też siedm synów, i trzy córki.
Ó sì ní ọmọkùnrin méje àti ọmọbìnrin mẹ́ta.
14 I dał imię pierwszej Jemina, a imię drugiej Kietzyja, a imię trzeciej Kierenhappuch.
Ó sì sọ orúkọ àkọ́bí ní Jemima, àti orúkọ èkejì ni Kesia àti orúkọ ẹ̀kẹta ní Kereni-Happuki.
15 A nie znajdowały się niewiasty tak piękne, jako córki Ijobowe, we wszystkiej onej ziemi; i dał im ojciec ich dziedzictwo między braćmi ich.
Àti ní gbogbo ilẹ̀ náà, a kò rí obìnrin tí ó ní ẹwà bí ọmọ Jobu; baba wọ́n sì pínlẹ̀ fún wọn nínú àwọn arákùnrin wọn.
16 Potem Ijob żył sto i czterdzieści lat, i oglądał synów swych, i synów synów swoich, aż do czwartego pokolenia.
Lẹ́yìn èyí Jobu wà ní ayé ní ogóje ọdún, ó sì rí àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin àti ọmọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àní ìran mẹ́rin.
17 A umarł Ijob, będąc starym i dni sytym.
Bẹ́ẹ̀ ni Jobu kú, ó gbó, ó sì kún fún ọjọ́ púpọ̀.

< Hioba 42 >