< Hioba 31 >

1 Uczyniłem przymierze z oczyma swemi, abym nie pomyślał o pannie.
“Mo ti bá ojú mi dá májẹ̀mú, èmi yó ha ṣe tẹjúmọ́ wúńdíá?
2 Bo cóż za dział od Boga z góry? a co za dziedzictwo Wszechmocnego z wysokości?
Nítorí pé kí ni ìpín Ọlọ́run láti ọ̀run wá? Tàbí kí ni ogún Olódùmarè láti òkè ọ̀run wá.
3 Azaż nie nagotowane zginienie złośnikom, a sroga pomsta czyniącym nieprawość?
Kò ṣe pé àwọn ènìyàn búburú ni ìparun wà fún, àti àjàkálẹ̀-ààrùn fún àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀?
4 Azaż on nie widzi dróg moich, a wszystkich kroków moich nie liczy?
Òun kò ha ri ipa ọ̀nà mi, òun kò ha sì ka gbogbo ìṣísẹ̀ mi?
5 Jeźlim chodził w kłamstwie, a spieszyła się na zdradę noga moja:
“Bí ó bá ṣe pé èmi bá fi àìṣòótọ́ rìn, tàbí tí ẹsẹ̀ mi sì yára sí ẹ̀tàn,
6 Niech mię zważy na wadze sprawiedliwej, a niech Bóg pozna szczerość moję.
(jẹ́ kí Ọlọ́run wọ́n mí nínú ìwọ̀n òdodo, kí Ọlọ́run le mọ ìdúró ṣinṣin mi.)
7 Jeźliż ustąpiła noga moja z drogi, a za oczyma memi szłoli serce moje, i do rąk moich jeźliż przylgnęła jaka zmaza:
Bí ẹsẹ̀ mí bá yà kúrò lójú ọ̀nà, tí àyà mí sì tẹ̀lé ipa ojú mi, tàbí bí àbàwọ́n kan bá sì lẹ̀ mọ́ mi ní ọwọ́,
8 Tedy niechże ja sieję, a inszy niech pożywa, a moje latorośle niech będą wykorzenione.
ǹjẹ́ kí èmi kí ó gbìn kí ẹlòmíràn kí ó sì mújẹ, àní kí a fa irú-ọmọ mi tu.
9 Jeźli zwiedzione jest serce moje do niewiasty, i jeźlim czyhał u drzwi przyjaciela mego:
“Bí àyà mi bá di fífà sí ipasẹ̀ obìnrin kan, tàbí bí mo bá lọ í ba de ènìyàn ní ẹnu-ọ̀nà ilé aládùúgbò mi,
10 Niechajże mele innemu żona moja, a niechaj się nad nią inni schylają.
kí àyà mi kí ó lọ ọlọ fún ẹlòmíràn, kí àwọn ẹlòmíràn kí ó tẹ̀ ara wọn ní ara rẹ̀.
11 Boć to jest sprosny występek, a nieprawość osądzenia godna,
Nítorí pé yóò jẹ́ ohun ìtìjú àní, ẹ̀ṣẹ̀ tí a ó ṣe onídàájọ́ rẹ̀.
12 Gdyż ten ogień aż do zatracenia pożera, a dochody moje wszystkie wykorzenić może.
Nítorí pé iná ní èyí tí ó jó dé ibi ìparun, tí ìbá sì fa gbòǹgbò ohun ìbísí mi gbogbo tu.
13 Jeźlim stronił od sądu z sługą moim, albo z służebnicą moją, gdy ze mną sprzeczkę mieli,
“Tí mo bá sì ṣe àìka ọ̀ràn ìránṣẹ́kùnrin mi tàbí ìránṣẹ́bìnrin mi sí, nígbà tí wọ́n bá ń bá mi jà;
14 (Bo cóżbym czynił, gdyby powstał Bóg? albo gdyby pytał, cobym mu odpowiedział?
kí ni èmi ó ha ṣe nígbà tí Ọlọ́run bá dìde? Nígbà tí ó bá sì ṣe ìbẹ̀wò, ohùn kí ni èmi ó dá?
15 Izaż nie ten, który mię w żywocie uczynił, nie uczynił też i onego? a nie onże nas sam w żywocie wykształtował?)
Ẹni tí ó dá mi ní inú kọ́ ni ó dá a? Ẹnìkan náà kí ó mọ wá ní inú ìyá wa?
16 Jeźliżem odmówił ubogim, czego chcieli, a oczy wdowy jeźliżem zasmucił;
“Bí mo bá fa ọwọ́ sẹ́yìn fún ìfẹ́ inú tálákà, tàbí bí mo bá sì mú kí ojú opó rẹ̀wẹ̀sì,
17 Jeźliżem jadł sztuczkę swoję sam, a nie jadała i sierota z niej;
tàbí tí mo bá nìkan bu òkèlè mi jẹ, tí aláìní baba kò jẹ nínú rẹ̀;
18 (Albowiem sierota z młodości mojej rosła ze mną, jako u ojca; a jakom wyszedł z żywota matki mojej, byłem wdowie za wodza.)
nítorí pé láti ìgbà èwe mi wá ni a ti tọ́ ọ dàgbà pẹ̀lú mi bí ẹni pé baba, èmi sì ń ṣe ìtọ́jú opó láti inú ìyá mi wá:
19 Jeźliżem widział kogo ginącego dla tego, że szaty nie miał, a nie dałem żebrakowi odzienia;
bí èmi bá rí olùpọ́njú láìní aṣọ, tàbí tálákà kan láìní ìbora;
20 Jeźliże mi nie błogosławiły biodra jego, że się wełną owiec moich zagrzał;
bí ọkàn rẹ̀ kò bá súre fún mi, tàbí bí ara rẹ̀ kò sì gbóná nípasẹ̀ irun àgùntàn mi;
21 Jeźliżem podniósł przeciwko sierocie rękę swoję, gdym widział w bramie pomoc moję:
bí mo bá sì gbé ọwọ́ mi sókè sí aláìní baba, nítorí pé mo rí ìrànlọ́wọ́ mi ní ẹnu ibodè,
22 Tedy niech odpadnie łopatka moja od plec swych, a ramię moje z stawu swego niech wytracone będzie.
ǹjẹ́, ní apá mi kí o wọ́n kúrò ní ihò èjìká rẹ̀, kí apá mi kí ó sì ṣẹ́ láti egungun rẹ̀ wá.
23 Albowiem lękałem się skruszenia od Boga, a przed jego zacnością nie mógłbym się ostać.
Nítorí pé ìparun láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá ni ẹ̀rù ńlá fún mi, àti nítorí ọláńlá rẹ̀ èmi kò le è dúró.
24 Jeźlim pokładał w złocie nadzieję moję, a do bryły złota mawiałem: Tyś ufanie moje;
“Bí ó bá ṣe pé mo fi wúrà ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé mi, tàbí tí mo bá wí fún fàdákà dídára pé, ‘Ìwọ ni ààbò mi,’
25 Jeźlim się weselił z wielu bogactw moich, a iż wiele nabyła ręka moja;
bí mo bá yọ̀ nítorí ọrọ̀ mí pọ̀, àti nítorí ọwọ́ mi dara lọ́pọ̀lọ́pọ̀,
26 Jeźlim patrzał na światłość słońca, gdy świeciło, a na miesiąc, gdy wspaniało chodził;
bí mo bá bojú wo oòrùn nígbà tí ń ràn, tàbí òṣùpá tí ń ràn nínú ìtànmọ́lẹ̀,
27 I dało się uwieść potajemnie serce moje, a całowały rękę moję usta moje:
bí a bá tàn ọkàn mi jẹ láti fi ẹnu mi kò ọwọ́ mi,
28 I toćby była nieprawość osądzenia godna; bobym się tem zaprzał Boga z wysokości.
èyí pẹ̀lú ni ẹ̀ṣẹ̀ ti àwọn onídàájọ́ ní láti bẹ̀wò, nítorí pé èmí yóò jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run tí ó wà lókè.
29 Jeźliżem się weselił z upadku nienawidzącego mię, a jeźlim się cieszył, gdy mu się źle powodziło.
“Bí ó bá ṣe pé mo yọ̀ sì ìparun ẹni tí ó kórìíra mi. Tàbí bí mo bá sì gbéraga sókè, nígbà tí ibi bá a.
30 (I owszem nie dałem zgrzeszyć ustom moim, abym miał żądać przeklęstwa duszy jego.)
Bẹ́ẹ̀ èmi kò sì jẹ ki ẹnu mi ki ó ṣẹ̀ nípa fífẹ́ ègún sí ọkàn rẹ̀.
31 Azaż nie mawiali domownicy moi: Oby nam kto dał mięsa tego, nie możemy się i najeść?
Bí àwọn ènìyàn inú àgọ́ mi kò bá lè wí pé, ‘Ta ni kò ì tí ì jẹ ẹran rẹ̀ ní àjẹyó?’
32 Bo gość nie nocował na dworze, a drzwi moje otwierałem podróżnemu.
Àlejò kò wọ̀ ni ìgboro rí; èmí ṣí ìlẹ̀kùn mi sílẹ̀ fún èrò.
33 Jeźlim zakrywał, jako ludzie zwykli, przestępstwa moje, i chowałem w skrytości mojej nieprawość moję;
Bí mo bá bò ẹ̀ṣẹ̀ mi mọ́lẹ̀ bí Adamu ni pápá, ẹ̀bi mi pamọ́ ni àyà mi.
34 I choćbym był mógł potłumić zgraję wielką, jednak i najpodlejszy z domu ustraszył mię; przetożem milczał, i nie wychodziłem ze drzwi.
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni mo ha bẹ̀rù bí? Tàbí ẹ̀gàn àwọn ìdílé ní ń bà mí ní ẹ̀rù? Tí mo fi pa ẹnu mọ́, tí èmí kò sì fi sọ̀rọ̀ jáde?
35 Obym miał kogo, coby mię wysłuchał; ale oto ten jest znak mój, że Wszechmogący sam odpowie za mię, i księga, którą napisał przeciwnik mój.
(“Ìbá ṣe pé ẹnìkan le gbọ́ ti èmí! Kíyèsi i, àmì mi, kí Olódùmarè kí ó dá mi lóhùn, kí èmí kí ó sì rí ìwé náà tí olùfisùn mi ti kọ.
36 Czylibym jej na ramieniu swojem nie nosił? a nie przywiązałbym jej sobie miasto korony?
Nítòótọ́ èmí ìbá gbé le èjìká mi, èmi ìbá sì dé bí adé mọ́ orí mi.
37 Liczbę kroków moich oznajmiłbym mu; jako do książęcia przystąpiłbym do niego.
Èmi ìbá sì sọ iye ìṣísẹ̀ mi fún un, bí ọmọ-aládé ni èmi ìbá súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀.)
38 Jeźliż przeciw mnie ziemia moja wołała, a jeźliże z nią społem zagony jej płakały;
“Bí ilẹ̀ mi bá sì ké rara lòdì sí mi tí a sì fi omijé kún gbogbo poro rẹ̀.
39 Jeźliżem pożytków jej używał bez pieniędzy, i jeźlim do wzdychania przywodził dzierżawców jej:
Bí mo bá jẹ èso oko mi láìsan owó tàbí tí mo sì mú ọkàn olúwa rẹ̀ fò lọ,
40 Miasto pszenicy niech wznijdzie oset, a miasto jęczmienia kąkol. Tu się skończyły słowa Ijobowe.
kí ẹ̀gún òṣùṣú kí ó hù dípò alikama, àti èpò búburú dípò ọkà barle.” Ọ̀rọ̀ Jobu parí.

< Hioba 31 >