< Hioba 30 >

1 Ale teraz śmieją się ze mnie młodsi nad mię w latach, których ojcówbym ja był nie chciał położyć ze psami trzody mojej.
“Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, àwọn tí mo gbà ní àbúrò ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà baba ẹni tí èmi kẹ́gàn láti tò pẹ̀lú àwọn ajá nínú agbo ẹran mi.
2 Acz na cóżby mi się była siła rąk ich przydała? bo przy nich starość ich zginęła.
Kí ni ìwúlò agbára ọwọ́ wọn sí mi, níwọ̀n ìgbà tí agbára wọn ti fi wọ́n sílẹ̀?
3 Albowiem dla niedostatku i głodu samotni byli, i uciekali na niepłodne, ciemne, osobne, i puste miejsce;
Wọ́n rù nítorí àìní àti ìyàn wọ́n ń rìn káàkiri ní ilẹ̀ gbígbẹ ní ibi ìkọ̀sílẹ̀ ní òru.
4 Którzy sobie rwali chwasty po chróstach, a korzonki jałowcowe były pokarmem ich.
Àwọn ẹni tí ń já ewé iyọ̀ ní ẹ̀bá igbó; gbogbo igikígi ni oúnjẹ jíjẹ wọn.
5 Z pośrodku ludzi wyganiano ich; wołano za nimi jako za złodziejem,
A lé wọn kúrò láàrín ènìyàn, àwọn ènìyàn sì pariwo lé wọn lórí bí ẹní pariwo lé olè lórí.
6 Tak, iż w łożyskach potoków mieszkać musieli, w jamach podziemnych i w skałach.
A mú wọn gbe inú pàlàpálá òkúta àfonífojì, nínú ihò ilẹ̀ àti ti òkúta.
7 Między chróstami ryczeli, pod pokrzywy zgromadzali się.
Wọ́n ń dún ní àárín igbó wọ́n kó ara wọn jọ pọ̀ ní abẹ́ ẹ̀gún neteli.
8 Synowie ludzi wzgardzonych, i synowie ludzi bezecnych, podlejsi byli nad proch ziemi.
Àwọn ọmọ ẹni tí òye kò yé, àní àwọn ọmọ lásán, a sì lé wọn jáde kúrò ní orí ilẹ̀.
9 Alem teraz pieśnią ich, i stałem się im przypowieścią.
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, àwọn ọmọ wọn ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà nínú orin; àní èmi di ẹni ìṣọ̀rọ̀ sí láàrín wọn.
10 Brzydzą się mną, a oddalają się odemnie, i na twarz moję plwać się nie wstydzą.
Wọ́n kórìíra mi; wọ́n sá kúrò jìnnà sí mi, wọn kò sì bìkítà láti tutọ́ sí mi lójú.
11 Bo Bóg powagę moję odjął i utrapił mię; dlatego oni wędzidło przed twarzą moją odrzucili.
Nítorí Ọlọ́run ti tú okùn ìyè mi, ó sì pọ́n mi lójú; àwọn pẹ̀lú sì dẹ ìdẹ̀kùn níwájú mi.
12 Po prawicy mojej młodzikowie powstawają, nogi moje potrącają, i torują na przeciwko mnie drogi zginienia swego.
Àwọn ènìyàn lásán dìde ní apá ọ̀tún mi; wọ́n tì ẹsẹ̀ mi kúrò, wọ́n sì la ipa ọ̀nà ìparun sílẹ̀ dè mí.
13 Popsuli ścieszkę moję, i nędzy do nędzy mojej przyczynili, a nie potrzebują do tego pomocnika.
Wọ́n da ipa ọ̀nà mi rú; wọ́n sì sọ ìparun mi di púpọ̀, àwọn tí kò ní olùrànlọ́wọ́.
14 Jako przerwą szeroką napadają na mię, i na spustoszenie moje walą się.
Wọ́n ya sí mi bí i omi tí ó ya gbuuru; ní ariwo ńlá ni wọ́n rọ́ wá.
15 Obróciły się przeciwko mnie strachy, jako wiatr ściągają duszę moję; bo jako obłok przemija zdrowie moje.
Ẹ̀rù ńlá bà mí; wọ́n lépa ọkàn mi bí ẹ̀fúùfù, àlàáfíà mi sì kọjá lọ bí àwọ̀ sánmọ̀.
16 A teraz we mnie rozlała się dusza moja; ogarnęły mię dni utrapienia;
“Àti nísinsin yìí, ayé mi n yòrò lọ díẹ̀díẹ̀; ọjọ́ ìpọ́njú mi dì mímú.
17 Które w nocy wiercą kości moje we mnie, skąd żyły moje nie mają odpoczynku.
Òru gún mi nínú egungun mi, èyí tí ó bù mí jẹ kò sì sinmi.
18 Dla wielkiej boleści zmieniła się szata moja, a jako kołnierz sukni mojej ściska mię.
Nípa agbára ńlá rẹ̀ Ọlọ́run wà bí aṣọ ìbora fún mi, ó sì lẹ̀ mọ́ mi ní ara yíká bí aṣọ ìlekè mi.
19 Wrzucił mię w błoto, a jestem podobien prochowi i popiołowi.
Ọlọ́run ti mú mi lọ sínú ẹrẹ̀, èmi sì dàbí eruku àti eérú.
20 Wołam do ciebie, a nie wysłuchujesz mię; stoję przed tobą, a nie patrzysz na mię.
“Èmi ké pè ọ́ ìwọ Ọlọ́run, ṣùgbọ́n ìwọ kò dá mi lóhùn; èmi dìde dúró ìwọ sì wò mí lásán.
21 Odmieniłeś mi się w okrutnego, a mocą ręki twej sprzeciwiasz mi się.
Ìwọ padà di ẹni ìkà sí mi; ọwọ́ agbára rẹ ni ìwọ fi dè mí ní ọ̀nà.
22 Podnosisz mię na wiatr, i wsadzasz mię nań, a zdrowemu rozsądkowi rozpłynąć się dopuszczasz.
Ìwọ gbé mi sókè sí inú ẹ̀fúùfù, ìwọ mú mi fò lọ, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ sì sọ mí di asán pátápátá.
23 Wiemci, że mię na śmierć podasz, i do domu wszystkim żyjącym naznaczonego.
Èmi sá à mọ̀ pé ìwọ yóò mú mi lọ sínú ikú, sí ilé ìpéjọ tí a yàn fún gbogbo alààyè.
24 Wszakże na grób nie ściągnie ręki swej, a gdy ich niszczyć będzie, wołać nie będą.
“Bí ó ti wù kí ó rí, ẹnìkan kí yóò ha nawọ́ rẹ̀ nígbà ìṣubú rẹ̀, tàbí kì yóò ké nínú ìparun rẹ̀.
25 Izalim nie płakał nad dniem utrapionego? izali się nie smuciła dusza moja nad ubogim?
Èmi kò ha sọkún bí fún ẹni tí ó wà nínú ìṣòro? Ọkàn mi kò ha bàjẹ́ fún tálákà bí?
26 Gdym dobrego oczekiwał, oto przyszło złe; a gdym się spodziewał światłości, przyszła ciemność.
Nígbà tí mo fojú ṣọ́nà fún àlàáfíà, ibi sì dé; nígbà tí mo dúró de ìmọ́lẹ̀, òkùnkùn sì dé.
27 Wnętrzności moje wezwrzały, a nie uspokoiły się, i ubieżały mię dni utrapienia.
Ikùn mí n ru kò sì sinmi, ọjọ́ ìpọ́njú ti dé bá mi.
28 Chodzę szczerniawszy, ale nie od słońca; powstaję i wołam w zgromadzeniu.
Èmí ń rìn kiri nínú ọ̀fọ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú oòrùn; èmi dìde dúró ní àwùjọ mo sì kígbe fún ìrànlọ́wọ́.
29 Stałem się bratem smoków, a towarzyszem strusiów młodych.
Èmi ti di arákùnrin ìkookò, èmi di ẹgbẹ́ àwọn ògòǹgò.
30 Skóra moja poczerniała na mnie, i kości moje wypiekły się od upalenia.
Àwọ̀ mi di dúdú ní ara mi; egungun mi sì jórun fún ooru.
31 Obróciła się w lament harfa moja, a instrument mój w głos płaczących.
Ohun èlò orin mi pẹ̀lú sì di ti ọ̀fọ̀, àti ìpè orin mi sì di ohùn àwọn tí ń sọkún.

< Hioba 30 >