< Hioba 39 >

1 Izali wiesz czas rodzenia kóz skalnych, a kiedy rodzą łanie, postrzegłżeś?
“Ìwọ mọ àkókò ìgbà tí àwọn ewúrẹ́ orí àpáta ń bímọ? Ìwọ sì lè kíyèsi ìgbà tí abo àgbọ̀nrín ń bímọ?
2 Możeszże zliczyć miesiące, jako długo płód noszą? a czas rodzenia ich wieszże?
Ìwọ lè ka iye òṣùpá tí wọn ń pé, ìwọ sì mọ àkókò ìgbà tí wọn ń bímọ.
3 Jako się kurczą, płód swój wyciskają, a rozstępując się z boleścią go pozbywają;
Wọ́n tẹ ara wọn ba, wọ́n bímọ, wọ́n sì mú ìkáàánú wọn jáde.
4 Jako moc biorą dzieci ich, i odchowywują się po zbożach, a odszedłszy nie wracają się do nich.
Àwọn ọmọ wọn rí dáradára, wọ́n dàgbà nínú ọ̀dàn; wọ́n jáde lọ, wọn kò sì tún padà wá sọ́dọ̀ wọn.
5 Któż wypuścił osła dzikiego na wolność? a pęta osła dzikiego któż rozwiązał?
“Ta ni ó jọ̀wọ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ oko lọ́wọ́? Tàbí ta ní ó tú ìdè kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó,
6 Któremu dał pustynię miasto domu jego, a miasto mieszkania jego miejsca słone.
èyí tí mo fi aginjù ṣe ilé fún, àti ilẹ̀ iyọ̀ ní ibùgbé rẹ̀.
7 On się naśmiewa ze zgrai miejskiej, a na głos tego, co go goni, nic niedba.
Ó rẹ́rìn-ín sí ariwo ìlú, bẹ́ẹ̀ ni òun kò sì gbọ́ igbe darandaran.
8 Patrzy po górach pastwy, a wszelkiej zielonej trawy szuka.
Orí àtòlé òkè ńlá ni ibùjẹ oko rẹ̀, òun a sì máa wá ewé tútù gbogbo rí.
9 Izalić będzie chciał jednorożec służyć, albo będzie nocował u jaśli twoich?
“Àgbáǹréré ha jẹ́ sìn ọ́ bí? Tàbí ó jẹ́ dúró ní ibùjẹ ẹran rẹ ní òru?
10 Izali możesz zaprządz w powróz swój jednorożca do orania? izali powleka będzie brózdy za tobą?
Ìwọ le fi òkun tata de àgbáǹréré nínú aporo? Tàbí ó jẹ́ máa fa ìtulẹ̀ nínú aporo oko tọ̀ ọ́ lẹ́yìn?
11 Izali się spuścisz nań, przeto, że wielka moc jego? albo poruczyszli mu robotę twoję?
Ìwọ ó gbẹ́kẹ̀lé e nítorí agbára rẹ̀ pọ̀? Ìwọ ó sì fi iṣẹ́ rẹ lé e lọ́wọ́?
12 Powierzyszże mu się, żeby zwiózł nasienie twoje, a do gumna twojego zgromadził?
Ìwọ le gbẹ́kẹ̀lé pé, yóò mú èso oko rẹ̀ wá sílé, àti pé yóò sì kó ọ jọ sínú àká rẹ?
13 Izaliś dał pawiowi piękne skrzydła, a pierze bocianowi i strusiowi?
“Ìwọ ni yóò ha fi ìyẹ́ dáradára fún ọ̀kín bí, tàbí ìyẹ́ àti ìhùhù bo ògòǹgò?
14 Który niesie na ziemi jajka swoje, a w prochu ogrzewa je.
Ó yé ẹ̀yìn rẹ̀ sílẹ̀ lórí ilẹ̀, a sì mú wọn gbóná nínú ekuru;
15 A nie pomni na to, że je noga zetrzeć, a zwierzę polne zdeptać może.
tí ó sì gbàgbé pé, ẹsẹ̀ lè tẹ̀ wọ́n fọ́, tàbí pé ẹranko igbó lè tẹ̀ wọ́n fọ́.
16 Zatwardza się przeciwko dzieciom swoim, jakoby nie były jego, a żeby nie była próżna praca jego, nie obawia się.
Kò ní àánú sí àwọn ọmọ rẹ̀ bí ẹni pé wọn kì í ṣe tirẹ̀; asán ni iṣẹ́ rẹ̀ láìní ìbẹ̀rù;
17 Bo mu nie dał Bóg mądrości, i nie udzielił mu wyrozumienia.
nítorí pé Ọlọ́run kò fún un ní ọgbọ́n, bẹ́ẹ̀ ni kò sì fi ìpín òye fún un.
18 Według czasu podnosi się ku górze, a naśmiewa się z konia i z jeźdźca jego.
Nígbà tí ó gbé ara sókè, ó gan ẹṣin àti ẹlẹ́ṣin.
19 Izali możesz dać koniowi moc? izali rzaniem ozdobisz szyję jego?
“Ìwọ ni ó fi agbára fún ẹṣin bí, tàbí ṣé ìwọ ni ó fi gọ̀gọ̀ wọ ọrùn rẹ̀ ní aṣọ?
20 Izali go ustraszysz jako szarańczę? i owszem chrapanie nozdrzy jego jest straszne.
Ìwọ le mú fò sókè bí ẹlẹ́ǹgà? Ògo èémí imú rẹ ní ẹ̀rù ńlá.
21 Kopie dół, a weseli się w mocy swej, i bieży przeciwko zbrojnym.
Ó fi ẹsẹ̀ halẹ̀ nínú àfonífojì, ó sì yọ̀ nínú agbára rẹ̀; ó lọ jáde láti pàdé àwọn ìhámọ́ra ogun.
22 Śmieje się z postrachu, a ani się lęka, ani nazad ustępuje przed ostrzem miecza.
Ó fi ojú kékeré wo ẹ̀rù, àyà kò sì fò ó; bẹ́ẹ̀ ni kì í sì í padà sẹ́yìn kúrò lọ́wọ́ idà.
23 Choć na nim chrzęści sajdak, i błyszczy się oszczep, i drzewce.
Lọ́dọ̀ rẹ ni apó-ọfà ń mì pẹkẹpẹkẹ, àti ọ̀kọ̀ dídán àti àpáta.
24 Z grzmotem i z gniewem kopie ziemię, a nie stoi spokojnie na głos trąby.
Ó fi kíkorò ojú àti ìbínú ńlá gbé ilé mi, bẹ́ẹ̀ ni òun kò sì gbà á gbọ́ pé, ìró ìpè ni.
25 Między trąbami poryza, a z daleka czuje bitwę, krzyk książąt, i wołanie.
Ó wí nígbà ìpè pé, Háà! Háà! Ó sì gbóhùn ogun lókèèrè réré, igbe àwọn balógun àti ìhó ayọ̀ ogun wọn.
26 Izali według twego rozumu lata jastrząb, i rozciąga skrzydła swe ku południowi?
“Àwòdì ha máa ti ipa ọgbọ́n rẹ̀ fò sókè, tí ó sì na ìyẹ́ apá rẹ̀ sí ìhà gúúsù?
27 Izali na twoje rozkazanie wzbija się orzeł w górę, i składa na wysokich miejscach gniazdo swoje?
Idì ha máa fi àṣẹ rẹ̀ fò sókè, kí ó sì lọ tẹ́ ìtẹ́ rẹ̀ sí òkè gíga?
28 Na opoce mieszka, i bawi się na ostrej skale, jako na zamku.
Ó ń gbé, ó sì ń wò ní orí àpáta, lórí pàlàpálá òkúta àti ibi orí òkè.
29 Stamtąd upatruje sobie pokarm, a daleko oczy jego widzą.
Láti ibẹ̀ lọ ni ó ti ń wá oúnjẹ kiri, ojú rẹ̀ sì ríran rí òkè réré.
30 Dzieci też jego piją krew, a gdzie są pobici, tam on jest.
Àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú a máa mu ẹ̀jẹ̀, níbi tí òkú bá gbé wà, níbẹ̀ ni òun wà pẹ̀lú.”

< Hioba 39 >