< Hioba 21 >

1 A odpowiadając Ijob rzekł:
Jobu wá dáhùn, ó sì wí pé,
2 Słuchajcież z pilnością słów moich, a będzie mi to od was pociechą.
“Ẹ tẹ́tí sílẹ̀ dáradára sì àwọn ọ̀rọ̀ mi, kí èyí kí ó jásí ìtùnú fún mi.
3 Znoście mię, a ja będę mówił; a gdy domówię, naśmiewajcie się.
Ẹ jọ̀wọ́ mi ki èmi sọ̀rọ̀; lẹ́yìn ìgbà ìwọ le máa fi mi ṣẹ̀sín ń ṣo.
4 Izaż do człowieka obracam narzekanie moje? a ponieważ mam o co, jakoż się niema trapić duch mój?
“Àròyé mi ha ṣe sí ènìyàn bí? Èétise tí ọkàn mi kì yóò fi ṣe àìbalẹ̀?
5 Wejrzyjcież na mię, a zdumiewajcie się, a połóżcie rękę na usta wasze.
Ẹ wò mí fín, kí ẹnu kí ó sì yà yín, kí ẹ sì fi ọwọ́ lé ẹnu yín.
6 Bo co sobie wspomnę, tedy się lękam, a strach zdejmuje ciało moje.
Àní nígbà tí mo rántí, ẹ̀rù bà mí, ìwárìrì sì mú mi lára.
7 Przeczże niepobożni żyją, starzeją się, i wzmagają się w bogactwa?
Nítorí kí ní ènìyàn búburú fi wà ní ayé, tí wọ́n gbó, àní tí wọ́n di alágbára ní ipa?
8 Nasienie ich trwałe jest przed obliczem ich z nimi, a rodzina ich przed oczyma ich.
Irú-ọmọ wọn fi ìdí kalẹ̀ ní ojú wọn pẹ̀lú wọn, àti ọmọ ọmọ wọn ní ojú wọn.
9 Domy ich bezpieczne od strachu, a niemasz rózgi Bożej nad nimi.
Ilé wọn wà láìní ewu àti ẹ̀rù, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá ìbínú Ọlọ́run kò sí lára wọn.
10 Byk ich przypuszczon bywa, a nie traci nasienia; krowa ich rodzi, a nie pomiata.
Akọ màlúù wọn a máa gùn, kì í sì tàsé; abo màlúù wọn a máa bí, kì í sì í ṣẹ́yun.
11 Wypuszczają maluczkie dziatki swoje jako trzodę, a synowie ich wyskakują.
Wọn a máa rán àwọn ọmọ wọn wẹ́wẹ́ jáde bí agbo ẹran, àwọn ọmọ wọn a sì máa jo kiri.
12 Wykrzykają przy bębnie i przy harfie, a weselą się przy głosie muzyki.
Wọ́n mú ohun ọ̀nà orin, ìlù àti haapu; wọ́n sì ń yọ̀ sí ohùn fèrè.
13 Trawią w dobrem dni swoje, a we mgnieniu oka do grobu zstępują. (Sheol h7585)
Wọ́n n lo ọjọ́ wọn nínú ọrọ̀; wọn sì lọ sí ipò òkú ní àlàáfíà. (Sheol h7585)
14 Którzy mawiają Bogu: Odejdź od nas; bo dróg twoich znać nie chcemy.
Nítorí náà ni wọ́n ṣe wí fún Ọlọ́run pé, ‘Lọ kúrò lọ́dọ̀ wa!’ Nítorí pé wọn kò fẹ́ ìmọ̀ ipa ọ̀nà rẹ.
15 Któż jest Wszechmocny, abyśmy mu służyli? a cóż nam to pomoże, choćbyśmy mu się modlili?
Kí ni Olódùmarè tí àwa ó fi máa sìn in? Èrè kí ni a ó sì jẹ bí àwa ba gbàdúrà sí i?
16 Ale oto, dobra ich nie są w rękach ich; przetoż rada niepobożnych daleka jest odemnie.
Kíyèsi i, àlàáfíà wọn kò sí nípa ọwọ́ wọn; ìmọ̀ ènìyàn búburú jìnnà sí mi réré.
17 Częstoż pochodnia niepobożnych gaśnie? a zginienie ich przychodzi na nich? Oddziela im Bóg boleści w gniewie swoim.
“Ìgbà mélòó mélòó ní a ń pa fìtílà ènìyàn búburú kú? Ìgbà mélòó mélòó ní ìparun wọn dé bá wọn, tí Ọlọ́run sì í máa pín ìbìnújẹ́ nínú ìbínú rẹ̀?
18 Stawają się jako plewa przed wiatrem, i jako perz, który wicher porywa.
Wọ́n dàbí àgékù koríko níwájú afẹ́fẹ́, àti bí ìyàngbò, tí ẹ̀fúùfù ńlá fẹ́ lọ.
19 Bo Bóg chowa synom jego pomstę jego; nadgradza mu, aby to poczuł.
Ẹ̀yin wí pé, ‘Ọlọ́run to ìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ jọ fún àwọn ọmọ rẹ̀.’ Jẹ́ kí ó san án fún un, yóò sì mọ̀ ọ́n.
20 Oglądają oczy jego nieszczęście swoje, a z popędliwości Wszechmocnego pić będzie.
Ojú rẹ̀ yóò rí ìparun ara rẹ̀, yóò sì máa mu nínú ríru ìbínú Olódùmarè.
21 Co za staranie jego o domu jego po nim, gdyż liczba miesięcy jego umniejszona jest?
Nítorí pé àlàáfíà kí ni ó ní nínú ilé rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, nígbà tí a bá ké iye oṣù rẹ̀ kúrò ní agbede-méjì?
22 Izali Boga kto nauczy umiejętności, gdyż on wysokich sądzi?
“Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni le kọ Ọlọ́run ní ìmọ̀? Òun ní í sá à ń ṣe ìdájọ́ ẹni ibi gíga.
23 Ten umiera w doskonałej sile swojej, gdy zewsząd bezpieczny i spokojny jest;
Ẹnìkan a kú nínú pípé agbára rẹ̀, ó wà nínú ìrora àti ìdákẹ́ pátápátá.
24 Gdy piersi jego pełne są mleka, a szpik kości jego odwilża się,
Ọpọ́n rẹ̀ kún fún omi ọmú, egungun rẹ̀ sì tutù fún ọ̀rá.
25 Inny zaś umiera w gorzkości ducha, który nie jadał z uciechą.
Ẹlòmíràn a sì kú nínú kíkorò ọkàn rẹ̀, tí kò sì fi inú dídùn jẹun.
26 Spólnie w prochu leżeć będą, a robaki ich okryją.
Wọ́n o dùbúlẹ̀ bákan náà nínú erùpẹ̀, kòkòrò yóò sì ṣùbò wọ́n.
27 Oto ja znam myśli wasze i zamysły, które przeciwko mnie złośliwie zmyślacie.
“Kíyèsi i, èmi mọ̀ èrò inú yín àti àrékérekè ọkàn yín láti ṣe ìlòdì sí mi.
28 Bo mówicie: Gdzież jest dom książęcy? gdzie namiot przybytków niepobożnych?
Nítorí tí ẹ̀yin wí pé, ‘Níbo ní ilé ọmọ-aládé, àti níbo ní àgọ́ àwọn ènìyàn búburú nì gbé wà?’
29 Izaliście nie pytali podróżnych? a znaków ich izali znać nie chcecie?
Ẹ̀yin kò béèrè lọ́wọ́ àwọn tí ń kọjá lọ ní ọ̀nà? Ẹ̀yin kò mọ̀ àmì wọn,
30 Że w dzień zatracenia zły zachowany bywa, w dzień, którego gniew przywiedziony bywa.
pé ènìyàn búburú ní a fi pamọ́ fún ọjọ́ ìparun. A ó sì mú wọn jáde ní ọjọ́ ríru ìbínú.
31 Któż mu oznajmi w oczy drogę jego? a to, co czynił, kto mu odpłaci?
Ta ni yóò tako ipa ọ̀nà rẹ̀ lójúkojú, ta ni yóò sì san án padà fún un ní èyí tí ó ti ṣe?
32 Wszakże i on do grobów zaprowadzony będzie, a w kupie umarłych zawżdy zostanie.
Síbẹ̀ a ó sì sin ín ní ọ̀nà ipò òkú, a ó sì máa ṣọ́ ibojì òkú.
33 Słodnieją mu bryły grobowe, i ciągnie za sobą wszystkich ludzi; a tych, którzy go poprzedzili, niemasz liczby.
Ògúlùtu àfonífojì yóò dùn mọ́ ọn. Gbogbo ènìyàn yóò sì máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, bí ènìyàn àìníye ti lọ síwájú rẹ̀.
34 Jakoż mię tedy próżno cieszycie, gdyż w odpowiedziach waszych zostaje kłamstwo?
“Èéha ti ṣe tí ẹ̀yin fi ń tù mí nínú lásán, bí ò ṣe pé ní ìdáhùn yín, àrékérekè wa níbẹ̀!”

< Hioba 21 >