< Hioba 34 >
1 Nadto mówił Elihu, i rzekł:
Nígbà náà ni Elihu dáhùn, ó sì wí pé,
2 Słuchajcież, mądrzy! mów moich, a nauczeni posłuchajcie mię.
“Ẹ̀yin ọlọ́gbọ́n ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, kí ẹ sì fi etí sílẹ̀ sí mi ẹ̀yin tí ẹ ní ìmòye.
3 Bo ucho słów doświadcza, jako podniebienie smakuje pokarmu.
Nítorí pé etí a máa dán ọ̀rọ̀ wò, bí adùn ẹnu ti ń tọ́ oúnjẹ wò.
4 Obierzmy sobie sąd, a rozeznajmy między sobą, co jest dobrego.
Ẹ jẹ́ kí a mọ òye ohun tí o tọ́ fún ara wa; ẹ jẹ́ kí a mọ ohun tí ó dára láàrín wa.
5 Ponieważ Ijob rzekł: Jestem sprawiedliwym, a Bóg odrzucił sprawę moję:
“Nítorí pé Jobu wí pé, ‘Aláìlẹ́ṣẹ̀ ni èmi; Ọlọ́run sì ti gba ìdájọ́ mi lọ.
6 I mamże kłamać, mając sprawiedliwą? Bolesny jest postrzał mój bez przewinienia.
Èmi ha purọ́ sí ẹ̀tọ́ mi bí, bí mo tilẹ̀ jẹ́ aláìjẹ̀bi, ọfà rẹ̀ kò ní àwòtán ọgbẹ́.’
7 Któryż jest mąż taki, jako Ijob, coby pił pośmiewisko jako wodę?
Ọkùnrin wo ni ó dàbí Jobu, tí ń mu ẹ̀gàn bí ẹní mú omi?
8 A coby chodził w towarzystwie czyniących nieprawość; i przestawałby z ludźmi niepobożnymi?
Tí ń bá àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ kẹ́gbẹ́ tí ó sì ń bá àwọn ènìyàn búburú rìn.
9 Bo powiedział: Nie pomoże człowiekowi, choćby się podobał Bogu.
Nítorí ó sá ti wí pé, ‘Èrè kan kò sí fún ènìyàn, tí yóò fi máa ṣe inú dídùn sí Ọlọ́run.’
10 Przetoż mię słuchajcie, mężowie rozumni! Niech będzie daleka niepobożność od Boga, i nieprawość od Wszechmocnego.
“Ǹjẹ́ nítorí náà, ẹ fetísílẹ̀ sí mi, ẹ fi etí sí mi ẹ̀yin ènìyàn amòye: Ó di èèwọ̀ fún Ọlọ́run ti ìbá fi hùwà búburú, àti fún Olódùmarè, tí yóò fi ṣe àìṣedéédéé!
11 Bo on według uczynku płaci człowiekowi, a według drogi jego każdemu nagradza.
Nítorí pé ó ń sán fún ènìyàn fún gẹ́gẹ́ bi ohun tí a bá ṣe, yóò sì mú olúkúlùkù kí ó rí gẹ́gẹ́ bí ipa ọ̀nà rẹ̀.
12 A zgoła Bóg przewrotnie nie czyni, a Wszechmocny nie podwraca sądu.
Nítòótọ́ Ọlọ́run kì yóò hùwàkiwà; bẹ́ẹ̀ ni Olódùmarè kì yóò yí ìdájọ́ po.
13 Któż go przełożył nad ziemią? a kto wystawił cały okrąg świata?
Ta ni ó fi ìtọ́jú ayé lé e lọ́wọ́, tàbí ta ni ó fi gbogbo ayé lé e lọ́wọ́?
14 Jeźliby obrócił przeciwko niemu serce swoje, a ducha jego, i dech jego do siebie wziął:
Bí ó bá gbé ayé rẹ̀ lé kìkì ara rẹ̀ tí ó sì gba ọkàn rẹ̀ àti ẹ̀mí rẹ̀ sọ́dọ̀ ara rẹ̀,
15 Zginęłoby wszelkie ciało społu, a człowiekby się do prochu nawrócił.
gbogbo ènìyàn ni yóò parun pọ̀, ènìyàn a sì tún padà di erùpẹ̀.
16 Maszli tedy rozum, słuchaj tego, a przyjmuj w uszy swe głos mowy mojej.
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, bí ìwọ bá ní òye, gbọ́ èyí; fetísí ohùn ẹnu mi.
17 Azaż ten, który ma w nienawiści sąd, panować może? azaż tego, który jest wielce sprawiedliwy, niepobożnym uczynisz?
Ẹni tí ó kórìíra òtítọ́ ha le ṣe olórí bí? Ìwọ ó ha sì dá olóòótọ́ àti ẹni ńlá lẹ́bi?
18 Zaż potępisz tego, który może rzec królowi: O bezecny! a książętom: O niepobożny!
O ha tọ́ láti wí fún ọba pé, ‘Ènìyàn búburú ní ìwọ,’ tàbí fún àwọn ọmọ-aládé pé, ‘Ìkà ni ẹ̀yin,’
19 Który nie ma względu na osoby książąt, i nie waży sobie więcej bogacza nad ubogiego; bo oni wszyscy są czynem rąk jego.
mélòó mélòó fún ẹni tí kì í ṣe ojúsàájú àwọn ọmọ-aládé tàbí tí kò kà ọlọ́rọ̀ sí ju tálákà lọ, nítorí pé iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni gbogbo wọn í ṣe?
20 Nagle umierają; a o północy wzruszony bywa naród, i przemija, a mocarz zniesiony bywa bez ręki ludzkiej.
Ní ìṣẹ́jú kan ni wọn ó kú, àwọn ènìyàn á sì di yíyọ́ lẹ́nu láàrín ọ̀gànjọ́, wọn a sì kọjá lọ; a sì mú àwọn alágbára kúrò láìsí ọwọ́ ènìyàn níbẹ̀.
21 Oczy bowiem jego nad drogami człowieczemi, a on widzi wszystkie kroki jego.
“Nítorí pé ojú rẹ̀ ń bẹ ní ipa ọ̀nà ènìyàn, òun sì rí ìrìn rẹ̀ gbogbo.
22 Niemasz ciemności, ani cienia śmierci, kędyby się skryli ci, którzy czynią nieprawość.
Kò sí ibi òkùnkùn, tàbí òjìji ikú, níbi tí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ yóò gbé sá pamọ́ sí.
23 Bo na nikogo nie wkłada więcej, tak, żeby miał wchodzić w sąd z Bogiem.
Nítorí pé òun kò pẹ́ àti kíyèsi ẹnìkan, kí òun kí ó sì mú lọ sínú ìdájọ́ níwájú Ọlọ́run.
24 Pociera bardzo wiele mocarzów, a inszych miasto nich wystawia.
Òun ó sì fọ́ àwọn alágbára túútúú láìní ìwádìí, a sì fi ẹlòmíràn dípò wọn,
25 Przeto, iż zna sprawy ich, obraca im dzień w noc, aby byli potarci.
nítorí pé ó mọ iṣẹ́ wọn, ó sì yí wọn po ní òru, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n di ìtẹ̀mọ́lẹ̀.
26 Poraża ich jako niepobożnych na miejscu jawnem.
Ó kọlù wọ́n nítorí ìwà búburú wọn níbi tí àwọn ẹlòmíràn ti lè rí i,
27 Przeto, iż odstąpili od niego, a żadnych dróg jego zrozumieć nie chcieli:
nítorí pé wọ́n padà pẹ̀yìndà sí i, wọn kò sì fiyèsí ipa ọ̀nà rẹ̀ gbogbo,
28 Aby przywiódł na nich wołanie znędzniałych, a pokazał, że wysłuchuje wołanie ubogich.
kí wọn kí ó sì mú igbe ẹkún àwọn tálákà lọ dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, òun sì gbọ́ igbe ẹkún aláìní.
29 Gdy on sprawi pokój, któż go wzruszy? także, gdy skryje oblicze, któż go ujrzy? A to czyni tak całemu narodowi, jako każdemu człowiekowi,
Ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá dákẹ́ síbẹ̀, ta ni yóò dá lẹ́bi? Nígbà tí ó bá pa ojú rẹ̀ mọ́, ta ni yóò lè rí i? Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe si orílẹ̀-èdè tàbí sí ènìyàn kan ṣoṣo;
30 Aby dalej nie panował człowiek obłudny na upadek ludzki.
kí aláìwà bi Ọlọ́run kí ó má bá à jẹ ọba kí wọn kí ó má di ìdẹwò fún ènìyàn.
31 Zaprawdę miałbyś mówić do Boga: Przepuść; poniosę, a nie będę się wzbraniał.
“Nítorí pé ẹnìkan ha lè wí fún Ọlọ́run pé, èmi jẹ̀bi, èmi kò sì ní ṣẹ̀ mọ́?
32 Nadto jeźlibym czego nie baczył, ty mię naucz; jeźlim nieprawość popełnił, nie uczynię tego więcej.
Èyí tí èmi kò rí ìwọ fi kọ́ mi bi mo bá sì dẹ́ṣẹ̀ èmi kì yóò ṣe bẹ́ẹ̀ mọ́.
33 Izali według zdania twego będziesz płacił, żeć się to nie podoba, a żeś ty owo obrał, a nie on? Ale wieszli co lepszego, powiedz.
Ǹjẹ́ bí ti inú rẹ̀ ni ki òun ó san ẹ̀ṣẹ̀ padà? Ǹjẹ́ òun yóò san án padà bí ìwọ bá kọ̀ ọ́ láti jẹ́wọ́, ìwọ gbọdọ̀ yan, kì í ṣe èmi. Nítorí náà sọ ohun tí o mọ̀, pẹ̀lúpẹ̀lú ohun tí ìwọ mọ̀, sọ ọ́!
34 Mężowie rozumni toż rzeką ze mną, a człowiek mądry przypadnie na to,
“Àwọn ènìyàn amòye yóò wí fún mi, àti pẹ̀lúpẹ̀lú ẹnikẹ́ni tí í ṣe ọlọ́gbọ́n tí ó sì gbọ́ mi pé,
35 Że Ijob nie mówi mądrze, a słowa jego nie są roztropne.
‘Jobu ti fi àìmọ̀ sọ̀rọ̀, ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì ṣe aláìgbọ́n.’
36 Boże, Ojcze mój! niech będzie Ijob doskonale doświadczony, przeto, iż nam odpowiada, jako ludziom złym.
Ìfẹ́ mi ni kí a dán Jobu wò dé òpin, nítorí ìdáhùn rẹ̀ dàbí i ti ènìyàn búburú.
37 Bo przestępstwa przyczynia do grzechu swego; chlubi się między nami, i mówi bardzo wiele przeciwko Bogu.
Nítorí pe ó fi ìṣọ̀tẹ̀ kún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀; ó pàtẹ́wọ́ ní àárín wa, ó sì sọ ọ̀rọ̀ odi púpọ̀ sí Ọlọ́run.”