< Hioba 29 >
1 Jeszcze dalej Ijob prowadził rzecz swoję, i rzekł:
Pẹ̀lúpẹ̀lú, Jobu sì tún tẹ̀síwájú nínú ọ̀rọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé,
2 Któż mi to da, abym był jako za miesięcy dawnych, za dni onych, których mię Bóg strzegł;
“Háà! ìbá ṣe pé èmi wà bí ìgbà oṣù tí ó kọjá, bí ọjọ́ tí Ọlọ́run pa mí mọ́,
3 Gdy pochodnia jego świeciła nad głową moją, a przy świetle jego przechodziłem ciemności;
nígbà tí fìtílà rẹ tàn sí mi ní orí, àti nípa ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ èmi rìn nínú òkùnkùn já.
4 Jakom był za dni młodości mojej, gdy była przytomność Boża nad przybytkiem moim;
Bí mo ti rí nígbà ọ̀dọ́ mi, nígbà tí ọ̀rẹ́ Ọlọ́run tímọ́tímọ́ bùkún ilé mi,
5 Gdy jeszcze Wszechmocny był ze mną, a około mnie dziatki moje;
nígbà tí Olódùmarè wà pẹ̀lú mi, nígbà tí àwọn ọmọ mi wà yí mi ká;
6 Gdy ścieszki moje opływały masłem, a opoka wylewała mi źródła oliwy;
nígbà tí èmi fi òrí-àmọ́ n wẹ ìṣísẹ̀ mi, àti tí àpáta ń tú ìṣàn òróró jáde fún mi wá.
7 Gdym wychodził do bramy przez miasto, a na ulicy kazałem sobie gotować stolicę moję.
“Nígbà tí mo jáde la àárín ìlú lọ sí ẹnu ibodè, nígbà tí mo tẹ́ ìtẹ́ mi ní ìgboro,
8 Widząc mię młodzi ukrywali się, a starcy powstawszy stali.
nígbà náà ni àwọn ọmọkùnrin rí mi, wọ́n sì sá pamọ́, àwọn àgbà dìde dúró ní ẹsẹ̀ wọn,
9 Przełożeni przestawali mówić, a ręką zatykali usta swoje.
àwọn ọmọ-aládé dákẹ́ ọ̀rọ̀ sísọ, wọn a sì fi ọwọ́ wọn lé ẹnu.
10 Głos książąt ucichał, a język ich do podniebienia ich przylegał.
Àwọn ọlọ́lá dákẹ́, ahọ́n wọn sì lẹ̀ mọ́ èrìgì ẹnu wọn.
11 Bo ucho słuchające błogosławiło mię, a oko widzące dawało o mnie świadectwo,
Nígbà tí etí gbọ́, ó sì súre fún mi, àti nígbà tí ojú sì rí mi, ó jẹ́rìí mi,
12 Żem wybawiał ubogiego wołającego, i sierotkę, i tego, który nie miał pomocnika.
nítorí mo gbà tálákà tí n fẹ́ ìrànlọ́wọ́, àti aláìní baba tí kò sí olùrànlọ́wọ́ fún un.
13 Błogosławieństwo ginącego przychodziło na mię, a serce wdowy rozweselałem.
Ẹni tí ó ń kìlọ̀ súre fún mi, èmi sì mú àyà opó kọrin fún ayọ̀.
14 W sprawiedliwość obłoczyłem się, a ona zdobiła mię; sąd mój był jako płaszcz i korona.
Èmi sì mú òdodo wọ̀ bí aṣọ, ẹ̀tọ́ mi dàbí aṣọ ìgúnwà àti adé ọba.
15 Byłem okiem ślepemu, a nogą chromemu.
Mo ṣe ojú fún afọ́jú mo sì ṣe ẹsẹ̀ fún amúnkùn ún.
16 Byłem ojcem ubogich, a sprawy, którejm nie wiedział, wywiadywałem się.
Mo ṣe baba fún tálákà; mo ṣe ìwádìí ọ̀ràn àjèjì tí èmi kò mọ̀ rí.
17 I kruszyłem szczęki złośnika, a z zębów jego wydzierałem łup.
Mo sì ká eyín ẹ̀rẹ̀kẹ́ ènìyàn búburú, mo sì já ohun ọdẹ náà kúrò ní eyín rẹ̀.
18 Przetożem rzekł: W gniaździe swojem umrę, a jako piasek rozmnożę dni moje.
“Nígbà náà ni mo rò pé, ‘Èmi yóò kú nínú ilé mi, èmi yóò sì mú ọjọ́ mi pọ̀ sí i bí iyanrìn.
19 Korzeń mój rozłoży się przy wodach, a rosa trwać będzie przez noc na gałązkach moich.
Gbòǹgbò mi yóò ta kan omi, ìrì yóò sì sẹ̀ ní gbogbo òru sí ara ẹ̀ka mi.
20 Chwała moja odmłodzi się przy mnie, a łuk mój w ręce mojej odnowi się.
Ògo mi yóò wà ní ọ̀tún ní ọ̀dọ̀ mi, ọrun mi sì padà di tuntun ní ọwọ́ mi.’
21 Słuchano mię, i oczekiwano na mię, a milczano na radę moję.
“Èmi ni ènìyàn ń dẹtí sílẹ̀ sí, wọn a sì dúró, wọn a sì dákẹ́ rọ́rọ́ ní ìmọ̀ràn mi.
22 Po słowie mojem nie powtarzano, tak na nich kropiła mowa moja.
Lẹ́yìn ọ̀rọ̀ mi, wọn kò tún sọ̀rọ̀ mọ́; ọ̀rọ̀ mi wọ̀ wọ́n ní etí ṣinṣin.
23 Bo mię oczekiwali jako deszczu, a usta swe otwierali jako na deszcz późny.
Wọn a sì dúró dè mí bí ẹni wí pé wọ́n dúró fún ọ̀wọ́ òjò; wọn a sì mu nínú ọ̀rọ̀ mi bí ẹní mu nínú òjò àrọ̀kúrò.
24 Jeźlim żartował z nimi, nie wierzyli, a powagi twarzy mojej nie odrzucali.
Èmi sì rẹ́rìn-ín sí wọn nígbà tí wọn kò bá gbà á gbọ́; ìmọ́lẹ̀ ojú mi jẹ́ iyebíye sí wọn.
25 Jeźlim kiedy do nich przyszedł, siadałem na przedniejszem miejscu, i mieszkałem jako król w wojsku, a jako ten, który smutnych cieszy.
Mo la ọ̀nà sílẹ̀ fún wọn, mo sì jókòó bí olóyè wọn. Mo jókòó bí ọba ní àárín ológun rẹ, mo sì rí bí ẹni tí ń tu ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀ nínú.