< Hioba 13 >

1 Oto te wszystkie rzeczy widziało oko moje, słyszało ucho moje, i zrozumiało.
“Wò ó, ojú mi ti rí gbogbo èyí rí, etí mí sì gbọ́, ó sì ti yé mi.
2 Jako wy to wiecie, tak ja też wiem, i nie jestem podlejszym niźli wy.
Ohun tí ẹ̀yin mọ̀, èmi mọ̀ pẹ̀lú, èmi kò kéré sí i yin.
3 Wszakże radbym z Wszechmocnym mówił, i radbym się z Bogiem rozpierał.
Nítòótọ́ èmi ó bá Olódùmarè sọ̀rọ̀, èmi sì ń fẹ́ bá Ọlọ́run sọ àsọyé.
4 Boście wy sprawcy kłamstwa: wszyscyście wy lekarze nikczemni.
Ẹ̀yin fi irọ́ bá mi sọ̀rọ̀, oníṣègùn lásán ni gbogbo yín.
5 Byście wy raczej milczeli, a poczytanoby wam to za mądrość.
Háà! ẹ̀yin kì bá kúkú dákẹ́! Èyí ni kì bá sì ṣe ọgbọ́n yín.
6 Słuchajcież teraz odporu mego, a dowody ust moich obaczcie.
Ẹ gbọ́ àwíyé mi nísinsin yìí; ẹ sì fetísílẹ̀ sí àròyé ẹnu mi.
7 Izali broniąc Boga mówić będziecie nieprawość? albo za nim mówić będziecie fałsz?
Ẹ̀yin fẹ́ sọ ìsọkúsọ fún Ọlọ́run? Ki ẹ sì fi ẹ̀tàn sọ̀rọ̀ gbè é?
8 Czy się na osobę jego oglądać będziecie? Czy się o Boga będziecie spierać?
Ẹ̀yin fẹ́ ṣe ojúsàájú rẹ̀? Ẹ̀yin fẹ́ gbèjà fún Ọlọ́run?
9 Zaż to dobrze będzie, gdy on was będzie próbował? Zaż, jako człowiek oszukany bywa, tak wy go oszukacie?
Ó ha dára to tí yóò hú àṣírí yín síta, tàbí kí ẹ̀yin tàn án bí ẹnìkan ti í tan ẹnìkejì?
10 Zaiste karać was będzie, jeźlibyście skrycie twarz jego przyjmowali.
Yóò máa bá yín wí nítòótọ́, bí ẹ̀yin bá ṣe ojúsàájú ènìyàn níkọ̀kọ̀.
11 Izali zacność jego nie ustraszy was? a strach jego nie przypadnie na was?
Ìwà ọlá rẹ̀ kì yóò bà yín lẹ́rù bí? Ìpayà rẹ̀ kì yóò pá yín láyà?
12 Pamiątki wasze podobne są popiołowi, a wyniosłość wasza kupie błota.
Àwọn òwe yín dàbí eérú, bẹ́ẹ̀ ni àwọn odi ìlú yin dàbí amọ̀.
13 Milczcież, zaniechajcie mię, a ja mówić będę; a niech przyjdzie na mię, co chce.
“Ẹ pa ẹnu yín mọ́ kúrò lára mi, kí èmi kí ó lè sọ̀rọ̀, ki ohun tí ń bọ̀ wá í bá mi, le è máa bọ̀.
14 Czemuż mam szarpać ciało moje zębami mojemi, i duszę moję kłaść w ręce swe?
Ǹjẹ́ nítorí kí ni èmi ṣe ń fi eyín mi bu ẹran-ara mi jẹ, tí mo sì gbé ẹ̀mí mi lé ara mi lọ́wọ́?
15 Oto, choćby mię i zabił, przecię w nim będę ufał; wszakże dróg moich przed obliczem jego będę bronił.
Bí ó tilẹ̀ pa mí, síbẹ̀ èmi ó máa gbẹ́kẹ̀lé e, èmi ó máa tẹnumọ́ ọ̀nà mi níwájú rẹ̀.
16 Onci sam będzie zbawieniem mojem, ale przed oblicze jego obłudnik nie przyjdzie;
Èyí ni yóò sì ṣe ìgbàlà mi, àgàbàgebè kì yóò wá síwájú rẹ̀.
17 Słuchajcież z pilnością mowy mojej, a powieść moja niech przyjdzie w uszy wasze.
Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹnu mi ní ìfarabalẹ̀, jẹ́ kí ọ̀rọ̀ mí dún ni etí yín.
18 Oto się teraz gotuję do prawa, i wiem, że usprawiedliwiony będę.
Wò ó nísinsin yìí, èmi ti mura ọ̀ràn mi sílẹ̀; èmi mọ̀ pé a ó dá mi láre.
19 Któż się będzie spierał ze mną, tak abym umilknął i umarł?
Ta ni òun ti yóò bá mi ṣàròyé? Ǹjẹ́ nísinsin yìí, èmi fẹ́ pa ẹnu mi mọ́, èmi ó sì jọ̀wọ́ ẹ̀mí mi lọ́wọ́.
20 Tylko dwóch rzeczy, o Boże! nie czyń ze mną, przed oblicznością twoją nie skryję się.
“Ṣùgbọ́n, má ṣe ṣe ohun méjì yìí sí mi, nígbà náà ni èmi kì yóò sì fi ara mi pamọ́ kúrò fún ọ.
21 Rękę twoję odemnie oddal, a strach twój niech mną nie trwoży.
Fa ọwọ́ rẹ sẹ́yìn kúrò lára mi, má sì jẹ́ kí ẹ̀rù rẹ kí ó pá mi láyà.
22 Potem zawołaj mię, a ja tobie odpowiem; albo ja niech mówię, a ty mnie odpowiedz.
Nígbà náà ni kí ìwọ kí ó pè, èmi o sì dáhùn, tàbí jẹ́ kí ń máa sọ̀rọ̀, ki ìwọ kí ó sì dá mi lóhùn.
23 Wieleż jest nieprawości i grzechów moich? przestępstwo moje, grzech mój pokaż mi.
Mélòó ní àìṣedéédéé àti ẹ̀ṣẹ̀ mi? Mú mi mọ̀ ìrékọjá àti ẹ̀ṣẹ̀ mi.
24 Przeczże oblicze twoje zakrywasz, a poczytasz mię sobie za nieprzyjaciela?
Nítorí kí ni ìwọ ṣe pa ojú rẹ mọ́, tí o sì yàn mí ní ọ̀tá rẹ?
25 Izali skruszysz liść chwiejący się? a źdźbło suche gonić będziesz?
Ìwọ ó fa ewé ti afẹ́fẹ́ ń fẹ́ síyìn-ín sọ́hùn-ún ya bi? Ìwọ a sì máa lépa ìyàngbò?
26 Albowiem piszesz przeciwko mnie gorzkości, a przywłaszczasz mi nieprawość młodości mojej;
Nítorí pé ìwọ kọ̀wé ohun kíkorò sí mi, o sì mú mi jogún àìṣedéédéé èwe mi.
27 I włożyłeś w pęta nogi moje, a podstrzegasz wszystkich ścieżek moich, i na ślad nóg moich następujesz.
Ìwọ kàn àbà mọ́ mi lẹ́sẹ̀ pẹ̀lú, ìwọ sì ń wò ipa ọ̀nà ìrìn mi ní àwòfín; nípa fífi ìlà yí gígísẹ̀ mi ká.
28 Choć jako spróchniałe drzewo niszczeję; a jako szata, którą mól psuje.
“Bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn ń ṣègbé bí ohun ìdíbàjẹ́, bi aṣọ tí kòkòrò jẹ.

< Hioba 13 >