< Hioba 15 >
1 A odpowiadając Elifas Temańczyk rzekł:
Ìgbà náà ní Elifasi, ará Temani, dáhùn wí pé,
2 Izali mądry ma na wiatr mówić? albo napełniać wschodnim wiatrem myśl swoję?
“Ọlọ́gbọ́n a máa sọ̀rọ̀ ìmọ̀ asán kí ó sì máa fi afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn kún ara rẹ̀ nínú?
3 Przytaczając słowa niepożyteczne, i mowy, z których nie masz pożytku?
Òun lè máa fi àròyé sọ̀rọ̀ tí kò ní èrè, tàbí pẹ̀lú ọ̀rọ̀ nínú èyí tí kò lè fi ṣe rere?
4 Zaiste ty psujesz bojaźń Bożą i znosisz modlitwy do Boga.
Ṣùgbọ́n ìwọ ṣá ìbẹ̀rù tì, ìwọ sì dí iṣẹ́ ìsìn lọ́nà níwájú Ọlọ́run.
5 Albowiem pokazują nieprawość twą usta twoje, chociażeś sobie obrał język chytrych,
Nítorí pé ẹnu ara rẹ̀ ni ó jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ìwọ sì yàn ahọ́n alárékérekè ni ààyò.
6 Potępiają cię usta twoje, a nie ja; a wargi twoje świadczą przeciwko tobie.
Ẹnu ara rẹ̀ ni ó dá lẹ́bi, kì í ṣe èmi; àní ètè ara rẹ̀ ni ó jẹ́rìí gbè ọ́.
7 Czyś się najpierwszym człowiekiem urodził? czyś przed pagórkami utworzony?
“Ìwọ ha í ṣe ọkùnrin tí a kọ́ bí? Tàbí a ha dá ọ ṣáájú àwọn òkè?
8 Izażeś tajemnic Bożych słuchał, a nie masz mądrości jedno w tobie?
Ìwọ gbúròó àṣírí Ọlọ́run rí? Tàbí ìwọ ha dá ọgbọ́n dúró sọ́dọ̀ ara rẹ?
9 Cóż ty umiesz, czego my nie wiemy? albo cóż ty rozumiesz, czegobyśmy my nie rozumieli?
Kí ni ìwọ mọ̀ tí àwa kò mọ̀? Òye kí ní ó yé ọ tí kò sí nínú wa?
10 I sędziwyć i starzec między nami jest starszy w latach niż ojciec twój.
Àwọn arúgbó àti ògbólógbòó ènìyàn wà pẹ̀lú wa, tí wọ́n dàgbà ju baba rẹ lọ.
11 I lekceż sobie ważysz pociechy Boskie? i maszże jeszcze co tak skrytego w sobie?
Ìtùnú Ọlọ́run ha kéré lọ́dọ̀ rẹ? Ọ̀rọ̀ kan sì ṣe jẹ́jẹ́ jù lọ́dọ̀ rẹ?
12 Czemuż cię tak uniosło serce twoje? Czemu mrugają oczy twoje?
Èéṣe ti ọkàn rẹ fi ń ti ọ kiri, kí ni ìwọ tẹjúmọ́ tóbẹ́ẹ̀.
13 Że tak odpowiada Bogu duch twój, a wypuszczasz z ust twoich takowe mowy?
Tí ìwọ fi yí ẹ̀mí rẹ padà lòdì sí Ọlọ́run, tí ó fi ń jẹ́ ki ọ̀rọ̀kọ́rọ̀ kí ó máa bọ́ ní ẹnu rẹ̀ bẹ́ẹ̀?
14 Cóż jest człowiek, aby miał być czystym, albo żeby miał być sprawiedliwym, urodzony z niewiasty?
“Kí ni ènìyàn tí ó fi jẹ mímọ́, àti ẹni tí a tinú obìnrin bí tí yóò fi ṣe olódodo?
15 Oto i w świętych jego niemasz doskonałości, i niebiosa nie są czyste w oczach jego.
Kíyèsi i, bi Ọlọ́run ko ba gbẹ́kẹ̀lé àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀, àní àwọn ọ̀run kò mọ́ ní ojú rẹ̀,
16 Daleko więcej obrzydły jest, i nieużyteczny człowiek, który pije nieprawość jako wodę.
mélòó mélòó ni ènìyàn, ẹni ìríra àti eléèérí, tí ń mu ẹ̀ṣẹ̀ bi ẹní mu omi.
17 Okażęć, tylko mię słuchaj; a com widział, oznajmięć,
“Èmi ó fihàn ọ́, gbọ́ ti èmi; èyí tí èmi sì rí, òun ni èmi ó sì sọ,
18 Co mędrzy powiedzieli, a nie zataili, co mieli od przodków swoich;
ohun tí àwọn ọlọ́gbọ́n ti pa ní ìtàn láti ọ̀dọ̀ àwọn baba wọn wá, ti wọ́n kò sì fi pamọ́.
19 Którym samym dana była ziemia, a żaden obcy nie przeszedł przez nię.
Àwọn tí a fi ilẹ̀ ayé fún nìkan, ti àlejò kan kò sì là wọ́n kọjá.
20 Po wszystkie dni swoje sam siebie niepobożny boleśnie trapi, a nie wiele lat zamierzono okrutnikowi.
Ènìyàn búburú ń ṣe làálàá, pẹ̀lú ìrora, ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo, àti iye ọdún ní a dá sílẹ̀ fún aninilára.
21 Głos straszliwy brzmi w uszach jego, że czasu pokoju pustoszący przypadnie nań.
Ìró ìbẹ̀rù ń bẹ ní etí rẹ̀; nínú ìrora ni apanirun yóò dìde sí i.
22 Nie wierzy, żeby się miał nawrócić z ciemności, obawiając się zewsząd miecza.
Kò gbàgbọ́ pé òun ó jáde kúrò nínú òkùnkùn; a sì ṣà á sápá kan fún idà.
23 Tuła się za chlebem, szukając gdzieby był; wie, że zgotowany jest dla niego dzień ciemności.
Ó ń wò káàkiri fún oúnjẹ wí pé, níbo ní ó wà? Ó mọ̀ pé ọjọ́ òkùnkùn súnmọ́ tòsí.
24 Straszą go utrapienie i ucisk, i zmocnią się przeciwko niemu jako król gotowy do boju.
Ìpọ́njú pẹ̀lú ìrora ọkàn yóò mú un bẹ̀rù, wọ́n ó sì ṣẹ́gun rẹ̀ bi ọba ti ìmúra ogun.
25 Bo wyciągną przeciw Bogu rękę swą, a przeciwko Wszechmocnemu zmocnił się.
Nítorí pé ó ti nawọ́ rẹ̀ jáde lòdì sí Ọlọ́run, ó sì múra rẹ̀ le lòdì sí Olódùmarè,
26 Natrze nań na szyję jego z gęstemi i wyniosłemi tarczami swemi.
ó súre, ó sì fi ẹ̀yìn gíga, àní fi ike-kókó àpáta rẹ̀ tí ó nípọn kọlù ú.
27 Bo okrył twarz swą tłustością swoją, a fałdów mu się naczyniło na słabiźnie.
“Nítorí tí òun fi ọ̀rá rẹ̀ bo ara rẹ̀ lójú, o sì ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran sí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀.
28 I mieszka w miastach popustoszonych, i w domach, w których nie mieszkano, które się miały obrócić w kupę rumu.
Òun sì gbé inú ahoro ìlú, àti nínú ilẹ̀ tí ènìyàn kò gbé mọ́, tí ó múra tán láti di àlàpà.
29 Nie zbogaci się, i nie ostoi się majętność jego, ani się rozszerzy na ziemi doskonałość takowych.
Òun kò lé di ọlọ́rọ̀, bẹ́ẹ̀ ohun ìní rẹ̀ kò lè dúró pẹ́; bẹ́ẹ̀ kò lè mú pípé rẹ̀ dúró pẹ́ lórí ilẹ̀.
30 Nie wynijdzie z ciemności; świeżą jego latorośl ususzy płomień, a zginie od ducha ust jego.
Òun kì yóò jáde kúrò nínú òkùnkùn; ọ̀wọ́-iná ni yóò jó ẹ̀ka rẹ̀, àti nípasẹ̀ ẹ̀mí ẹnu Ọlọ́run ní a ó gba kúrò.
31 Nie wierzy, że w próżności jest, który błądzi; a że próżność będzie nagrodą jego.
Kí òun kí ó má ṣe gbẹ́kẹ̀lé asán, kí ó má sì ṣe tan ara rẹ̀ jẹ. Nítorí pé asán ní yóò jásí èrè rẹ̀.
32 Przed wypełnieniem dni swoich wycięty będzie, a różdżka jego nie zakwitnie.
A ó mú un ṣẹ ṣáájú pípé ọjọ́ rẹ̀, ẹ̀ka rẹ̀ kì yóò sì tutù.
33 Jako winna macica utraci niedojrzałe grona swoje, a jako oliwa kwiat swój zrzuci.
Yóò dàbí àjàrà tí a gbọn èso àìpọ́n rẹ̀ dànù, yóò sì rẹ̀ ìtànná rẹ̀ dànù bí i ti igi Olifi.
34 Albowiem zgromadzenie obłudnych spustoszone będzie, a ogień pożre przybytki pobudowane za dary.
Nítorí pé ayọ̀ àwọn àgàbàgebè yóò túká, iná ní yóò sì jó àgọ́ àwọn tí ó fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀.
35 Poczęli kłopot, a porodzili nieprawość; a żywot ich gotuje zdradę.
Wọ́n lóyún ìwà ìkà, wọ́n sì bí ẹ̀ṣẹ̀, ikùn wọn sì pèsè ẹ̀tàn.”