< Hioba 11 >

1 I odpowiedział Sofar Naamatczyk, i rzekł:
Ìgbà náà ni Sofari, ará Naama, dáhùn, ó sì wí pé,
2 Izaż się nie godzi na wiele słów odpowiedzieć? Albo izali mąż wielomowny będzie usprawiedliwiony?
“A ha lè ṣe kí a máa dáhùn sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọ̀rọ̀? A ha lè fi gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí da ènìyàn láre?
3 Bedąż na twoje plotki ludzie milczeć? A gdy ty sobie przeszydzasz, ciebie nikt nie zawstydzi?
Ṣé àmọ̀tán rẹ le mú ènìyàn pa ẹnu wọn mọ́ bí? Ṣé ẹnikẹ́ni kò ní bá ọ wí bí ìwọ bá yọ ṣùtì sí ni?
4 Albowiemeś powiedział: Czysta jest nauka moja, a jestem czystym przed oczyma twemi.
Ìwọ sá à ti wí fún Ọlọ́run pé, ‘Ìṣe mi jẹ́ aláìléérí, èmi sì mọ́ ní ojú rẹ.’
5 Ale gdyby Bóg chciał mówić, i otworzyć usta swoje przeciwko tobie:
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run ìbá jẹ́ sọ̀rọ̀, kí ó sì ya ẹnu rẹ̀ sí ọ
6 Tedyćby objawił tajemnice mądrości, żeś dwa kroć większe karanie nadto zasłużył; przetoż uznaj, że cię Bóg przebaczył dla nieprawości twojej.
kí ó sì fi àṣírí ọgbọ́n hàn ọ́ pé, ó pọ̀ ju òye ènìyàn lọ, nítorí náà, mọ̀ pé Ọlọ́run ti gbàgbé àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kan.
7 Izali tajemnice Boże wybadasz? albo doskonałości Wszechmocnego dościgniesz?
“Ìwọ ha le ṣe àwárí ohun ìjìnlẹ̀ Ọlọ́run bí? Ìwọ ha le ṣe àwárí ibi tí Olódùmarè dé bi?
8 Wyższe są niż niebiosa, cóż uczynisz? Głębsze niż piekło, jakoż poznasz? (Sheol h7585)
Ó ga ju àwọn ọ̀run lọ; kí ni ìwọ le è ṣe? Ó jìn ju jíjìn isà òkú lọ; kí ni ìwọ le mọ̀? (Sheol h7585)
9 Dłuższa miara ich, niż ziemia, a szersza, niż morze.
Ìwọ̀n rẹ̀ gùn ju ayé lọ, ó sì ní ibú ju òkun lọ.
10 Jeźli wypełni, albo jeźli zawrze, albo jeźli w jedno ściśnie, któż go zawściągnie?
“Bí òun bá rékọjá, tí ó sì sé ọnà tàbí tí ó sì mú ni wá sí ìdájọ́, ǹjẹ́, ta ni ó lè dí i lọ́wọ́?
11 Albowiem on zna marność ludzką, i widzi nieprawość; a nie miałby tego baczyć?
Òun sá à mọ ẹlẹ́tàn ènìyàn; àti pé ṣé bí òun bá rí ohun búburú, ṣé òun kì i fi iyè sí i?
12 Człowiek nierozumny nabywa rozumu, choć się jako źrebię leśnego osła rodzi człowiek.
Ṣùgbọ́n òmùgọ̀ ènìyàn ki yóò di ọlọ́gbọ́n bi ko ti rọrùn fún ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó láti bí ènìyàn.
13 Jeźli ty przygotujesz serce twoje, a wyciągniesz do niego ręce twoje;
“Bí ìwọ bá fi ọkàn rẹ fún un, tí ìwọ sì na ọwọ́ rẹ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀,
14 Jeźliż nieprawość jest w ręce twej oddal ją, a mieszkać nie dopuszczaj nieprawości w przybytkach twoich;
bí ìwọ bá gbé ẹ̀ṣẹ̀ tí ń bẹ ní ọwọ́ rẹ jù sọnù tí ìwọ kò sì jẹ́ kí aburú gbé nínú àgọ́ rẹ,
15 Tedy podniesiesz oblicze twoje bez zmazy, a będziesz stały, i nie będziesz się bał.
nígbà náà ni ìwọ ó gbé ojú rẹ sókè láìní àbàwọ́n, àní ìwọ yóò dúró ṣinṣin, ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù.
16 Albowiem zapomnisz kłopotu, a jako wody, które pominęły, wspominać go będziesz.
Nítorí pé ìwọ ó gbàgbé ìṣòro rẹ; ìwọ ó sì rántí rẹ̀ bí omi tí ó ti sàn kọjá lọ.
17 I nad południe jaśniejszy nastanie czas twój; zaćmiszli się, będziesz jako zaranek.
Ọjọ́ ayé rẹ yóò sì mọ́lẹ̀ ju ọ̀sán gangan lọ, bí òkùnkùn tilẹ̀ bò ọ́ mọ́lẹ̀ nísinsin yìí, ìwọ ó dàbí òwúrọ̀.
18 I będziesz ufał, mając nadzieję, a jako w okopach bezpiecznie spać będziesz.
Ìwọ ó sì wà láìléwu, nítorí pé ìrètí wà; àní ìwọ ó rin ilé rẹ wò, ìwọ ó sì sinmi ní àlàáfíà.
19 Będziesz leżał, a nikt cię nie przestraszy; i uniżać się będą przed twarzą twoją wiele ich.
Ìwọ ó sì dùbúlẹ̀ pẹ̀lú, kì yóò sì sí ẹni tí yóò dẹ́rùbà ọ́, àní ènìyàn yóò máa wá ojúrere rẹ.
20 Ale oczy niepobożnych ustaną i ucieczka ich zginie, a nadzieja ich będzie jako wyjście duszy z człowieka.
Ṣùgbọ́n ojú ìkà ènìyàn yóò mófo; gbogbo ọ̀nà àbáyọ ni yóò nù wọ́n, ìrètí wọn a sì dàbí ẹni tí ó jọ̀wọ́ ẹ̀mí rẹ̀ lọ́wọ́.”

< Hioba 11 >